< UHoseya 1 >

1 Ilizwi leNkosi elafika kuHoseya indodana kaBeyeri ensukwini zaboUziya, uJothamu, uAhazi, uHezekhiya, amakhosi akoJuda, lensukwini zikaJerobhowamu indodana kaJowasi inkosi yakoIsrayeli.
Ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó tọ Hosea ọmọ Beeri wá ní àkókò ìjọba Ussiah, Jotamu, Ahasi àti Hesekiah; àwọn ọba Juda àti ní àkókò ọba Jeroboamu ọmọ Jehoaṣi ní Israẹli.
2 Ukuqala kwelizwi leNkosi ngoHoseya. INkosi yasisithi kuHoseya: Hamba uzithathele umfazi wobuwule, labantwana bobuwule; ngoba ilizwe liyawula kakhulu ngokungayilandeli iNkosi.
Nígbà tí Olúwa bẹ̀rẹ̀ sí ní sọ̀rọ̀ láti ẹnu Hosea, Olúwa wí fún un pé, “Lọ, fẹ́ àgbèrè obìnrin kan fún ara rẹ, kí ó sì bí ọmọ àgbèrè fún ọ nípasẹ̀ àwọn ọkùnrin mìíràn, nítorí ilẹ̀ ti ṣẹ ẹ̀ṣẹ̀ àgbèrè púpọ̀ nípa yíyapa kúrò lọ́dọ̀ Olúwa.”
3 Wasehamba wathatha uGomeri indodakazi kaDibilayimi; wasekhulelwa, wamzalela indodana.
Nígbà náà ni ó sì lọ, ó sì fẹ́ Gomeri ọmọbìnrin Diblaimu, ọmọbìnrin náà sì lóyún, ó sì bí ọmọkùnrin kan fún un.
4 INkosi yasisithi kuye: Biza ibizo layo uthi nguJizereyeli, ngoba kuseseyisikhatshana ngizaphindisela icala legazi leJizereyeli phezu kwendlu kaJehu, ngiwuqede umbuso wendlu kaIsrayeli.
Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Hosea pé, “Pe orúkọ ọmọ náà ní Jesreeli, nítorí pé láìpẹ́ ni èmi yóò jẹ ìdílé Jehu ní ìyà fún ẹ̀jẹ̀ àwọn ènìyàn tó pa ní ìpakúpa ní Jesreeli, Èmi yóò sì mú ìjọba Israẹli wá sí òpin.
5 Kuzakuthi ngalolosuku ngephule idandili likaIsrayeli esigodini seJizereyeli.
Ní ọjọ́ náà ni Èmi yóò ṣẹ́ ọrun Israẹli ní àfonífojì Jesreeli.”
6 Wasebuya ekhulelwa, wazala indodakazi. UNkulunkulu wasesithi kuye: Biza ibizo layo uthi nguLo-Ruhama, ngoba kangisayikubuya ngihawukele indlu kaIsrayeli, kodwa ngizabasusa lokubasusa.
Gomeri sì tún lóyún, ó sì bí ọmọbìnrin kan. Olúwa sọ fún un pé, “Pe orúkọ rẹ̀ ní Lo-ruhama, nítorí pé, Èmi kò ní ṣàánú fún ilé Israẹli mọ́, Èmi kò sì ní dáríjì wọ́n.
7 Kodwa ngizayihawukela indlu yakoJuda, ngibasindise ngeNkosi uNkulunkulu wabo; njalo kangiyikubasindisa ngedandili, loba ngenkemba, loba ngempi, ngamabhiza, kumbe ngabagadi bamabhiza.
Síbẹ̀, èmi yóò ṣàánú fún ilé Juda, èmi ó gbà wọ́n—kì í ṣe nípa ọfà, idà tàbí ogun, ẹṣin tàbí kẹ̀kẹ́ ẹlẹ́ṣin bí kò ṣe nípa Olúwa Ọlọ́run wọn.”
8 Esemlumulile uLo-Ruhama, wakhulelwa, wazala indodana.
Lẹ́yìn ìgbà tí ó gba ọmú lẹ́nu Lo-ruhama, ó sì lóyún ó sì bí ọmọkùnrin mìíràn. Nígbà náà ni
9 UNkulunkulu wasesithi: Biza ibizo layo uthi nguLo-Ami; ngoba kalisibo abantu bami, ngakho mina kangisuye owenu.
Olúwa sì sọ fún un pé, “Pe orúkọ rẹ̀ ní Lo-Ammi, nítorí pé ẹ kì í ṣe ènìyàn mi, èmi náà kì í sì í ṣe Ọlọ́run yín.
10 Kube kanti inani labantwana bakoIsrayeli lizakuba ngangetshebetshebe lolwandle elingeke lilinganiswe elingeke libalwe. Njalo kuzakuthi, endaweni yokuthi kuthiwe kubo: Kalisibo abantu bami; kuzakuthiwa kubo: Lingabantwana bakaNkulunkulu ophilayo.
“Ṣùgbọ́n àwọn ọmọ Israẹli yóò pọ̀ bí i iyanrìn etí Òkun tí a kò le wọ́n, tí a kò sì le è kà, yóò sì ṣe. Ní ibi tí wọ́n ti sọ fún wọn pé. ‘Ẹ̀yin kì í ṣe ènìyàn mi,’ níbẹ̀ ni a ó ti máa pè wọ́n ní ‘Ọmọ Ọlọ́run alààyè.’
11 Ngakho abantwana bakoJuda labantwana bakoIsrayeli bazabuthaniswa ndawonye, bazimisele inhloko eyodwa, benyuke baphume elizweni. Ngoba luzakuba lukhulu usuku lweJizereyeli.
Àwọn ènìyàn Juda àti àwọn ènìyàn Israẹli yóò parapọ̀, wọn yóò sì yan olórí kan tí yóò jáde láti ilẹ̀ náà, nítorí pé ọjọ́ ńlá ni ọjọ́ Jesreeli yóò jẹ́.

< UHoseya 1 >