< UGenesisi 49 >

1 UJakobe wasebiza amadodana akhe wathi: Buthanani ukuze ngilazise okuzalehlela ensukwini ezizayo.
Nígbà náà ni Jakọbu ránṣẹ́ pe àwọn ọmọ rẹ̀, ó sì wí pé, “Ẹ kó ara yín jọ pọ̀, kí n le è sọ ohun tí yóò ṣẹlẹ̀ ní ọjọ́ iwájú fún un yín.
2 Buthanani, lizwe madodana kaJakobe, limlalele uIsrayeli uyihlo.
“Ẹ kó ara yín jọ pọ̀, kí ẹ sì tẹ́tí, ẹ̀yin ọmọ Jakọbu; ẹ fetí sí Israẹli baba yín.
3 Rubeni, ulizibulo lami, amandla ami, lokuqala kokuqina kwami, ukuphelela kwesithunzi, lokuphelela kwamandla.
“Reubeni, ìwọ ni àkọ́bí mi, agbára mi, ìpilẹ̀ṣẹ̀ ipá mi, títayọ ní ọlá àti títayọ ní agbára.
4 Uphuphuma njengamanzi, kawuyikuba ngopheleleyo, ngoba ukhwele embhedeni kayihlo, wasuwona; wakhwela embhedeni wami.
Ẹni ríru bí omi Òkun, ìwọ kì yóò tayọ mọ́, nítorí pé ìwọ gun ibùsùn baba rẹ, lórí àkéte mi, ìwọ sì bà á jẹ́ (ìwọ bá ọ̀kan nínú àwọn aya baba rẹ lòpọ̀).
5 USimeyoni loLevi bayizelamani; inkemba zabo ziyizikhali zokuphanga.
“Simeoni àti Lefi jẹ́ arákùnrin— idà wọn jẹ́ ohun èlò ogun alágbára.
6 Umphefumulo wami ungangeni emphakathini wabo wangasese, udumo lwami lungahlangani emhlanganweni wabo; ngoba ngolaka lwabo babulala umuntu, langokuzithokozisa baquma izinkabi umsipha.
Kí ọkàn mi má ṣe ni àṣepọ̀ pẹ̀lú wọn, kí n má sì ṣe dúró níbí ìpéjọpọ̀ wọn, nítorí wọ́n ti pa àwọn ènìyàn ní ìbínú wọn, wọ́n sì da àwọn màlúù lóró bí ó ti wù wọ́n.
7 Kaluqalekiswe ulaka lwabo ngoba lulamandla, lentukuthelo yabo ngoba ilesihluku. Ngizabehlukanisa koJakobe, ngibahlakaze koIsrayeli.
Ìfibú ni ìbínú wọn nítorí tí ó gbóná púpọ̀, àti fún ìrunú wọn nítorí tí ó kún fún ìkà! Èmi yóò tú wọn ká ní Jakọbu, èmi ó sì fọ́n wọn ká ní Israẹli.
8 Juda, wena, abafowenu bazakudumisa; isandla sakho sizakuba sentanyeni yezitha zakho; amadodana kayihlo azakukhothamela.
“Juda, àwọn arákùnrin rẹ yóò yìn ọ, ọwọ́ rẹ yóò wà ní ọrùn àwọn ọ̀tá rẹ, àwọn ọmọkùnrin baba rẹ yóò foríbalẹ̀ fún ọ.
9 UJuda ungumdlwane wesilwane; wenyukile empangweni, ndodana yami, uguqile, ulele njengesilwane, lanjengesilwane esisikazi; ngubani ozamsukumisa?
Ọmọ kìnnìún ni ọ́, ìwọ Juda, o darí láti igbó ọdẹ, ọmọ mi. Bí i kìnnìún, o ba mọ́lẹ̀, o sì sùn sílẹ̀ bí i abo kìnnìún, ta ni ó tó bẹ́ẹ̀, kí o lé e dìde?
10 Intonga yobukhosi kayiyikusuka kuJuda, lomnikumthetho phakathi kwenyawo zakhe, aze afike uShilo, njalo izizwe zizamlalela.
Ọ̀pá oyè kì yóò kúrò ní Juda bẹ́ẹ̀ ni ọ̀pá-ìṣàkóso kì yóò kúrò láàrín ẹsẹ̀ rẹ̀, títí tí Ṣilo tí ó ni í yóò fi dé, tí gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè yóò máa wárí fún un.
11 Ubophela ithole lakhe likababhemi evinini, lethole likababhemikazi wakhe evinini elihle. Uhlamba isigqoko sakhe ewayinini, lesembatho sakhe egazini lezithelo zevini.
Yóò má so ọmọ ẹṣin rẹ̀ mọ́ igi àjàrà, àti ọmọ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ̀ mọ́ ẹ̀ka tí ó dára jù. Yóò fọ aṣọ rẹ̀ nínú wáìnì àti ẹ̀wù rẹ̀ nínú omi-pupa ti èso àjàrà.
12 Amehlo akhe azakuba nsundu ngewayini, lamazinyo akhe mhlophe ngochago.
Ojú rẹ̀ yóò rẹ̀ dòdò ju wáìnì lọ, eyín rẹ yóò sì funfun ju omi-ọyàn lọ.
13 UZebuluni uzahlala ethekwini lolwandle, abe litheku lemikhumbi, lomngcele wakhe uzakuba ngaseSidoni.
“Sebuluni yóò máa gbé ní etí Òkun, yóò sì jẹ́ èbúté fún ọkọ̀ ojú omi, agbègbè rẹ yóò tàn ká títí dé Sidoni.
14 UIsakari ungubabhemi olamathambo alamandla, oqutha phakathi kwemithwalo emibili.
“Isakari jẹ́ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ alágbára tí ó dùbúlẹ̀ láàrín agbo àgùntàn.
15 Wathi ebona indawo yokuphumula ukuthi inhle, lelizwe ukuthi liyabukeka, wagobisa amahlombe akhe ukuze athwale, waba yinceku esibhalweni.
Nígbà tí ó bá rí bí ibi ìsinmi òun ti dára tó, àti bí ilẹ̀ rẹ̀ ti ní ìdẹ̀ra tó, yóò tẹ èjìká rẹ̀ ba láti ru àjàgà, yóò sì fi ara rẹ̀ fún iṣẹ́ ipá.
16 UDani uzakwahlulela abantu bakhe, njengesinye sezizwe zakoIsrayeli.
“Dani yóò ṣe ìdájọ́ àwọn ènìyàn rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọ̀kan nínú àwọn ẹ̀yà Israẹli.
17 UDani uzakuba yinyoka endleleni, inhlangwana emkhondweni, eluma izithende zebhiza, ukuze umgadi walo awe nyovane.
Dani yóò jẹ́ ejò ni pópónà àti paramọ́lẹ̀ ní ẹ̀bá ọ̀nà, tí ó bu ẹṣin jẹ ní ẹsẹ̀, kí ẹni tí ń gùn ún bá à le è ṣubú sẹ́yìn.
18 Ngilindele usindiso lwakho, Nkosi.
“Mo ń dúró de ìtúsílẹ̀ rẹ, Olúwa.
19 UGadi, iviyo lizamhlasela, kodwa yena uzahlasela ezithendeni.
“Ẹgbẹ́ ogun àwọn ẹlẹ́ṣin yóò kọlu Gadi, ṣùgbọ́n yóò kọlu wọ́n ní gìgísẹ̀ wọn.
20 Kuvela kuAsheri, ukudla kwakhe kuzanona, uzaveza izibiliboco zenkosi.
“Oúnjẹ Aṣeri yóò dára; yóò ṣe àsè tí ó yẹ fún ọba.
21 UNafithali uyimpala ethukululiweyo, eveza amazwi amahle.
“Naftali yóò jẹ́ abo àgbọ̀nrín tí a tú sílẹ̀ tí ó ń bí ọmọ dáradára.
22 UJosefa ulugatsha oluthelayo, ugatsha oluthelayo emthonjeni, ingatsha zikhwela phezu komduli.
“Josẹfu jẹ́ àjàrà eléso, àjàrà eléso ní etí odò, tí ẹ̀ka rẹ̀ gun orí odi.
23 Abatshoki basebemphatha kabuhlungu, bamtshoka, bamzonda.
Pẹ̀lú ìkorò, àwọn tafàtafà dojú ìjà kọ ọ́, wọ́n tafà sí í pẹ̀lú ìkanra.
24 Kodwa idandili lakhe lahlala liqinile, lengalo zezandla zakhe zaqiniswa ngezandla zikaSomandla kaJakobe, okuvela khona umelusi, ilitshe likaIsrayeli,
Ṣùgbọ́n ọrun rẹ̀ dúró ni agbára, ọwọ́ agbára rẹ̀ ni a sì mu lára le, nítorí ọwọ́ alágbára Jakọbu, nítorí olùtọ́jú àti aláàbò àpáta Israẹli,
25 ngoNkulunkulu kayihlo ozakusiza, langoSomandla ozakubusisa ngezibusiso zamazulu ezivela phezulu, izibusiso zokujula okulele phansi, izibusiso zamabele lesizalo,
nítorí Ọlọ́run baba rẹ tí ó ràn ọ́ lọ́wọ́, nítorí Olódùmarè tí ó bùkún ọ pẹ̀lú láti ọ̀run wá, ìbùkún ọ̀gbìn tí ó wà ní ìsàlẹ̀, ìbùkún ti ọmú àti ti inú.
26 izibusiso zikayihlo ziyedlula izibusiso zabokhokho bami, kuze kube sengqongeni zamaqaqa aphakade; zizakuba phezu kwekhanda likaJosefa, laphezu kwenkanda yalowo owehlukaniswe kubafowabo.
Ìbùkún baba rẹ pọ̀ púpọ̀ ju ìbùkún àwọn òkè ńlá ìgbàanì, ju ẹ̀bùn ńlá àwọn òkè láéláé. Jẹ́ kí gbogbo èyí sọ̀kalẹ̀ sí orí Josẹfu, lé ìpéǹpéjú ọmọ-aládé láàrín arákùnrin rẹ̀.
27 UBhenjamini uyimpisi edabulayo; ekuseni izakudla ekujimbileyo, lakusihlwa izakwehlukanisa impango.
“Benjamini jẹ́ ìkookò tí ó burú; ní òwúrọ̀ ni ó jẹ ẹran ọdẹ rẹ, ní àṣálẹ́, ó pín ìkógun.”
28 Bonke labo bayizizwe ezilitshumi lambili zakoIsrayeli; futhi lokho yikho uyise akukhuluma kubo ebabusisa; ngulowo lalowo ngesibusiso sakhe wababusisa.
Gbogbo ìwọ̀nyí ni àwọn ẹ̀yà Israẹli méjìlá, èyí sì ni ohun tí baba wọn sọ fún wọn nígbà tí ó súre fún wọn, tí ó sì fún ẹnìkọ̀ọ̀kan ní ìbùkún tí ó tọ́ sí i.
29 Wasebalaya wathi kubo: Sengibuthelwa ebantwini bakithi; lingingcwabe labobaba obhalwini olusensimini kaEfroni umHethi,
Nígbà náà ni ó fún wọn ní àwọn ìlànà yìí, “Ọjọ́ ikú mi kù fẹ́ẹ́rẹ́. Kí ẹ sin mí sí ibojì pẹ̀lú àwọn baba mi ní inú àpáta ní ilẹ̀ Hiti ará Efroni.
30 obhalwini olusensimini yeMakaphela eqondane leMamre, elizweni leKhanani, uAbrahama owaluthenga lensimu kuEfroni umHethi ibe yindawo yethu yokungcwabela.
Ihò àpáta tí ó wà ní ilẹ̀ Makpela, nítòsí Mamre ní Kenaani, èyí tí Abrahamu rà gẹ́gẹ́ bí ilẹ̀ ìsìnkú lọ́wọ́ Efroni ará Hiti pẹ̀lú ilẹ̀ rẹ̀.
31 Lapho bangcwaba oAbrahama loSara umkakhe; lapho bangcwaba oIsaka loRebeka umkakhe; lalapho ngangcwaba uLeya,
Níbẹ̀ ni a sin Abrahamu àti aya rẹ̀ Sara sí, níbẹ̀ ni a sin Isaaki àti Rebeka aya rẹ̀ sí, níbẹ̀ sì ni mo sìnkú Lea sí.
32 insimu, lobhalu olukiyo, kwathengwa emadodaneni kaHethi.
Ilẹ̀ náà àti ihò àpáta tí ó wà nínú rẹ̀ ni a rà lọ́wọ́ ará Hiti.”
33 Kwathi uJakobe eseqedile ukulaya amadodana akhe, waqoqela inyawo zakhe embhedeni, waphela, wabuthelwa ebantwini bakibo.
Nígbà tí Jakọbu ti pàṣẹ yìí fún àwọn ọmọ rẹ̀, ó gbé ẹsẹ̀ rẹ̀ sókè sórí ibùsùn, ó sì kú, a sì ko jọ pọ̀ mọ́ àwọn ènìyàn rẹ̀.

< UGenesisi 49 >