< UGenesisi 48 >

1 Kwasekusithi emva kwalezizinto kwathiwa kuJosefa: Khangela, uyihlo uyagula. Wasethatha amadodana akhe amabili laye, uManase loEfrayimi.
Lẹ́yìn ìgbà díẹ̀ si, a wí fún Josẹfu pé, “Baba rẹ ń ṣàìsàn,” nítorí náà, ó mú àwọn ọmọ rẹ̀ méjèèjì, Manase àti Efraimu lọ́wọ́ lọ pẹ̀lú rẹ̀.
2 Kwasekubikwa kuJakobe ukuthi: Khangela, indodana yakho uJosefa iyeza kuwe. UIsrayeli waseziqinisa wahlala embhedeni.
Nígbà tí a sọ fún Jakọbu pé, “Josẹfu ọmọ rẹ wá sí ọ̀dọ̀ rẹ,” Israẹli rọ́jú dìde jókòó lórí ibùsùn rẹ̀.
3 UJakobe wasesithi kuJosefa: UNkulunkulu uSomandla wabonakala kimi eLuzi elizweni leKhanani, wangibusisa,
Jakọbu wí fún Josẹfu pé, “El-Ṣaddai, fi ara hàn mí ní Lusi ní ilẹ̀ Kenaani, níbẹ̀ ni ó sì ti súre fún mi.
4 wathi kimi: Khangela, ngizakwenza uzale ngikwandise ngikwenze ube yizizwe ezinengi, nginike inzalo yakho emva kwakho lelilizwe, libe yimfuyo elaphakade.
Ó sì wí fún mi pé, ‘Èmi yóò mú kí o bí sí i, ìwọ yóò sì pọ̀ sí i, èmi yóò sì sọ ọ́ di orílẹ̀-èdè ńlá, èmi yóò sì fún ìwọ àti irú-ọmọ rẹ lẹ́yìn rẹ ní ilẹ̀ yìí gẹ́gẹ́ bí ohun ìní ayérayé.’
5 Khathesi-ke, amadodana akho amabili, owawazalelwa elizweni leGibhithe ngingakafiki kuwe eGibhithe, angawami; uEfrayimi loManase njengoRubeni loSimeyoni bazakuba ngabami.
“Nítorí náà báyìí, àwọn ọmọ rẹ méjèèjì tí a bí fún ọ ní ilẹ̀ Ejibiti, kí èmi kí ó tó tọ̀ ọ́ wá ní ìhín, ni mo sọ di ọmọ mi fúnra mi. Manase àti Efraimu yóò jẹ́ tèmi gẹ́gẹ́ bí Reubeni àti Simeoni ti jẹ́ tèmi.
6 Kodwa izizukulwana zakho ozazizala emva kwabo zizakuba ngezakho; ngebizo labafowabo zizabizwa elifeni lazo.
Àwọn ọmọ mìíràn tí ìwọ bá bí lẹ́yìn wọn yóò jẹ́ ọmọ rẹ. Ní ilẹ̀ tí wọn yóò jogún, orúkọ arákùnrin wọn ni a ó máa fi pè wọ́n.
7 Mina-ke, ekusukeni kwami ePadani, uRasheli wafa elami elizweni leKhanani, endleleni, kuselomangwana ukuya eEfrathi, ngasengimngcwaba khona endleleni yeEfrathi, eyiBhethelehema.
Bí mo ti ń padà láti Padani, Rakeli kú ní ọ̀nà nígbà tí ó ṣì wà ní ilẹ̀ Kenaani, èyí tó mú ìbànújẹ́ bá mi, níbi tí kò jìnnà sí Efrata. Nítorí náà èmí sì sin ín sí ẹ̀bá ọ̀nà tí ó lọ sí Efrata” (tí ṣe Bẹtilẹhẹmu).
8 UIsrayeli wasebona amadodana kaJosefa wathi: Ngobani laba?
Nígbà tí Israẹli rí àwọn ọmọ Josẹfu, ó béèrè wí pé, “Àwọn wo nìyí?”
9 UJosefa wasesithi kuyise: Bangamadodana ami, uNkulunkulu anginika wona lapha. Wasesithi: Ake uwalethe kimi ngiwabusise.
Josẹfu fún baba rẹ̀ lésì pé, “Wọ̀nyí ni àwọn ọmọkùnrin tí Ọlọ́run ti fi fún mi ní ìhín.” Nígbà náà ni Israẹli wí pé, “Kó wọn wá sí ọ̀dọ̀ mi kí èmi kí ó ba à le súre fún wọn.”
10 Njalo amehlo kaIsrayeli ayefiphele ngenxa yobudala, engelakubona. Wasewasondeza kuye, wawanga, wawagona.
Báyìí, ojú Israẹli ti ń di bàìbàì nítorí ogbó, agbára káká sì ni ó fi ń ríran. Josẹfu sì kó àwọn ọmọ rẹ̀ súnmọ́ ọ̀dọ̀ rẹ̀, baba rẹ̀ fẹnukò wọ́n ni ẹnu, ó sì dì mọ́ wọn.
11 UIsrayeli wasesithi kuJosefa: Ngangingacabanganga ukuthi ngingabona ubuso bakho, kodwa khangela, uNkulunkulu ungibonise lenzalo yakho.
Israẹli wí fún Josẹfu pé, “Èmi kò lérò rárá pé, mo tún le rí ojú rẹ mọ́ láéláé, ṣùgbọ́n Ọlọ́run tún fún mi ní àǹfààní, mo sì tún rí àwọn ọmọ rẹ pẹ̀lú.”
12 UJosefa wasewakhupha emadolweni akhe, wakhothama ngobuso bakhe emhlabathini.
Nígbà náà ni Josẹfu kó àwọn ọmọ náà kúrò ní orí eékún baba rẹ̀, ó wólẹ̀, ó sì tẹríba.
13 UJosefa wasebathatha bobabili, uEfrayimi ngesandla sakhe sokunene ngakwesokhohlo sikaIsrayeli, loManase ngesandla sakhe sokhohlo ngakwesokunene sikaIsrayeli, wabasondeza kuye.
Josẹfu sì mú àwọn méjèèjì, Efraimu ni o fi sí ọwọ́ ọ̀tún òun tìkára rẹ̀, èyí tí í ṣe ọwọ́ òsì fún Israẹli, ó sì fi Manase sí ọwọ́ òsì ara rẹ̀, èyí tí ó bọ́ sí ọwọ́ ọ̀tún Israẹli.
14 Kodwa uIsrayeli welula isandla sakhe sokunene, wasibeka ekhanda likaEfrayimi, lanxa engomncinyane, lesandla sakhe sokhohlo ekhanda likaManase, eqondisa izandla zakhe esazi, ngoba uManase wayelizibulo.
Israẹli sì na ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ jáde, ó sì gbe lé Efraimu lórí, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé òun ni àbúrò, ó sì fi ọwọ́ rẹ̀ tàsé ara wọn, ó sì na ọwọ́ òsì lé Manase lórí, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé Manase ni àkọ́bí.
15 Wasembusisa uJosefa wathi: UNkulunkulu abahamba phambi kwakhe obaba oAbrahama loIsaka, uNkulunkulu owangondla kusukela ebukhoneni bami kuze kube lamuhla,
Nígbà náà ni ó súre fún Josẹfu wí pé, “Ǹjẹ́ kí Ọlọ́run, ẹni tí baba mi Abrahamu àti Isaaki rìn níwájú rẹ̀, Ọlọ́run tí ó ti jẹ́ olùtọ́jú àti aláàbò mi ní gbogbo ọjọ́ ayé mi títí di òní,
16 ingilosi engihlenge kokubi konke, ibusise abafana; njalo ibizo lami libizwe kubo, lebizo labobaba oAbrahama loIsaka; bande babebanengi phakathi komhlaba.
Angẹli tí ó dá mi ní ìdè kúrò lọ́wọ́ gbogbo ewu, kí ó súre fún àwọn ọmọkùnrin wọ̀nyí. Kí a máa fi orúkọ mi pè wọ́n àti orúkọ àwọn baba mi Abrahamu àti Isaaki, kí wọn kí ó sì pọ̀ sí i lọ́pọ̀lọ́pọ̀ lórí ilẹ̀ ayé.”
17 Kwathi uJosefa esebonile ukuthi uyise ubeke isandla sakhe sokunene ekhanda likaEfrayimi, kwaba kubi emehlweni akhe; wasibamba isandla sikayise ukuze asisuse ekhanda likaEfrayimi asise ekhanda likaManase.
Nígbà tí Josẹfu rí i pé baba òun gbé ọwọ́ ọ̀tún lé Efraimu lórí, inú rẹ̀ bàjẹ́, ó sì gbá ọwọ́ baba rẹ̀ mú láti gbé ọwọ́ rẹ̀ kúrò lórí Efraimu lọ sí orí Manase.
18 UJosefa wasesithi kuyise: Hayi njalo, baba, ngoba lo ulizibulo; beka isandla sakho sokunene ekhanda lakhe.
Josẹfu wí fun pé, “Rárá, baba mi, èyí ni àkọ́bí, orí rẹ̀ ni kí ìwọ kí o gbé ọwọ́ ọ̀tún rẹ lé.”
19 Kodwa uyise wala wathi: Ngiyazi, ndodana yami, ngiyazi; laye uzakuba yisizwe, laye uzakuba mkhulu; kanti lanxa kunjalo umfowabo omncinyane uzakuba mkhulu kulaye, lenzalo yakhe izakuba yikugcwala kwezizwe.
Ṣùgbọ́n baba rẹ̀ kò gbà, ó wí pé, “Mo mọ̀, ọmọ mi, mo mọ̀. Òun náà yóò di orílẹ̀-èdè, òun náà yóò sì di ńlá. Ṣùgbọ́n àbúrò rẹ̀ yóò di ẹni ńlá jù ú lọ, irú-ọmọ rẹ yóò sì di ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè.”
20 Wasebabusisa ngalolosuku esithi: Ngawe uIsrayeli uzabusisa, esithi: UNkulunkulu kakumise njengoEfrayimi lanjengoManase. Wasebeka uEfrayimi phambi kukaManase.
Ó súre fún wọn lọ́jọ́ náà pé, “Ní orúkọ yín ni Israẹli yóò máa súre yìí pé, ‘Kí Ọlọ́run ṣe ọ́ bí i ti Efraimu àti Manase.’” Ó sì gbé Efraimu gẹ́gẹ́ bí ẹ̀gbọ́n sí Manase.
21 UIsrayeli wasesithi kuJosefa: Khangela, ngiyafa; kodwa uNkulunkulu uzakuba lani, njalo uzalibuyisela elizweni laboyihlo.
Nígbà náà ni Israẹli wí fún Josẹfu pé, “Ọjọ́ ikú mi súnmọ́ etílé, ṣùgbọ́n Ọlọ́run yóò wà pẹ̀lú yín, yóò sì mú un yín padà sí ilẹ̀ àwọn baba yín.
22 Futhi mina ngikunikile isabelo esisodwa okwedlula abafowenu, engasithatha esandleni samaAmori ngenkemba yami langedandili lami.
Pẹ̀lúpẹ̀lú èmi yóò fún ọ ní ìpín kan ju ti àwọn arákùnrin rẹ lọ. Ilẹ̀ tí mo fi idà àti ọ̀kọ̀ mi gbà lọ́wọ́ àwọn ará Amori.”

< UGenesisi 48 >