< UGenesisi 14 >

1 Kwasekusithi ensukwini zikaAmrafeli inkosi yeShinari, uAriyoki inkosi yeElasari, uKedolawoma inkosi yeElamu, loTidali inkosi yezizwe,
Ní àsìkò yìí ni Amrafeli ọba Ṣinari, Arioku ọba Ellasari, Kedorlaomeri ọba Elamu àti Tidali ọba Goyimu
2 balwa impi loBera inkosi yeSodoma, loBirisha inkosi yeGomora, uShinabi inkosi yeAdima, loShemebere inkosi yeZeboyimi, lenkosi yeBhela, eliyiZowari.
jáde lọ láti bá Bera ọba Sodomu, Birṣa ọba Gomorra, Ṣenabu ọba Adma, Ṣemeberi ọba Seboimu àti ọba Bela (èyí ni Soari) jagun.
3 Bonke labo bahlangana esigodini iSidima esiluLwandle lweTshwayi.
Gbogbo àwọn ọba wọ̀nyí ni ó kó ogun wọn jọ pọ̀ sí àfonífojì Siddimu (ti o túmọ̀ sí Òkun Iyọ̀).
4 Babemkhonzile uKedolawoma okweminyaka elitshumi lambili, kodwa ngomnyaka wetshumi lantathu bavukela.
Fún ọdún méjìlá gbáko ni wọ́n ti ń sin Kedorlaomeri bí ẹrú. Ṣùgbọ́n nígbà tí ó di ọdún kẹtàlá wọ́n ṣọ̀tẹ̀ sí i.
5 Langomnyaka wetshumi lane kweza uKedolawoma, lamakhosi ayelaye, batshaya amaRefa eAshiterothi-Karnayimi, lamaZuzi eHamu, lamaEmi egcekeni leKiriyathayimi,
Ní ọdún kẹrìnlá, ni Kedorlaomeri àti àwọn ọba tí wọ́n ti jọ ni májẹ̀mú àṣepọ̀ wá, wọ́n ṣígun, wọ́n sì ṣẹ́gun ará Refaimu ní Aṣteroti-Karnaimu, àwọn ará Susimu ni Hamu, àwọn ará Emimu ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Kiriataimu,
6 lamaHori entabeni yabo yeSeyiri, kuze kube eEliparani eliseduze lenkangala.
àti àwọn ará Hori ní orí òkè wọ̀n-ọn-nì Seiri, títí ó fi dé Eli-Parani ní etí ijù.
7 Basebebuyela bafika eEnimishipati eliyiKadeshi, batshaya ilizwe lonke lamaAmaleki, njalo lamaAmori ayehlala eHazazoni-Tamari.
Wọ́n sì tún yípadà lọ sí En-Miṣpati (ti o túmọ̀ sí Kadeṣi), wọ́n sì ṣẹ́gun gbogbo ilẹ̀ àwọn Amaleki, àti àwọn ará Amori tí ó tẹ̀dó sí Hasason Tamari pẹ̀lú.
8 Kwasekuphuma inkosi yeSodoma lenkosi yeGomora, lenkosi yeAdima lenkosi yeZeboyimi, lenkosi yeBhela eliyiZowari, bahlomisa impi bemelene labo esigodini iSidima,
Nígbà náà ni ọba Sodomu, ọba Gomorra, ọba Adma, ọba Seboimu àti ọba Bela (èyí ni Soari), kó àwọn ọmọ-ogun wọn, wọ́n sì pa ibùdó ogun wọn sí Àfonífojì Siddimu,
9 emelane loKedolawoma inkosi yeElamu, loTidali inkosi yezizwe, loAmrafeli inkosi yeShinari, loAriyoki inkosi yeElasari; amakhosi amane emelane lamakhosi amahlanu.
láti kojú ìjà sí Kedorlaomeri ọba Elamu, Tidali ọba Goyimu, Amrafeli ọba Ṣinari àti Arioku ọba Ellasari (ọba mẹ́rin kọjú ìjà sí ọba márùn-ún).
10 Lesigodi seSidima sasilemigodigodi yengcino; lenkosi yeSodoma leyeGomora yabaleka, yawela khona; labaseleyo babalekela entabeni.
Àfonífojì Siddimu sì kún fún kòtò ọ̀dà ilẹ̀, nígbà tí ọba Sodomu àti ọba Gomorra sì sá, díẹ̀ nínú àwọn ọkùnrin ogun náà ṣubú sínú àwọn kòtò náà, àwọn tókù sì sálọ sì orí òkè.
11 Asethatha yonke impahla yeSodoma leyeGomora, lokudla kwabo konke, ahamba.
Àwọn ọba mẹ́rẹ̀ẹ̀rin náà sì kó gbogbo ẹrù Sodomu àti Gomorra àti oúnjẹ wọn; wọ́n sì lọ.
12 Amthatha loLothi lempahla yakhe, indodana yomfowabo kaAbrama, asehamba, ngoba wayehlala eSodoma.
Wọ́n sì mú Lọti ọmọ arákùnrin Abramu tí ń gbé ní Sodomu àti gbogbo ohun ìní rẹ̀.
13 Kwasekusiza owayephunyukile, wamlandisela uAbrama umHebheru, owayehlala ezihlahleni zama-okhi zikaMamre umAmori, umfowabo kaEshikoli lomfowabo kaAneri ababelesivumelwano loAbrama.
Ẹnìkan tí ó sá àsálà sì wá ròyìn fún Abramu, ará Heberu ni. Abramu sá ti tẹ̀dó sí ẹ̀gbẹ́ igi ńlá igbó Mamre ará Amori, arákùnrin Eṣkolu àti Aneri: àwọn ẹni tí ó ń bá Abramu ní àṣepọ̀.
14 Kwathi uAbrama esezwile ukuthi isihlobo sakhe sasithunjiwe, wahlomisa ayebafundisile, bezelwe endlini yakhe, abangamakhulu amathathu letshumi lesificaminwembili, waxotshana lawo waze wafika koDani.
Nígbà tí Abramu gbọ́ wí pé, a di Lọti ní ìgbèkùn, ó kó àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ tí a bí sí ilẹ̀ rẹ̀ tí ó sì ti kọ́ ni ogun jíjà jáde, wọ́n jẹ́ okòó lé lọ́ọ̀dúnrún ó dín méjì ènìyàn, ó sì lépa wọn títí dé Dani.
15 Wasezehlukanisa emelane lawo ebusuku, yena lenceku zakhe, wawatshaya, waxotshana lawo waze wafika eHoba, ekwesokhohlo seDamaseko.
Ní ọ̀gànjọ́ òru, Abramu pín àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ sí méjì, ó sì kọlù wọ́n, ó sì ṣẹ́gun wọn, ó sì lé wọn títí dé Hoba tí ó wà ní apá òsì Damasku.
16 Wasebuyisa yonke impahla, wasebuyisa loLothi umfowabo lempahla yakhe, labesifazana labo labantu.
Gbogbo ìkógun ni ó rí gbà padà àti ọmọ arákùnrin rẹ̀, Lọti pẹ̀lú ohun ìní rẹ̀, àti àwọn obìnrin pẹ̀lú àwọn ènìyàn tókù.
17 Inkosi yeSodoma yasiphuma ukumhlangabeza, esebuyile ekutshayeni uKedolawoma lamakhosi ayelaye, esigodini iShave, esiyisigodi senkosi.
Nígbà tí Abramu ti ṣẹ́gun Kedorlaomeri àti àwọn ọba tí ó pẹ̀lú rẹ̀, ọba Sodomu lọ pàdé rẹ̀ ní àfonífojì Ṣafe (èyí ni àfonífojì Ọba).
18 UMelkizedeki inkosi yeSalema waseletha isinkwa lewayini; njalo yena ngumpristi kaNkulunkulu oPhezukonke.
Melkisedeki ọba Salẹmu sì mú oúnjẹ àti ọtí wáìnì jáde wá. Òun ni àlùfáà Ọlọ́run Ọ̀gá-ògo.
19 Wasembusisa wathi: Kabusiswe uAbrama nguNkulunkulu oPhezukonke, uMnini wamazulu lomhlaba.
Ó sì súre fún Abramu, wí pé, “Ìbùkún ni fún Abramu ti Ọlọ́run Ọ̀gá-ògo, Ẹni tí ó dá ọ̀run òun ayé.
20 Kabusiswe-ke uNkulunkulu oPhezukonke onikele izitha zakho esandleni sakho. Wasemnika okwetshumi kwakho konke.
Ìbùkún sì ni fún Ọlọ́run Ọ̀gá-ògo jùlọ, tí ó fi àwọn ọ̀tá rẹ lé ọ lọ́wọ́.” Abramu sì fún un ní ìdámẹ́wàá ohun gbogbo.
21 Inkosi yeSodoma yasisithi kuAbrama: Nginika abantu, kodwa uzithathele impahla.
Ọba Sodomu sì wí fún Abramu pé, “Kó àwọn ènìyàn mi fún mi, ṣùgbọ́n mú àwọn ẹrù fún ara rẹ.”
22 UAbrama wasesithi eNkosini yeSodoma: Ngiphakamise isandla sami eNkosini uNkulunkulu oPhezukonke, uMnini wamazulu lomhlaba,
Ṣùgbọ́n Abramu dá ọba Sodomu lóhùn pé, “Mo ti búra fún Olúwa, Ọlọ́run Ọ̀gá-ògo, tí ó dá ọ̀run àti ayé, mo sì ti gbọ́wọ́ sókè,
23 ngithi kangiyikuthatha kusukela kumucu kusiya emchilweni wenyathela, kukho konke olakho! Hlezi uthi: Mina ngimnothisile uAbrama.
pé, èmi kì yóò mú láti fọ́nrán òwú títí dé okùn bàtà, àti pé, èmi kí yóò mú ohun kan tí ṣe tìrẹ, kí ìwọ kí ó má ba à wí pé, ‘Mo sọ Abramu di ọlọ́rọ̀.’
24 Ngaphandle kwalokho kuphela akudlileyo amajaha, lesabelo samadoda ahambe lami, uAneri, uEshikoli loMamre, bona kabathathe isabelo sabo.
Èmi kì yóò gba ohunkóhun yàtọ̀ sí ohun tí àwọn ọkùnrin mi ti jẹ́, ṣùgbọ́n fi ìpín fún àwọn ọkùnrin tí ó bá mi lọ, Aneri, Eṣkolu àti Mamre. Jẹ́ kí wọn kí ó gba ìpín wọn.”

< UGenesisi 14 >