< UHezekheli 30 >

1 Ilizwi leNkosi lafika kimi futhi, lisithi:
Ọ̀rọ̀ Olúwa tún tọ̀ mí wá: wí pé:
2 Ndodana yomuntu, profetha uthi: Itsho njalo iNkosi uJehova: Qhinqani isililo: Maye ngalolosuku!
“Ọmọ ènìyàn, sọtẹ́lẹ̀ kí o sì wí pé: ‘Báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí: “‘Hu, kí o sì wí pé, “Ó ṣe fún ọjọ́ náà!”
3 Ngoba usuku luseduze, ngitsho usuku lweNkosi luseduze, usuku olulamayezi; kuzakuba yisikhathi sezizwe.
Nítorí ọjọ́ náà súnmọ́ tòsí àní ọjọ́ Olúwa súnmọ́ tòsí, ọjọ́ tí ọjọ́ ìkùùkuu ṣú dúdú, àsìkò ìparun fún àwọn kèfèrí.
4 Lenkemba izafika eGibhithe, losizi luzakuba seEthiyophiya, lapho ababuleweyo bezakuwa eGibhithe; ngoba bazasusa ixuku layo, lezisekelo zayo zidilizelwe phansi.
Idà yóò wá sórí Ejibiti ìrora ńlá yóò sì wá sórí Kuṣi. Nígbà tí àwọn tí a pa yóò ṣubú ní Ejibiti wọn yóò kò ọrọ̀ rẹ̀ lọ ìpìlẹ̀ rẹ̀ yóò sì wó lulẹ̀.
5 IEthiyophiya, lePuti, leLudi, labo bonke abantu abahlanganisiweyo, leKhubi, labantwana belizwe lesivumelwano, bazakuwa ngenkemba kanye labo.
Kuṣi àti Puti, Libia, Ludi àti gbogbo Arabia, Kubu àti àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà tí ó mulẹ̀ yóò ṣubú nípa idà pẹ̀lú Ejibiti.
6 Itsho njalo iNkosi: Yebo, abasekela iGibhithe bazakuwa, lokuzigqaja kwamandla ayo kuzakwehla; kusukela eMigidoli kuze kube seSevene bazakuwa kuyo ngenkemba, itsho iNkosi uJehova.
“‘Èyí yìí ní Olúwa wí: “‘Àwọn àlejò Ejibiti yóò ṣubú agbára ìgbéraga rẹ yóò kùnà láti Migdoli títí dé Siene, wọn yóò ti ipa idà ṣubú nínú rẹ; ní Olúwa Olódùmarè wí.
7 Njalo bazachitheka phakathi kwamazwe achithekileyo; lemizi yayo izakuba phakathi kwemizi engamanxiwa.
Wọn yóò sì wà lára àwọn ilẹ̀ tí ó di ahoro, ìlú rẹ yóò sì wà ní ara àwọn ìlú tí ó di ahoro.
8 Khona bezakwazi ukuthi ngiyiNkosi, sengibeke umlilo eGibhithe, lapho bonke abasizi bayo sebephuliwe.
Lẹ́yìn náà wọn yóò mọ̀ pé èmi ní Olúwa, nígbà tí mo bá gbé iná kalẹ̀ ní Ejibiti tí gbogbo àwọn olùrànlọ́wọ́ rẹ̀ bá parun.
9 Ngalolosuku izithunywa zizaphuma phambi kwami ngemikhumbi ukuyakwethusa amaEthiyophiya onwabileyo, losizi luzakuba phakathi kwabo osukwini lweGibhithe, ngoba, khangela, luyeza.
“‘Ní ọjọ́ náà oníṣẹ́ yóò ti ọ̀dọ̀ mi jáde nínú ọkọ̀ ojú omi láti dẹ́rùbà Kuṣi tí ó wà nínú àlàáfíà. Ìrora yóò wá sórí wọn gẹ́gẹ́ bí ti ọjọ́ ìparun Ejibiti. Kíyèsi i, ó dé.
10 Itsho njalo iNkosi uJehova: Yebo, ngizaqeda ixuku leGibhithe ngesandla sikaNebhukadirezari inkosi yeBhabhiloni.
“‘Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: “‘Èmi yóò mú òpin bá ọ̀gọ̀ọ̀rọ̀ àwọn ènìyàn Ejibiti láti ọwọ́ Nebukadnessari ọba Babeli.
11 Yena, labantu bakhe kanye laye, abesabekayo bezizwe, bazalethwa ukuzachitha ilizwe; njalo bazahwatsha izinkemba zabo bemelene leGibhithe, bagcwalise ilizwe ngababuleweyo.
Òun àti àwọn ológun rẹ̀ ẹ̀rù àwọn orílẹ̀-èdè ní a o mú wá láti pa ilẹ̀ náà run. Wọn yóò fa idà wọn yọ sí Ejibiti ilẹ̀ náà yóò sì kún fún àwọn tí a pa.
12 Njalo ngizakwenza imifula itshe, ngithengise ilizwe esandleni sabakhohlakeleyo, ngilichithe ilizwe lokugcwala kwalo ngesandla sabezizwe; mina Nkosi ngikhulumile.
Èmi yóò mú kí àwọn odò Naili gbẹ, Èmi yóò sì ta ilẹ̀ náà fún àwọn ènìyàn búburú: láti ọwọ́ àwọn àjèjì ènìyàn, Èmi yóò jẹ́ kí ilẹ̀ náà àti gbogbo ohun tí ó wá nínú rẹ ṣòfò. Èmi Olúwa ni ó ti sọ ọ́.
13 Itsho njalo iNkosi uJehova: Ngizabhubhisa lezithombe, ngiqede izifanekiso eNofi; njalo kakusayikuba khona isiphathamandla esivela elizweni leGibhithe; njalo ngizaletha ukwesaba elizweni leGibhithe.
“‘Báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí: “‘Èmi yóò pa àwọn òrìṣà run, Èmi yóò sì mú kí òpin dé bá ère gbígbẹ́ ni Memfisi. Kò ní sí ọmọ-aládé mọ́ ní Ejibiti, Èmi yóò mú kí ìbẹ̀rù gba gbogbo ilẹ̀ náà.
14 Ngenze iPatrosi ibe lunxiwa, ngibeke umlilo eZowani, ngenze izahlulelo eNo.
Èmi yóò sì mú kí Paturosi di ahoro, èmi yóò fi iná sí Ṣoani, èmi yóò sì fi ìyà jẹ Tebesi.
15 Ngithulule ulaka lwami phezu kweSini, amandla eGibhithe; ngiqume ixuku leNo.
Èmi yóò tú ìbínú mi jáde sórí Pelusiumu ìlú odi Ejibiti èmi yóò sì ké àkójọpọ̀ Tebesi kúrò.
16 Ngibeke umlilo eGibhithe; iSini izakuba lobuhlungu obukhulu; leNo izadatshulwa phakathi; leNofi izakhathazeka nsuku zonke.
Èmi yóò ti iná bọ Ejibiti Pelusiumu yóò japoró ní ìrora. Ìjì líle yóò jà ní Tebesi Memfisi yóò wà ìpọ́njú ní ìgbà gbogbo.
17 Amajaha eAvene lePhibhesethi azakuwa ngenkemba, lale imizi izakuya ekuthunjweni.
Àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin ní Heliopolisi àti Bubasiti yóò ti ipa idà ṣubú wọn yóò sì kó àwọn ìlú wọn ní ìgbèkùn.
18 Njalo eThahaphanesi imini izakuba mnyama, lapho ngizakwephula khona amajogwe eGibhithe, lokuzikhukhumeza kwamandla ayo kuzaphela kiyo. Yona, iyezi lizayisibekela, lamadodakazi ayo azakuya ekuthunjweni.
Ojú ọjọ́ yóò ṣókùnkùn ní Tafanesi nígbà tí mo bá já àjàgà Ejibiti kúrò; níbẹ̀ agbára iyì rẹ̀ yóò dópin wọn yóò fi ìkùùkuu bò ó àwọn abúlé rẹ ní wọn yóò lọ sí ìgbèkùn.
19 Ngokunjalo ngizakwenza izahlulelo eGibhithe. Khona bezakwazi ukuthi ngiyiNkosi.
Nítorí náà, Èmi yóò mú ki ìjìyà wá sórí Ejibiti, wọn yóò sì mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.’”
20 Kwasekusithi ngomnyaka wetshumi lanye, ngenyanga yokuqala, ngolwesikhombisa lwenyanga, ilizwi leNkosi lafika kimi, lisithi:
Ní ọjọ́ keje oṣù kìn-ín-ní ọdún kọkànlá ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá,
21 Ndodana yomuntu, ngiyephule ingalo kaFaro inkosi yeGibhithe; khangela-ke kayibotshwanga ukuthi kunikwe ukuphola, ukuthi kufakwe uhlaka lokuyibopha, ukuyiqinisela ukubamba inkemba.
“Ọmọ ènìyàn, Èmi ti ṣẹ́ apá Farao ọba Ejibiti. A kò ì tí ì di apá náà papọ̀ láti mu kí ó san, a kò sì ti di i si àárín igi pẹlẹbẹ kí o lè ni agbára tó láti di idà mú.
22 Ngakho itsho njalo iNkosi uJehova: Khangela, ngimelene loFaro inkosi yeGibhithe, njalo ngizakwephula ingalo zakhe, elamandla, laleyo eyephukileyo, ngenze inkemba iwe esandleni sakhe.
Nítorí náà, báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí: Èmi lòdì sí Farao ọba Ejibiti. Èmi yóò sẹ́ apá rẹ̀ méjèèjì, èyí tí ó dára àti èyí tí a ti ṣẹ́ pẹ̀lú, yóò sì mú kí idà bọ́ sọnù ní ọwọ́ rẹ̀.
23 Ngihlakazele amaGibhithe phakathi kwezizwe, ngiwasabalalisele emazweni.
Èmi yóò sì fọ́n àwọn ènìyàn Ejibiti ká sí àárín àwọn orílẹ̀-èdè, èmi yóò sì tú wọn ká gbogbo ilẹ̀.
24 Ngiqinise ingalo zenkosi yeBhabhiloni, ngibeke inkemba yami esandleni sayo; kodwa ngizakwephula izingalo zikaFaro, abubule phambi kwayo ngokububula kogwaziweyo.
Èmi yóò mú kí apá ọba Babeli ní agbára, èmi yóò sì fi idà mi sí ọwọ́ rẹ, ṣùgbọ́n èmi yóò ṣẹ́ apá Farao, yóò sì kérora níwájú rẹ̀ bí ọkùnrin tí a sá ní àṣápa.
25 Kodwa ngizaqinisa ingalo zenkosi yeBhabhiloni, lengalo zikaFaro zizawela phansi; njalo bazakwazi ukuthi ngiyiNkosi, sengifake inkemba yami esandleni senkosi yeBhabhiloni, isiyelule phezu kwelizwe leGibhithe.
Èmi yóò mú kí apá ọba Babeli lé, ṣùgbọ́n apá Farao yóò sì rọ. Nígbà náà wọn yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa, nígbà tí mo bá mú idà mi sí ọwọ́ ọba Babeli yóò sì fi idà náà kọlu Ejibiti.
26 Njalo ngizahlakaza amaGibhithe phakathi kwezizwe, ngiwasabalalisele emazweni. Njalo bazakwazi ukuthi ngiyiNkosi.
Èmi yóò fọ́n àwọn ara Ejibiti ká sí àárín orílẹ̀-èdè, èmi yóò sì tú wọn ká sí àárín orílẹ̀-èdè, èmi yóò sì tú wọn ká sí gbogbo ilẹ̀. Nígbà náà wọn yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa.”

< UHezekheli 30 >