< UHezekheli 25 >

1 Ilizwi leNkosi laselifika kimi, lisithi:
Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
2 Ndodana yomuntu, misa ubuso bakho bumelene labantwana bakoAmoni, uprofethe umelene labo.
“Ọmọ ènìyàn, kọ ojú rẹ sí àwọn ará Ammoni kí ó sì sọ àsọtẹ́lẹ̀ sí wọn.
3 Uthi kubantwana bakoAmoni: Zwanini ilizwi leNkosi uJehova: Itsho njalo iNkosi uJehova: Ngoba wathi: Aha; ngenxa yendawo yami engcwele, lapho ingcoliswa, langenxa yelizwe lakoIsrayeli, lapho lalichithiwe, langenxa yendlu yakoJuda, lapho baya ekuthunjweni,
Sì wí fún àwọn ará Ammoni pé, ‘Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa Olódùmarè tí ó wí pé. Nítorí tí ìwọ wí pé, “Á hà!” Sí ibi mímọ́ mi nígbà tí ó di àìlọ́wọ̀ àti sí orí ilẹ̀ Israẹli nígbà tí ó di ahoro; àti sí ilẹ̀ Juda, nígbà tí wọ́n lọ sí ìgbèkùn,
4 ngakho, khangela, ngizakunikela ebantwaneni basempumalanga ube yilifa, ukuthi bamise inkamba zabo phakathi kwakho, benze izindawo zabo zokuhlala phakathi kwakho; bona bazakudla izithelo zakho, bona banathe uchago lwakho.
kíyèsi i, nítorí náà ni èmi yóò fi fi ọ lé àwọn ènìyàn ìlà-oòrùn lọ́wọ́ ni ohun ìní. Wọn yóò sì gbé ààfin wọn kalẹ̀ nínú rẹ, wọn yóò sì gbé ibùgbé wọn nínú rẹ, wọn yóò jẹ èso rẹ, wọn yóò sì mu wàrà rẹ.
5 Njalo ngizakwenza iRaba ibe yisitebele samakamela, labantwana bakoAmoni babe yindawo yokucambalala yemihlambi. Khona lizakwazi ukuthi ngiyiNkosi.
Èmi yóò sì sọ Rabba di ibùjẹ, fún àwọn ìbákasẹ àti àwọn ọmọ Ammoni di ibùsùn fún agbo ẹran. Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.
6 Ngoba itsho njalo iNkosi uJehova: Ngoba utshayile isandla, watshaya phansi ngonyawo, wathokoza emphefumulweni ngokudelela kwakho konke umelene lelizwe lakoIsrayeli;
Nítorí báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí. Nítorí pé ìwọ pàtẹ́wọ́, ìwọ sì jan ẹsẹ̀ mọ́lẹ̀, tí ìwọ ń yọ̀ pẹ̀lú gbogbo àrankàn rẹ sí ilẹ̀ Israẹli
7 ngakho, khangela, ngizakwelulela isandla sami phezu kwakho, ngikunikele ube yimpango kwabezizwe, ngikuqume usuke ebantwini, ngizakwenza ubhubhe emazweni, ngikuchithe. Khona uzakwazi ukuthi ngiyiNkosi.
nítorí náà, èmi yóò na ọwọ́ mi lé ọ, èmi yóò sì fi ọ fún àwọn aláìkọlà fún ìkógun. Èmi yóò sì gé ọ kúrò láàrín àwọn ènìyàn, èmi yóò sì jẹ́ kí o parun kúrò ni ilẹ̀ gbogbo. Èmi yóò sì pa ọ́ run, ìwọ yóò sì mọ̀ pé èmi ni Olúwa.’”
8 Itsho njalo iNkosi uJehova: Ngoba oMowabi loSeyiri bathi: Khangela, indlu kaJuda injengezizwe zonke;
“Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: ‘Nítorí pé Moabu àti Seiri sọ wí pé, “Wò ó, ilé Juda ti dàbí gbogbo àwọn kèfèrí,”
9 ngakho khangela, ngizavula uhlangothi lukaMowabi kusukela emizini, kusukela emizini yakhe, kusukela emngceleni wakhe, ubuhle belizwe, iBeti-Jeshimothi, iBhali-Meyoni, leKiriyathayimi;
nítorí náà, Èmi yóò ṣí Moabu sílẹ̀ láti àwọn ìlú gbogbo tí ó wà ní ààlà rẹ̀, ògo ilẹ̀ náà, Beti-Jeṣimoti, Baali-Meoni àti Kiriataimu.
10 njalo ngizayinikela emadodaneni empumalanga kube yilifa ngimelene labantwana bakoAmoni, ukuze abantwana bakoAmoni bangakhunjulwa phakathi kwezizwe.
Èmi yóò fi Moabu pẹ̀lú àwọn ará Ammoni lé àwọn ènìyàn ìlà-oòrùn ní ìní, kí a má bà á lè rántí àwọn ará Ammoni láàrín orílẹ̀-èdè gbogbo.
11 Ngizakwenza izahlulelo laphakathi kukaMowabi; njalo bazakwazi ukuthi ngiyiNkosi.
Èmi yóò sì mú ìdájọ́ sẹ sí Moabu lára, wọn yóò sì mọ̀ pé èmi ni Olúwa.’”
12 Itsho njalo iNkosi uJehova: Ngoba uEdoma enze ngokuphindisela impindiselo emelene lendlu kaJuda, wonile ngokona, waziphindisela phezu kwabo;
“Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí pé: ‘Nítorí pé Edomu gbẹ̀san lára ilé Juda, ó sì jẹ̀bi gidigidi nípa ṣíṣe bẹ́ẹ̀,
13 ngakho itsho njalo iNkosi uJehova: Lami ngizakwelula isandla sami phezu kukaEdoma, ngiqume kuye umuntu lenyamazana, ngimenze incithakalo kusukela eThemani, njalo kuze kufike eDedani bazakuwa ngenkemba.
nítorí náà báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí pé: Èmi yóò na ọwọ́ mi sórí Edomu èmi yóò sì pa àwọn ènìyàn àti àwọn ẹranko rẹ̀. Èmi yóò fi ṣófo láti Temani dé Dedani yóò ti ipa idà ṣubú.
14 Njalo ngizabeka impindiselo yami phezu kukaEdoma ngesandla sabantu bami uIsrayeli, benze kuEdoma njengokwentukuthelo yami lanjengokolaka lwami; khona bezakwazi impindiselo yami, itsho iNkosi uJehova.
Èmi yóò gbẹ̀san lára Edomu láti ọwọ́ àwọn ènìyàn mi Israẹli, wọn sì ṣe sí Edomu gẹ́gẹ́ bí ìbínú àti ìrunú mi, wọn yóò mọ̀ ìgbẹ̀san mi ní Olúwa Olódùmarè wí.’”
15 Itsho njalo iNkosi uJehova: Ngoba amaFilisti enze ngempindiselo, aphindisela impindiselo ngokudelela emphefumulweni, ukuthi achithe ngenzondo yaphakade;
“Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí pé: ‘Nítorí tí àwọn ará Filistini hùwà ẹ̀san tí wọ́n sì gbẹ̀san pẹ̀lú odì ní ọkàn wọn, àti pẹ̀lú ìkórìíra gbangba àtijọ́ ní wíwá ọ̀nà láti pa Juda run,
16 ngakho itsho njalo iNkosi uJehova: Khangela, ngizakwelulela isandla sami phezu kwamaFilisti, ngiqume amaKerethi, ngibhubhise insali yokhumbi lolwandle.
nítorí náà báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí pé, “Èmi ti ṣetán láti na ọwọ́ mi jáde sí àwọn ará Filistini, èmi yóò sì ké àwọn ará Kereti kúrò, èmi yóò sì pa àwọn tí ó kù ní etí kún run.
17 Ngenze izimpindiselo ezinkulu phezu kwabo ngokukhuza kwentukuthelo; khona bazakwazi ukuthi ngiyiNkosi, lapho ngibeka impindiselo yami phezu kwabo.
Èmi yóò sì gbẹ̀san ńlá lára wọn nípa ìbáwí gbígbóná; wọn yóò sì mọ̀ wí pé, Èmi ni Olúwa. Nígbà tí èmi yóò gba ẹ̀san lára wọn.”’”

< UHezekheli 25 >