< UDutheronomi 2 >

1 Sasesiphenduka, sasuka saya enkangala, indlela yoLwandle oluBomvu, njengokutsho kweNkosi kimi; njalo sayibhoda intaba yeSeyiri insuku ezinengi.
Nígbà náà ni a yípadà, tí a sì mú ọ̀nà wa pọ̀n lọ sí aginjù, a gba ọ̀nà Òkun Pupa, bí Olúwa ti darí mi. Ìgbà pípẹ́ ni a fi ń rìn kiri yíká agbègbè àwọn ìlú olókè Seiri.
2 INkosi yasikhuluma kimi isithi:
Nígbà náà ni Olúwa sọ fún mi pé,
3 Selibhode intaba le okweneleyo; phendukelani lina enyakatho.
“Ẹ ti rìn yí agbègbè ilẹ̀ olókè yìí pẹ́ tó, nísinsin yìí, ẹ yípadà sí ìhà àríwá.
4 Balaye-ke abantu usithi: Lidabula umngcele wabafowenu, abantwana bakaEsawu abahlala eSeyiri. Njalo bazalesaba, ngakho lizinanzelele kakhulu,
Fún àwọn ènìyàn náà ní àwọn òfin wọ̀nyí: ‘Ẹ ti fẹ́ la ilẹ̀ àwọn arákùnrin yín kọjá, àwọn ọmọ Esau; àwọn ará Edomu tí ń gbé ní Seiri. Ẹ̀rù yín yóò bà wọ́n, ṣùgbọ́n ẹ ṣọ́ra gidigidi.
5 lingalwi labo; ngoba kangiyikulinika okwelizwe labo, lelingangokunyathela kwangaphansi konyawo, ngoba ngimnikile uEsawu intaba yeSeyiri ibe yilifa.
Ẹ má ṣe wá wọn níjà torí pé èmi kò ní fún un yín ní èyíkéyìí nínú ilẹ̀ wọn. Bí ó ti wù kí ó kéré mọ èmi kò ní fún un yín. Mo ti fi ilẹ̀ òkè Seiri fún Esau gẹ́gẹ́ bí ìní rẹ̀.
6 Lizathenga ukudla kubo ngemali ukuze lidle, lithenge kubo lamanzi ngemali ukuze linathe.
Ẹ san owó oúnjẹ tí ẹ bá jẹ fún wọn àti omi tí ẹ bá mu.’”
7 Ngoba iNkosi uNkulunkulu wakho ikubusisile emsebenzini wonke wesandla sakho; iyazi ukuhamba kwakho kulinkangala enkulu. Le iminyaka engamatshumi amane iNkosi uNkulunkulu wakho ibilawe, kawuswelanga lutho.
Olúwa Ọlọ́run yín ti bùkún un yín nínú gbogbo iṣẹ́ ọwọ́ yín. Ó ti mójútó ìrìnàjò yín nínú aginjù ńlá yìí. Olúwa Ọlọ́run yín wà pẹ̀lú u yín ní ogójì ọdún wọ̀nyí, dé bi pé ẹ̀yin kò ṣaláìní ohunkóhun.
8 Uba sisedlula sisuka kubafowethu, abantwana bakaEsawu abahlala eSeyiri, ngendlela yegceke sisuke eElathi njalo sisuka eEziyoni-Geberi, saphenduka, sadlula ngendlela yenkangala yakoMowabi.
Bẹ́ẹ̀ ni a kọjá ọ̀dọ̀ àwọn arákùnrin wa, àwọn ọmọ Esau tí ń gbé ní Seiri. A yà kúrò ní ọ̀nà Arabah èyí tí ó wá láti Elati àti Esioni-Geberi, a sì rìn gba ọ̀nà aginjù Moabu.
9 INkosi yasisithi kimi: Ungahlukuluzi uMowabi, ungalwi labo empini; ngoba kangiyikukunika okwelizwe labo kube yilifa, ngoba ngibanikile abantwana bakaLothi iAri ibe yilifa.
Olúwa sì sọ fún mi pé, “Ẹ má ṣe dẹ́rùba àwọn ará Moabu bẹ́ẹ̀ ni kí ẹ má ṣe bá wọn jagun torí pé n kò ní fi èyíkéyìí nínú ilẹ̀ wọn fún un yín. Mo ti fi Ari fún àwọn ọmọ Lọti bí i ìní.”
10 Kwakuhlala khona endulo amaEmi, abantu abakhulu, labanengi, labade, njengamaAnaki;
(Àwọn Emimu ti gbé ibẹ̀ rí, àwọn ènìyàn tó síngbọnlẹ̀ tó sì pọ̀, wọ́n ga bí àwọn Anaki.
11 babebalwa njengeziqhwaga labo njengamaAnaki, kodwa amaMowabi ababiza ngokuthi ngamaEmi.
Gẹ́gẹ́ bí Anaki àwọn ènìyàn náà pè wọ́n ní ará Refaimu ṣùgbọ́n àwọn ará Moabu pè wọ́n ní Emimu.
12 LamaHori ayehlala eSeyiri endulo, kodwa abantwana bakaEsawu bawakhupha emfuyweni yabo, bawachitha phambi kwabo, bahlala endaweni yawo, njengokwenza kukaIsrayeli elizweni lelifa lakhe, iNkosi eyabanika lona.
Àwọn ará Hori gbé ní Seiri, kí àwọn ọmọ Esau tó lé wọn kúrò níwájú wọn. Wọ́n sì gba ilẹ̀ wọn, wọ́n tẹ̀dó sí ààyè wọn gẹ́gẹ́ bí àwọn ọmọ Israẹli tí ṣe ní ilẹ̀ tí Olúwa yóò fún wọn ní ìní wọn.)
13 Khathesi, sukumani lina lichaphe isifula iZeredi. Ngakho sachapha isifula iZeredi.
Olúwa sì wí pé, “Ẹ dìde, kí ẹ sì la àfonífojì Seredi kọjá.” Bẹ́ẹ̀ ni a la àfonífojì náà kọjá.
14 Lensuku esahamba ngazo sisuka eKadeshi-Bhaneya saze sachapha isifula iZeredi zaziyiminyaka engamatshumi amathathu lesificaminwembili, kwaze kwaphela isizukulwana sonke samadoda empi sisuka phakathi kwenkamba, njengokufunga kweNkosi kuwo.
Ó gbà wá ní ọdún méjìdínlógójì kí ó tó di wí pé a la àfonífojì Seredi kọjá láti ìgbà tí a ti kúrò ní Kadeṣi-Barnea. Nígbà náà gbogbo ìran àwọn tí ó jẹ́ jagunjagun láàrín àwọn ènìyàn náà ti ṣègbé kúrò láàrín àwọn ènìyàn náà ní àsìkò yìí bí Olúwa ti búra fún wọn.
15 Ngoba isibili isandla seNkosi sasimelene lawo, ukuwachitha esuka phakathi kwenkamba, aze aphela.
Ọwọ́ Olúwa sì wà lòdì sí wọn nítòótọ́, láti run wọn kúrò nínú ibùdó, títí gbogbo wọn fi run tan.
16 Kwasekusithi lapho wonke amadoda empi esephelile esifa esuka phakathi kwabantu,
Lẹ́yìn tí ẹni tí ó gbẹ̀yìn pátápátá nínú àwọn jagunjagun àwọn ènìyàn wọ̀nyí ti kú,
17 INkosi yasikhuluma kimi isithi:
Olúwa sọ fún mi pé,
18 Lamuhla uzakwedlula iAri, umngcele wakoMowabi,
“Lónìí ni ẹ̀yin yóò la agbègbè Moabu kọjá ní Ari.
19 lapho ususondele maqondana labantwana bakoAmoni, ungabahlukuluzi, ungalwi labo, ngoba kangiyikukunika okwelizwe labantwana bakoAmoni kube yilifa, ngoba ngilinike abantwana bakaLothi libe yilifa.
Bí ẹ bá dé ọ̀dọ̀ àwọn ará Ammoni, ẹ má ṣe halẹ̀ mọ́ wọn, ẹ kò sì gbọdọ̀ bá wọn jagun, torí pé èmi kì yóò fi àwọn ilẹ̀ tí ó jẹ́ ti àwọn ará Ammoni fún un yín ní ìní. Mo ti fi fún àwọn ọmọ Lọti ní ìní.”
20 Lalelo labalwa njengelizwe leziqhwaga. Iziqhwaga zahlala kulo endulo, kodwa amaAmoni bazibiza ngokuthi ngamaZamuzumu;
(A ka ilẹ̀ yìí sí ilẹ̀ àwọn Refaimu, tí wọ́n ti gbé níbẹ̀ rí, ṣùgbọ́n àwọn ará Ammoni ń pè wọ́n ní ará Samsummimu.
21 abantu abakhulu, labanengi, labade, njengamaAnaki; kodwa iNkosi yabachitha phambi kwabo, babakhupha emfuyweni yabo, bahlala endaweni yabo,
Wọ́n jẹ́ àwọn ènìyàn tó lágbára, wọ́n sì pọ̀, wọ́n sì ga gogoro bí àwọn ará Anaki. Olúwa run wọn kúrò níwájú àwọn ará Ammoni, tí wọ́n lé wọn jáde tí wọ́n sì gba ilẹ̀ wọn.
22 njengalokho eyakwenzela abantwana bakaEsawu, ababehlala eSeyiri, lapho yawachitha amaHori esuka phambi kwabo, bawakhupha emfuyweni yabo, bahlala endaweni yawo kuze kube lamuhla.
Bákan náà ni Olúwa ṣe fún àwọn ọmọ Esau, tí wọ́n ń gbé ní Seiri, nígbà tí ó pa àwọn ará Hori run níwájú wọn. Wọ́n lé wọn jáde wọ́n sì ń gbé ní ilẹ̀ wọn títí di òní.
23 LamaAvi, ayehlala eHazerimi kuze kube seGaza; amaKafitori, aphuma eKafitori, awachitha, ahlala endaweni yawo.
Nípa ti àwọn ará Affimu, tí wọ́n ń gbé ní àwọn ìlú kéékèèké dé Gasa, àwọn ará Kaftorimu, tí wọ́n jáde láti Krete wá ni ó pa wọ́n run, wọ́n sì gba ilẹ̀ wọn.)
24 Sukumani, lisuke lichaphe isifula iArinoni. Bona, nginikele esandleni sakho uSihoni, inkosi yeHeshiboni, umAmori, lelizwe lakhe; qala ukudla ilifa lalo, ulwe laye empini.
“Ẹ gbáradì, kí ẹ sì kọjá odò Arnoni. Kíyèsi, Mo ti fi Sihoni ará Amori, ọba Heṣboni àti ilẹ̀ rẹ̀ lé ọ lọ́wọ́. Ẹ bá ilẹ̀ náà jagun kí ẹ sì gbà á.
25 Lamuhla ngizaqalisa ukufaka uvalo ngawe lokwesabeka kwakho phezu kobuso bezizwe, ngaphansi kwamazulu wonke, ezizakuzwa umbiko ngawe, zithuthumele, ziqhaqhazele ngenxa yakho.
Èmi bẹ̀rẹ̀ sí ní fi ìbẹ̀rù àti ìfòyà yín sára gbogbo orílẹ̀-èdè lábẹ́ ọ̀run láti òní lọ. Wọn yóò gbọ́ ìròyìn in yín, wọn yóò sì wárìrì, wọn yóò sì wà nínú ìdààmú ọkàn torí i tiyín.”
26 Ngasengithuma izithunywa zisuka enkangala yeKedemothi kuSihoni inkosi yeHeshiboni, zilamazwi okuthula, zisithi:
Mo rán àwọn ìránṣẹ́ láti aginjù Kedemoti lọ́ sọ́dọ̀ Sihoni ọba Heṣboni pẹ̀lú ọ̀rọ̀ àlàáfíà wí pé,
27 Ake ngidabule elizweni lakho; ngizahamba ngomgwaqo kuphela, ngingaphambukeli ngakwesokunene loba ngakwesokhohlo.
“Jẹ́ kí a la ilẹ̀ ẹ yín kọjá. Àwa yóò gba ti òpópónà nìkan. A kò ní yà sọ́tùn tàbí sósì.
28 Uzangithengisela ukudla ngemali ukuze ngidle, ungiphe amanzi ngemali ukuze nginathe; kuphela ngizadabula ngenyawo zami,
Ẹ ta oúnjẹ tí a ó jẹ àti omi tí a ó mu fún wa ní iye owó wọn. Kìkì kí ẹ sá à jẹ́ kí a rìn kọjá:
29 njengalokhu abantwana bakaEsawu abahlala eSeyiri lamaMowabi ahlala eAri benza kimi, ngize ngichaphe iJordani, ngingene elizweni iNkosi uNkulunkulu wethu esinika lona.
gẹ́gẹ́ bí àwọn ọmọ Esau tí ó ń gbé ní Seiri àti àwọn ará Moabu tí ó ń gbé ní Ari, ti gbà wá láààyè títí a fi la Jordani já dé ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run wa yóò fún wa.”
30 Kodwa uSihoni inkosi yeHeshiboni kasivumelanga ukuthi sidlule kuye; ngoba iNkosi uNkulunkulu wakho yenza umoya wakhe waba lukhuni, yenza lenhliziyo yakhe yaba lenkani, ukuze imnikele esandleni sakho, njengalamuhla.
Ṣùgbọ́n Sihoni ọba Heṣboni kò gbà fún wa láti kọjá. Torí pé Olúwa Ọlọ́run yín ti mú ọkàn rẹ̀ yigbì, àyà rẹ̀ sì kún fún agídí kí ó ba à le fi lé e yín lọ́wọ́, bí ó ti ṣe báyìí.
31 INkosi yathi kimi: Bona, sengiqalisile ukunikela phambi kwakho uSihoni lelizwe lakhe; qalisa ukudla ilifa, ukuze udle ilifa lelizwe lakhe.
Olúwa sì bá mi sọ̀rọ̀ pé, “Kíyèsi i, mo ti bẹ̀rẹ̀ sí ní fi Sihoni àti ilẹ̀ rẹ̀ lé e yín lọ́wọ́. Báyìí, ẹ máa ṣẹ́gun rẹ̀, kí ẹ sì gba ilẹ̀ rẹ̀.”
32 Kwasekuphuma uSihoni ukumelana lathi, yena labantu bakhe bonke, ukulwa eJahazi.
Nígbà tí Sihoni àti gbogbo àwọn jagunjagun rẹ̀ jáde wá láti bá wa jagun ní Jahasi,
33 INkosi uNkulunkulu wethu yasimnikela phambi kwethu; sasesimtshaya lamadodana akhe labantu bakhe bonke.
Olúwa Ọlọ́run wa fi lé wa lọ́wọ́ bẹ́ẹ̀ ni a ṣẹ́gun rẹ̀ pẹ̀lú àwọn ọmọ rẹ̀ àti gbogbo ológun rẹ̀.
34 Ngalesosikhathi sasesithumba yonke imizi yakhe, satshabalalisa wonke umuzi, abesilisa labesifazana labantwanyana; kasitshiyanga insali;
Nígbà náà, gbogbo ìlú wọn ni a kó tí a sì pa wọ́n run pátápátá tọkùnrin, tobìnrin àti gbogbo ọmọ wọn. A kò sì dá ẹnikẹ́ni sí.
35 sazithumbela izifuyo kuphela, lempango yemizi esayithumbayo.
Ṣùgbọ́n a kó gbogbo ohun ọ̀sìn àti ìkógun àwọn ìlú tí a ṣẹ́gun fún ara wa.
36 Kusukela eAroweri esekhunjini lwesifula iArinoni, lomuzi osesifuleni, kuze kube seGileyadi kwakungekho muzi owawuphakeme kakhulu kithi. INkosi uNkulunkulu wethu yayinikela yonke phambi kwethu.
Láti Aroeri, létí odò Arnoni àti láti àwọn ìlú tí ó wà lẹ́bàá odò náà títí ó fi dé Gileadi, kò sí ìlú tí ó lágbára jù fún wa, Olúwa Ọlọ́run wa fi gbogbo wọn fún wa.
37 Kuphela kawusondelanga elizweni labantwana bakoAmoni, endaweni yonke yesifula iJaboki, lemizini esezintabeni, lakukuphi iNkosi uNkulunkulu wethu esenqabela khona.
Ní ìbámu pẹ̀lú òfin Olúwa Ọlọ́run wa, ẹ kò súnmọ́ ọ̀kan nínú ilẹ̀ àwọn ará Ammoni, bẹ́ẹ̀ ni ẹ kò dé ilẹ̀ tí ó lọ sí Jabbok, tàbí ilẹ̀ tí ó yí àwọn ìlú òkè e nì ká.

< UDutheronomi 2 >