< UDanyeli 12 >

1 Langalesosikhathi uMikayeli uzasukuma, isiphathamandla esikhulu esimela abantwana babantu bakini. Njalo kuzakuba khona isikhathi sokuhlupheka, esingazanga sibe khona lokhe kwaba lesizwe kuze kube yilesosikhathi. Kodwa ngalesosikhathi abantu bakini bazakhululwa, wonke otholwa ebhaliwe ogwalweni.
“Ní àkókò náà, ni Mikaeli, ọmọ-aládé ńlá, ẹni tí o ń dáàbò bo àwọn ènìyàn an rẹ̀ yóò dìde. Àkókò ìpọ́njú yóò wà, irú èyí tí kò tí ì ṣẹlẹ̀ rí láti ìbẹ̀rẹ̀ àwọn orílẹ̀-èdè títí di àkókò náà. Ṣùgbọ́n ní àkókò náà àwọn ènìyàn rẹ̀, gbogbo àwọn tí a bá ti rí orúkọ wọn nínú ìwé ni a ó gbàlà.
2 Labanengi babo abalele othulini lomhlaba bazavuka, abanye besiya empilweni elaphakade, labanye besiya kumahlazo ekunengweni okulaphakade.
Ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn tí ó sùn nínú erùpẹ̀ ilẹ̀ ni yóò jí: àwọn mìíràn sí ìyè àìnípẹ̀kun, àwọn tókù sí ìtìjú àti sí ẹ̀gàn àìnípẹ̀kun.
3 Njalo abahlakaniphileyo bazakhanya njengokukhazimula kwesibhakabhaka, lalabo abaphendulela abanengi ekulungeni, njengezinkanyezi kuze kube nini lanini.
Àwọn tí ó jẹ́ ọlọ́gbọ́n yóò máa tàn bí ìmọ́lẹ̀ ọ̀run, àti àwọn tí ó ń tọ́nisọ́nà sí òdodo, yóò máa tàn bí ìràwọ̀ láé àti láéláé.
4 Kodwa wena, Daniyeli, vala lamazwi, unameke ugwalo, kuze kube sesikhathini sokuphela. Abanengi bazagijima baye le lale, lolwazi luzakwandiswa.
Ṣùgbọ́n ìwọ Daniẹli, pa ìwé náà dé kí o sì pa ọ̀rọ̀ ọ rẹ̀ mọ́ títí àkókò ìgbẹ̀yìn. Ọ̀pọ̀lọpọ̀ yóò máa lọ sí ìhín sí ọ̀hún láti jẹ́ kí ìmọ̀ wọn di púpọ̀.”
5 Mina, Daniyeli, ngasengibona, khangela-ke, abanye ababili bemi, omunye enganeno kokhumbi lomfula lomunye engaphetsheya kokhumbi lomfula.
Nígbà náà, ni èmi Daniẹli, wò, ní iwájú mi àwọn méjì mìíràn dúró, ọ̀kan dúró sí apá ìhín ní etí bèbè odò ẹnìkan náà ní apá òdìkejì ọ̀hún etí i bèbè.
6 Kwasekuthiwa kulowomuntu ogqoke ilembu elicolekileyo, owayengaphezu kwamanzi omfula: Koze kube nini ukuze kuphele lezizimangaliso?
Ọ̀kan lára wọn sọ fún ọkùnrin tí ó wọ aṣọ àlà, ẹni tí ó wà lórí omi odò pé, “Báwo ni yóò ṣe pẹ́ tó kí àwọn nǹkan ìyanu wọ̀nyí tó wá sí ìmúṣẹ?”
7 Ngasengisizwa lowomuntu ogqoke ilembu elicolekileyo, owayengaphezu kwamanzi omfula, lapho ephakamisela isandla sakhe sokunene lesandla sakhe sokhohlo emazulwini, efunga ngalowo ophila phakade, ukuthi kuzakuba ngokwesikhathi esimisiweyo, izikhathi ezimisiweyo, lengxenye; lalapho esephelelise ukuhlakaza amandla abantu abangcwele, zonke lezizinto zizaphela.
Ọkùnrin tí ó wọ aṣọ àlà, ẹni tí ó wà lórí omi odò, gbé ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ àti ọwọ́ òsì rẹ̀, mo gbọ́ tí ó fi ẹni tí ó wà títí láé búra, ó sọ wí pé, “Yóò ṣe ní àkókò kan, àkókò méjì àti ààbọ̀. Nígbà tí agbára àwọn ẹni mímọ́ yóò ti fọ́ tán pátápátá, gbogbo nǹkan wọ̀nyí yóò sì parí.”
8 Mina ngasengisizwa, kodwa kangiqedisisanga. Ngasengisithi: Nkosi yami, kuzakuba yini ukuphela kwalezizinto?
Èmi gbọ́, ṣùgbọ́n kò yé mi. Nígbà náà ni mo béèrè pé, “Olúwa mi, kí ni yóò jẹ́ àbábọ̀ àwọn nǹkan wọ̀nyí?”
9 Wasesithi: Hamba, Daniyeli, ngoba amazwi avalelwe ananyekwa kuze kube yisikhathi sokuphela.
Ó sì dáhùn pé, “Máa lọ ní ọ̀nà rẹ, Daniẹli nítorí tí a ti pa ọ̀rọ̀ náà dé, a sì ti fi èdìdì dì í di ìgbà ìkẹyìn.
10 Abanengi bazahlanjululwa, benziwe mhlophe, bahlolwe; kodwa ababi bazakwenza okubi; njalo kakho loyedwa wababi ozaqedisisa; kodwa abahlakaniphileyo bazaqedisisa.
Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ni a ó fọ̀ mọ́, wọn yóò wà láìlábàwọ́n, a ó sì tún wọn ṣe, ṣùgbọ́n àwọn ẹni búburú yóò máa ṣe búburú lọ, kò sí ẹni búburú tí òye yóò yé ṣùgbọ́n òye yóò yé àwọn ọlọ́gbọ́n.
11 Njalo kusukela esikhathini sokususwa komnikelo oqhubekayo, lokumiswa kwesinengiso esichithayo, kuzakuba lezinsuku eziyinkulungwane lamakhulu amabili lamatshumi ayisificamunwemunye.
“Láti àkókò tí a ó mú ẹbọ ojoojúmọ́ kúrò, tí a ó sì gbé ìríra tí ó ń fa ìsọdahoro kalẹ̀ yóò sì jẹ́ ẹgbẹ̀rún àti igba lé àádọ́rùn-ún ọjọ́.
12 Ubusisiwe olindayo aze afinyelele ezinsukwini eziyinkulungwane lamakhulu amathathu lamatshumi amathathu lanhlanu.
Ìbùkún ni fún ẹni tí ó dúró, ti ó sì di òpin ẹgbẹ̀rún àti ọ̀ọ́dúnrún lé àrùndínlógójì ọjọ́.
13 Kodwa wena, hamba kuze kube sekupheleni; ngoba uzaphumula, ume esabelweni sakho ekupheleni kwezinsuku.
“Ṣùgbọ́n ìwọ, máa lọ ní ọ̀nà rẹ, títí di òpin. Ìwọ yóò sinmi, àti ní òpin ọjọ́ ìwọ yóò dìde láti gba èrè rẹ.”

< UDanyeli 12 >