< 2 USamuyeli 24 >

1 Lwaselubuya lwamvuthela uIsrayeli ulaka lukaJehova, wabavusela uDavida, esithi: Hamba ubale uIsrayeli loJuda.
Ìbínú Olúwa sì ru sí Israẹli, ó sì ti Dafidi sí wọn, pé, “Lọ ka iye Israẹli àti Juda!”
2 Ngakho inkosi yathi kuJowabi induna yebutho eyayilaye: Hamba khathesi ubhode ezizweni zonke zakoIsrayeli, kusukela koDani kuze kube seBherishebha, libale abantu ukuze ngazi inani labantu.
Ọba sì wí fún Joabu olórí ogun, tí ń bẹ lọ́dọ̀ rẹ̀ pé, “Lọ ní ìsinsin yìí sí gbogbo ẹ̀yà Israẹli láti Dani títí dé Beerṣeba, kí ẹ sì ka iye àwọn ènìyàn, kí èmi lè mọ iye àwọn ènìyàn náà!”
3 UJowabi wasesithi enkosini: Aluba iNkosi uNkulunkulu wakho ingandisa ebantwini, loba bebanengi kangakanani, kuphindwe ngokulikhulu, ukuthi amehlo enkosi yami, inkosi, akubone. Kodwa inkosi yami, inkosi, ithokozelani kulinto?
Joabu sì wí fún ọba pé, “Kí Olúwa Ọlọ́run rẹ fi kún iye àwọn ènìyàn náà, iyekíye tí ó wù kí wọn jẹ́, ní ọ̀rọ̀ọ̀rún, ojú olúwa mi ọba yóò sì rí i, ṣùgbọ́n èétiṣe tí olúwa mi ọba fi fẹ́ nǹkan yìí?”
4 Kodwa ilizwi lenkosi lalilamandla phezu kukaJowabi laphezu kwezinduna zebutho. Ngakho uJowabi lenduna zebutho baphuma phambi kwenkosi ukuze babale abantu, uIsrayeli.
Ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ ọba borí ti Joabu, àti ti àwọn olórí ogun. Joabu àti àwọn olórí ogun sì jáde lọ kúrò níwájú ọba, láti lọ ka àwọn ènìyàn Israẹli.
5 Basebechapha iJordani, bamisa inkamba eAroweri, ngakwesokunene komuzi ophakathi kwesifula seGadi, lamaqondana leJazeri.
Wọ́n sì kọjá odò Jordani, wọ́n sì pàgọ́ ní Aroeri, ní ìhà apá ọ̀tún ìlú tí ó wà láàrín àfonífojì Gadi, àti sí ìhà Jaseri.
6 Basebefika eGileyadi lelizweni leTahetimi-Hodishi; bafika eDani-Jahani, babhoda ngaseSidoni,
Wọ́n sì wá sí Gileadi, àti sí ilé Tatimi Hodṣi; wọ́n sì wá sí Dani Jaani àti yíkákiri sí Sidoni.
7 bafika enqabeni yeTire lemizini yonke yamaHivi leyamaKhanani; baphuma baya eningizimu yakoJuda, eBherishebha.
Wọ́n sì wá sí ìlú olódi Tire, àti sí gbogbo ìlú àwọn Hifi, àti ti àwọn ará Kenaani, wọ́n sì jáde lọ síhà gúúsù ti Juda, àní sí Beerṣeba.
8 Sebebhode badabula ilizwe lonke, bafika eJerusalema ekupheleni kwenyanga eziyisificamunwemunye lensuku ezingamatshumi amabili.
Wọ́n sì la gbogbo ilẹ̀ náà já, wọ́n sì wá sí Jerusalẹmu ní òpin oṣù kẹsànán àti ogúnjọ́.
9 UJowabi waseyinika inkosi inani lokubalwa kwabantu; njalo kwakukhona koIsrayeli amaqhawe ayizinkulungwane ezingamakhulu ayisificaminwembili ahwatsha inkemba; lamadoda akoJuda ayengamadoda ayizinkulungwane ezingamakhulu amahlanu.
Joabu sì fi iye tí àwọn ènìyàn náà jásí lé ọba lọ́wọ́. Ó sì jẹ́ ogójì ọ̀kẹ́ ọkùnrin alágbára ní Israẹli, àwọn onídà, àwọn ọkùnrin Juda sì jẹ́ ọ̀kẹ́ mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n ènìyàn.
10 Inhliziyo kaDavida yasimtshaya emva kokuthi esebale abantu. UDavida wasesithi eNkosini: Ngonile kakhulu ngalokho engikwenzileyo. Ngakho-ke, Nkosi, ngiyakuncenga, susa ububi benceku yakho, ngoba ngenze ngobuthutha obukhulu.
Àyà Dafidi sì gbọgbẹ́ lẹ́yìn ìgbà tí ó ka àwọn ènìyàn náà tán. Dafidi sì wí fún Olúwa pé, “Èmi ṣẹ̀ gidigidi ní èyí tí èmi ṣe, ṣùgbọ́n, èmi bẹ̀ ọ, Olúwa, fi ẹ̀ṣẹ̀ ìránṣẹ́ rẹ jì ní, nítorí pé èmi hùwà aṣiwèrè gidigidi!”
11 Kwathi uDavida esevukile ekuseni, kwafika ilizwi leNkosi kuGadi umprofethi, umboni kaDavida, lisithi:
Dafidi sì dìde ní òwúrọ̀, ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Gadi wòlíì wá, aríran Dafidi wí pé,
12 Hamba uthi kuDavida: Itsho njalo iNkosi ithi: Ngikubekela okuthathu; zikhethele okukodwa kukho, ukuthi ngikwenze kuwe.
“Lọ kí o sì wí fún Dafidi pé, ‘Báyìí ni Olúwa wí, èmi fi nǹkan mẹ́ta lọ̀ ọ́; yan ọ̀kan nínú wọn, kí èmi ó sì ṣe é sí ọ.’”
13 UGadi wasefika kuDavida, wamtshela wathi kuye: Kufike kuwe yini iminyaka eyisikhombisa yendlala elizweni lakini? Loba ubalekele izitha zakho inyanga ezintathu zixotshana lawe? Ingabe kube khona umatshayabhuqe wesifo okwensuku ezintathu elizweni lakini? Khathesi cabanga, ubone ukuthi yimpendulo bani engizayibuyisela kongithumileyo.
Gadi sì tọ Dafidi wá, ó sì bi í léèrè pé, “Kí ìyàn ọdún méje ó tọ̀ ọ́ wá ní ilẹ̀ rẹ bí? Tàbí kí ìwọ máa sá ní oṣù mẹ́ta níwájú àwọn ọ̀tá rẹ, nígbà tí wọn ó máa lé ọ? Tàbí kí ààrùn ìparun ọjọ́ mẹ́ta ó wá sí ilẹ̀ rẹ? Rò ó nísinsin yìí, kí o sì mọ èsì tí èmi ó mú padà tọ ẹni tí ó rán mi.”
14 UDavida wasesithi kuGadi: Ngicindezelekile kakhulu; ake siwele esandleni seNkosi, ngoba izisa zayo zinkulu, kodwa kangingaweli esandleni somuntu.
Dafidi sì wí fún Gadi pé, “Ìyọnu ńlá bá mi. Jẹ́ kí a fi ara wa lé Olúwa ní ọwọ́; nítorí pé àánú rẹ̀ pọ̀; kí ó má sì ṣe fi mí lé ènìyàn ní ọwọ́.”
15 Ngakho iNkosi yasibeka umatshayabhuqe wesifo kuIsrayeli, kusukela ekuseni kwaze kwaba sesikhathini esimisiweyo; kwasekusifa ebantwini abantu abayizinkulungwane ezingamatshumi ayisikhombisa kusukela koDani kwaze kwaba seBherishebha.
Olúwa sì rán ààrùn ìparun sí Israẹli láti òwúrọ̀ títí dé àkókò tí a dá, ẹgbẹ̀rún ní ọ̀nà àádọ́rin ènìyàn sì kú nínú àwọn ènìyàn náà láti Dani títí fi dé Beerṣeba.
16 Lapho ingilosi iselulela isandla sayo eJerusalema ukuyibhubhisa, iNkosi yazisola ngalobobubi, yathi engilosini eyayibhubhisa abantu: Sekwanele. Khathesi finyeza isandla sakho. Ingilosi yeNkosi yayisebaleni lokubhulela likaArawuna umJebusi.
Nígbà tí angẹli náà sì nawọ́ rẹ̀ sí Jerusalẹmu láti pa á run, Olúwa sì káàánú nítorí ibi náà, ó sì sọ fún angẹli tí ń pa àwọn ènìyàn náà run pé, “Ó tó, dá ọwọ́ rẹ dúró wàyí!” Angẹli Olúwa náà sì wà níbi ìpakà Arauna ará Jebusi.
17 UDavida wasekhuluma eNkosini lapho ebona ingilosi eyayitshaya abantu, wathi: Khangela, mina ngonile, njalo mina ngenze okubi; pho, lezizimvu zenzeni? Isandla sakho ake simelane lami njalo simelane lendlu kababa.
Dafidi sì wí fún Olúwa nígbà tí ó rí angẹli tí ń kọlu àwọn ènìyàn pé, “Wò ó, èmi ti ṣẹ̀, èmi sì ti hùwà búburú ṣùgbọ́n àwọn àgùntàn wọ̀nyí, kín ni wọ́n ha ṣe? Jẹ́ kí ọwọ́ rẹ, èmi bẹ̀ ọ́, kí ó wà lára mi àti ìdílé baba mi.”
18 UGadi wasefika kuDavida ngalolosuku, wathi kuye: Yenyuka, umisele iNkosi ilathi ebaleni lokubhulela likaArawuna umJebusi.
Gadi sì tọ Dafidi wá ní ọjọ́ náà, ó sì wí fún un pé, “Gòkè, tẹ́ pẹpẹ kan fún Olúwa lórí ilẹ̀ ìpakà Arauna ará Jebusi.”
19 UDavida wasesenyuka njengokutsho kukaGadi, njengokulaya kweNkosi.
Gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Gadi, Dafidi sì gòkè lọ bí Olúwa ti pa á ní àṣẹ.
20 UArawuna waselunguza, wabona inkosi lenceku zayo beqhubeka besiza kuye; uArawuna wasephuma wakhothama phambi kwenkosi ngobuso bakhe emhlabathini.
Arauna sì wò, ó sì rí ọba àti àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ ń bọ̀ wá lọ́dọ̀ rẹ̀, Arauna sì jáde, ó sì wólẹ̀ níwájú ọba ó sì dojú rẹ̀ bolẹ̀.
21 UArawuna wasesithi: Kungani inkosi yami, inkosi, ize encekwini yayo? UDavida wasesithi: Ukuthi ngithenge kuwe ibala lokubhulela, ukuthi ngakhele iNkosi ilathi, ukuze inhlupheko ithinteke ingafiki ebantwini.
Arauna sì wí pé, “Nítorí kín ni olúwa mi ọba ṣe tọ ìránṣẹ́ rẹ̀ wá?” Dafidi sì dáhùn pé, “Láti ra ibi ìpakà rẹ lọ́wọ́ rẹ, láti tẹ́ pẹpẹ kan fún Olúwa, kí ààrùn ìparun lè dá lára àwọn ènìyàn náà.”
22 UArawuna wasesithi kuDavida: Inkosi yami, inkosi, kayithathe inikele lokho okuhle emehlweni ayo; bona, nanzi inkabi zomnikelo wokutshiswa, lezimbulo lezinto zenkabi kube zinkuni.
Arauna sì wí fún Dafidi pé, “Jẹ́ kí olúwa mi ọba ó mú èyí tí ó dára lójú rẹ̀, kí o sì fi í rú ẹbọ, wò ó, màlúù nìyìí láti fi ṣe ẹbọ sísun, àti ohun èlò ìpakà, àti ohun èlò mìíràn ti màlúù fún igi.
23 Konke lokhu, nkosi, uArawuna wakunika inkosi; uArawuna wasesithi enkosini: INkosi uNkulunkulu wakho kayikwemukele.
Gbogbo nǹkan wọ̀nyí ni Arauna fi fún ọba, bí ọba.” Arauna sì wí fún ọba pé, “Kí Olúwa Ọlọ́run rẹ ó gba ọrẹ rẹ.”
24 Inkosi yasisithi kuArawuna: Hatshi, kodwa ngizakuthenga lokukuthenga kuwe ngentengo; njalo kangiyikunikela iminikelo yokutshiswa engangibizanga lutho eNkosini uNkulunkulu wami. UDavida waselithenga ibala lokubhulela lezinkabi ngamashekeli esiliva angamatshumi amahlanu.
Ọba sì wí fún Arauna pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́; ṣùgbọ́n èmi ó rà á ní iye kan lọ́wọ́ rẹ, bí ó ti wù kí ó ṣe; bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò fi èyí tí èmi kò náwó fún, rú ẹbọ sísun sí Olúwa Ọlọ́run mi.” Dafidi sì ra ibi ìpakà náà, àti àwọn màlúù náà ní àádọ́ta ṣékélì fàdákà.
25 UDavida wasesakhela khona iNkosi ilathi, wanikela iminikelo yokutshiswa leminikelo yokuthula. Ngakho iNkosi yancengeka ngelizwe, inhlupheko yasithinteka phezu kukaIsrayeli.
Dafidi sì tẹ́ pẹpẹ kan níbẹ̀ sí Olúwa, ó sì rú ẹbọ sísun àti ti ìlàjà. Olúwa sì gbọ́ ẹ̀bẹ̀ fún ilẹ̀ náà, ààrùn náà sì dá kúrò ní Israẹli.

< 2 USamuyeli 24 >