< 2 Amakhosi 1 >

1 UMowabi wasevukela uIsrayeli emva kokufa kukaAhabi.
Lẹ́yìn ikú Ahabu, Moabu ṣọ̀tẹ̀ sí Israẹli.
2 UAhaziya wasesiwa eminxibeni yewindi ekamelweni lakhe eliphezulu eliseSamariya, wagula. Wathuma izithunywa, wathi kuzo: Hambani liyebuza kuBhali-Zebhubi unkulunkulu weEkhironi ukuthi ngizasila yini emkhuhlaneni lo.
Nísinsin yìí Ahasiah ti ṣubú láàrín fèrèsé láti òkè yàrá rẹ̀ tí ó wà ní Samaria, ó sì fi ara pa. Ó sì rán oníṣẹ́, ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ lọ ṣe ìwádìí lọ́wọ́ Baali-Sebubu, òrìṣà Ekroni, bóyá èmi ó lè rí ìwòsàn ìfarapa yìí.”
3 Kodwa ingilosi yeNkosi yathi kuElija umTishibi: Sukuma, wenyuke ukuhlangabeza izithunywa zenkosi yeSamariya, uthi kizo: Kungenxa yokuthi kakulaNkulunkulu yini koIsrayeli ukuthi lihambe liyebuza kuBhali-Zebhubi unkulunkulu weEkhironi?
Ṣùgbọ́n angẹli Olúwa wí fún Elijah ará Tiṣibi pé, “Lọ sókè kí o lọ bá ìránṣẹ́ ọba Samaria kí o sì béèrè lọ́wọ́ wọn, ‘Ṣé nítorí pé kò sí Ọlọ́run ní Israẹli ni ẹ̀yìn fi jáde lọ ṣèwádìí lọ́wọ́ Baali-Sebubu òrìṣà Ekroni?’
4 Ngakho-ke itsho njalo iNkosi: Umbheda owenyukele kuwo kawuyikwehla kuwo, ngoba uzakufa lokufa. UElija wasehamba.
Nítorí náà ohun tí Olúwa sọ ní èyí, ‘Ìwọ kò ní kúrò lórí ibùsùn tí o dùbúlẹ̀ lé. Dájúdájú ìwọ yóò kú!’” Bẹ́ẹ̀ ni Elijah lọ.
5 Lapho izithunywa sezibuyele kuyo, wathi kuzo: Kungani selibuyile?
Nígbà tí ìránṣẹ́ náà padà sí ọ̀dọ̀ ọba, ó béèrè ní ọwọ́ wọn pé, “Kí ni ó dé tí ẹ̀yin fi tètè padà wá?”
6 Zasezisithi kuyo: Umuntu wenyukile ukusihlangabeza, wathi kithi: Hambani libuyele enkosini elithumileyo, lithi kuyo: Itsho njalo iNkosi: Kungenxa yokuthi kakulaNkulunkulu koIsrayeli yini ukuthi uthumele ukubuza kuBhali-Zebhubi unkulunkulu weEkhironi? Ngakho umbheda owenyukele kuwo kawuyikwehla kuwo, ngoba sibili uzakufa.
Wọ́n dáhùn pé, “Ọkùnrin kan wá láti pàdé wa, ó sì wí fún wa pé, ‘Ẹ padà sí ọ̀dọ̀ ọba tí ó rán an yín kí ẹ sì wí fún un pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa wí: Ṣé nítorí wí pé kò sí Ọlọ́run ní Israẹli ni o fi ń rán àwọn ènìyàn láti lọ ṣe ìwádìí lọ́wọ́ Baali-Sebubu, òrìṣà Ekroni? Nítorí náà ìwọ kò ní fi orí ibùsùn tí ìwọ dùbúlẹ̀ lé sílẹ̀. Láìsí àní àní ìwọ yóò kùú!”’”
7 Yasisithi kuzo: Besinjani isimo salowomuntu owenyukele ukulihlangabeza, wakhuluma kini lamazwi?
Ọba béèrè lọ́wọ́ wọn pé, “Irú ọkùnrin wo ni ó wá pàdé yín, tí ó sì sọ irú èyí fún un yín?”
8 Basebesithi kuyo: Ubeyindoda eloboya, ebophe ngozwezwe lwesikhumba ekhalweni lwayo. Yasisithi: NguElija umTishibi.
Wọ́n dáhùn pé, “Ó jẹ́ ọkùnrin tí ó wọ ẹ̀wù onírun lára pẹ̀lú ọ̀já àmùrè aláwọ tí ó gbà yíká ìbàdí rẹ̀.” Ọba sì wí pé, “Elijah ará Tiṣibi ni.”
9 Inkosi yasithuma kuye induna yabangamatshumi amahlanu labangamatshumi amahlanu bayo. Yasisenyukela kuye; khangela-ke, wayehlezi engqongeni yentaba; yathi kuye: Muntu kaNkulunkulu, inkosi ithe: Yehla.
Ó sì rán balógun pẹ̀lú àwọn ẹgbẹ́ ogun àádọ́ta rẹ̀. Balógun náà sì gòkè tọ Elijah lọ, ẹni tí ó jókòó ní orí òkè, wọ́n sì wí fún un pé, “Ènìyàn Ọlọ́run, ọba wí pé, ‘Sọ̀kalẹ̀ wá!’”
10 UElija wasephendula wathi enduneni yabangamatshumi amahlanu: Uba-ke ngingumuntu kaNkulunkulu, kakwehle umlilo ovela emazulwini uqothule wena labangamatshumi amahlanu bakho. Wasusehla umlilo uvela emazulwini, wayiqothula yona labangamatshumi amahlanu bayo.
Elijah sì dá balógun lóhùn pé, “Tí ó bá jẹ́ wí pé ènìyàn Ọlọ́run ni mí, kí iná kí ó sọ̀kalẹ̀ láti òkè ọ̀run wá kí ó sì jó ìwọ àti àwọn àádọ́ta ọkùnrin rẹ!” Nígbà náà iná náà sì sọ̀kalẹ̀ wá láti òkè ọ̀run ó sì jó balógun àti àwọn ènìyàn rẹ̀.
11 Yasibuya ithuma kuye enye induna yabangamatshumi amahlanu labangamatshumi amahlanu bayo. Yasiphendula yathi kuye: Muntu kaNkulunkulu, itsho njalo inkosi: Yehla masinyane.
Ọba sì tún rán balógun àádọ́ta pẹ̀lú àwọn ènìyàn àádọ́ta rẹ̀ sí Elijah. Balógun náà sì wí fún un pé, “Ènìyàn Ọlọ́run, èyí ni ohun tí ọba sọ, ‘Sọ̀kalẹ̀ kánkán!’”
12 UElija wasephendula wathi kubo: Uba ngingumuntu kaNkulunkulu, kakwehle umlilo ovela emazulwini uqothule wena labangamatshumi amahlanu bakho. Wasusehla umlilo kaNkulunkulu uvela emazulwini, wayiqothula yona labangamatshumi amahlanu bayo.
“Tí èmi bá jẹ́ ènìyàn Ọlọ́run,” Elijah sì dáhùn, “Ǹjẹ́ kí iná kí ó sọ̀kalẹ̀ láti ọ̀run kí ó sì jó ọ run àti àwọn àádọ́ta ènìyàn rẹ!” Nígbà náà iná Ọlọ́run sọ̀kalẹ̀ láti ọ̀run ó sì jó o run pẹ̀lú àwọn àádọ́ta ènìyàn rẹ̀.
13 Yasithuma futhi induna yabangamatshumi amahlanu besithathu labangamatshumi amahlanu bayo. Leyonduna yesithathu yabangamatshumi amahlanu yasisenyuka yeza yawa ngamadolo ayo phambi kukaElija, yamncenga yathi kuye: Muntu kaNkulunkulu, ake ibe ligugu impilo yami lempilo yalezi inceku zakho ezingamatshumi amahlanu emehlweni akho.
Bẹ́ẹ̀ ni ọba tún rán balógun kẹta pẹ̀lú àwọn àádọ́ta ọkùnrin. Balógun ẹ̀ẹ̀kẹ́ta lọ sí òkè, ó sì kúnlẹ̀ lórí orókún rẹ̀ níwájú Elijah. “Ènìyàn Ọlọ́run,” Ó sì bẹ̀bẹ̀ pé, “Ìwọ ènìyàn Ọlọ́run, jọ̀wọ́ jẹ́ kí ẹ̀mí mi àti ẹ̀mí àwọn àádọ́ta ìránṣẹ́ rẹ wọ̀nyí ṣọ̀wọ́n ní ojú rẹ!
14 Khangela, wehla umlilo uvela emazulwini, waqothula induna ezimbili zabangamatshumi amahlanu zokuqala labangamatshumi amahlanu azo; ngakho-ke kayibe ligugu impilo yami emehlweni akho.
Wò ó, iná ti sọ̀kalẹ̀ láti ọ̀run láti jó àwọn balógun méjì àràádọ́ta àkọ́kọ́ pẹ̀lú àràádọ́ta wọn. Ṣùgbọ́n nísinsin yìí ní ojúrere fún ẹ̀mí mi!”
15 Ingilosi yeNkosi yasisithi kuElija: Yehla laye, ungamesabi. Wasesukuma, wehla laye waya enkosini;
Angẹli Olúwa sọ fún Elijah pé, “Sọ̀kalẹ̀ lọ pẹ̀lú rẹ̀; má ṣe bẹ̀rù rẹ̀.” Bẹ́ẹ̀ ni Elijah dìde ó sì sọ̀kalẹ̀ lọ pẹ̀lú rẹ̀ sí ọ̀dọ̀ ọba.
16 wathi kuyo: Itsho njalo iNkosi: Ngenxa yokuthi uthume izithunywa ukuyabuza kuBhali-Zebhubi, unkulunkulu weEkhironi, kungenxa yokuthi kakulaNkulunkulu koIsrayeli yini, ukubuza ilizwi lakhe? Ngakho-ke umbheda owenyukele kuwo kawuyikwehla kuwo, ngoba uzakufa lokufa.
Ó sọ fún ọba pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa wí, ‘Ṣé nítorí wí pé kò sí Ọlọ́run ní Israẹli fún ọ láti pè ni ìwọ fi rán ìránṣẹ́ lọ sí ọ̀dọ̀ Baali-Sebubu, òrìṣà Ekroni láti lọ ṣe ìwádìí?’ Nítorí pé o ṣe èyí, ìwọ kò ní dìde lórí ibùsùn tí o dùbúlẹ̀ lé láìsí àní àní ìwọ yóò kú!”
17 Wasesifa njengokwelizwi leNkosi uElija ayelikhulumile. UJehoramu wasesiba yinkosi esikhundleni sakhe, ngomnyaka wesibili kaJoramu indodana kaJehoshafathi inkosi yakoJuda, ngoba wayengelandodana.
Bẹ́ẹ̀ ó sì kú, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa tí Elijah ti sọ. Nítorí Ahasiah kò ní ọmọ, Jehoramu jẹ ọba ní ọdún kejì tí Jehoramu ọmọ Jehoṣafati ọba Juda.
18 Ezinye-ke zezindaba zikaAhaziya, azenzayo, kazibhalwanga yini egwalweni lwemilando yamakhosi akoIsrayeli?
Àti ní ti gbogbo àwọn ohun tí ó ṣẹlẹ̀ nígbà ìjọba Ahasiah, àti ohun tí ó ṣe, ṣe a kò ha kọ wọ́n sí inú ìwé ọdọọdún ti àwọn ọba Israẹli?

< 2 Amakhosi 1 >