< 1 Amakhosi 20 >

1 UBenihadadi inkosi yeSiriya wasebutha ibutho lakhe lonke, elamakhosi angamatshumi amathathu lambili, lamabhiza lezinqola. Wenyuka wayavimbezela iSamariya, walwa layo.
Beni-Hadadi ọba Aramu sì gbá gbogbo ogun rẹ̀ jọ. Ọba méjìlélọ́gbọ̀n sì ń bẹ pẹ̀lú rẹ̀ àti ẹṣin àti kẹ̀kẹ́, ó sì gòkè lọ, ó sì dó ti Samaria, ó sì kọlù ú.
2 Wathuma izithunywa kuAhabi inkosi yakoIsrayeli, emzini, wathi kuye: Utsho njalo uBenihadadi:
Ó sì rán àwọn ìránṣẹ́ sí ìlú sí Ahabu ọba Israẹli wí pé, “Báyìí ni Beni-Hadadi wí,
3 Isiliva sakho legolide lakho ngokwami, labafazi bakho labantwana bakho abahle ngabami.
‘Fàdákà àti wúrà rẹ tèmi ni, àti àwọn tí ó dára jùlọ nínú àwọn aya rẹ àti àwọn ọmọ rẹ tèmi ni wọ́n.’”
4 Inkosi yakoIsrayeli yasiphendula yathi: Njengokwelizwi lakho, nkosi yami, nkosi, ngingowakho, lakho konke engilakho.
Ọba Israẹli sì dá a lóhùn pé, “Gẹ́gẹ́ bí ìwọ ṣe wí olúwa mi ọba, èmi àti ohun gbogbo tí mo ní tìrẹ ni.”
5 Izithunywa zasezibuyela zathi: Utsho njalo uBenihadadi uthi: Lanxa ngithumele kuwe ngisithi: Isiliva sakho legolide lakho labafazi bakho labantwana bakho, kunike mina;
Àwọn oníṣẹ́ náà sì tún padà wá, wọ́n sì wí pé, “Báyìí ni Beni-Hadadi sọ wí pé, ‘Mo ránṣẹ́ láti béèrè fún fàdákà rẹ àti wúrà rẹ, àwọn aya rẹ àti àwọn ọmọ rẹ.
6 kube kanti phose ngalesisikhathi kusasa ngizathuma kuwe izinceku zami, zizaguduza indlu yakho lezindlu zezinceku zakho; kuzakuthi-ke, yonke into ethandekayo emehlweni akho, zizayifaka esandleni sazo ziyithathe.
Ṣùgbọ́n ní ìwòyí ọ̀la, èmi yóò rán àwọn ìránṣẹ́ mi sí ọ láti wá ilé rẹ wò àti ilé àwọn ìránṣẹ́ rẹ. Wọn yóò gba gbogbo ohun tí ó bá dára lójú rẹ, wọn yóò sì kó o lọ.’”
7 Ngakho inkosi yakoIsrayeli yabiza bonke abadala belizwe yathi: Ake linanzelele libone ukuthi lo udinga ububi, ngoba uthumele kimi ngabafazi bami langabantwana bami langesiliva sami langegolide lami, njalo kangimalelanga.
Nígbà náà ni ọba Israẹli pe gbogbo àwọn àgbàgbà ìlú, ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ wo bí ọkùnrin yìí ti ń fẹ́ ìyọnu! Nígbà tí ó ránṣẹ́ fún àwọn aya mi, àti fún àwọn ọmọ mi, àti fún fàdákà mi, àti fún wúrà mi, èmi kò sì fi dù ú.”
8 Bonke abadala labo bonke abantu basebesithi kuyo: Ungalaleli, njalo ungavumi.
Àwọn àgbàgbà àti gbogbo ènìyàn dá a lóhùn pé, “Má ṣe fi etí sí tirẹ̀ tàbí kí ó gbà fún un.”
9 Wasesithi kuzo izithunywa zikaBenihadadi: Tshelani inkosi yami, inkosi ukuthi: Konke eyakuthumela encekwini yayo kuqala ngizakwenza; kodwa linto kangilamandla okuyenza. Izithunywa zasezihamba, zayibuyisela ilizwi.
Nígbà náà ni ó sọ fún àwọn oníṣẹ́ Beni-Hadadi pé, “Sọ fún olúwa mi ọba pé, ‘Ìránṣẹ́ rẹ̀ yóò ṣe ohun gbogbo tí ó ránṣẹ́ fún látètèkọ́ṣe, ṣùgbọ́n nǹkan yìí ni èmi kò le ṣe.’” Wọ́n padà lọ, wọ́n sì mú èsì padà wá fún Beni-Hadadi.
10 UBenihadadi wasethumela kuye wathi: Kabenze njalo onkulunkulu kimi, bengezelele njalo, uba ubhuqu lweSamariya lungenela izandla ezigcweleyo zabo bonke abantu abangilandelayo.
Beni-Hadadi sì tún rán oníṣẹ́ mìíràn sí Ahabu wí pé, “Kí àwọn òrìṣà kí ó ṣe bẹ́ẹ̀ sí mi àti jù bẹ́ẹ̀ lọ pẹ̀lú bí eruku Samaria yóò tó fún ìkúnwọ́ fún gbogbo ènìyàn tí ń tẹ̀lé mi.”
11 Inkosi yakoIsrayeli yasiphendula yathi: Mtsheleni: Lowo obhinca izikhali kangaziqakisi njengozikhululayo.
Ọba Israẹli sì dáhùn wí pé, “Sọ fún un pé, ‘Má jẹ́ kí ẹni tí ń hámọ́ra halẹ̀ bí ẹni tí ń bọ́ ọ sílẹ̀.’”
12 Kwasekusithi esizwa lelilizwi esanatha, yena lamakhosi emadumbeni, wathi ezincekwini zakhe: Zimiseni! Zasezizimisa ukumelana lomuzi.
Beni-Hadadi sì gbọ́ ọ̀rọ̀ yìí nígbà tí òun àti àwọn ọba ń mu ọtí nínú àgọ́ wọn, ó sì pàṣẹ fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ wí pé, “Ẹ ṣígun sí ìlú náà.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì ṣe tan láti kọlu ìlú náà.
13 Khangela-ke, umprofethi othile wasondela kuAhabi inkosi yakoIsrayeli, wathi: Itsho njalo iNkosi: Uyalibona lelixuku lonke elikhulu yini? Khangela, ngizalinikela esandleni sakho lamuhla, njalo uzakwazi ukuthi mina ngiyiNkosi.
Sì kíyèsi i, wòlíì kan tọ Ahabu ọba Israẹli wá, ó sì wí pé, “Báyìí ni Olúwa wí: ‘Ìwọ rí gbogbo ọ̀pọ̀lọpọ̀ ogun yìí? Èmi yóò fi wọ́n lé ọ lọ́wọ́ lónìí, nígbà náà ni ìwọ yóò mọ̀ pé Èmi ni Olúwa.’”
14 UAhabi wasesithi: Ngobani? Wasesithi: Itsho njalo iNkosi: Ngamajaha abaphathi bezabelo. Wasesithi: Ngubani ozaqalisa impi? Wasesithi: Wena.
Ahabu sì béèrè pé, “Ṣùgbọ́n ta ni yóò ṣe èyí?” Wòlíì náà sì dáhùn wí pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa wí: ‘Nípa ìpẹ́ẹ̀rẹ̀ àwọn ìjòyè ìgbèríko.’” Nígbà náà ni ó wí pé. “Ta ni yóò bẹ̀rẹ̀ ogun náà?” Wòlíì sì dalóhùn pé, “Ìwọ ni yóò ṣe é.”
15 Wasebala amajaha abaphathi bezabelo, ayengamakhulu amabili lamatshumi amathathu lambili; lemva kwawo wabala bonke abantu, bonke abantwana bakoIsrayeli, izinkulungwane eziyisikhombisa.
Nígbà náà ni Ahabu ka àwọn ìjòyè kéékèèké ìgbèríko, wọ́n sì jẹ́ igba ó lé méjìlélọ́gbọ̀n. Nígbà náà ni ó sì kó gbogbo àwọn ọmọ Israẹli tókù jọ, gbogbo wọn sì jẹ́ ẹ̀ẹ́dẹ́gbàárin.
16 Basebephuma emini, uBenihadadi esenathe wadakwa emadumbeni, yena lamakhosi, amakhosi angamatshumi amathathu lambili ayemsiza.
Wọ́n sì jáde lọ ní ọ̀sán gangan, nígbà tí Beni-Hadadi àti àwọn ọba méjìlélọ́gbọ̀n tí ń ràn án lọ́wọ́ ń mu àmupara nínú àgọ́.
17 Amajaha abaphathi bezabelo asephuma kuqala. UBenihadadi wasethuma, basebemtshela besithi: Kuphume amadoda eSamariya.
Àwọn ìjòyè kéékèèké ìgbèríko tètè kọ́ jáde lọ. Beni-Hadadi sì ránṣẹ́ jáde, wọ́n sì sọ fún un wí pé, “Àwọn ọkùnrin ń ti Samaria jáde wá.”
18 Wasesithi: Loba ephumele ukuthula, abambeni ephila; loba-ke ephumele impi, abambeni ephila.
Ó sì wí pé, “Bí wọ́n bá bá ti àlàáfíà jáde wá, ẹ mú wọn láààyè; bí ti ogun ni wọ́n bá bá jáde, ẹ mú wọn láààyè.”
19 Lala aphuma emzini, amajaha abaphathi bezabelo, lebutho elawalandelayo.
Àwọn ìjòyè kéékèèké wọ̀nyí ti àwọn ìjòyè ìgbèríko jáde ti ìlú wá, àti ogun tí ó tẹ̀lé wọn.
20 Babulala, ngulowo lalowo umuntu wakhe. AmaSamariya asebaleka, uIsrayeli wasexotshana lawo, kodwa uBenihadadi inkosi yeSiriya waphunyuka ngebhiza kanye labagadi bamabhiza.
Olúkúlùkù sì pa ọkùnrin kọ̀ọ̀kan. Àwọn ará Aramu sì sá, Israẹli sì lépa wọn. Ṣùgbọ́n Beni-Hadadi ọba Aramu sì sálà lórí ẹṣin pẹ̀lú àwọn ẹlẹ́ṣin.
21 Inkosi yakoIsrayeli yasiphuma, yatshaya amabhiza lenqola, yatshaya phakathi kwamaSiriya ngokubulala okukhulu.
Ọba Israẹli sì jáde lọ, ó sì kọlu àwọn ẹṣin àti kẹ̀kẹ́, ó pa àwọn ará Aramu ní ọ̀pọ̀lọpọ̀.
22 Lowomprofethi wasesondela enkosini yakoIsrayeli wathi kuyo: Hamba, uziqinise, unanzelele njalo ubone okwenzayo; ngoba ekuthwaseni komnyaka inkosi yeSiriya izakwenyuka imelane lawe.
Lẹ́yìn náà, wòlíì náà sì wá sọ́dọ̀ ọba Israẹli, ó sì wí pé, “Lọ, mú ara rẹ gírí, kí o sì mọ̀, kí o sì wo ohun tí ìwọ yóò ṣe, nítorí ní àmọ́dún ọba Aramu yóò tún gòkè tọ̀ ọ́ wá.”
23 Lezinceku zenkosi yeSiriya zathi kuyo: Onkulunkulu babo bangonkulunkulu bezintaba, yikho belamandla kulathi; kube kanti asilwe labo emagcekeni, sibili sizabehlula.
Àwọn ìránṣẹ́ ọba Aramu sì wí fún un pé, “Ọlọ́run wọn, ọlọ́run òkè ni. Ìdí nìyìí tí wọ́n ṣe ní agbára jù wá lọ. Ṣùgbọ́n bí a bá bá wọn jà ní pẹ̀tẹ́lẹ̀, àwa yóò ní agbára jù wọ́n lọ dájúdájú.
24 Ngakho yenza linto: Susa amakhosi, ngulowo lalowo endaweni yakhe, ubeke izinduna esikhundleni sawo;
Nǹkan yìí ni kí o sì ṣe, mú àwọn ọba kúrò, olúkúlùkù kúrò ní ipò rẹ̀, kí o sì fi baálẹ̀ sí ipò wọn.
25 njalo wena zibalele ibutho njengebutho eliwileyo kuwe, lebhiza njengebhiza, lenqola njengenqola; njalo sizakulwa labo emagcekeni, isibili sizabehlula. Yasilalela ilizwi labo, yenza njalo.
Kí o sì tún kó ogun jọ fún ara rẹ bí èyí tí ó ti sọnù; ẹṣin fún ẹṣin, kẹ̀kẹ́ fún kẹ̀kẹ́; kí a bá lè bá Israẹli jà ní pẹ̀tẹ́lẹ̀. Nítòótọ́ àwa yóò ní agbára jù wọ́n lọ.” Ó sì gba tiwọn, ó sì ṣe bẹ́ẹ̀.
26 Kwasekusithi ekuthwaseni komnyaka uBenihadadi wabala amaSiriya, wenyukela eAfeki ekulweni loIsrayeli.
Ó sì ṣe ní àmọ́dún, Beni-Hadadi ka iye àwọn ará Aramu, ó sì gòkè lọ sí Afeki, láti bá Israẹli jagun.
27 Abantwana bakoIsrayeli babalwa-ke, banikwa imiphako, basebephuma ukumelana lawo; abantwana bakoIsrayeli bamisa inkamba phambi kwawo njengemihlanjana yembuzi emibili, kodwa amaSiriya agcwala ilizwe.
Nígbà tí a sì ka àwọn ọmọ Israẹli, wọ́n sì pèsè oúnjẹ, wọ́n sì lọ pàdé wọn. Àwọn ọmọ Israẹli sì dó ní òdìkejì wọn gẹ́gẹ́ bí agbo ọmọ ewúrẹ́ kékeré méjì, nígbà tí àwọn ará Aramu kún ilẹ̀ náà.
28 Kwasekusondela umuntu kaNkulunkulu, wakhuluma enkosini yakoIsrayeli wathi: Itsho njalo iNkosi: Ngenxa yokuthi amaSiriya athe: INkosi inguNkulunkulu wezintaba, kodwa kayisuye uNkulunkulu wezihotsha, ngakho ngizanikela esandleni sakho lelixuku lonke elikhulu, njalo lizakwazi ukuthi mina ngiyiNkosi.
Ènìyàn Ọlọ́run kan sì gòkè wá, ó sì sọ fún ọba Israẹli pé, “Báyìí ni Olúwa wí: ‘Nítorí tí àwọn ará Aramu rò pé Olúwa, Ọlọ́run òkè ni, ṣùgbọ́n òun kì í ṣe Ọlọ́run àfonífojì, nítorí náà èmi ó fi gbogbo ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn yìí lé ọ lọ́wọ́, ẹ̀yin yóò sì mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.’”
29 Basebemisa inkamba, enye iqondene lenye, insuku eziyisikhombisa. Kwasekusithi ngosuku lwesikhombisa impi yadibana; abantwana bakoIsrayeli basebetshaya ngosuku lunye amaSiriya azinkulungwane ezilikhulu ahamba ngenyawo.
Wọ́n sì dó sí òdìkejì ara wọn fún ọjọ́ méje, àti ní ọjọ́ keje, wọ́n pàdé ogun. Àwọn ọmọ Israẹli sì pa ọ̀kẹ́ márùn-ún ẹlẹ́ṣẹ̀ nínú àwọn ará Aramu ní ọjọ́ kan.
30 Labaseleyo babalekela eAfeki emzini; lomduli wawela phezu kwamadoda ayizinkulungwane ezingamatshumi amabili lesikhombisa ayesele. UBenihadadi laye wabaleka, wangena emzini ekamelweni elingaphakathi.
Àwọn tókù sì sá àsálà lọ sí Afeki, sínú ìlú tí odi ti wó lù ẹgbàá mẹ́tàlá lé ẹgbẹ̀rún nínú wọn. Beni-Hadadi sì sálọ sínú ìlú, ó sì fi ara pamọ́ sínú ìyẹ̀wù.
31 Lezinceku zakhe zathi kuye: Khangela-ke, sizwile ukuthi amakhosi endlu yakoIsrayeli angamakhosi alesihawu; ake sifake amasaka enkalweni zethu, lamagoda emakhanda ethu, siphumele enkosini yakoIsrayeli; mhlawumbe izagcina umphefumulo wakho uphile.
Àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ sì wí fún un pé, “Wò ó, a ti gbọ́ pé àwọn ọba ilẹ̀ Israẹli jẹ́ ọba aláàánú, mo bẹ̀ ọ́ jẹ́ kí àwa kí ó tọ̀ ọ́ lọ pẹ̀lú aṣọ ọ̀fọ̀ ní ẹ̀gbẹ́ wa, àti okùn yí orí wa ká. Bóyá òun yóò gba ẹ̀mí rẹ là.”
32 Basebethandela amasaka enkalweni zabo, lamagoda emakhanda abo, bafika enkosini yakoIsrayeli, bathi: Inceku yakho uBenihadadi ithi: Ake ungiyekele ngiphile. Yasisithi: Usaphila yini? Ungumfowethu.
Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n di aṣọ ọ̀fọ̀ mọ́ ẹ̀gbẹ́ wọn, wọ́n sì fi okùn yí orí wọn ká, wọ́n sì tọ ọba Israẹli wá, wọ́n sì wí pé, “Ìránṣẹ́ rẹ Beni-Hadadi wí pé, ‘Èmi bẹ̀ ọ́ jẹ́ kí èmi kí ó yè.’” Ọba sì dáhùn wí pé, “Ó ń bẹ láààyè bí? Arákùnrin mi ni òun.”
33 Lamadoda aqaphela ngokukhuthala aphangisa ukukuhluthuna kuyo, athi: Umfowenu uBenihadadi. Yasisithi: Hambani liyemthatha. UBenihadadi wasephumela kuyo, yamkhweza enqoleni.
Àwọn ọkùnrin náà sì ṣe àkíyèsí gidigidi, wọ́n sì yára gbá ọ̀rọ̀ rẹ̀ mú, wọ́n sì wí pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, Beni-Hadadi arákùnrin rẹ.” Ọba sì wí pé, “Ẹ lọ mú u wá.” Nígbà tí Beni-Hadadi jáde tọ̀ ọ́ wá, Ahabu sì mú u gòkè wá sínú kẹ̀kẹ́.
34 Wasesithi kuyo: Imizi ubaba ayithatha kuyihlo ngizayibuyisela; futhi ungazenzela izitalada eDamaseko njengokwenza kukababa eSamariya. Khona uAhabi wathi: Mina ngizakuyekela uhambe ngalesisivumelwano. Yasisenza laye isivumelwano yamyekela ehamba.
Beni-Hadadi sì wí pé, “Èmi yóò dá àwọn ìlú tí baba mi ti gbà lọ́wọ́ baba rẹ padà, ìwọ sì le la ọ̀nà fún ara rẹ ní Damasku, bí baba mi ti ṣe ní Samaria.” Ahabu sì wí pé, “Èmi yóò rán ọ lọ pẹ̀lú májẹ̀mú yìí.” Bẹ́ẹ̀ ni ó ba dá májẹ̀mú, ó sì rán an lọ.
35 Umuntu othile wamadodana abaprofethi wasesithi kumakhelwane wakhe ngelizwi leNkosi uNkulunkulu: Ake ungitshaye. Kodwa lowomuntu wala ukumtshaya.
Nípa ọ̀rọ̀ Olúwa, ọkùnrin kan nínú àwọn ọmọ àwọn wòlíì sì wí fún èkejì rẹ̀ pé, “Jọ̀ ọ́, lù mí,” ṣùgbọ́n ó kọ̀ láti lù ú.
36 Wasesithi kuye: Ngenxa yokuthi ungalilalelanga ilizwi leNkosi, khangela, ekusukeni kwakho kimi isilwane sizakutshaya. Wasesuka kuye, lesilwane samfica, sambulala.
Nígbà náà ni ó wí pé, “Nítorí tí ìwọ kò gba ohùn Olúwa gbọ́, kíyèsi i, bí ìwọ bá kúrò ní ọ̀dọ̀ mi, kìnnìún yóò pa ọ́.” Bí ó ti jáde lọ kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀, kìnnìún kan rí i, ó sì pa á.
37 Wasethola omunye umuntu wathi: Ake ungitshaye. Lalowomuntu wamtshaya lokumtshaya emlimaza.
Wòlíì náà sì rí ọkùnrin mìíràn, ó sì wí fún un pé, “Jọ̀ ọ́, lù mí.” Bẹ́ẹ̀ ni ọkùnrin náà sì lù ú, ó sì pa á lára.
38 Ngakho umprofethi wasuka, wamelela inkosi endleleni, ezifihle isimo ngelembu emehlweni.
Wòlíì náà sì lọ, ó sì dúró de ọba ní ojú ọ̀nà. Ó pa ara rẹ̀ dà ní fífi eérú bo ojú.
39 Kwasekusithi inkosi idlula, yena wamemeza enkosini wathi: Inceku yakho yaphuma phakathi kwempi; khangela-ke, umuntu waphambuka, waletha umuntu kimi, wathi: Londoloza lumuntu; uba elahleka lokulahleka, khona impilo yakho izakuba sesikhundleni sempilo yakhe, kumbe uhlawule ngethalenta lesiliva.
Bí ọba sì ti ń rékọjá, wòlíì náà ké sí i, ó sì wí pé, “Ìránṣẹ́ rẹ jáde wọ àárín ogun lọ, ẹnìkan sì wá sí ọ̀dọ̀ mi pẹ̀lú ìgbèkùn kan, ó sì wí pé, ‘Pa ọkùnrin yìí mọ́. Bí a bá fẹ́ ẹ kù, ẹ̀mí rẹ yóò lọ dípò ẹ̀mí rẹ̀, tàbí kí ìwọ san tálẹ́ǹtì fàdákà kan.’
40 Kwasekusithi inceku yakho isaphathekile lapha lalaphaya, yena wayengekho. Inkosi yakoIsrayeli yasisithi kuye: Sinjalo isahlulelo sakho, ususiqumile wena.
Nígbà tí ìránṣẹ́ rẹ̀ sì ní ìṣe níhìn-ín àti lọ́hùn ún, a fẹ́ ẹ kù.” Ọba Israẹli sì wí fún un pé, “Bẹ́ẹ̀ ni ìdájọ́ rẹ yóò rí, ìwọ fúnra rẹ̀ ti dá a.”
41 Wasephangisa walisusa ilembu emehlweni akhe. Inkosi yakoIsrayeli yasimazi ukuthi ungowabaprofethi.
Nígbà náà ni wòlíì náà yára, ó sì mú eérú kúrò ní ojú rẹ̀, ọba Israẹli sì mọ̀ ọ́n pé ọ̀kan nínú àwọn wòlíì ni ó ń ṣe.
42 Wasesithi kuyo: Itsho njalo iNkosi: Ngoba umyekele ukuthi aphume esandleni umuntu engimmisele ukumtshabalalisa, ngakho impilo yakho izakuba sesikhundleni sempilo yakhe, labantu bakho esikhundleni sabantu bakhe.
Ó sì wí fún ọba pé, “Báyìí ni Olúwa wí: ‘Ìwọ ti jọ̀wọ́ ọkùnrin tí èmi ti yàn sí ìparun pátápátá lọ́wọ́ lọ. Nítorí náà, ẹ̀mí rẹ yóò lọ fún ẹ̀mí rẹ, ènìyàn rẹ fún ènìyàn rẹ̀.’”
43 Inkosi yakoIsrayeli yasisiya endlini yayo inyukumele, ithukuthele, yafika eSamariya.
Ọba Israẹli sì lọ sí ilé rẹ̀ ní wíwú gbọ́, inú rẹ sì bàjẹ́, ó sì wá sí Samaria.

< 1 Amakhosi 20 >