< UJeremiya 2 >
1 Ilizwi likaThixo lafika kimi lisithi,
Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ̀ mí wá wí pé:
2 “Hamba umemezele iJerusalema lisizwa uthi: Lokhu yikho okutshiwo nguThixo: ‘Ngiyakukhumbula ukuzinikela kwasebutsheni bakho, ukungithanda kwakho njengomlobokazi ungilandela enkangala, phakathi kwelizwe elingahlanyelwanga.
“Lọ kí o sì kéde sí etí Jerusalẹmu pé: “Báyìí ni Olúwa wí, “‘Èmi rántí ìṣeun ìgbà èwe rẹ, ìfẹ́ ìgbéyàwó rẹ àti nígbà tí ìwọ tẹ̀lé mi nínú ijù, nínú ìyàngbẹ ilẹ̀.
3 U-Israyeli wayengcwele kuThixo, eyizithelo zakuqala zesivuno sakhe, bonke abamtshwabadelayo baba lecala, behlelwa yincithakalo,’” kutsho uThixo.
Israẹli jẹ́ mímọ́ sí Olúwa, àkọ́kọ́ èso ìkórè rẹ̀, gbogbo ẹnikẹ́ni tí ó jẹ run ni a ó dá lẹ́bi, ibi yóò sì wá sí orí wọn,’” bẹ́ẹ̀ ni Olúwa wí.
4 Zwana ilizwi likaThixo, we ndlu kaJakhobe, lani lonke sendo lwendlu ka-Israyeli.
Gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa, ẹ̀yin ìdílé Jakọbu àti gbogbo ẹ̀yin ará ilé Israẹli.
5 UThixo uthi: “Yibubi bani okhokho benu ababubona kimi, baze bedukele khatshana kangaka lami? Balandela izithombe eziyize, labo ngokwabo baba yize.
Báyìí ni Olúwa wí: “Irú àìṣedéédéé wo ni baba yín rí lọ́wọ́ mi, tí wọ́n fi jìnnà sí mi? Wọ́n tẹ̀lé àwọn òrìṣà asán, àwọn fúnra wọn sì di asán.
6 Kababuzanga ukuthi, ‘Ungaphi uThixo, owasikhupha elizweni laseGibhithe wasikhokhela emagangeni alugwadule phakathi kwelizwe lezinkangala lezindonga, ilizwe lokoma lobumnyama, ilizwe elingahanjwa muntu lelingelamuntu ohlala kulo?’
Wọn kò béèrè, ‘Níbo ni Olúwa wà, tí ó mú wa jáde láti ilẹ̀ Ejibiti wá, tí ó mú wa la aginjù já, tí ó mú wa la àárín pẹ̀tẹ́lẹ̀ àti ihò, ìyàngbẹ ilẹ̀ àti òkùnkùn biribiri, ilẹ̀ ibi tí ẹnikẹ́ni kò là kọjá, tí ẹnikẹ́ni kò sì tẹ̀dó sí?’
7 Ngaliletha elizweni elivundileyo ukuba lidle izithelo zalo lezilimo ezinhle. Kodwa lina lafika langcolisa ilizwe lami, lenza ilifa lami langakhwabitheki.
Èmi mú yín wá sí ilẹ̀ ọlọ́ràá láti máa jẹ èso ibẹ̀ àti ọrọ̀ rẹ̀, ṣùgbọ́n ẹ̀yin wọ inú rẹ̀, ẹ sì bà á jẹ́, ẹ sì sọ ogún mi di ohun ìríra.
8 Abaphristi kababuzanga ukuthi, ‘Ungaphi UThixo?’ Labo abaphatha umthetho abangazanga; abakhokheli bangihlamukela. Abaphrofethi baphrofetha ngoBhali balandela izithombe eziyize.
Àwọn àlùfáà kò béèrè wí pé, ‘Níbo ni Olúwa wà?’ Àwọn tí ń ṣiṣẹ́ pẹ̀lú òfin kò si mọ̀ mí, àwọn olùṣọ́ sì ṣẹ̀ sí mi. Àwọn wòlíì sì ń sọtẹ́lẹ̀ nípa òrìṣà Baali, wọ́n sì ń tẹ̀lé àwọn òrìṣà asán.
9 Ngakho-ke ngilethesa amacala futhi,” kutsho uThixo. “Labantwana babantwana benu ngizabethesa amacala.
“Nítorí náà, mo fi ẹ̀sùn kàn yín lẹ́ẹ̀kan sí i,” ni Olúwa wí. “Èmi ó sì fi ẹ̀sùn kan àwọn ọmọ ọwọ́ rẹ.
10 Welani liye ngasemakhunjini aseKhithimi likhangele, thumelani eKhedari lihlolisise kuhle, libone langabe sekwake kwaba lento enjengale:
Rékọjá lọ sí erékùṣù àwọn ara Kittimu, kí ẹ sì wò ó, ránṣẹ́ lọ sí ìlú Kedari, kí ẹ sì kíyèsi gidigidi; kí ẹ wò bí irú nǹkan báyìí bá ń bẹ níbẹ̀?
11 Isizwe sake santshintsha onkulunkulu baso na? (Belo bavele kabasibo onkulunkulu.) Kodwa abantu bami bantshintshe inkazimulo yabo ngenxa yezithombe eziyize.
Orílẹ̀-èdè kan ha á pa ọlọ́run rẹ̀ dà? (Síbẹ̀, wọ́n kì í ṣe iṣẹ́ ọlọ́run.) Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn mi ti pààrọ̀ Ọlọ́run ògo wọn fún àwọn ère tí kò níyì.
12 Mangalani lokhu, lina mazulu, lithuthumele ngokwesaba okukhulu,” kutsho UThixo.
Àwọn ènìyàn mi ti dẹ́ṣẹ̀ méjì kí ẹ sì wárìrì pẹ̀lú ìbẹ̀rù ńlá,” ni Olúwa wí.
13 “Abantu bami benze izono ezimbili: Bangidelile, mina mthombo wamanzi okuphila, bagebha eyabo imithombo, imithombo evuzayo engagcini manzi.
“Àwọn ènìyàn mi ti dẹ́ṣẹ̀ méjì, wọ́n ti kọ̀ mí sílẹ̀, Èmi orísun omi ìyè, wọ́n sì ti ṣe àmù, àmù fífọ́ tí kò lè gba omi dúró.
14 Kambe u-Israyeli yisisebenzi, isigqili ngokuzalwa na? Pho kungani eseyimpango na?
Israẹli ha á jẹ́ ọmọ ọ̀dọ̀ ẹrú nípa ìbí? Kí ló ha a dé tí ó fi di ìkógun?
15 Izilwane zibhongile; sezihwabhile kuye. Zilichithile ilizwe lakhe; amadolobho akhe atshisiwe, atshiywa engaselamuntu.
Àwọn kìnnìún ké ramúramù; wọ́n sì ń bú mọ́ wọn. Wọ́n ti fi ilẹ̀ rẹ̀ ṣòfò; ìlú rẹ̀ ti di jíjóná, ó sì ti di ìkọ̀sílẹ̀.
16 Njalo, labantu baseMemfisi leThahiphanesi baphuce ikhanda lakho.
Bákan náà, àwọn ọkùnrin Memfisi àti Tafanesi wọ́n ti fa adé orí rẹ yọ.
17 Lokhu kawukwehliselanga phezu kwakho ngokudela uThixo uNkulunkulu wakho lapho ekukhokhela endleleni na?
Ẹ̀yin kò ha a ti fa èyí sórí ara yín nípa kíkọ Olúwa Ọlọ́run sílẹ̀ nígbà tí ó tọ́ ọ lójú ọ̀nà?
18 Khathesi kungani usiya eGibhithe ukuba unathe amanzi eShihori na? Njalo kungani usiya e-Asiriya ukuba unathe amanzi eYufrathe na?
Kí ló dé tí o ṣe wá lọ Ejibiti láti lọ mu omi ní Ṣihori? Kí ló dé tí o sì fi lọ sí Asiria láti lọ mú omi ni odò Eufurate náà?
19 Ububi bakho buzakujezisa; ukutshedela kwakho emuva kuzakukhuza. Ngakho cabanga ubone ukuthi kubi njalo kubuhlungu kanjani lapho udela uThixo uNkulunkulu wakho njalo ungelavalo ngami,” kutsho iNkosi uThixo uSomandla.
Iṣẹ́ búburú yín yóò fìyà jẹ yín ìpadàsẹ́yìn rẹ yóò sì bá ọ wí mọ̀ kí o sì rí i wí pé ibi àti ohun búburú yóò sì jẹ́ tìrẹ nígbà tí o ti kọ Olúwa Ọlọ́run sílẹ̀, ẹ kò sì ní ìbẹ̀rù fún mi,” ni Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
20 “Endulo wephula ijogwe lakho, waquma izibopho zakho; wathi, ‘Kangiyikukukhonza!’ Lakanye, phezu kwamaqaqa wonke langaphansi kwazo zonke izihlahla eziluhlaza walala phansi njengesifebe.
“Nígbà àtijọ́, o ti fọ́ àjàgà rẹ sọnù, ìwọ sì já ìdè rẹ; ìwọ wí pé, ‘Èmi kì yóò sìn ọ́!’ Lóòtítọ́, lórí gbogbo òkè gíga ni àti lábẹ́ igi tí ó tànkálẹ̀ ni ìwọ dùbúlẹ̀ sí gẹ́gẹ́ bí panṣágà.
21 Ngikuhlanyele njengevini elikhethiweyo elohlobo oluqinileyo loluthembekileyo. Pho kwenzakala njani ukuba ungiphendukele ube livini elibolileyo, leganga?
Èmi ti gbìn ọ́ gẹ́gẹ́ bí àjàrà ọ̀tọ̀, gẹ́gẹ́ bí ìṣúra ọlọ́lá. Báwo wá ni ìwọ ṣe yípadà sí mi di àjàrà búburú àti aláìmọ́?
22 Lanxa ugeza ngesepa usebenzisa lesepa enengi, ichatha lobubi bakho lilokhu likhona phambi kwami,” kutsho uThixo Wobukhosi.
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé o wẹ ara rẹ pẹ̀lú sódà tí o sì lo ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọṣẹ síbẹ̀síbẹ̀ èérí ni ẹ̀ṣẹ̀ rẹ níwájú,” ni Olúwa Olódùmarè wí.
23 “Ungatsho kanjani na uthi, ‘Kangingcolanga, kangibalandelanga oBhali’? Khangela ukuthi waziphatha njani esigodini, khumbula osukwenzile. Ulikamela elisikazi elilesiqubu eligijima lapha lalaphaya,
“Báwo ni ìwọ ṣe wí pé, ‘Èmi kò ṣe aláìmọ́, Èmi kò sá à tẹ̀lé àwọn Baali’? Wo bí o ṣe hùwà ní àfonífojì; wo ohun tí o ṣe. Ìwọ jẹ́ abo ìbákasẹ tí ń sá síyìn-ín sọ́hùn-ún.
24 ubabhemi weganga ojwayele inkangala, ophembela umoya enkanukweni yakhe, ngubani ongamenqabela ekukhanukeni kwakhe? Abaduna abamxotshayo bangazidinisi ukuxotshana labo; bazamthola ngesikhathi sezinsikazikhwela.
Kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ igbó tí ń gbé aginjù tí ń fa ẹ̀fúùfù ìfẹ́ sí i mu rẹ, ta ni ó le è mú dúró ní àkókò rẹ̀? Kí gbogbo àwọn akọ ẹran tí o wá a kiri kì ó má ṣe dá ara wọn lágara, nítorí wọn yóò rí ní àkókò oṣù rẹ̀.
25 Ungagijimi inyawo zakho zize zihlubuke lomphimbo wakho uze wome. Kodwa wena wathi, ‘Akusizi lutho! Ngiyabathanda onkulunkulu bezizweni, kumele ngibalandele.’
Dá ẹsẹ̀ dúró láìwọ bàtà, àti ọ̀fun rẹ nínú òǹgbẹ. Ṣùgbọ́n ìwọ wí pé, ‘Asán ni! Èmi fẹ́ràn àwọn ọlọ́run àjèjì, àwọn ni èmi yóò tọ̀ lẹ́yìn.’
26 Njengokuyangeka kwesela nxa selibanjiwe, ngokunjalo abantu bako-Israyeli bayangekile, bona kanye lamakhosi abo lezikhulu zabo, abaphristi babo labaphrofethi babo.
“Gẹ́gẹ́ bí a ṣe ń dójútì olè nígbà tí a bá mú u, bẹ́ẹ̀ náà ni ojú yóò ti ilé Israẹli— àwọn ọba àti àwọn ìjòyè wọn, àwọn àlùfáà àti wòlíì wọn pẹ̀lú.
27 Bathi esigodweni, ‘Wena ungubaba wami,’ elitsheni bathi, ‘Nguwe owangizalayo.’ Bangifulathele, hatshi ngobuso babo nje; kodwa nxa sebehlupheka bathi, ‘Woza usihlenge.’
Wọ́n sọ fún igi pé, ‘Ìwọ ni baba mi,’ àti sí òkúta wí pé, ‘Ìwọ ni ó bí mi,’ wọ́n ti kọ ẹ̀yìn wọn sí mi, wọn kò kọ ojú sí mi síbẹ̀ nígbà tí wọ́n bá wà nínú ìṣòro, wọn yóò wí pé, ‘Wá kí o sì gbà wá!’
28 Pho bangaphi onkulunkulu elazenzela bona? Kabeze nxa bengakuhlenga lapho usuphakathi kokuhlupheka! Ngoba wena Juda ulabonkulunkulu abanengi njengobunengi bamadolobho akho.
Níbo wá ni àwọn ọlọ́run tí ẹ ṣe fúnra yín ha a wà? Jẹ́ kí wọ́n wá kí wọ́n sì gbà yín nígbà tí ẹ bá wà nínú ìṣòro! Nítorí pé ẹ̀yin ní àwọn ọlọ́run púpọ̀, gẹ́gẹ́ bí ẹ ti ṣe ni àwọn ìlú, ìwọ Juda.
29 Kungani lingethesa umlandu? Lonke lingihlamukele,” kutsho uThixo.
“Kí ló dé tí o ṣe wá ń fi ẹ̀sùn kàn mí? Gbogbo yín ni ó ti ṣọ̀tẹ̀ sí mi,” ni Olúwa wí.
30 “Ukubajezisa kwami abantu bakho kwaba yize; kabakuvumanga ukuqondiswa. Inkemba yakho isibatshwabadele abaphrofethi bakho njengesilwane esiphangayo.
“Nínú asán mo fìyà jẹ àwọn ènìyàn yín, wọn kò sì gba ìbáwí. Idà yín ti pa àwọn wòlíì yín run, gẹ́gẹ́ bí kìnnìún tí ń bú ramúramù.
31 Wena owalesisizukulwane, khumbula ilizwi likaThixo: Ngibe ngiyinkangala ku-Israyeli kumbe ilizwe lomnyama omkhulu na? Kungani abantu bami besithi, ‘Sikhululekile ukuba sizulazule; kasiyikuza kuwe futhi’?
“Ẹ̀yin ìran yìí, ẹ kíyèsi ọ̀rọ̀ Olúwa: “Mo ha ti di aginjù sí Israẹli tàbí mo jẹ ilẹ̀ olókùnkùn biribiri? Èéṣe tí àwọn ènìyàn mi ṣe wí pé, ‘A ní àǹfààní láti máa rìn kiri; àwa kì yóò tọ̀ ọ́ wá mọ́?’
32 Intombi ingazikhohlwa iziceciso zayo na, lomlobokazi akhohlwe izembatho zakhe na? Kodwa abantu bami bangikhohliwe, okwensuku ezingeke zibalwe.
Wúńdíá ha le gbàgbé ohun ọ̀ṣọ́ rẹ̀, tàbí ìyàwó ohun ọ̀ṣọ́ ìgbéyàwó rẹ̀? Síbẹ̀, àwọn ènìyàn mi ti gbàgbé mi ní ọjọ́ àìníye.
33 Yeka ukuhlakanipha kwakho ekufuneni uthando! Labesifazane ababi kakhulu bangafunda ezindleleni zakho.
Ìwọ ti jẹ́ ọlọ́gbọ́n tó nípa ọ̀rọ̀ ìfẹ́! Àwọn obìnrin búburú yóò kẹ́kọ̀ọ́ nípa ọ̀nà rẹ.
34 Ezigqokweni zakho abantu bathola igazi lokuphila elabayanga abangelacala lanxa ungababambanga befohlela phakathi. Kodwa kukho konke lokhu
Lórí aṣọ rẹ ni wọ́n bá ẹ̀jẹ̀ àwọn tálákà aláìṣẹ̀, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ìwọ kò ká wọn mọ́ níbi tí wọ́n ti ń rùn wọlé. Síbẹ̀ nínú gbogbo èyí
35 uthi, ‘Kangilacala; kangithukuthelelanga.’ Kodwa mina ngizakwahlulela, ngoba uthi, ‘Angonanga.’
ìwọ sọ wí pé, ‘Èmi jẹ́ aláìṣẹ̀; kò sì bínú sí mi.’ Èmi yóò mú ìdájọ́ mi wá sórí rẹ nítorí pé ìwọ wí pé, ‘Èmi kò dẹ́ṣẹ̀.’
36 Kungani uqhubeka kangaka, untshintsha izindlela zakho? IGibhithe izakuyangisa njengalokhu owakwenziwa yi-Asiriya.
Èéṣe tí ìwọ fi ń lọ káàkiri láti yí ọ̀nà rẹ padà? Ejibiti yóò dójútì ọ́ gẹ́gẹ́ bí i ti Asiria.
37 Uzasuka kuleyondawo izandla zakho zisekhanda lakho, ngoba uThixo ubalahlile labo obathembayo; kabayikukusiza.”
Ìwọ yóò sì fi ibẹ̀ sílẹ̀ pẹ̀lú kíkáwọ́ rẹ lé orí rẹ, nítorí pé Olúwa ti kọ̀ àwọn tí ìwọ gbẹ́kẹ̀lé sílẹ̀, kì yóò sí ìrànlọ́wọ́ kankan fún ọ láti ọ̀dọ̀ wọn.