< U-Isaya 52 >

1 Vuka, vuka, wena Ziyoni, uzembese ngamandla! Gqoka izigqoko zakho zenkazimulo, wena Jerusalema, muzi ongcwele. Ongasokanga longcolileyo akayikungena kuwe futhi.
Jí, jí, ìwọ Sioni, wọ ara rẹ ní agbára. Gbé aṣọ ògo rẹ wọ̀, ìwọ Jerusalẹmu, ìlú mímọ́ n nì. Àwọn aláìkọlà àti aláìmọ́ kì yóò wọ inú rẹ mọ́.
2 Thintitha uthuli lwakho; sukuma, uhlale ebukhosini, wena Jerusalema. Zikhulule izibopho ezisentanyeni yakho, wena Ndodakazi ethunjiweyo yaseZiyoni.
Gbọn eruku rẹ kúrò; dìde sókè, kí o sì gúnwà, ìwọ Jerusalẹmu. Bọ́ ẹ̀wọ̀n tí ń bẹ lọ́rùn rẹ kúrò, ìwọ ọ̀dọ́mọbìnrin ìgbèkùn Sioni.
3 Ngoba nanku okutshiwo nguThixo: “Lathengiswa ngeze, njalo lizahlengwa kungekho mali.”
Nítorí èyí ni ohun tí Olúwa wí, “Ọ̀fẹ́ ni a tà ọ́, láìsanwó ni a ó sì rà ọ́ padà.”
4 Ngoba nanku okutshiwo nguThixo Wobukhosi: “Ekuqaleni abantu bami baya eGibhithe besiyahlala khona; muva i-Asiriya yabancindezela.
Nítorí èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí. “Ní ìgbà àkọ́kọ́ àwọn ènìyàn mi sọ̀kalẹ̀ lọ sí Ejibiti láti gbé; láìpẹ́ ni Asiria pọ́n wọn lójú.
5 Khathesi kuyini engilakho lapha?” kubuza uThixo. “Ngoba abantu bami bathunjwa kungekho sizatho, njalo labo abababusayo bayakloloda,” kutsho uThixo. “Ilanga lonke ibizo lami lihlanjazwa kokuphela.
“Àti ní àkókò yìí, kí ni mo ní níbí?” ni Olúwa wí. “Nítorí a ti kó àwọn ènìyàn mi lọ lọ́fẹ̀ẹ́, àwọn tí ó sì ń jẹ ọba lórí wọn fi wọ́n ṣẹlẹ́yà,” ni Olúwa wí. “Àti ní ọjọọjọ́ orúkọ mi ni asọ̀rọ̀-òdì sí nígbà gbogbo.
6 Ngakho-ke abantu bami bazalazi ibizo lami, ngakho-ke ngalolosuku bazakwazi ukuthi yimi engamemezela lokho ngaphambilini. Yebo, yimi.”
Nítorí náà àwọn ènìyàn mi yóò mọ orúkọ mi; nítorí ní ọjọ́ náà, wọn yóò mọ̀ pé, Èmi ni ó ti sọ àsọtẹ́lẹ̀ rẹ̀. Bẹ́ẹ̀ ni, Èmi ni.”
7 Yeka ubuhle phezu kwezintaba, bezinyawo zalabo abaletha izindaba ezinhle, abamemezela ukuthula, abaletha izindaba ezinhle, abamemezela insindiso, abathi kulo iZiyoni, “UNkulunkulu wakho uyabusa!”
Báwo ni ó ṣe dára tó lórí òkè ẹsẹ̀ àwọn tí ó mú ìyìnrere ayọ̀ wá, tí wọ́n kéde àlàáfíà, tí ó mú ìyìnrere wá, tí ó kéde ìgbàlà, tí ó sọ fún Sioni pé, “Ọlọ́run rẹ ń jẹ ọba!”
8 Lalela! Abalindi bakho baphakamisa amazwi abo, bonke bahlaba umkhosi ngokuthokoza. Lapho uThixo ebuyela eZiyoni bazayibona iZiyoni ngamehlo abo.
Tẹ́tí sílẹ̀! Àwọn olùṣọ́ rẹ gbé ohùn wọn sókè wọ́n kígbe papọ̀ fún ayọ̀. Nígbà tí Olúwa padà sí Sioni, wọn yóò rí i pẹ̀lú ojú u wọn.
9 Hlokomani ndawonye ngezingoma zokuthokoza, lina manxiwa aseJerusalema, ngoba uThixo usebaduduzile abantu bakhe, uselihlengile iJerusalema.
Ẹ bú sí orin ayọ̀ papọ̀, ẹ̀yin ahoro Jerusalẹmu, nítorí Olúwa ti tu àwọn ènìyàn rẹ̀ nínú, ó sì ti ra Jerusalẹmu padà.
10 UThixo uzaveza ingalo yakhe engcwele phambi kwezizwe zonke, njalo yonke imikhawulo yomhlaba izabona insindiso kaNkulunkulu wethu.
Olúwa yóò ṣí apá mímọ́ rẹ̀ sílẹ̀ ní ojú gbogbo orílẹ̀-èdè, àti gbogbo òpin ilẹ̀ ayé yóò rí ìgbàlà Ọlọ́run wa.
11 Sukani, sukani, phumani lapho! Lingathinti lutho olungcolileyo! Phumani kulo libe ngabahlambulukileyo, lina eliphatha izitsha zikaThixo.
Ẹ túká, ẹ túká, ẹ jáde kúrò níhìn-ín yìí! Ẹ má fọwọ́ kan ohun àìmọ́ kan! Ẹ jáde kúrò nínú rẹ̀ kí ẹ sì di mímọ́, ẹ̀yin tí ẹ̀ ń gbé ohun èlò Olúwa.
12 Kodwa kaliyikusuka ngokuphangisa, kumbe libaleka; ngoba uThixo uzahamba phambi kwenu, uNkulunkulu ka-Israyeli uzakuba ngumvikeli wenu emva kwenu.
Ṣùgbọ́n ẹ̀yin kì yóò yára kúrò tàbí kí ẹ sáré lọ; nítorí Olúwa ni yóò síwájú yín lọ, Ọlọ́run Israẹli ni yóò sì ṣe ààbò lẹ́yìn ín yín.
13 Khangelani, inceku yami izakwenza ngokuhlakanipha, izaphakanyiswa ikhwezwe, iphiwe lodumo olukhulu.
Kíyèsi i, ìránṣẹ́ mi yóò hùwà ọlọ́gbọ́n; òun ni a ó gbé sókè tí a ó sì gbéga a ó sì gbé e lékè gidigidi.
14 Njengoba babebanengi abanengwayo yiyo, ubuso bayo babulimele okudlula okwabantu bonke, lesimo sayo sonakele singase njengesomuntu,
Gẹ́gẹ́ bí a ti rí ọ̀pọ̀lọpọ̀ tí wọ́n ń bu ọlá fún un— ìwò ojú rẹ ni a ti bàjẹ́ kọjá ti ẹnikẹ́ni àti ìrísí rẹ̀ ní a ti bàjẹ́ kọjá ohun tí ènìyàn ń fẹ́.
15 ngakho-ke izachela izizwe ezinengi, amakhosi azavala imilomo yawo ngenxa yayo. Ngoba lokho abangakutshelwanga bazakubona, labangakuzwanga, bazakuqedisisa.
Bẹ́ẹ̀ ni yóò ṣe bomirin àwọn orílẹ̀-èdè ká, àwọn ọba yóò sì pa ẹnu wọn mọ́ nítorí rẹ̀. Nítorí ohun tí a kò sọ fún wọn, wọn yóò rí i, àti ohun tí wọn kò tí ì gbọ́, ni yóò sì yé wọn.

< U-Isaya 52 >