< 2 Amakhosi 3 >
1 UJoramu indodana ka-Ahabi waba yinkosi yako-Israyeli eSamariya ngomnyaka wetshumi lasificaminwembili wokubusa kukaJehoshafathi inkosi yakoJuda, yena wabusa okweminyaka elitshumi lambili.
Jehoramu ọmọ Ahabu sì di ọba Israẹli ní Samaria ní ọdún kejìdínlógún ti Jehoṣafati ọba Juda, ó sì jẹ ọba fún ọdún méjìlá.
2 Wona emehlweni kaThixo, kodwa kwakungafanani lokukayise lonina ababekwenzile. Walahla ilitshe likaBhali elalizila elalibazwe nguyise.
Ó sì ṣe búburú níwájú Olúwa, ṣùgbọ́n kì í ṣe bí ti ìyá àti baba rẹ̀ ti ṣe. Ó gbé òkúta ère ti Baali tí baba rẹ̀ ti ṣe kúrò.
3 Kodwa wagxila ezonweni zikaJerobhowamu indodana kaNebhathi, lezo ayebangele u-Israyeli ukuthi azenze; kazange azifulathele.
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ó fi ara mọ́ ẹ̀ṣẹ̀ Jeroboamu ọmọ Nebati, tí ó ti fi Israẹli bú láti dẹ́ṣẹ̀; kò sì yí kúrò lọ́dọ̀ wọn.
4 UMesha inkosi yaseMowabi wayefuya izimvu, wayefanele ukubhadala inkosi yako-Israyeli izimvu ezizinkulungwane ezilikhulu kanye loboya benqama ezizinkulungwane ezilikhulu.
Nísinsin yìí Meṣa ọba Moabu ń sin àgùntàn, ó sì gbọdọ̀ fi fún ọba Israẹli pẹ̀lú ọ̀kẹ́ márùn-ún ọ̀dọ́-àgùntàn àti pẹ̀lú irun ọ̀kẹ́ márùn-ún àgbò.
5 Kodwa ngemva kokufa kuka-Ahabi, inkosi yamaMowabi yahlamukela inkosi yako-Israyeli.
Ṣùgbọ́n lẹ́yìn ikú Ahabu, ọba Moabu ṣọ̀tẹ̀ lórí ọba Israẹli.
6 Ngalesosikhathi inkosi uJoramu yasuka eSamariya yabutha abako-Israyeli bonke.
Lásìkò ìgbà yìí ọba Jehoramu jáde kúrò ní Samaria ó sì yí gbogbo Israẹli ní ipò padà.
7 Wathumela lelilizwi kuJehoshafathi inkosi yakoJuda wathi: “Inkosi yamaMowabi isingihlamukele. Singahambisana siyehlasela amaMowabi na?” UJehoshafathi waphendula esithi, “Ngizahamba lawe. Mina nginguwe, abantu bami banjengabantu bakho, amabhiza ami anjengamabhiza akho.”
Ó sì ránṣẹ́ yìí sí Jehoṣafati ọba Juda pé, “Ọba Moabu sì ṣọ̀tẹ̀ sí mi. Ṣé ìwọ yóò lọ pẹ̀lú mi láti lọ bá Moabu jà?” Ọba Juda sì dáhùn pé, “Èmi yóò lọ pẹ̀lú rẹ. Èmi jẹ́ gẹ́gẹ́ bí ìwọ ti wà, ènìyàn rẹ bí ènìyàn mi, ẹṣin mi bí ẹṣin rẹ.”
8 Wasebuza ukuthi, “Sizahlasela sivelela ngaphi na?” UJoramu wathi “Sizavelela eNkangala yase-Edomi.”
“Nípa ọ̀nà wo ni àwa yóò gbà dojúkọ wọ́n?” Ó béèrè. “Lọ́nà aginjù Edomu,” ó dáhùn.
9 Ngakho inkosi yako-Israyeli yaphuma lenkosi yakoJuda kanye lenkosi yase-Edomi. Ngemva kohambo bezulazula okwensuku eziyisikhombisa amanzi amabutho kanye lawezinyamazana zempi aphela.
Bẹ́ẹ̀ ni ọba Israẹli jáde lọ pẹ̀lú ọba Juda àti ọba Edomu. Lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n yíká fún ọjọ́ méje. Àwọn ọmọ-ogun wọn kò ní omi púpọ̀ fún ara wọn tàbí fún ẹranko tí ó wà pẹ̀lú wọn.
10 Inkosi yako-Israyeli yababaza yathi, “Kutheni kanti? UThixo angasibiza singamakhosi amathathu ukuze azosinikela ezandleni zamaMowabi na?”
“Kí ni?” ọba Israẹli kígbe sókè. “Ṣé Olúwa pe àwa ọba mẹ́tẹ̀ẹ̀ta papọ̀ láti fi wá lé Moabu lọ́wọ́?”
11 Kodwa uJehoshafathi wabuza wathi, “Akulamphrofethi kaThixo yini, esingabuza ngaye kuThixo na?” Esinye sezikhulu zenkosi yako-Israyeli sathi, “Ukhona u-Elisha indodana kaShafathi. Wayeyinceku ka-Elija.”
Ṣùgbọ́n Jehoṣafati sì wí pé, “Ṣé kò sí wòlíì Olúwa níbí, tí àwa ìbá ti ọ̀dọ̀ rẹ̀ béèrè lọ́wọ́ rẹ̀?” Ọ̀kan lára àwọn ìránṣẹ́ ọba Israẹli dáhùn pé, “Eliṣa ọmọ Ṣafati wà níbí. Ó máa sábà bu omi sí ọwọ́ Elijah.”
12 UJehoshafathi wathi, “Ilizwi likaThixo likuye.” Ngakho inkosi yako-Israyeli kanye loJehoshafathi lenkosi yase-Edomi baya kuye.
Jehoṣafati wí pé, “Ọ̀rọ̀ Olúwa wà pẹ̀lú rẹ̀.” Bẹ́ẹ̀ ni ọba Israẹli àti Jehoṣafati àti ọba Edomu sọ̀kalẹ̀ tọ̀ ọ́ lọ.
13 U-Elisha wathi enkosini yako-Israyeli, “Mina lawe singenelana njani? Hamba kubaphrofethi bakayihlo lakubaphrofethi bakanyoko.” Inkosi yako-Israyeli yaphendula yathi, “Hayi, kungenxa yokuthi uThixo wasibiza sobathathu singamakhosi sinje ukuze asinikele kumaMowabi.”
Eliṣa wí fún ọba Israẹli pé, “Kí ni àwa ní ṣe pẹ̀lú ara wa? Lọ sọ́dọ̀ wòlíì baba rẹ àti wòlíì ti ìyá rẹ.” Ọba Israẹli dá a lóhùn, “Rárá, nítorí Olúwa ni ó pe àwa ọba mẹ́tẹ̀ẹ̀ta papọ̀ láti fi wá lé Moabu lọ́wọ́.”
14 U-Elisha wathi, “Njengoba uThixo uSomandla engimkhonzayo ephila, kungasikuhlonipha kwami ukuthi kuloJehoshafathi inkosi yakoJuda, ngibe ngingayikukukhangela loba ukukubona ukuthi ukhona kodwa lokhu.
Eliṣa wí pé, “Gẹ́gẹ́ bí ó ti wà pé Olúwa àwọn ọmọ-ogun wà láyé, ẹni tí mo ń sìn tí èmi kò bá ní ọ̀wọ̀ fún ojú Jehoṣafati ọba Juda, èmi kò ní wò ó tàbí èmi kì bá ti rí ọ.
15 Kodwa-ke ngibizela umtshayi wechacho.” Umtshayi wechacho esatshaya ichacho, amandla kaThixo ehlela ku-Elisha,
Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, mú wá fún mi ohun èlò orin olókùn.” Nígbà tí akọrin náà n kọrin, ọwọ́ Olúwa wá sórí Eliṣa.
16 wasesithi, “Ilizwi likaThixo lithi: Lungisani imigelo eminengi kulesisigodi.
Ó sì wí pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa sọ, ‘Jẹ́ kí àfonífojì kún fún ọ̀gbun.’
17 Ngoba ilizwi likaThixo lithi: Aliyikubona yezi loba izulu, kodwa lesisigodi sizagcwala ngamanzi, kuthi lina lenkomo zenu kanye lezinyamazana zonke lithole ukunatha.
Nítorí èyí ni Olúwa wí, o kò ní í rí afẹ́fẹ́ tàbí òjò, bẹ́ẹ̀ ni àfonífojì yìí yóò kún pẹ̀lú omi, àti ìwọ àti ẹran ọ̀sìn àti pẹ̀lú àwọn ẹran yóò mu.
18 Le yinto elula kuThixo, njalo uzanikela amaMowabi esandleni sakho.
Èyí jẹ́ ohun tí kò lágbára níwájú Olúwa, yóò sì fi Moabu lé e yín lọ́wọ́ pẹ̀lú.
19 Uzanqoba kuzozonke izinqaba zedolobho lakuyo yonke imizi eqakathekileyo. Uzawisa zonke izihlahla ezinhle, ugqibele yonke imithombo yamanzi, wonakalise wonke amasimu amahle ngamatshe.”
Ìwọ yóò sì bi gbogbo ìlú olódi àti gbogbo àgbà ìlú ṣubú. Ìwọ yóò sì gé gbogbo igi dáradára ṣubú, dá gbogbo orísun omi dúró, kí o sì pa gbogbo pápá dáradára pẹ̀lú òkúta run.”
20 Ngosuku olulandelayo ekuseni, ngesikhathi sokunikela imihlatshelo, lakanye babona, nanko amanzi egeleza evelela e-Edomi! Ngakho ilizwe lagcwala amanzi.
Ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, ní àsìkò ẹbọ, níbẹ̀ ni omí sàn láti ọ̀kánkán Edomu! Ilé náà sì kún pẹ̀lú omi.
21 AmaMowabi wonke ayesezwile ukuthi amakhosi ayezohlasela; ngalokho amadoda wonke, abadala lamajaha, ababengenelisa ukuphatha izikhali balawulwa ukuba bayevikela umngcele.
Nísinsin yìí gbogbo ará Moabu gbọ́ pé àwọn ọba tí dé láti bá wọn jà. Bẹ́ẹ̀ ni gbogbo ènìyàn, ọmọdé àti àgbà tí ó lè ja ogun wọn pè wọ́n sókè wọ́n sì dúró ní etí ilẹ̀.
22 Bathi bevuka emadabukakusa bathola ilanga linkanyazela phezu kwamanzi. Ekuboneni kwamaMowabi ngale, amanzi ayekhanya ebomvu kungani ligazi. AmaMowabi asesithi,
Nígbà tí wọ́n dìde ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, oòrùn ti tàn sí orí omi náà sí àwọn ará Moabu ní ìkọjá ọ̀nà, omi náà sì pupa bí ẹ̀jẹ̀.
23 “Ligazi leliyana! Kutsho ukuthi amakhosi lawayana alwile abulalana wodwa. Asiyeni butha impango, maMowabi!”
“Ẹ̀jẹ̀ ni èyí!” wọ́n wí pé, “Àwọn ọba wọ̀nyí lè ti jà kí wọn sì pa ara wọn ní ìpakúpa. Nísinsin yìí sí àwọn ìkógun Moabu!”
24 Kodwa amaMowabi athe efika enkambeni yama-Israyeli, ama-Israyeli awavukela awahlasela, amaMowabi aze abaleka. Ngakho ama-Israyeli ahlasela ilizwe lelo abhubhisa amaMowabi.
Ṣùgbọ́n nígbà tí àwọn ará Moabu dé sí ibùdó ti Israẹli, àwọn ará Israẹli dìde, wọ́n sì kọlù wọ́n títí tí wọ́n fi sálọ. Àwọn ará Israẹli gbógun sí ilẹ̀ náà wọ́n sì pa Moabu run.
25 Atshabalalisa imizi kwathi indoda nganye yaphosela ilitshe kuwo wonke amasimu amahle aze agcwala ngamatshe. Bagqibela yonke imithombo yamanzi njalo bagamula zonke izihlahla ezinhle. Kwasala iKhiri-Haresethi eyasala amatshe ayo elokhu enjalo, kodwa amadoda ayehlome ngezavutha ayihonqolozela njalo ayihlasela.
Wọ́n sì wọ gbogbo ìlú náà olúkúlùkù ènìyàn, wọ́n ju òkúta sí gbogbo ohun dáradára orí pápá títí tí ó fi run. Wọ́n sì dá gbogbo orísun omi dúró wọ́n sì gé gbogbo orísun dáradára. Kiri-Hareseti nìkan ni wọ́n fi òkúta rẹ̀ sílẹ̀ ní ààyè rẹ̀, ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn ológun pẹ̀lú kànnàkànnà yíká, wọ́n sì kọlù ìlú náà.
26 Inkosi yamaMowabi ithe ibona ukuthi isikhulelwa ekulweni, yathatha amadoda angamakhulu ayisikhombisa alwa ngenkemba yazama ukuthi idabule phakathi ngamandla iyephutshela enkosini yase-Edomi, kodwa yehluleka.
Nígbà tí ọba Moabu rí i wí pé ogun náà le ju ti òun lọ, ó mú idà pẹ̀lú ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rin ọkùnrin onídà láti jà pẹ̀lú ọba Edomu, ṣùgbọ́n wọn kò yege.
27 Inkosi yaseMowabi yasithatha ingqabutho yayo eyiyo indodana eyayizasala ibusa yayinikela njengomnikelo wokutshiswa phezu kwemiduli yedolobho. Kwakukukhulu ukuthukuthelela abako-Israyeli baze bahlehla babuyela kwelakibo.
Nígbà náà ó mú àkọ́bí ọmọkùnrin rẹ̀, tí kò bá jẹ́ gẹ́gẹ́ bí ọba, ó sì fi rú ẹbọ sísun ní orí ògiri ìlú. Wọ́n sì bínú lórí Israẹli púpọ̀púpọ̀; wọ́n yọ́ kúrò wọ́n sì padà sí ìlú wọn.