< Tauanga 12 >
1 Na ka whakahe a Miriama rau ko Arona ki a Mohi mo te wahine Kuhi i marenatia e ia: he wahine Kuhi hoki tana i marena ai.
Miriamu àti Aaroni sọ̀rọ̀-òdì sí Mose nítorí pé ó fẹ́ obìnrin ará Etiopia.
2 A ka mea raua, Koia ranei i a Mohi anake nga korero a Ihowa? kahore ranei ana korero hoki i a maua? A ka rongo a Ihowa.
Wọ́n sì wí pé, “Nípa Mose nìkan ni Olúwa ti sọ̀rọ̀ bí, kò ha ti ipa wa sọ̀rọ̀ bí?” Olúwa sì gbọ́ èyí.
3 Na, he tangata mahaki rawa a Mohi i nga tangata katoa o te mata o te whenua.
(Mose sì jẹ́ ọlọ́kàn tútù ju gbogbo ènìyàn tó wà lórí ilẹ̀ ayé lọ).
4 Na i ohorere tunu te korerotanga a Ihowa ki a Mohi ratou ko Arona, ko Miriama, Puta mai koutou tokotoru ki te tapenakara o te whakaminenga. A ka puta atu ratu tokotoru.
Lẹ́ẹ̀kan náà ni Olúwa sọ fún Mose, Aaroni àti Miriamu pé, “Ẹ̀yin mẹ́tẹ̀ẹ̀ta, jáde wá sínú àgọ́ ìpàdé.” Àwọn mẹ́tẹ̀ẹ̀ta sì jáde síta.
5 Na ka heke iho a Ihowa i roto i te pou kapua, a ka tu ki te whatitoka o te tapenakara, ka karanga hoki ki a Arona raua ko Miriama: a ka puta raua.
Nígbà náà ni Olúwa sọ̀kalẹ̀ nínú ọ̀wọ́n ìkùùkuu, ó sì dúró ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́, ó ké sí Aaroni àti Miriamu. Àwọn méjèèjì sì bọ́ síwájú,
6 A ka mea ia, Tena, whakarongo ki aku korero: ki te mea he poropiti kei a koutou, ka whakaatu atu ahau, a Ihowa i ahau ki a ia, he mea whakakite, he korero moemoea ki a ia.
Ó wí pé, “Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ mi, “Bí wòlíì Olúwa bá wà láàrín yín, Èmi Olúwa a máa fi ara à mi hàn án ní ojúran, Èmi a máa bá a sọ̀rọ̀ nínú àlá.
7 Ehara taku pononga, a Mohi i te pera; he pono ia i toku whare katoa:
Ṣùgbọ́n èyí kò rí bẹ́ẹ̀ pẹ̀lú Mose ìránṣẹ́ mi; ó jẹ́ olóòtítọ́ nínú gbogbo ilé mi.
8 Ka korero ahau ki a ia, he mangai, he mangai, he korero mata nui, kahore hoki he kupu ngaro; a e kite ano ia i te ahua o Ihowa: he aha ra korua te wehi ai ki te whakahe mo taku pononga, mo Mohi?
Mo sì ń bá a sọ̀rọ̀ ní ojúkojú, ọ̀rọ̀ yékéyéké tí kì í ṣe òwe, ó rí àwòrán Olúwa. Kí ló wá dé tí ẹ̀yin kò ṣe bẹ̀rù láti sọ̀rọ̀-òdì sí Mose ìránṣẹ́ mi?”
9 Na ka mutu te riri o Ihowa ki a raua, a haere ana ia.
Ìbínú Olúwa sì ru sókè sí wọn Olúwa sì fi wọ́n sílẹ̀.
10 Na ka riro atu te kapua i runga i te tapenakara: na! he repera a Miriama, kua rite ki te hukarere: a ka titiro a Arona ki a Miriama, e! he repera.
Nígbà tí ìkùùkuu kúrò lórí àgọ́ lójijì ni Miriamu di adẹ́tẹ̀, ó funfun bí i yìnyín. Aaroni sì padà wo Miriamu ó sì rí i pé ó ti di adẹ́tẹ̀,
11 Na ka mea a Arona ki a Mohi, Aue, e toku ariki, kaua e utaina ki a maua tenei hara i poauau nei, i hara nei maua.
Aaroni sì wí fún Mose pé, “Jọ̀wọ́ olúwa mi, má ṣe ka ẹ̀ṣẹ̀, èyí tí a fi ìwà òmùgọ̀ dá sí wa lọ́rùn.
12 Kei rite ia ki te mea kua mate, ki te mea kua pau tetahi wahi o ona kikokiko i te putanga mai i te kopu o tona whaea.
Má ṣe jẹ́ kí ó dàbí òkú ọmọ tí a bí, tí ìdajì ara rẹ̀ ti rà dànù.”
13 Na ka karanga atu a Mohi ki a Ihowa, ka mea, E te Atua, tena ra, whakaorangia ia.
Torí èyí Mose sì kígbe sí Olúwa, “Ọlọ́run, jọ̀wọ́, mú un láradá!”
14 Na ka mea a Ihowa, ki a Mohi, Me i tuwha kau tona papa ki tona mata e kore ianei ia e whakama, a whitu noa nga ra? kia whitu nga ra e tutakina atu ai ia ki waho o te puni, a muri iho ka mauria mai ano.
Olúwa sì dá Mose lóhùn, “Bí baba rẹ̀ bá tutọ́ sí i lójú, ojú kò wa ní í tì í fún ọjọ́ méje? Dá a dúró sí ẹ̀yìn ibùdó fún ọjọ́ méje, lẹ́yìn èyí ki a tó ó le mú wọlé.”
15 Na tutakina atu ana a Miriama ki waho o te puni, e whitu nga ra; kihai ano hoki te iwi i haere, kia whakahokia mai ra ano a Miriama.
Miriamu sì dúró sí ẹ̀yìn ibùdó fún ọjọ́ méje, àwọn ènìyàn kò sì tẹ̀síwájú nínú ìrìnàjò wọn títí tí Miriamu fi wọ inú ibùdó padà.
16 A muri iho ka turia e te iwi i Hateroto, a noho ana i te koraha o Parana.
Lẹ́yìn èyí, àwọn ènìyàn kúrò ní Haserotu, wọ́n sì pa ibùdó sí aginjù Parani.