< Tauanga 11 >

1 A ka takiamuamu te iwi, ka korero kino ki nga taringa o Ihowa: a, no te rongonga o Ihowa, ka mura tona riri; a ka ka te ahi a Ihowa i roto i a ratou, a pau ake te hunga i nga pito ki waho o te puni.
Àwọn ènìyàn ń ṣe àròyé nípa wàhálà wọn sí etí ìgbọ́ Olúwa. Ìbínú Olúwa sì ru sókè nígbà tí ó gbọ́ àròyé yìí. Nígbà náà ni iná jáde láti ọ̀dọ̀ Olúwa bọ́ sí àárín wọn, ó sì run àwọn tó wà ní òpin ibùdó.
2 Na ka tangi te iwi ki a Mohi; a ka inoi a Mohi ki a Ihowa, na, ka mate te ahi.
Nígbà náà ni àwọn ènìyàn kígbe sí Mose, Mose sì gbàdúrà sí Olúwa iná náà sì kú.
3 A huaina iho te ingoa o tena wahi ko Tapera: no te kaanga hoki o te ahi a Ihowa i roto i a ratou.
Wọ́n sì ń pe ibẹ̀ ní Tabera nítorí pé, iná láti ọ̀dọ̀ Olúwa jó láàrín wọn.
4 Na ka minamina nga whakauru i roto i a ratou: me nga tama hoki a Iharaira i tangi ano, i mea, Ma wai e homai he kikokiko hei kai ma tatou?
Àwọn ọ̀pọ̀ ènìyàn aláìníláárí tó wà láàrín àwọn ọmọ Israẹli pẹ̀lú ọkàn ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ wọn fi ìtara béèrè fún oúnjẹ mìíràn, àwọn ọmọ Israẹli náà bá bẹ̀rẹ̀ sí í sọkún wí pé, “Bí i pé kí á rí ẹran jẹ báyìí!
5 E mahara ana tatou ki nga ika i kainga noatia e tatou ki Ihipa; ki nga kukama, ki nga merengi, ki nga riki, ki nga aniana, me te karika:
Àwa rántí ẹja tí à ń jẹ lọ́fẹ̀ẹ́ ní Ejibiti, apálà, bàrà, ewébẹ̀, àlùbọ́sà àti àwọn ẹ̀fọ́ mìíràn.
6 Ko tenei ia, kua maroke o tatou wairua; kahore rawa nei tetahi mea: kahore he mea ke hei tirohanga ma tatou ko tenei mana anake.
Ṣùgbọ́n báyìí gbogbo ara wa ti gbẹ, kò sí ohun mìíràn láti jẹ àfi manna nìkan tí a rí yìí!”
7 Na ko te rite o te mana kei te pua korianara; ko tona kara kei te kara teriuma.
Manna náà dàbí èso korianderi, ìrísí rẹ̀ sì dàbí oje igi.
8 I kopikopiko te iwi ki te kohi, a hurihia ana e ratou ki nga mira, i tukia ranei ki te kumete, a tunua ana e ratou ki te kohua, hanga ana hoki hei keke: ko tona reka kei to te hinu hou.
Àwọn ènìyàn náà ń lọ káàkiri láti kó o, wọn ó lọ̀ ọ́ lórí ọlọ tàbí kí wọ́n gún un nínú odó. Wọ́n le sè é nínú ìkòkò tàbí kí wọn ó fi ṣe àkàrà, adùn rẹ̀ yóò sì dàbí adùn ohun tí a fi òróró ṣe.
9 A, i te taunga iho o te haunui ki te puni i te po, i tau ano te mana ki runga.
Nígbà tí ìrì bá ẹ̀ sí ibùdó lórí ni manna náà máa ń bọ́ pẹ̀lú rẹ̀.
10 A i rongo a Mohi i te iwi e tangi ana, puta noa i o ratou hapu, tenei, tenei, i te whatitoka o tona teneti: a he nui te muranga o te riri o Ihowa; a i kino hoki ki ta Mohi.
Mose sì gbọ́ tí àwọn ènìyàn ń sọkún ní gbogbo ìdílé wọn, oníkálùkù ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ tirẹ̀. Olúwa sì bínú gidigidi. Inú Mose sì bàjẹ́ pẹ̀lú.
11 Na ka mea a Mohi ki a Ihowa, He aha koe i whakatupu kino ai i tau pononga? he aha ahau te manakohia ai e koe, i whakawaha ai e koe tenei iwi katoa ki ahau?
Mose sì béèrè lọ́wọ́ Olúwa pé, “Kí ló dé tí o fi mú wàhálà yìí bá ìránṣẹ́ rẹ? Kí ni mo ṣe tí n kò fi tẹ ọ lọ́rùn tí ìwọ fi di ẹrù àwọn ènìyàn wọ̀nyí lé mi lórí.
12 He uri ianei noku tenei iwi katoa? i whanau ranei ratou i ahau, i mea ai koe ki ahau, Hikitia ki tou uma, kia rite ki ta te matu atawhai, ki tana hiki i te potiki, ki te whenua i oatitia e koe ki o ratou matua?
Èmi ni mo ha lóyún gbogbo àwọn ènìyàn wọ̀nyí bí? Àbí èmi ló bí wọn? Tí ìwọ fi sọ fún mi pé, máa gbé wọn sí oókan àyà rẹ, gẹ́gẹ́ bí abiyamọ ti máa ń gbe ọmọ ọmú lọ sí ilẹ̀ tí o ti búra láti fún àwọn baba ńlá wọn.
13 No hea aku kikokiko hei hoatutanga maku ki tenei iwi katoa? e tangi mai ana hoki ratou ki ahau, e mea mai ana, Homai he kikokiko ki matou hei kai ma matou.
Níbo ni n ó ti rí ẹran fún àwọn ènìyàn wọ̀nyí? Nítorí wọ́n ń sọkún sí mi pé, ‘Fún wa lẹ́ran jẹ́!’
14 E kore tenei iwi katoa e taea e ahau anake te waha, he taimaha rawa maku.
Èmi nìkan kò lè dágbé wàhálà àwọn ènìyàn wọ̀nyí, ẹrù wọn ti wúwo jù fún mi.
15 A ki te penei tau mahi ki ahau, tena, whakamatea rawatia ahau, ki te mea kua manakohia mai ahau e koe; kaua hoki ahau e kite i te he moku.
Bí ó bá sì ṣe pé báyìí ni ìwọ ó ṣe máa ṣe fún mi, kúkú pa mí báyìí, tí mo bá ti bá ojúrere rẹ pàdé—kí ojú mi má ba à rí ìparun mi.”
16 Na ka mea a Ihowa ki a Mohi, Huihuia mai ki ahau kia whitu tekau o nga kaumatua o Iharaira, au i mohio ai he kaumatua no te iwi, he rangatira no ratou; me kawe mai ratou ki te tapenakara o te whakaminenga, me tu tahi koutou ki reira.
Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Mose pé, “Mú àádọ́rin ọkùnrin nínú àwọn àgbàgbà àwọn ọmọ Israẹli, àwọn tí o mọ̀ gẹ́gẹ́ bí olórí àti olóyè láàrín àwọn ènìyàn wá sínú àgọ́ ìpàdé, kí wọ́n lé dúró níwájú mi.
17 A maku e haere iho, e korero ki a koe ki reira: me tongo ano e ahau tetahi wahi o te wairua i runga i a koe, ka hoatu ki runga ki a ratou; a ko ratou hei hoa mou ki te waha i te pikaunga, ara i te iwi; kei waha e koe anake.
Èmi ó sì sọ̀kalẹ̀ wá bá yín sọ̀rọ̀ níbẹ̀. Èmi ó sì mú díẹ̀ nínú agbára Ẹ̀mí tí ń bẹ lára rẹ láti fi sí orí àwọn ènìyàn wọ̀nyí. Wọn ó sì máa ràn ọ́ lọ́wọ́ láti ru àjàgà àwọn ènìyàn kí ó má ṣe pé ìwọ nìkan ni ó o máa ru àjàgà náà.
18 Me ki atu hoki e koe ki te iwi, Whakatapu i a koutou mo apopo a ka kai kikokiko koutou: kua tangi na hoki koutou ki nga taringa o Ihowa, kua mea, Ma wai e homai he kikokiko hei kai ma matou? he pai hoki nga mea i a matou i Ihipa: mo reira ka hom ai e Ihowa he kikokiko ki a koutou, a ka kai koutou.
“Sọ fún àwọn ènìyàn náà pé, ‘Ẹ ya ara yín sí mímọ́ ní ìmúrasílẹ̀ fún ọ̀la, ẹ ó sì jẹ ẹran. Nítorí pé Olúwa ti gbọ́ igbe ẹkún yín, èyí tí ẹ sun pé, “Ìbá ṣe pé a lè rí ẹran jẹ ni! Ó sàn fún wa ní Ejibiti jù báyìí lọ!” Nítorí náà ni Olúwa yóò fi fún yín ní ẹran, ẹ ó sì jẹ ẹ́.
19 E kore e kotahi te ra e kai ai koutou, e kore ano hoki e rua nga ra, e kore e rima nga ra, e kore e tekau nga ra, e kore e rua tekau nga ra;
Ẹ kò ní i jẹ ẹ́ fún ọjọ́ kan, ọjọ́ méjì, ọjọ́ márùn-ún, ọjọ́ mẹ́wàá tàbí ogúnjọ́ lásán,
20 Engari kia pau te marama, a puta noa i o koutou ihu, a ngaruru iho koutou: mo koutou i whakahawea ki a Ihowa e noho nei i waenganui i a koutou, i tangi hoki ki tona aroaro, i mea, He aha tatou i haere mai ai i Ihipa?
ṣùgbọ́n fún odidi oṣù kan, títí tí ẹran náà yóò fi máa yọ ní imú yín, tí yóò sì sú yín, nítorí pé ẹ ti kẹ́gàn Olúwa tí ó wà láàrín yín, ẹ sì ti sọkún fún un wí pé, “Kí ló dé tí a fi kúrò ní Ejibiti gan an?”’”
21 Ko te iwi kei roto nei ahau i a ratou e ono rau mano, he hunga haere raro, a kua mea mai nei koe, Ka hoatu e ahau he kikokiko ki a ratou, a kia kotahi tino marama e kai ai ratou.
Ṣùgbọ́n Mose sọ pé, “Mo wà láàrín ọgbọ̀n ọ̀kẹ́ ènìyàn ni ìrìnkiri, ó sì sọ pé, ‘Èmi ó fún wọn ní ẹran láti jẹ fún oṣù kan gbáko!’
22 Me patu ranei nga hipi me nga kau ma ratou, kia rato ai ratou? me kohi mai ranei nga ika katoa o te moana ma ratou, kia rato ai ratou?
Ǹjẹ́ bí a tilẹ̀ pa àgbò ẹran àti ọmọ ẹran, yóò ha tó wọn bí? Tàbí bí a tilẹ̀ pa gbogbo ẹja inú omi fún wọn, yóò wa tó bí?”
23 Ano ra ko Ihowa ki a Mohi, Kua mutua ranei te ringa o Ihowa? ka kite koe aianei he pono ranei taku kupu ki a koe, kahore ranei.
Olúwa sì dá Mose lóhùn pé, “Ọwọ́ Olúwa ha kúrú bí? Ìwọ yóò ri nísinsin yìí bóyá ọ̀rọ̀ tí mo sọ yóò ṣẹ tàbí kò ni í ṣẹ.”
24 Na ka puta a Mohi ki waho, a korerotia ana e ia nga kupu a Ihowa ki te iwi, a huihuia ana e ia e whitu tekau o nga kaumatua o te iwi, a whakaturia ana ki tetahi taha, ki tetahi taha o te tapenakara.
Mose sì jáde, ó sọ ohun tí Olúwa wí fún àwọn ènìyàn. Ó mú àwọn àádọ́rin àgbàgbà Israẹli dúró yí àgọ́ ká.
25 Na ko te hekenga iho o Ihowa i roto i te kapua, ko te korerotanga hoki ki a ia, na ka tangohia e ia tetahi wahi o te wairua i runga i a ia, a hoatu ana ki nga kaumatua e whitu tekau: a i te taunga iho o te wairua ki a ratou, ka poropiti ratou, a kore ake i pera i muri.
Nígbà náà ni Olúwa sọ̀kalẹ̀ nínú àwọ̀ sánmọ̀ ó sì bá wọn sọ̀rọ̀, ó sì mú lára Ẹ̀mí tó wà lára Mose sí ara àwọn àádọ́rin àgbàgbà náà, Ó sì ṣẹlẹ̀ pé nígbà tí Ẹ̀mí náà bà lé wọn, wọ́n sọtẹ́lẹ̀, ṣùgbọ́n lẹ́yìn èyí wọn kò sọtẹ́lẹ̀ mọ́.
26 A tokorua i mahue ki te puni, ko Ererara te ingoa o tetahi, ko Merara te ingoa o tetahi: na ko te taunga iho o te wairua ki runga ki a raua; no te hunga hoki raua i tuhituhia, otiia kihai i haere ki te tapenakara: na ka poropiti raua i roto i te puni.
Àwọn ọkùnrin méjì, tí orúkọ wọn ń jẹ́ Eldadi àti Medadi kò kúrò nínú àgọ́. Orúkọ wọn wà lára àádọ́rin àgbàgbà yìí ṣùgbọ́n wọn kò jáde nínú àgọ́ síbẹ̀ Ẹ̀mí náà bà lé wọn, wọ́n sì sọtẹ́lẹ̀ nínú àgọ́.
27 Na ka oma tetahi taitama ki te korero ki a Mohi, a ka mea, Kei te poropiti a Ererara raua ko Merara i roto i te puni.
Ọmọkùnrin kan sì sáré lọ sọ fún Mose pé, “Eldadi àti Medadi ń sọtẹ́lẹ̀ nínú àgọ́.”
28 Na ko te ohonga o te tangata a Mohi, o Hohua tama a Nunu, ko tetahi hoki ia o ana taitamariki, ka mea, E toku ariki, e Mohi, riria raua.
Joṣua ọmọ Nuni tí í ṣe ìránṣẹ́ Mose, láti kékeré tó jẹ́ ọ̀kan nínú àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ dáhùn pé, “Mose olúwa mi, dá wọn lẹ́kun!”
29 Ano ra ko Mohi ki a ia, He whakaaro ki ahau i hae ai koe? he oranga ngakau ra me i poropiti katoa te iwi o Ihowa, me i tukua iho hoki e Ihowa tona wairua ki a ratou.
Mose sì wí fún un pé, “Àbí ìwọ ń jowú nítorí mi? Ìbá ti wù mí tó, kí gbogbo àwọn ènìyàn Olúwa jẹ́ wòlíì, kí Olúwa sì fi Ẹ̀mí rẹ̀ sí wọn lára!”
30 Na ka haere a Mohi ki roto ki te puni, a ia me nga kaumatua o Iharaira.
Mose àti àwọn àgbàgbà Israẹli yìí sì padà sínú àgọ́.
31 Na ka puta he hau i a Ihowa, a kawea ana mai nga koitareke i te moana, kua maka ki te taha o te puni, kia kotahi pea te ra e haere ai i tetahi taha, kia kotahi pea hoki te ra e haere ai i tera taha, a tawhio noa te puni, me te mea ano e rua what ianga te teitei i runga i te mata o te whenua.
Afẹ́fẹ́ sì jáde láti ọ̀dọ̀ Olúwa ó sì kó àparò wá láti inú Òkun. Ó sì dà wọ́n káàkiri gbogbo ibùdó ní ìwọ̀n gíga ẹsẹ̀ bàtà mẹ́ta sórí ilẹ̀, bí ìwọ̀n ìrìn ọjọ́ kan ní gbogbo àyíká.
32 Na ka tu te iwi a pau katoa taua ra, taua po katoa hoki, me te ra katoa hoki i te aonga ake, ki te kohikohi i nga koitareke: kotahi tekau nga homa a te tangata nana te kohinga iti: a horahorangia noatia atu ana e ratou hei kai ma ratou, a tawhio noa te puni.
Ní gbogbo ọjọ́ náà àti òru, títí dé ọjọ́ kejì ni àwọn ènìyàn fi ń kó àparò yìí, ẹni tó kó kéré jùlọ kó ìwọ̀n homeri mẹ́wàá, wọ́n sì ṣà wọ́n sílẹ̀ fún ara wọn yí gbogbo ibùdó.
33 A, i te mea kei o ratou niho ano te kokokiko, i te mea kahore ano i ngaua noatia, na ka mura te riri o Ihowa ki te iwi, a whiua ana te iwi e Ihowa ki tetahi whiu nui rawa atu.
Ṣùgbọ́n nígbà tí ẹran náà sì wà láàrín eyín wọn, kó tó di pé wọ́n jẹ ẹ́, ìbínú Olúwa sì ru sí àwọn ènìyàn, ó sì pa wọ́n pẹ̀lú àjàkálẹ̀-ààrùn.
34 Na huaina iho e ia te ingoa o taua wahi ko Kipiroto Hataawa; no te mea i tanumia e ratou ki reira te hunga i minamina.
Torí èyí ni wọ́n ṣe pe ibẹ̀ ní Kibirotu-Hattaafa nítorí pé níbẹ̀ ni wọ́n gbé sìnkú àwọn ènìyàn tó ní ọ̀kánjúwà oúnjẹ sí.
35 Na ka turia atu e te iwi i Kipiroto Hataawa ki Hateroto; a noho ana i Hateroto.
Àwọn ènìyàn yòókù sì gbéra láti Kibirotu-Hattaafa lọ pa ibùdó sí Haserotu wọ́n sì dúró níbẹ̀.

< Tauanga 11 >