< Nehemia 4 >

1 No te rongonga ia o Hanaparata kei te hanga matou i te taiepa, ka riri, nui atu te riri, ka whakahi ki nga Hurai.
Nígbà tí Sanballati gbọ́ pé àwa ń tún odi náà mọ, ó bínú, ó sì bínú púpọ̀. Ó fi àwọn ará Júù ṣe ẹlẹ́yà,
2 Na ka korero ia i te aroaro o ona teina, o te ope ano o Hamaria, ka mea, E aha ana enei Hurai ngoikore? e hanga pa ranei ratou? e mea patunga tapu ranei ratou? e oti ranei i a ratou i te ra kotahi? e whakaorangia ake ranei e ratou nga kohatu i ro to i nga puranga paru kua oti na te tahu?
ó sọ níwájú àwọn ẹlẹgbẹ́ rẹ̀ àti níwájú àwọn ọmọ-ogun Samaria pé, “Kí ni àwọn aláìlera Júù wọ̀nyí ń ṣe yìí? Ṣé wọn yóò mú odi wọn padà ni? Ṣé wọn yóò rú ẹbọ ni? Ṣé wọn yóò parí i rẹ̀ lóòjọ́ ni bí? Ṣé wọ́n lè mú òkúta tí a ti sun láti inú òkìtì padà bọ̀ sípò tí ó jóná bí wọ́n ṣe wà?”
3 Na i tona taha a Topia Amoni, a ka mea ia, Ko taua mea e hanga na e ratou, ki te piki atu he pokiha, ka pakaru ta ratou taiepa kohatu.
Tobiah ará Ammoni, ẹni tí ó wà lẹ́gbẹ̀ẹ́ rẹ̀, wí pé, “Ohun tí wọ́n ń mọ—bí kọ̀lọ̀kọ̀lọ̀ lásán bá gùn ún sókè, yóò fọ́ odi òkúta wọn lulẹ̀!”
4 Whakarongo, e to matou Atua, e whakahaweatia ana hoki matou; whakahokia iho ano ta ratou taunu ki runga ki to ratou upoko; hoatu hoki ratou hei taonga parakete ki te whenua e whakaraua ai;
Gbọ́ ti wa, Ọlọ́run wa, nítorí àwa di ẹni ẹ̀gàn. Dá ẹ̀gàn wọn padà sórí ara wọn. Kí o sì fi wọ́n fún ìkógun ní ilẹ̀ ìgbèkùn.
5 A kei hipokina to ratou he, kaua ano to ratou hara e murua i tou aroaro; mo ratou i whakapataritari i a koe i te aroaro o nga kaihanga.
Má ṣe bo ẹ̀bi wọn tàbí wẹ àwọn ẹ̀ṣẹ̀ wọn nù kúrò níwájú rẹ, nítorí wọ́n mú ọ bínú níwájú àwọn ọ̀mọ̀lé.
6 Na hanga ana e matou te taiepa; a ka honoa te taiepa katoa, kia tae ki te hawhe ano o tona tiketike: he ngakau hoki to te iwi ki te mahi.
Bẹ́ẹ̀ ni àwa mọ odi náà títí gbogbo rẹ̀ fi dé ìdajì gíga rẹ̀, nítorí àwọn ènìyàn ṣiṣẹ́ pẹ̀lú gbogbo ọkàn an wọn.
7 I te rongonga ia o Hanaparata, o Topia, o nga Arapi, o nga Amoni, o nga Aharori, kua neke haere te hanga o nga taiepa o Hiruharama, a kua timata nga wahi pakaru te kapi, na nui atu to ratou riri.
Ṣùgbọ́n nígbà tí Sanballati, Tobiah, àwọn ará Arabia, ará Ammoni, àti àwọn ènìyàn Aṣdodu gbọ́ pé àtúnṣe odi Jerusalẹmu ti ga dé òkè àti pé a ti mọ àwọn ibi tí ó yá dí, inú bí wọn gidigidi.
8 Na ka whakatupu ngatahi ratou katoa i te he, kia haere mai ki te whawhai ki Hiruharama, whakaware ai.
Gbogbo wọn jọ gbìmọ̀ pọ̀ láti wá bá Jerusalẹmu jà àti láti dìde wàhálà sí í.
9 Heoi inoi ana matou ki to matou Atua, whakaturia ana e matou he atiati mo ratou, i te ao, i te po, i te wehi hoki i a ratou.
Ṣùgbọ́n àwa gbàdúrà sí Ọlọ́run wa, a sì yan olùṣọ́ ọ̀sán àti ti òru láti kojú ìhàlẹ̀ yìí.
10 Na ka mea a Hura, Kua hemo te kaha o nga kaipikau, e nui ana hoki te paru; na e kore matou e kaha ki te hanga i te taiepa.
Lákòókò yìí, àwọn ènìyàn Juda wí pé, “Agbára àwọn òṣìṣẹ́ ti dínkù, àlàpà púpọ̀ ni ó wà tó bẹ́ẹ̀ tí àwa kò fi le è mọ odi náà.”
11 I mea ano o matou hoariri, E kore ratou e mohio, e kore e kite, kia tae atu ra ano tatou ki waenganui i a ratou, ko reira tatou tukituki ai i a ratou, whakamutu ai hoki i te mahi.
Bẹ́ẹ̀ sì ni àwọn ọ̀tá wa wí pé, “Kí wọn tó mọ̀ tàbí kí wọn tó rí wa, àwa yóò ti dé àárín wọn, a ó sì pa wọ́n, a ó sì dá iṣẹ́ náà dúró.”
12 A, no te taenga mai o nga Hurai e noho ana i to ratou taha, tekau a ratou meatanga mai ki a matou i nga wahi katoa, Me hoki mai koutou ki a matou.
Nígbà náà ni àwọn Júù tí ó ń gbé ní ẹ̀gbẹ́ wọn wá sọ fún wa ní ìgbà mẹ́wàá pé, “Ibikíbi tí ẹ̀yin bá padà sí, wọn yóò kọlù wá.”
13 Na reira i whakaturia ai e ahau ki nga wahi o raro, ki tua mai o te taiepa, ki nga wahi tuwhera ano hoki, whakaturia ana e ahau te iwi, tenei hapu, tenei hapu, o ratou, i a ratou ano a ratou hoari, a ratou tao, a ratou kopere.
Nítorí náà mo dá ènìyàn díẹ̀ dúró níbi tí ó rẹlẹ̀ jù lẹ́yìn odi ní ibi gbangba, mo fi wọ́n síbẹ̀ nípa àwọn ìdílé wọn, pẹ̀lú àwọn idà wọn, àwọn ọ̀kọ̀ wọn àti àwọn ọrun wọn.
14 Na ka titiro ahau, ka whakatika ki runga, ka mea ki nga rangatira, ki nga tangata nunui, ki era atu ano o te iwi, Kaua e wehi ki a ratou. Kia mahara ki te Ariki, ki te mea nui e wehingia ana, ka whawhai kia ora ai o koutou tuakana, teina, a kout ou tama, a koutou tamahine, a koutou wahine, me o koutou whare.
Lẹ́yìn ìgbà tí mo wo àwọn nǹkan yíká, mo dìde mo sì wí fún àwọn ọlọ́lá àwọn ìjòyè àti àwọn ènìyàn tókù pé, “Ẹ má ṣe bẹ̀rù u wọn. Ẹ rántí Olúwa, ẹni tí ó tóbi, tí ó sì ní ẹ̀rù, kí ẹ sì jà fún àwọn arákùnrin yín, àwọn ọmọkùnrin yín, àwọn ọmọbìnrin yín, àwọn ìyàwó yín àti àwọn ilé yín.”
15 A, ka rongo o matou hoariri ka mohiotia tera e matou, a kua whakataka nei e te Atua o ratou whakaaro, na hoki ana matou katoa ki te taiepa ki tana mahi, ki tana mahi.
Nígbà tí àwọn ọ̀tá wa gbọ́ pé àwa ti mọ èrò wọn àti wí pé Ọlọ́run ti bà á jẹ́, gbogbo wa padà sí ibi odi, ẹnìkọ̀ọ̀kan sí ibi iṣẹ́ tirẹ̀.
16 No taua ra ano ko tetahi tanga o aku tangata hei mahi i te mahi, a ko tetahi tanga o ratou hei pupuri i nga tao, i nga whakangungu rakau, i nga kopere, i nga pukupuku; ko nga rangatira, i muri ratou i te whare katoa o Hura.
Láti ọjọ́ náà lọ, ìdajì àwọn ènìyàn ń ṣe iṣẹ́ náà, nígbà tí àwọn ìdajì tókù múra pẹ̀lú ọ̀kọ̀, asà, ọrun àti ìhámọ́ra. Àwọn ìjòyè sì pín ara wọn sẹ́yìn gbogbo ènìyàn Juda.
17 Ko nga kaihanga i te taiepa, me nga kaiwaha i nga pikaunga, whakawaha ana ratou, a kotahi te ringa o tenei, o tenei, ki te mahi i te mahi, kotahi hei pupuri i te patu.
Àwọn ẹni tí ó ń mọ odi. Àwọn tí ń ru àwọn ohun èlò ṣe iṣẹ́ náà pẹ̀lú ọwọ́ kan, wọ́n sì fi ọwọ́ kejì di ohun ìjà mú,
18 Na, ko nga kaihanga, whitiki rawa tana hoari ki tona taha, ki tona taha: na hanga ana ratou: i toku taha ano hoki ko te kaiwhakatangi tetere.
olúkúlùkù àwọn ọ̀mọ̀lé fi idà wọn sí ẹ̀gbẹ́ wọn bí wọ́n ṣe ń ṣiṣẹ́. Ṣùgbọ́n ọkùnrin tí ń fọn ìpè dúró pẹ̀lú mi.
19 I mea ano ahau ki nga rangatira, ki nga tangata nunui, ki era atu ano o te iwi, He nui te mahi, he tatahi, kua tohatoha noa atu ano tatou ki te taiepa, matara noa tetahi i tetahi;
Nígbà náà ni mo sọ fún àwọn ọlọ́lá, àwọn ìjòyè àti àwọn ènìyàn tókù pé, “Iṣẹ́ náà fẹ̀ ó sì pọ̀, a sì ti jìnnà sí ara wa púpọ̀ lórí odi.
20 Ko te wahi e rongo ai koutou i te tangi o te tetere, me huihui ki a matou ki reira: ma to tatou Atua ta tatou pakanga.
Níbikíbi tí ẹ bá ti gbọ́ ohùn ìpè, ẹ da ara pọ̀ mọ́ wa níbẹ̀. Ọlọ́run wa yóò jà fún wa!”
21 Heoi mahia ana e matou te mahi; na ko tetahi tanga ki te pupuri tao, no te haukanga ake ano o te ata a puta noa nga whetu.
Bẹ́ẹ̀ ni àwa ṣe iṣẹ́ náà pẹ̀lú àwọn ìdajì ènìyàn tí ó di ọ̀kọ̀ mú, láti òwúrọ̀ kùtùkùtù títí di ìgbà tí ìràwọ̀ yóò fi yọ.
22 I mea ano ahau ki te iwi i taua wa, Kia moe tenei tangata, tenei tangata, me tana pononga ano, ki roto ki Hiruharama, a ka ai ratou hei kaitiaki mo tatou i te po, hei mahi ano i te awatea.
Ní ìgbà náà mo tún sọ fún àwọn ènìyàn pé, “Jẹ́ kí olúkúlùkù ènìyàn àti olùrànlọ́wọ́ rẹ̀ dúró ní Jerusalẹmu ní òru, nítorí kí wọn le jẹ́ ẹ̀ṣọ́ fún wa ní òru, kí wọn sì le ṣe iṣẹ́ ní ọ̀sán.”
23 Heoi ko ahau, ko oku teina, ko aku pononga, me nga kaitiaki i whai mai nei i ahau, kihai i whakarerea atu o matou kakahu. Mau tonu te patu a tenei, a tenei, i te haerenga ki te wai.
Bẹ́ẹ̀ ni èmi àti àwọn arákùnrin mi àti àwọn ènìyàn mi àti àwọn ẹ̀ṣọ́ tí ó wà pẹ̀lú mi kò bọ́ aṣọ wa, olúkúlùkù wa ní ohun ìjà tirẹ̀, kódà nígbà tí wọ́n bá ń lọ pọn omi.

< Nehemia 4 >