< Nehemia 13 >

1 I taua ra i korerotia i te pukapuka a Mohi, me te whakarongo ano te iwi, a ka kitea te mea i tuhituhia ki reira kia kaua te Amoni me te Moapi e tapoko ki te whakaminenga a te Atua a ake ake;
Ní ọjọ́ náà ni a ka ìwé Mose sókè sí etí ìgbọ́ àwọn ènìyàn, nínú rẹ̀ ni a ti rí i tí a kọ ọ́ sílẹ̀ pé a kò gbọdọ̀ gba àwọn ará a Ammoni tàbí àwọn ará a Moabu sí àárín ìjọ ènìyàn Ọlọ́run láéláé.
2 No te mea kihai i maua mai e ratou he taro, he wai, hei tukunga mai mo nga tama a Iharaira: engari, utua ana e ratou a Paraama hei hoariri mo ratou, hei kanga mo ratou: heoi whakaputaina ketia ake e to tatou Atua te kanga hei manaaki.
Nítorí wọn kò mú oúnjẹ àti omi wá pàdé àwọn ọmọ Israẹli lọ́nà, dípò bẹ́ẹ̀, wọ́n bẹ Balaamu ní ọ̀wẹ̀ láti gégùn ún lé wọn lórí. (Ṣùgbọ́n Ọlọ́run wa yí ègún náà padà sí ìbùkún.)
3 Na, i to ratou rongonga i te ture, ka wehea atu e ratou nga whakauru katoa i roto i a Iharaira.
Nígbà tí àwọn ènìyàn gbọ́ òfin yìí, wọ́n yọ gbogbo àwọn àjèjì ènìyàn tí ó darapọ̀ mọ́ wọn kúrò láàrín àwọn Israẹli.
4 Na, i mua ake o tenei ko Eriahipi, tohunga, kaitiaki i nga ruma o te whare o to tatou Atua, he whanaunga no Topia.
Ṣáájú èyí a ti fi Eliaṣibu àlùfáà ṣe alákòóso yàrá ìkó nǹkan ilé Ọlọ́run wa sí. Ó súnmọ́ Tobiah pẹ́kípẹ́kí.
5 Whakapaia ana e tenei he ruma nui mona, ko te wahi i whakatakotoria nei i mua nga whakahere totokore, te parakihe, nga oko, me te whakatekau o te witi, o te waina hou, o te hinu, ko te mea i kiia iho ma nga Riwaiti, ratou ko nga kaiwaiata, ko nga kaitiaki tatau, me nga whakahere hapahapai ma nga tohunga.
Ó sì ti pèsè yàrá ńlá kan fún un, èyí tí a ń lò tẹ́lẹ̀ fún ìtọ́jú ọrẹ ọkà, tùràrí àti àwọn ohun èlò tẹmpili àti ìdámẹ́wàá ọkà, wáìnì tuntun àti òróró ti a fi lélẹ̀ bí ìlànà fún àwọn ọmọ Lefi, àwọn akọrin àti àwọn aṣọ́nà àti pẹ̀lú gbogbo ọrẹ fún àwọn àlùfáà.
6 Otiia i tenei wa katoa kahore ahau i Hiruharama; no te toru tekau ma rua nei hoki o nga tau o Arataherehe kingi o Papurona i tae ai ahau ki te kingi, a maha noa nga ra, ka inoitia e ahau i te kingi:
Ṣùgbọ́n nígbà tí gbogbo èyí ń lọ lọ́wọ́, èmi kò sí ní Jerusalẹmu, nítorí pé ní ọdún kejìlélọ́gbọ̀n Artasasta ọba Babeli ni mo padà tọ ọba lọ. Ṣùgbọ́n nígbà tí ó ṣe díẹ̀, mo gba ààyè lọ́dọ̀ọ rẹ̀.
7 Na ka tae mai ahau ki Hiruharama, a ka mohio ki ta Eriahipi mahi kino, ki tana mo Topia, i a ia i whakapai i tetahi ruma mona i nga marae o te whare o te Atua;
Mo sì padà sí Jerusalẹmu. Níhìn-ín ni mo ti mọ̀ nípa onírúurú ohun búburú tí Eliaṣibu ti ṣe ní ti pípèsè yàrá fún Tobiah nínú àgbàlá ilé Ọlọ́run.
8 Na kino rawa ki ahau; akiritia atu ana e ahau nga mea katoa o te whare o Topia i roto i taua ruma.
Kò tẹ́ mi lọ́rùn rárá, mo kó gbogbo ohun èlò ìdílé e Tobiah dà síta láti inú iyàrá náà.
9 Katahi ahau ka korero; a tahia ana e ratou nga ruma. Na whakahokia ana e ahau ki reira nga oko o te whare o te Atua, nga whakahere totokore me te parakihe.
Mo pàṣẹ kí wọn ya àwọn iyàrá náà sí mímọ́, mo sì kó àwọn ohun èlò ilé Ọlọ́run padà síbẹ̀ pẹ̀lú ọrẹ ọkà àti tùràrí.
10 I kite ano ahau kihai nga wahi ma nga Riwaiti i hoatu, na oma ana ratou ki tana mara, ki tana mara, nga Riwaiti, nga kaiwaiata i mahia ai te mahi.
Mo sì tún gbọ́ pé, kò fi àwọn ìpín tí a yà sọ́tọ̀ fún àwọn Lefi, àwọn akọrin tí ń ṣe àkóso ìsìn sì ti padà sí ẹnu onírúurú iṣẹ́ wọn.
11 Katahi ka whawhaitia e ahau nga rangatira; i mea ahau, He aha i whakarerea ai te whare o te Atua? Na huihuia ana ratou e ahau, whakaturia ana ki to ratou turanga.
Nígbà náà ni mo bá àwọn ìjòyè wí, mo sì béèrè lọ́wọ́ wọn pé, “Èéṣe tí a fi kọ ilé Ọlọ́run sílẹ̀?” Nígbà náà ni mo pè wọ́n jọ pọ̀, mo sì fi olúkúlùkù sí ẹnu iṣẹ́ rẹ̀.
12 Katahi ka kawea mai e Hura katoa nga whakatekau o te witi, o te waina hou o te hinu, ki nga whare taonga.
Gbogbo Juda mú ìdámẹ́wàá ọkà, wáìnì tuntun àti òróró wá sínú yàrá ìkó nǹkan pamọ́ sí.
13 Na ka whakaritea e ahau he kaitiaki mo nga taonga, ko Heremia tohunga, ko Haroko karaipi, a o nga Riwaiti ko Peraia; i to ratou taha ko Hanana tama a Takuru tama a Matania: i kiia hoki ratou he hunga pono; a ko ta ratou, he tuwha ma o ratou tuak ana, teina.
Mo sì fi àlùfáà Ṣelemiah, Sadoku akọ̀wé àti ọmọ Lefi kan tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Pedaiah ṣe alákòóso àwọn yàrá ìkó nǹkan pamọ́ sí. Mo sì yan Hanani ọmọ Sakkuri, ọmọ Mattaniah bí olùrànlọ́wọ́ ọ wọn. Àwọn ènìyàn wọ̀nyí ni a kà sí àwọn tó ṣé e gbẹ́kẹ̀lé. Àwọn ni a yàn láti máa pín ohun èlò fún àwọn arákùnrin wọn.
14 Kia mahara, e toku Atua, ki tenei mea aku, kaua hoki e horoia atu tenei tikanga pai aku i puta nei ki te whare o toku Atua, ki nga ritenga mahi ano mo reira.
Rántí ì mi fún èyí, Ọlọ́run mi, kí o má sì ṣe gbàgbé ohun tí mo fi òtítọ́ ṣe fún ilé Ọlọ́run mi yìí àti fún iṣẹ́ ẹ rẹ̀ gbogbo.
15 I aua ra ka kitea e ahau etahi i roto i a Hura e takahi ana i nga takahanga waina i te hapati, e kawe ana mai i nga paihere witi, e whakawaha ana i nga kaihe; me te waina ano, me nga karepe, me nga piki, me nga pikaunga katoa, e kawea mai ana e ratou ki Hiruharama i te ra o te hapati. Na whakaaturia ana e ahau to ratou he i te ra i hoko ai ratou i te kai.
Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì, mo rí àwọn ènìyàn ní Juda tí wọ́n ń fúntí ní ọjọ́ ìsinmi, tí wọ́n sì ń gbé ọkà wọlé, tí wọn ń di ẹrù lé orí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ pẹ̀lú wáìnì, èso àjàrà, ọ̀pọ̀tọ́ àti onírúurú ẹrù. Wọ́n sì ń kó gbogbo èyí wá sí Jerusalẹmu ní ọjọ́ ìsinmi. Nítorí náà, mo kìlọ̀ fún wọn nípa títa oúnjẹ ní ọjọ́ náà.
16 I reira ano e noho ana etahi tangata o Taira, he ika te kawenga, me nga mea hoko katoa, a hokona ana e ratou i te hapati ki nga tama a Hura, i roto ano i Hiruharama.
Àwọn ará Tire ti ń gbé nínú Jerusalẹmu ń gbé ẹja àti onírúurú ọjà wá fún títà ní ọjọ́ ìsinmi fún àwọn ènìyàn Jerusalẹmu àti fún àwọn ọmọ Juda.
17 Katahi ka whawhaitia e ahau nga rangatira o Hura. I mea ahau ki a ratou, He aha tenei mea kino e mea nei koutou, i a koutou ka whakapoke nei i te ra hapati?
Mo bá àwọn ọlọ́lá Juda wí, mo wí fún wọn pé, “Èwo ni ohun búburú tí ẹ ń ṣe yìí ti ẹ ń ba ọjọ́ ìsinmi jẹ́.
18 Kahore ianei o koutou matua i penei, a kawea mai ana e to tatou Atua tenei kino katoa ki runga ki a tatou, ki runga ano i tenei pa? Na ko koutou hei whakaneke ake i te riri mo Iharaira, i te mea ka whakapokea nei te hapati.
Ṣé àwọn baba ńlá yín kò ha ti ṣe nǹkan kan náà tí Ọlọ́run wa fi mú gbogbo àjálù yìí wá orí wa, àti sórí ìlú yìí? Báyìí, ẹ̀yin tún ń ru ìbínú sókè sí i sórí Israẹli nípa bíba ọjọ́ ìsinmi jẹ́.”
19 Na pouriuri kau nga kuwaha o Hiruharama i mua ake o te hapati, ka mea ahau, kia tutakina nga keti. I mea ano ahau kia kaua e whakatuwheratia, kia taka ra ano te hapati: i whakaturia ano e ahau etahi o aku: tangata ki nga kuwaha, kei kawea mai ki roto he pikaunga i te ra o te hapati.
Nígbà tí ojú ọjọ́ ń bora ní ẹnu ibodè Jerusalẹmu, ṣáájú ọjọ́ ìsinmi, mo pàṣẹ pé kí a ti àwọn ìlẹ̀kùn, kí wọn má sì ṣí i títí tí ọjọ́ ìsinmi yóò fi kọjá. Mo yan àwọn ìránṣẹ́ mi láti ṣọ́ ẹnu ibodè, kí a má ba à lè gbé ẹrù kankan wọlé ní ọjọ́ ìsinmi.
20 Heoi kotahi, e rua nga moenga i waho o Hiruharama, o nga tangata i nga taonga, o nga kaihoko i nga tini mea.
Síbẹ̀, àwọn tí ń tà àti àwọn tí ń rà sùn ẹ̀yìn odi Jerusalẹmu ní ẹ̀ẹ̀kan tàbí ẹ̀ẹ̀mejì.
21 Katahi ahau ka whakaatu i to ratou he, a ka mea ki a ratou, He aha koutou i moe ai i te aronga o te taiepa? Ki te pena ano koutou, ka totoro atu toku ringa ki a koutou. No taua ra ano i kore ai to ratou haere mai i te hapati.
Ṣùgbọ́n mo kìlọ̀ fún wọn pé, “Èétijẹ́ ti ẹ̀yin fi ń sùn ní ẹ̀yin odi ní òru? Bí ẹ̀yìn bá tún dánwò mọ́, èmi yóò fi ọwọ́ líle mú yín.” Láti ọjọ́ náà lọ, wọn kò sì wá ní ọjọ́ ìsinmi mọ́.
22 I ki atu ano ahau ki nga Riwaiti kia purea ratou, kia haere hoki ki te tiaki i nga kuwaha hei whakatapu mo te ra hapati. Maharatia ano tenei aku e toku Atua; tohungia hoki ahau, kia rite ki te nui o tou atawhai.
Nígbà náà ni mo pàṣẹ fún àwọn ọmọ Lefi pé kí wọn ya ara wọn sí mímọ́, kí wọn sì ṣọ́ ẹnu ibodè kí a lè pa ọjọ́ ìsinmi mọ́. Tún rántí mi fún èyí, Ọlọ́run mi, kí o sì fi àánú un rẹ hàn fún mi gẹ́gẹ́ bí i títóbi ìfẹ́ ẹ̀ rẹ.
23 I aua ra ano ka kite ahau i nga Hurai kei a ratou e noho ana etahi wahine o Aharoro, o Amona, o Moapa.
Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì, mo rí àwọn ọkùnrin Juda tí wọ́n fẹ́ àwọn obìnrin láti Aṣdodu, Ammoni àti Moabu.
24 Ko a ratou tama hoki, ko tetahi wahi o te reo no Aharoro, kihai ratou i mohio ki to nga Hurai reo; heoi i rite ki te reo o tetahi iwi, o tetahi iwi.
Ìdajì àwọn ọmọ wọn ń sọ èdè Aṣdodu tàbí èdè ọ̀kan lára àwọn ènìyàn mìíràn tókù, wọn kò sì mọ bí a ṣe ń sọ èdè Juda.
25 Na, whawhaitia iho e ahau, kanga iho, patua ana etahi o ratou, hutihutia ana o ratou makawe, whakaoatitia ana ki te Atua, Kaua e hoatu a koutou tamahine ki a ratou tama, kaua ano hoki e tangohia mai a ratou tamahine ma a koutou tama, ma koutou r anei.
Mo bá wọn wí mo sì gégùn ún lé wọn lórí. Mo lu àwọn ènìyàn díẹ̀ nínú wọn mo sì fa irun orí wọn tu. Mo mú kí wọn búra ní orúkọ Ọlọ́run, kí wọn wí pé, “Ẹ̀yin kì yóò fi àwọn ọmọbìnrin wọn fún àwọn ọmọkùnrin yín ní ìyàwó tàbí fún ẹ̀yin tìkára yín.
26 He teka ianei na enei mea i hara ai a Horomona kingi o Iharaira? he maha nga iwi, kahore rawa o ratou kingi hei rite mona, he mea aroha ia na tona Atua, a meinga ana e te Atua hei kingi mo Iharaira katoa: ahakoa ko ia, i meinga ia e nga wahine k e kia hara.
Kì í ha á ṣe àwọn ìgbéyàwó bí irú èyí ni ọba Solomoni fi dá ẹ̀ṣẹ̀? Láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, kò sí ọba kan bí i tirẹ̀. Ọlọ́run rẹ̀ fẹ́ràn rẹ̀, Ọlọ́run sì fi jẹ ọba lórí i gbogbo Israẹli, ṣùgbọ́n àwọn obìnrin àjèjì ti sọ ọ́ sínú òfin ẹ̀ṣẹ̀.
27 Na kia rongo ranei matou ki a koutou, kia mahi i tenei he nui katoa, kia tutu ki to tatou Atua, kia marena ki nga wahine ke?
Ǹjẹ́ ó ha yẹ kí àwa tún gbọ́ báyìí pé ẹ̀yin náà tún ń ṣe àwọn nǹkan tí ó burú jọjọ wọ̀nyí tí ẹ sì ń ṣe aláìṣòótọ́ sí Ọlọ́run wa nípa fífẹ́ àwọn obìnrin àjèjì?”
28 Na he hunaonga na Hanaparata Horoni tetahi o nga tama a Ioiara tama a Eriahipi tino tohunga; na peia ana ia e ahau i toku taha.
Ọ̀kan lára àwọn ọmọ Joiada, ọmọ Eliaṣibu olórí àlùfáà jẹ́ àna Sanballati ará a Horoni. Mo sì lé e jáde kúrò lọ́dọ̀ mi.
29 Kia mahara ki a ratou, e toku Atua, mo ratou i whakapoke i te tohungatanga, i te kawenata ano o te tohungatanga, o nga Riwaiti ano hoki.
Rántí wọn, Ọlọ́run mi, nítorí wọ́n ti ba iṣẹ́ àlùfáà jẹ́ pẹ̀lú májẹ̀mú iṣẹ́ àlùfáà àti ti àwọn Lefi.
30 Heoi kua ma ratou i ahau i te poke o nga tangata ke, whakaritea ana hoki e ahau te mahi tiaki a nga tohunga, a nga Riwaiti, te mahi a tenei, a tenei,
Nítorí náà, mo ya àwọn àlùfáà àti àwọn Lefi sí mímọ́ kúrò nínú gbogbo ohun àjèjì, mo sì yan iṣẹ́ fún wọn, olúkúlùkù sí ẹnu iṣẹ́ rẹ̀.
31 Me te tikanga ano mo te whakahere wahie i nga wa i whakaritea; mo nga matamua ano. Maharatia ahau e toku Atua mo te pai.
Mo sì tún pèsè fún ọrẹ, igi—pákó ní àkókò tí a yàn àti fún àwọn èso àkọ́so. Rántí mi fún rere, Ọlọ́run mi.

< Nehemia 13 >