< Kaiwhakariterite 7 >

1 Na ka maranga wawe a Ierupaara, ara a Kiriona, ratou ko tona nuinga katoa, a noho ana i te puna o Haroro; a i te taha ki te raki o ratou te puni o Miriana, i te puke o More, i te raorao.
Ní òwúrọ̀ kùtùkùtù Jerubbaali (èyí ni Gideoni) pẹ̀lú gbogbo àwọn ọmọ-ogun tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ kó ogun jọ lẹ́bàá a orísun Harodi. Àwọn ogun Midiani sì wà ní apá àríwá tí wọ́n ní àfonífojì tí ó wà ní ẹ̀bá òkè More.
2 Na ka mea a Ihowa ki a Kiriona, He nui rawa te iwi i a koe nei hei hoatutanga maku i nga Miriani ki o ratou ringa, kei whakapehapeha a Iharaira ki ahau, kei mea, Na toku ringa ake ahau i whakaora.
Olúwa wí fún Gideoni pé, “Àwọn ọmọ-ogun tí o kójọ sọ́dọ̀ ti pọ̀jù fún mi láti fi àwọn ogun Midiani lé wọn lọ́wọ́, kí Israẹli má ba à gbé ara rẹ̀ ga sí mi wí pé agbára òun ni ó gbà á là,
3 Na, tena, karanga ki nga taringa o te iwi, mea atu, Ki te wehi, ki te pawera tetahi, hoki atu, hohoro te haere atu i Maunga Kireara. Na e rua tekau ma rua mano o te iwi i hoki; a mahue iho, kotahi tekau mano.
sì kéde sí àwọn ènìyàn nísinsin yìí pé, ‘Ẹnikẹ́ni tí ó bá ń gbọ̀n, tí ó sì ń bẹ̀rù lè padà sẹ́yìn, kí ó sì kúrò lórí òkè Gileadi.’” Báyìí ni Gideoni ṣe ya àwọn ènìyàn náà. Ẹgbẹ̀rún méjìlélógún ọkùnrin sì padà sẹ́yìn àwọn ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá sì dúró.
4 I mea ano a Ihowa ki a Kiriona, He nui rawa ano te iwi na; kawea ratou ki raro, ki te wai, a ko ahau hei kaiwhakamatautau mau i a ratou ki reira: a ko taku e mea ai ki a koe, Me haere tahi tenei i a koe; ko ia e haere tahi i a koe; a ko taku e me a ai ki a koe, E kore tenei e haere tahi i a koe; kaua tena e haere.
Olúwa sì tún sọ fún Gideoni pé, “Àwọn ènìyàn yìí sì tún pọ̀jù. Kó wọn lọ sí ibi tí omi wà, èmi yóò sì yọ̀rọ̀ wọn níbẹ̀ fún ọ. Bí mo bá wí pé eléyìí yóò bá ọ lọ yóò lọ, ṣùgbọ́n tí mo bá sọ pé, ‘Eléyìí kò ní bá ọ lọ,’ òun kò gbọdọ̀ lọ.”
5 Na ko tana kawenga i te iwi ki raro, ki te wai, a ka mea a Ihowa ki Kiriona, Ko te hunga katoa e mitikia ai te wai ki o ratou arero, pera me te kuri e miti nei, me whakatu ratou ki tahaki me te hunga katoa ano e tuturi ana ki te inu.
Gideoni sì kó àwọn ọkùnrin náà lọ sí ibi ìsun omi. Níbẹ̀ ni Olúwa ti wí fún un pé, “Kí ó pín àwọn ènìyàn náà sí ọ̀nà méjì. Ya àwọn tí ó fi ahọ́n wọn lá omi bí ajá kúrò lára àwọn tí ó kúnlẹ̀ láti mu omi pẹ̀lú ọwọ́ wọn.”
6 A, ko te tokomaha o te hunga i mitimiti, me te pa ano o o ratou ringa ki o ratou mangai, e toru rau tangata: i tuturi ia te nuinga katoa o te iwi ki te inu i te wai.
Ọ̀ọ́dúnrún ọkùnrin ni ó lá omi pẹ̀lú ahọ́n wọn. Gbogbo àwọn ìyókù ni ó kúnlẹ̀ láti mu mi.
7 Na ka mea a Ihowa ki a Kiriona, Ma nga rau tangata e toru i mitimiti ra e whakaora ai ahau i a koutou, e hoatu ai hoki nga Miriani ki tou ringa; a kia haere te iwi katoa, tera, ki tona wahi.
Olúwa wí fún Gideoni pé, “Àwọn ọ̀ọ́dúnrún ọkùnrin tí ó lá omi ni èmi yóò lò láti gbà yín là àti láti fi ogun Midiani lé yín lọ́wọ́. Jẹ́ kí àwọn tókù padà sí ilé wọn.”
8 Na ka mauria e te iwi he o ki o ratou ringa, me a ratou tetere: ko te nuinga ia o Iharaira i tonoa e ia ki tona teneti, ki tona teneti, a puritia ana aua tangata e toru ra: na i raro i a ia te puni o Miriana, i te raorao.
Báyìí ni Gideoni ṣe dá àwọn Israẹli tí ó kù padà sí àgọ́ wọn, ṣùgbọ́n ó dá àwọn ọ̀ọ́dúnrún ọkùnrin náà dúró. Àwọn wọ̀nyí sì gba gbogbo ohun èlò àti fèrè àwọn tí ó ti padà. Ibùdó ogun àwọn Midiani wà ní àfonífojì ní ìsàlẹ̀. Ibi tí ó wà.
9 Na i taua po ano ka mea a Ihowa ki a ia, Whakatika, haere ki raro, ki te puni ra, kua hoatu hoki e ahau ki tou ringa.
Ní òru ọjọ́ náà Olúwa sọ fún Gideoni pé, “Dìde, dojú ogun kọ ibùdó ogun àwọn ará Midiani nítorí èmi yóò fi lé ọ lọ́wọ́.
10 A ki te wehi koe ki te haere ki raro, haere korua ko Pura, ko tau tangata, ki raro ki te puni.
Ṣùgbọ́n bí ẹ̀rù àti kọlù wọ́n bá ń bà ọ́, yọ́ wọ ibùdó wọn lọ kí o mú Pura ìránṣẹ́ rẹ lọ́wọ́
11 A ka rongo koe ki a ratou korero, muri iho ka maia ou ringa, a ka haere koe ki raro, ki te puni. Na ko to raua haerenga atu ko tana tangata, ko Pura, ki te hiku o nga matua o te puni.
kí o sì fi ara balẹ̀ gbọ́ ohun tí wọ́n ń sọ nínú ibùdó náà. Lẹ́yìn èyí ọkàn rẹ̀ yóò le láti kọlù ibùdó náà.” Báyìí ni òun àti Pura ìránṣẹ́ rẹ̀ wọ ẹnu-ọ̀nà ibùdó yìí.
12 A e takoto haere ana i te raorao nga Miriani, ratou ko nga Amareki, me nga tamariki katoa o te rawhiti, kei te manawhitiwhiti te tokomaha; me a ratou kamera, kahore e taea te tatau; rite tahi ki te onepu i te taha o te moana te tokomaha.
Àwọn ará Midiani, àwọn ará Amaleki àti gbogbo ènìyàn ìlà-oòrùn tó lọ ní àfonífojì bí eṣú ni wọ́n rí nítorí púpọ̀ wọn. Àwọn ìbákasẹ wọn kò sì lóǹkà, wọ́n sì pọ̀ bí yanrìn inú Òkun.
13 A, no te taenga atu o Kiriona, na e korero ana tetahi i te moe ki tona hoa, e mea ana, Nana, moe iho ahau, he keke taro pare e takahuri mai ana ki te puni o Miriana. Na kua tae mai ki te teneti; kua aki atu; na kua hinga, kua huri koaro, a takot o ana te teneti.
Gideoni dé sí àsìkò tí ọkùnrin kan bẹ̀rẹ̀ sí í rọ́ àlá tí ó lá sí ọ̀kan nínú àwọn ọ̀rẹ́ rẹ̀. Ó ní, “Mo lá àlá kan, nínú àlá náà mo rí àkàrà kan tó ṣe róbótó tí a fi barle ṣe ń yí wọ inú ibùdó àwọn ará Midiani, ó sì kọlu àgọ́ pẹ̀lú agbára ńlá dé bi wí pé àgọ́ náà dojúdé, ó sì ṣubú.”
14 Na ka utu tona hoa, ka mea, Ehara tena i te mea ke atu i te hoari a Kiriona tama a Ioaha, he tangata no Iharaira: kua hoatu e te Atua a Miriana me te ope katoa ki tona ringa.
Ọ̀rẹ́ rẹ̀ dá a lóhùn pé, “Èyí kò le túmọ̀ sí ohun mìíràn ju idà Gideoni ọmọ Joaṣi ará Israẹli lọ: Ọlọ́run ti fi àwọn ará Midiani àti gbogbo ogun ibùdó lé e lọ́wọ́.”
15 A, i te rongonga o Kiriona i te korerotanga o te moe, i tona tikanga, na ka koropiko ia, a hoki ana ki te puni o Iharaira, ka mea, Whakatika, kua homai hoki e te Atua te ope o Miriana ki o koutou ringa.
Nígbà tí Gideoni gbọ́ àlá náà àti ìtumọ̀ rẹ̀, ó wólẹ̀ sin Ọlọ́run: lẹ́yìn náà ni ó padà sí ibùdó àwọn ọmọ Israẹli ó sì pè wọ́n pé, “Ẹ dìde! Nítorí pé Olúwa yóò lò yín láti ṣẹ́gun gbogbo ogun Midiani.”
16 Katahi ka wehea e ia nga tangata e toru rau, kia toru nga matua, a whakawhiwhia ana e ia nga ringa o ratou katoa ki te tetere, ki te oko tahanga, ki te rama i roto i te oko.
Nígbà tí ó ti pín àwọn ọ̀ọ́dúnrún ọkùnrin wọ̀n-ọn-nì sí ọ̀nà mẹ́ta, ó fi fèrè, pẹ̀lú àwọn òfìfo ìkòkò lé ẹnìkọ̀ọ̀kan wọn lọ́wọ́, iná sì wà nínú àwọn ìkòkò náà.
17 I mea ano ia ki a ratou, Me titiro mai ki ahau, a kia rite ta koutou ki taku; na, e tae ahau ki te wahi i waho rawa o te puni, ko taku e mea ai, kia pera hoki koutou.
Ó sọ fún wọn pé, “Ẹ máa wò mí, kí ẹ sì máa ṣe ohun tí mo bá ṣe. Nígbà tí mo bá dé igun ibùdó wọn ẹ ṣe ohun tí mo bá ṣe.
18 Ka whakatangi ahau i te tetere, matou ko oku hoa katoa, me whakatangi hoki koutou i nga tetere i nga taha katoa o te puni, me te karanga ano, Ko te hoari a Ihowa, a Kiriona.
Nígbà tí èmi àti àwọn ọkùnrin tí ó wà pẹ̀lú mi bá fun fèrè wa, bẹ́ẹ̀ ni kí ẹ̀yin náà ni gbogbo igun ibùdó tí ẹ̀ bá wà kí ẹ fun àwọn fèrè yín kí ẹ sì hó pé, ‘Fún Olúwa àti fún Gideoni.’”
19 Na ka tae a Kiriona me te rau tangata i a ia ki te wahi i waho rawa o te puni, i te timatanga o to waenga mataaratanga, i te mea katahi ano ka whakaturia atu nga kaimataara: na whakatangihia ana e ratou nga tetere, a wahia iho nga oko i o ratou ringa.
Gideoni àti àwọn ọgọ́rùn-ún ọkùnrin tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ dé òpin ibùdó àwọn ará Midiani ní nǹkan bí agogo méjìlá padà. Wọ́n fun fèrè wọn, wọ́n sì tún fọ́ àwọn ìkòkò tí ó wà ní ọwọ́ mọ́lẹ̀.
20 A whakatangihia ana hoki nga tetere e nga matua e toru, wahia iho nga oko, i puritia ano nga rama ki o ratou ringa maui, me nga tetere ki o ratou ringa matau whakatangi ai; me ta ratou karanga hoki, Ko te hoari a Ihowa, a Kiriona.
Àwọn ẹgbẹ́ mẹ́tẹ̀ẹ̀ta fun fèrè wọn, wọ́n tún fọ́ àwọn ìkòkò wọn mọ́lẹ̀. Wọ́n mú àwọn fìtílà iná wọn ní ọwọ́ òsì wọn àti fèrè tí wọ́n ń fun ní ọwọ́ ọ̀tún wọn. Wọ́n pariwo hé è pé, “Idà kan fún Olúwa àti fún Gideoni!”
21 Na tu ana ratou i tona turanga, i tona turanga, taiawhio noa te puni: a ka rere katoa te puni; a ko to ratou hamamatanga, na ko te whatinga.
Nígbà tí ọkùnrin kọ̀ọ̀kan dúró ní ipò rẹ̀ yí ibùdó àwọn Midiani ká, gbogbo àwọn ọmọ-ogun Midiani ń sá káàkiri, wọ́n ń pariwo bí wọ́n ṣe ń sálọ.
22 I whakatangihia hoki e ratou nga tetere e toru rau, a meinga ana e Ihowa kia anga te hoari a tenei tangata, a tenei tangata, ki tona hoa, ki tona hoa, ki te ope katoa ano hoki: a ka whati te ope tae noa ki Petehita e ahu atu ana ki Tererara, tae noa ki te rohe o Aperemehora, e tata ana ki Tapata.
Nígbà tí àwọn ọ̀ọ́dúnrún ọkùnrin wọ̀n-ọn-nì fun fèrè wọn, Olúwa sì yí ojú idà ọkùnrin kọ̀ọ̀kan padà sí ẹnìkejì rẹ̀ àti sí gbogbo ogun wọn. Àwọn ọmọ-ogun sì sá títí dé Beti-Sitta ní ọ̀nà Serera títí lọ dé ìpínlẹ̀ Abeli-Mehola ní ẹ̀bá Tabbati.
23 Katahi ka huihuia nga tangata o Iharaira, i roto i a Napatari, i a Ahera, i a Manahi katoa, a whaia ana a Miriana e ratou.
Gbogbo àwọn ọmọ-ogun Israẹli láti ẹ̀yà Naftali, Aṣeri àti gbogbo Manase ni Gideoni ránṣẹ́ si, wọ́n wá wọ́n sì lé àwọn ará Midiani.
24 A i tono karere a Kiriona puta noa i te whenua pukepuke katoa o Eparaima hei mea, Haere mai ki raro ki te whawhai ki a Miriana; tangohia hoki nga wai i mua i a ratou, a puta noa ki Petepara ki Horano. Na ka huihui nga tangata katoa o Eparaima, a tangohia ana nga wai, a puta noa ki Petepara ki Horano.
Gideoni tún ránṣẹ́ sí gbogbo àwọn ìlú tí ó wà ní orí òkè Efraimu wí pé, “Ẹ jáde wá bá àwọn ará Midiani jà, kí ẹ tètè gba àwọn omi Jordani títí dé Beti-Bara kí wọ́n tó dé bẹ̀.” Báyìí ni a ṣe pe gbogbo ọkùnrin ológun Efraimu jáde tí wọ́n sì gba gbogbo àwọn à bá wọ odò Jordani títí dé Beti-Bara.
25 A tokorua nga rangatira o Miriana i mau i a ratou, ko Orepe raua ko Teepe; a patua iho e ratou a Orepe ki te kamaka a Orepe, i patua hoki a Teepe ki te poka waina a Teepe, a whaia ana e ratou a Miriana, a kawea ana e ratou nga matenga o Orepe ra ua ko Teepe ki a Kiriona ki tawahi o Horano.
Wọ́n mú méjì nínú àwọn olórí àwọn ará Midiani, àwọn náà ni Orebu àti Seebu. Wọ́n pa Horebu nínú àpáta Orebu, wọ́n sì pa Seebu níbi tí àwọn ènìyàn ti mọ̀ fún wáìnì tí a ń pè ní ìfúntí Seebu. Wọ́n lé àwọn ará Midiani, nígbà tí wọ́n gbé orí Orebu àti Seebu tọ Gideoni wá ẹni tí ó wà ní apá kejì Jordani.

< Kaiwhakariterite 7 >