< Kaiwhakariterite 6 >
1 Na ka mahi kino nga tamariki a Iharaira i te tirohanga a Ihowa, a tukua ana ratou e Ihowa ki te ringa o Miriana e whitu nga tau.
Àwọn ọmọ Israẹli sì túnṣe ohun tí ó burú ní ojú Olúwa, Ó sì fi wọ́n lé àwọn ará Midiani lọ́wọ́ fún ọdún méje.
2 A nui atu te kaha o te ringa o Miriana i to Iharaira: a na Miriana i hanga ai e nga tamariki a Iharaira nga rua i nga maunga mo ratou, me nga ana, me nga pa taiepa.
Agbára àwọn ará Midiani sì pọ̀ púpọ̀ lórí àwọn Israẹli, wọ́n sì hùwà ipá sí wọn, nítorí ìdí èyí, àwọn Israẹli sálọ sí àwọn orí òkè, wọ́n sì kọ́ àgọ́ fún ara wọn nínú ihò àpáta, àti nínú ọ̀gbun àti ní ibi agbára nínú àpáta.
3 Na ka oti te mahi whakato a Iharaira, ka haere ake nga Miriani ratou ko nga Amareki, me nga tangata o te rawhiti; ka haere ake ki te whakaeke i a ratou.
Ní ìgbàkúgbà tí àwọn ọmọ Israẹli bá ti gbin ọ̀gbìn wọn, àwọn ará Midiani, àwọn ará Amaleki àti àwọn ará ìlà-oòrùn mìíràn yóò wá láti bá wọn jà.
4 Whakapaea iho e ratou, a moti ake i a ratou nga hua o te whenua, a tae noa koe ki Kaha, kihai hoki i mahue tetahi oranga mo Iharaira, kahore he hipi, he kau, he kaihe ranei.
Wọn yóò tẹ̀dó sí orí ilẹ̀ náà, wọn a sì bá irúgbìn wọ̀nyí jẹ́ títí dé Gasa, wọn kì í sì í fi ohun alààyè kankan sílẹ̀ fún àwọn ọmọ Israẹli, kì bá à ṣe àgùntàn, màlúù tàbí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́.
5 I whakaeke mai hoki ratou me a ratou kararehe, i haere mai me o ratou teneti; koia ano kei nga mawhitiwhiti te maha; e kore hoki e taea te tatau ratou me a ratou kamera: na haere mai ana ratou ki te whenua whakangaro ai.
Wọn a máa wá pẹ̀lú ohun ọ̀sìn wọn àti àwọn àgọ́ wọn, wọn a sì dàbí eṣú nítorí i púpọ̀ wọn. Ènìyàn kò sì lè ka iye àwọn ènìyàn náà bẹ́ẹ̀ ni àwọn ìbákasẹ, wọ́n pọ̀ dé bi pé wọn kò ṣe é kà ní iye, wọn a bo ilẹ̀ náà wọn a sì jẹ ẹ́ run.
6 Na kua rawakore noa iho a Iharaira i a Miriana; a ka tangi nga tamariki a Iharaira ki a Ihowa.
Àwọn ará Midiani sì pọ́n àwọn ọmọ Israẹli lójú, wọ́n sọ wọ́n di òtòṣì àti aláìní, fún ìdí èyí wọ́n ké pe Olúwa nínú àdúrà fún ìrànlọ́wọ́.
7 A, no te tangihanga o nga tamariki a Iharaira ki a Ihowa i te mahi a Miriana,
Nígbà tí àwọn ọmọ Israẹli ké pe Olúwa nítorí àwọn ará Midiani.
8 Ka tono tangata a Ihowa ki nga tamariki a Iharaira, he poropiti, hei mea ki a ratou, Ko te kupu tenei a Ihowa, a te Atua o Iharaira, Naku koutou i kawe mai ki runga nei i Ihipa; naku hoki koutou i whakaputa mai i te whare pononga;
Olúwa fi etí sí igbe wọn, ó sì rán wòlíì kan sí wọn, ẹni tí ó wí pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí: mo mú yín gòkè ti Ejibiti wá, láti oko ẹrú.
9 Naku koutou i whakaora i te ringa o nga Ihipiana, i te ringa hoki o o koutou kaitukino katoa; a peia atu ana ratou e ahau i to koutou aroaro, hoatu ana hoki e ahau to ratou whenua ki a koutou.
Mo gbà yín kúrò nínú agbára Ejibiti àti kúrò ní ọwọ́ gbogbo àwọn aninilára yín. Mo lé wọn kúrò ní iwájú yín, mo sì fi ilẹ̀ wọn fún yín.
10 I mea ano ahau ki a koutou, Ko Ihowa ahau, ko to koutou Atua; kaua e wehingia nga atua o nga Amori no ratou nei te whenua e noho na koutou: heoi kahore koutou i rongo ki toku reo.
Mo wí fún un yín pé, ‘Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín; ẹ má ṣe sin àwọn òrìṣà àwọn ará Amori, ní ilẹ̀ ẹni tí ẹ̀yin ń gbé.’ Ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò gbọ́rọ̀ sí ohun tí mo sọ.”
11 Na ka haere mai te anahera a Ihowa, a noho ana i raro i tetahi oki i Opora, he rakau na Ioaha Apieteri: i te patu witi hoki tana tama, a Kiriona ki te poka waina, he mea kia toe ai i nga Miriani.
Ní ọjọ́ kan angẹli Olúwa wá, ó sì jókòó ní abẹ́ igi óákù Ofira èyí ti ṣe ti Joaṣi ará Abieseri, níbi tí Gideoni ọmọ rẹ̀ ti ń lu ọkà jéró, níbi ìpọntí wáìnì láti fi pamọ́ kúrò níwájú àwọn ará Midiani.
12 Na ka puta te anahera a Ihowa ki a ia, ka mea ki a ia, Kei a koe a Ihowa, e te tangata marohirohi.
Nígbà tí angẹli Olúwa fi ara han Gideoni, ó wí fún un pé, “Olúwa wà pẹ̀lú rẹ, akọni ológun.”
13 Na ka mea a Kiriona ki a ia, Aue, e toku Ariki, me i a matou a Ihowa, na te aha i pono mai ai ki a matou enei mea katoa? kei hea hoki ana merekara i korero mai ai o matou matua ki a matou, i mea ai, Kahore ianei a Ihowa i kawe mai i a tatou i Ih ipa? na kua whakarere nei a Ihowa i a matou, kua tukua ano matou ki te ringa o Miriana.
Gideoni dáhùn pé, “Alàgbà, bí Olúwa bá wà pẹ̀lú wa, kí ló dé tí gbogbo ìwọ̀nyí fi ń ṣẹlẹ̀ sí wa? Níbi gbogbo àwọn iṣẹ́ ìyanu rẹ tí àwọn baba wa ròyìn rẹ̀ fún wa nígbà tí wọ́n wí pé, ‘Olúwa kò ha mú wa gòkè láti ilẹ̀ Ejibiti wá?’ Ṣùgbọ́n nísinsin yìí Olúwa ti kọ̀ wá sílẹ̀, ó sì ti fi wá lé àwọn ará Midiani lọ́wọ́.”
14 Na ka tahuri atu a Ihowa ki a ia, ka mea, Haere i runga i tenei kaha ou, whakaorangia hoki a Iharaira i te ringa o Miriana: kahore ianei ahau i tono i a koe?
Olúwa sì yípadà sí i, ó sì wí fún un pé, “Lọ nínú agbára tí o ní yìí, kí o sì gba àwọn ará Israẹli sílẹ̀ kúrò lọ́wọ́ àwọn ará Midiani. Èmi ni ó ń rán ọ lọ.”
15 Na ka mea tera ki a ia, Aue, e toku Ariki, ma te aha ahau e whakaora ai i a Iharaira? titiro, noku te hapu rawakore i roto i a Manahi, ko te iti rawa hoki ahau i roto i te whare o toku papa.
Gideoni sì dáhùn pé, “Yéè olúwa mi, ọ̀nà wo ni èmi yóò fi gba Israẹli là? Ìdílé mi ni ó jẹ́ aláìlera jù ní Manase, àti pé èmi ni ó sì kéré jù ní ìdílé baba mi.”
16 Na ka mea a Ihowa ki a ia, Ko ahau ra hei hoa mou; a ka patua e koe nga Miriani, me te mea he tangata kotahi.
Olúwa sì dáhùn pé, “Èmi yóò wà pẹ̀lú rẹ, ìwọ yóò sì pa gbogbo àwọn ará Midiani láì ku ẹnìkankan.”
17 Ano ra ko ia ki a ia, Na ki te mea kua manakohia ahau e koe, tena ra, whakaaturia mai he tohu ki ahau ko koe tenei e korero mai nei ki ahau.
Gideoni sì dáhùn pé, nísinsin yìí tí mo bá bá ojúrere rẹ pàdé, fún mi ní àmì pé ìwọ ni ń bá mi sọ̀rọ̀.
18 Kaua ra e haere atu i konei, kia tae mai ra ano ahau ki a koe ki te kawe mai i taku whakahere, kia whakatakotoria ra ano e ahau ki tou aroaro. Na ko tana meatanga, Ka noho ahau, kia hoki mai ra ano koe.
Jọ̀wọ́ má ṣe kúrò níbí títí èmi yóò fi mú ọrẹ wá fún ọ kí n sì gbé e sí iwájú rẹ. Olúwa sì wí pé, “Èmi yóò dúró títí ìwọ yóò fi dé.”
19 Katahi ka haere a Kiriona ki roto, a taka ana e ia tetahi kuao koati, me tetahi epa paraoa hei keke rewenakore: ko te kikokiko i whaowhina e ia ki te kete, ko te hupa i ringihia ki te pata, na kawea ana ki waho, ki a ia ki raro i te oki; a tapae a atu ana ki a ia.
Gideoni sì yára wọ ilé lọ, ó sì pa ọ̀dọ́ ewúrẹ́ kan, wọ́n sì sè é, ó sì mú ìyẹ̀fun efa kan, ó fi ṣe àkàrà aláìwú. Ó gbé ẹran náà sínú agbọ̀n, ṣùgbọ́n ó fi ọbẹ̀ rẹ̀ sínú ìkòkò, ó gbé wọn jáde tọ angẹli náà wá bí ọrẹ lábẹ́ igi óákù.
20 Na ka mea te anahera a te Atua ki a ia, Tangohia te kikokiko me nga keke rewenakore, ka whakatakoto ai ki runga ki tenei kamaka, ka riringi ai hoki i te hupa. Na pera ana ia.
Angẹli Ọlọ́run náà sì wí fún un pé, “Gbé ẹran náà àti àkàrà àìwú náà, sí orí àpáta yìí, kí o sì da omi ọbẹ̀ rẹ̀ sí orí rẹ̀.” Gideoni sì ṣe bẹ́ẹ̀.
21 Katahi ka whatorona atu e te anahera a Ihowa te pito o te tokotoko i tona ringa, a pa ana ki te kikokiko, ki nga keke rewenakore; na ko te putanga ake o te ahi i roto i te kamaka, pau ake te kikokiko me nga keke rewenakore. Na kua riro atu te an ahera a Ihowa i tana tirohanga.
Angẹli Olúwa sì fi orí ọ̀pá tí ó wà ní ọwọ́ rẹ̀ kan ẹran àti àkàrà àìwú náà. Iná sì jáde láti inú àpáta, ó sì jó ẹran àti àkàrà náà, kò sì rí angẹli náà mọ́.
22 A, no te kitenga o Kiriona ko te anahera ia a Ihowa, ka mea a Kiriona, Aue, e te Ariki, e Ihowa! moku hoki i kite i te anahera a Ihowa, he kanohi, he kanohi.
Nígbà tí Gideoni sì ti mọ̀ dájúdájú pé angẹli Olúwa ni, ó ké wí pé, “Háà! Olúwa Olódùmarè! Mo ti rí angẹli Olúwa ní ojúkorojú!”
23 Na ka mea a Ihowa ki a ia, Kia tau te rangimarie ki a koe; kaua e wehi: e kore koe e mate.
Ṣùgbọ́n Olúwa wí fún un pé, “Àlàáfíà! Má ṣe bẹ̀rù, ìwọ kì yóò kùú.”
24 Na ka hanga e Kiriona tetahi aata ma Ihowa ki reira, a huaina iho e ia ko Ihowaharomo: kei Opora o nga Apieteri na ano taua mea a taea noatia tenei ra.
Báyìí ni Gideoni mọ pẹpẹ kan fún Olúwa níbẹ̀, ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní “Àlàáfíà ni Olúwa.” Ó sì wà ní Ofira ti Abieseri títí di òní.
25 A i taua po ano ka mea a Ihowa ki a ia, Tikina te puru a tou papa, ara te rua o nga puru, e whitu nei ona tau, ka wawahi ai i te aata a Paara, i tera a tou papa: me tua hoki te motu nehenehe i tona taha.
Ní òru ọjọ́ náà Olúwa wí fún un pé, mú akọ màlúù baba rẹ, àní akọ màlúù kejì ọlọ́dún méje. Wó pẹpẹ Baali baba rẹ lulẹ̀, kí o sì bẹ́ igi ère òrìṣà Aṣerah tí ó wà ní ẹ̀gbẹ́ rẹ̀ lulẹ̀.
26 Me hanga hoki ki tona tikanga ano he aata ma Ihowa ma tou Atua ki runga ki tenei kamaka, ka mau ai ki te tuarua o nga puru, ka whakaeke hei tahunga tinana ki runga ki nga rakau o te nehenehe e tuaina e koe.
Lẹ́yìn èyí kí o wá mọ pẹpẹ èyí tí ó yẹ fún Olúwa Ọlọ́run rẹ lórí òkè yìí. Kí o sì mú akọ màlúù kejì, kí o sì mú igi ère òrìṣà Aṣerah tí ìwọ bẹ́ lulẹ̀ rú ẹbọ sísun sí Olúwa.
27 Na ka tango a Kiriona i etahi tangata kotahi tekau no ana pononga, a rite tonu tana i mea ai ki ta Ihowa i korero ai ki a ia: na i wehi ia i te whare o tona papa, i nga tangata ano hoki o te pa, i kore ai e meatia e ia i te awatea; koia i meatia ai e ia i te po.
Gideoni mú mẹ́wàá nínú àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, ó sì ṣe bí Olúwa ti pàṣẹ fún un ṣùgbọ́n, nítorí ó bẹ̀rù àwọn ará ilé baba rẹ̀ àti àwọn ènìyàn ìlú náà kò ṣe é ní ọ̀sán, òru ni ó ṣe.
28 Na, i te marangatanga ake o nga tangata o te pa i te ata, rere! kua wahia iho te aata a Paara, kua oti te motu nehenehe i tona taha te tua, kua oti hoki te tuarua o nga puru te whakaeke ki te aata i hanga ra.
Nígbà tí ilẹ̀ ọjọ́ kejì mọ́, tí àwọn ènìyàn ìlú náà jí, wọ́n rí i pé àti fọ́ pẹpẹ Baali àti pé a ti bẹ́ igi ère òrìṣà Aṣerah tí ó wà ní ẹ̀gbẹ́ rẹ̀, a sì ti fi akọ màlúù kejì rú ẹbọ lórí pẹpẹ tí a ṣẹ̀ṣẹ̀ mọ.
29 Na ka mea tetahi ki tetahi, Na wai tenei mahi? A ka rapu ratou, ka ui, na ka korerotia, I meatia tenei e Kiriona tama a Ioaha.
Àwọn ènìyàn ìlú náà bi ara wọn wí pé, “Ta ni ó ṣe èyí?” Lẹ́yìn tí wọn fi ara balẹ̀ ṣe ìwádìí, wọ́n gbọ́ wí pé, “Gideoni ọmọ Joaṣi ni ó ṣe é.”
30 Na ka mea nga tangata o te pa ki a Ioaha, Whakaputaina mai tau tama ki waho, kia whakamatea; mona i wahi i te aata a Paara, i tua hoki i te nehenehe i tona taha.
Àwọn ọkùnrin ìlú náà sì wí fún Joaṣi wí pé, “Mú ọmọ rẹ jáde wá. Ó ní láti kú nítorí pé ó ti wó pẹpẹ Baali lulẹ̀ ó sì ti ké ère òrìṣà Aṣerah tí ó wà ní ẹ̀bá rẹ̀ lulẹ̀.”
31 Na ka mea a Ioaha ki te hunga katoa e tu mai ana ki a ia, Ko koutou ranei hei tohe i ta Paara? Ko koutou ranei hei whakaora i a ia? Ki te tohe tetahi mona, me whakamate ia i te ata nei ano. Ki te mea he atua ia, mana ano ia e tohe mo tana aata k ua wahia nei.
Ṣùgbọ́n Joaṣi bi àwọn èrò tí wọ́n fi ìbínú dúró tì í wí pé, “Ẹ̀yin yóò ha gbìjà Baali bí? Ẹ̀yin yóò ha gbà á sílẹ̀ bí? Ẹnikẹ́ni tí ó bá gbìjà rẹ̀ kíkú ni olúwa rẹ̀ yóò kú ní òwúrọ̀. Bí Baali bá ṣe Ọlọ́run nítòótọ́ yóò jà fún ara rẹ̀ bí ẹnikẹ́ni bá wó pẹpẹ rẹ̀ lulẹ̀.”
32 Na huaina iho ia e ia taua ra, Ko Ierupaara; i mea hoki, Ma Paara ano e tohe ki a ia mo tana aata kua wahia nei.
Fún ìdí èyí ní ọjọ́ náà wọ́n pe Gideoni ní “Jerubbaali” wí pé, “Jẹ́ kí Baali bá a jà,” nítorí pé ó ti wó pẹpẹ Baali.
33 Na ka huihui tahi nga Miriani katoa ratou ko nga Amareki, ko nga tangata o te rawhiti, a ka whiti, ka noho hoki ki te raorao o Ietereere.
Láìpẹ́ jọjọ, àwọn ogun àwọn Midiani, ti àwọn Amaleki àti ti àwọn ènìyàn ìhà ìlà-oòrùn yòókù kó ara wọn jọ pọ̀ ní ìṣọ̀kan, wọ́n sì kọjá Jordani wọ́n sì tẹ̀dó sí àfonífojì Jesreeli.
34 Na kua tau te wairua o Ihowa ki runga ki a Kiriona, a whakatangihia ana e ia te tetere; a huihuia ana a Apietere ki te aru i a ia.
Ẹ̀mí Olúwa sì bà lé Gideoni, ó sì fun fèrè ìpè, láti pe àwọn ará Abieseri láti tẹ̀lé òun.
35 I tono karere ano ia puta noa i a Manahi, a ka huihuia ano ratou ki a ia: i tono karere ano ia ki a Ahera, ki a Hepurona, ki a Napatari; a ka haere ake ratou ki te whakatau i a ratou.
Ó rán àwọn oníṣẹ́ la ilẹ̀ Manase já pé kí wọ́n dira ogun, àti sí Aṣeri, Sebuluni àti Naftali gbogbo pẹ̀lú sì lọ láti pàdé wọn.
36 Na ka mea a Kiriona ki te Atua, Ki te mea noku te ringa e whakaorangia ai e koe a Iharaira, pera me tau i korero mai ra,
Gideoni wí fún Ọlọ́run pé, “Bí ìwọ yóò bá gba Israẹli là nípasẹ̀ mi bí ìwọ ti ṣe ìlérí—
37 Na ka waiho e ahau te huruhuru hipi ki runga ki te patunga witi; a ki te mea kei te huruhuru anake te tomairangi, a he maroke a runga katoa o te whenua, katahi ahau ka mohio noku te ringa e whakaorangia ai e koe a Iharaira, ka rite ano ki tau i korero ra.
kíyèsi, èmi yóò fi awọ irun àgùntàn lé ilẹ̀ ìpakà ní alẹ́ òní. Bí ìrì bá sẹ̀ sí orí awọ yìí nìkan tí gbogbo ilẹ̀ yòókù sì gbẹ, nígbà náà ni èmi yóò mọ̀ lóòótọ́ pé ìwọ yóò gba Israẹli là nípasẹ̀ mi bí ìwọ ti sọ.”
38 A pera tonu: i maranga wawe hoki ia i te ata, a ka romia e ia te huruhuru, a tauia ana te tomairangi i roto i te huruhuru, ki tonu te peihana i te wai.
Èyí ni ó sì ṣẹlẹ̀. Nígbà tí Gideoni jí ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, ó sì fún irun àgùntàn náà, ọpọ́n omi kan sì kún.
39 I mea ano a Kiriona ki te Atua, Kei mura tou riri ki ahau, a heoi ano he korero maku ko tenei: tena, kia kotahi ake whakamatau maku i te huruhuru, a ka kati. Kia maroke ko te huruhuru anake, a kia whai tomairangi a runga i te whenua katoa.
Gideoni sì tún wí fún Ọlọ́run pé, “Jọ̀wọ́ má ṣe bínú sí mi, ṣùgbọ́n jẹ́ kí n tún wá ìdánilójú kan sí i, èmi bẹ̀ ọ́ jẹ́ kí n fi awọ irun yìí ṣe ìdánwò kan sí i. Ní àsìkò yìí, jẹ́ kí awọ irun yìí gbẹ kí gbogbo ilẹ̀ sì tutù pẹ̀lú ìrì.”
40 A i peratia e te Atua i taua po: ko te huruhuru anake i maroke, a he tomairangi i te whenua katoa.
Ní òru náà Ọlọ́run ṣe bẹ́ẹ̀, awọ irun àgùntàn nìkan ni ó gbẹ; gbogbo ilẹ̀ yòókù sì tutù nítorí ìrì.