< Kaiwhakariterite 17 >
1 Na i te whenua pukepuke o Eparaima tetahi tangata, ko Mika tona ingoa.
Nígbà náà ni ọkùnrin kan tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Mika láti agbègbè òkè Efraimu
2 Na ka mea ia ki tona whaea, Ko nga hiriwa kotahi tekau ma tahi rau i tangohia ra i a koe, te mea i kanga ra koe, i korero ai hoki koe ki oku taringa, nana, kei ahau aua hiriwa; naku i tango. Na ka mea tona whaea, Ma Ihowa koe e manaaki, e taku ta ma.
sọ fún ìyá rẹ̀ pé, “Ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀fà ṣékélì fàdákà èyí tí wọ́n jí mọ́ ọ lọ́wọ́, àti nípa èyí tí mo gbọ́ tí ìwọ ń ṣẹ́ èpè. Kíyèsi fàdákà náà wà ní ọ̀dọ̀ mi, èmi ni mo kó o.” Nígbà náà ni ìyá rẹ̀ dáhùn pé, “Kí Olúwa bùkún ọ ọmọ mi!”
3 Na ka whakahokia e ia nga hiriwa kotahi tekau ma tahi rau ki tona whaea, a ka mea tona whaea; Ka whakatapua rawatia e ahau te hiriwa ma Ihowa, he mea na toku ringa ma taku tama, hei hanga whakapakoko, he mea whaowhao, he mea whakarewa. Na, me wha kahoki atu e ahau ki a koe inaianei.
Nígbà tí ó da ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀fà ṣékélì fàdákà náà padà fún ìyá rẹ̀, ìyá rẹ̀ dáhùn pé, “Èmi ti fi òtítọ́ inú ya sílífà náà sọ́tọ̀ sí Olúwa fún ọmọ mi láti fi dá ère dídá àti ère gbígbẹ́. Èmi yóò dá a padà fún ọ.”
4 Na, i tana whakahokinga i te moni ki tona whaea, ka tango tona whaea i nga pihi hiriwa e rua rau, a hoatu ana ki te kaiwhakarewa, a nana i hanga tetahi whakapakoko whaowhao me tetahi mea whakarewa; na ka takoto aua mea ki te whare o Mika.
Nítorí náà òun dá sílífà náà padà fún ìyá rẹ̀, ìyá rẹ̀ sì mú igba ṣékélì fàdákà, ó sì fún alágbẹ̀dẹ fàdákà ẹni tí ó fi wọ́n rọ ère fínfín àti ère dídà. Wọ́n sì kó wọn sí ilé Mika.
5 Na he whare atua to taua tangata, to Mika, i hanga ano he epora e ia, me etahi terapimi, a i whakatohungatia hoki e ia tetahi o ana tama, a meinga ana hei tohunga mana.
Ọkùnrin náà, Mika sì ní ojúbọ kan. Òun sì ra ẹ̀wù efodu kan, ó sì ṣe àwọn ère kan, ó sì fi ọ̀kan nínú àwọn ọmọ rẹ̀ ọkùnrin ṣe àlùfáà rẹ̀.
6 I aua ra kahore o Iharaira kingi; ko ta ratou i mea ai ko nga mea i tika ki te titiro a tenei, a tenei.
Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì àwọn ọmọ Israẹli kò ní ọba; olúkúlùkù ṣe bí ó ti rò pé ó tọ́ ní ojú ara rẹ́.
7 Na tera tetahi taitama o Peterehema Hura, o te hapu o Hura, he Riwaiti, a i reira ano ia e noho ana.
Ọ̀dọ́mọkùnrin kan sì ti Bẹtilẹhẹmu ti Juda wá, tí í ṣe ìdílé Juda, ẹni tí í ṣe ẹ̀yà Lefi, òun sì ṣe àtìpó níbẹ̀,
8 Na ka haere atu taua tangata i te pa, i Peterehema Hura, kia noho ki tana wahi e kite ai: a, i a ia e haere ana, ka tae ia ki te whenua pukepuke o Eparaima, ki te whare o Mika.
ọkùnrin náà sì ti ìlú Bẹtilẹhẹmu ti Juda lọ, láti ṣe àtìpó ní ibikíbi tí ó bá rí. Ní ojú ọ̀nà àjò rẹ̀, ó dé ilẹ̀ Mika nínú àwọn ilẹ̀ òkè Efraimu.
9 Na ka mea a Mika ki a ia, I haere mai koe i hea? A ka mea ia ki a ia, He Riwaiti ahau no Peterehema Hura, a e haere ana ahau kia noho ki taku wahi e kite ai.
Mika bi í pé, “Níbo ni ó ti ń bọ̀?” Ó dáhùn pé, “Ọmọ Lefi ni mí láti Bẹtilẹhẹmu Juda, mo sì ń wá ibi tí èmi yóò máa gbé.”
10 Na ka mea a Mika ki a ia, E noho ki ahau, a hei matua koe moku, hei tohunga hoki, a kia tekau nga kiriwa e hoatu e ahau ki a koe i te tau, kia kotahi ano te whakaritenga kakahu, me te kai ano mau. Na ka tomo atu te Riwaiti.
Mika sì sọ fún un wí pé, “Dúró lọ́dọ̀ mi kí ìwọ sì jẹ́ baba mi àti àlùfáà fún mi, èmi ó sì máa fún ọ ní ṣékélì mẹ́wàá fàdákà ní ọdọọdún, pẹ̀lú aṣọ àti oúnjẹ rẹ̀.”
11 A pai tonu te Riwaiti kia noho ki taua tangata; a ka meinga taua taitamariki e ia kia rite ki tetahi o ana tama.
Ọmọ Lefi náà sì gbà láti máa bá a gbé, ọ̀dọ́mọkùnrin náà sì dàbí ọ̀kan nínú àwọn ọmọ rẹ̀.
12 Na whakatohungatia ana e Mika taua Riwaiti, a ka waiho taua taitama hei tohunga mana, a noho ana i roto i te whare o Mika.
Nígbà náà ni Mika ya ará Lefi náà sí mímọ́, ọ̀dọ́mọkùnrin náà sì di àlùfáà rẹ̀, ó sì ń gbé ilé rẹ̀.
13 Na ka mea a Mika, Katahi ahau ka mohio ka atawhaitia ahau e Ihowa, ina hoki ka riro mai nei te Riwaiti hei tohunga moku.
Mika sì wí pé, “Báyìí, èmi mọ̀ pé Olúwa yóò ṣe mi ní oore nítorí pé mo ní ọmọ Lefi ní àlùfáà mi.”