< Hohua 7 >

1 Otiia i taka nga tama a Iharaira ki te kino i te mea kua oti te kanga: he tangohanga na Akana tama a Karami, tama a Taperi, tama a Tera, o te iwi o Hura, i tetahi wahi o te mea kua oti te kanga; a mura iho te riri o Ihowa ki nga tama a Iharaira.
Ṣùgbọ́n àwọn ará Israẹli ṣe àìṣòótọ́ nípa ohun ìyàsọ́tọ̀, Akani ọmọ Karmi, ọmọ Sabdi, ọmọ Sera, ẹ̀yà Juda, mú nínú wọn. Bẹ́ẹ̀ ni ìbínú Olúwa ru sí àwọn ará Israẹli.
2 Na ka tonoa atu e Hohua etahi tangata i Heriko ki Hai, ki te taha o Peteawene, i te taha ki te rawhiti o Peteere, ka korero hoki ki a ratou, ka mea, Haere ki runga ki te titiro i te whenua. Na ka haere aua tangata, ka titiro i Hai.
Joṣua rán àwọn ọkùnrin láti Jeriko lọ sí Ai, tí ó súnmọ́ Beti-Afeni ní ìlà-oòrùn Beteli, ó sì sọ fún wọn pé, “Ẹ gòkè lọ kí ẹ sì ṣe ayọ́lẹ̀wò.” Bẹ́ẹ̀ ni àwọn arákùnrin náà lọ, wọ́n sì yọ́ Ai wò.
3 A ka hoki mai ratou ki a Hohua, ka mea ki a ia, Kaua e haere katoa te iwi ki runga; engari kia rua, kia toru ranei mano o nga tangata e haere ki runga ki te patu i Hai; kaua hei whakangenge kau atu i te iwi ki reira; he tokoouou hoki ratou.
Nígbà tí wọ́n padà sí ọ̀dọ̀ Joṣua, wọ́n wí pé, “Kì í ṣe gbogbo àwọn ènìyàn ni ó ni láti gòkè lọ bá Ai jà. Rán ẹgbẹ̀rún méjì tàbí ẹgbẹ̀rún mẹ́ta ọkùnrin láti gbà á, kí ó má ṣe dá gbogbo àwọn ènìyàn ní agara, nítorí ìba ọkùnrin díẹ̀ ní ó wà níbẹ̀.”
4 Heoi haere ana ki reira etahi o te iwi, me te mea e toru mano: na rere ana ratou i te aroaro o nga tangata o Hai.
Bẹ́ẹ̀ ní àwọn bí ẹgbẹ̀rún mẹ́ta ọkùnrin lọ; ṣùgbọ́n àwọn ọkùnrin Ai lé wọn sá.
5 A tukitukia iho o ratou e nga tangata o Hai me te mea e toru tekau ma ono tangata; i whaia hoki ratou i mua i te kuwaha a tae noa ki Heparimi, na patupatua ana ratou i te heketanga: a ngohe kau te ngakau o te iwi, koia ano kei te wai.
Àwọn ènìyàn Ai sì pa àwọn bí mẹ́rìndínlógójì nínú wọn. Wọ́n sì ń lépa àwọn ará Israẹli láti ibodè ìlú títí dé Ṣebarimu, wọ́n sì pa àwọn tí ń sọ̀kalẹ̀. Àyà àwọn ènìyàn náà sì já, ọkàn wọn sì pami.
6 Na ka haehae a Hohua i ona kakahu, ka tapapa ki te whenua, ki mua o te aaka a Ihowa a ahiahi noa, a ia me nga kaumatua o Iharaira; a opehia ana e ratou he puehu ki o ratou upoko.
Joṣua sì fa aṣọ rẹ̀ ya, ó sì dojúbolẹ̀ níwájú àpótí ẹ̀rí Olúwa títí di àṣálẹ́. Àwọn àgbà Israẹli sì ṣe bákan náà, wọ́n ku eruku sí orí wọn.
7 Na ka mea a Hohua, Aue, e te Ariki, e Ihowa, na te aha rawa ra koe i anga ai ki te whakawhiti mai i tenei iwi i Horano, i hoatu ai matou ki te ringa o nga Amori, kia huna ai matou? Aue, me i aro matou ki te noho atu i tera taha o Horano!
Joṣua sì wí pé, “Háà, Olúwa Olódùmarè, nítorí kín ni ìwọ ṣe mú àwọn ènìyàn yìí kọjá Jordani, láti fi wọ́n lé àwọn ará Amori lọ́wọ́, láti pa wọn run? Àwa ìbá mọ̀ kí a dúró ní òdìkejì Jordani?
8 E te Ariki, me pehea ra he kupu maku, kua parea atu nei e Iharaira o ratou tuara i te aroaro o o ratou hoariri?
Olúwa, kín ni èmi yóò sọ nísinsin yìí tí Israẹli sì ti sá níwájú ọ̀tá a rẹ̀?
9 Na te mea ka rongo nga Kanaani me nga tangata katoa o te whenua, na ka karapotia matou, ka huna hoki o matou ingoa i te whenua: a ka pehea koe ki tou ingoa nui?
Àwọn Kenaani àti àwọn ènìyàn ìlú tí ó kù náà yóò gbọ́ èyí, wọn yóò sì yí wa ká, wọn yóò sì ké orúkọ wa kúrò ní ayé. Kí ni ìwọ ó ha ṣe fún orúkọ ńlá à rẹ?”
10 Na ka mea a Ihowa ki a Hohua, Whakatika; he aha tau e takoto tapapa na?
Olúwa sì sọ fún Joṣua pé, “Dìde! Kín ni ìwọ ń ṣe tí ó fi dojúbolẹ̀?
11 Kua hara a Iharaira; ae, kua takahi ratou i taku kawenata i whakarite ai ahau ki a ratou: ae, kua tangohia nei e ratou tetahi wahi o te mea kua oti te kanga, me te tahae, me te teka ano ratou, a whaowhina ana e ratou ki roto ki a ratou mea.
Israẹli ti ṣẹ̀, wọ́n sì ti ba májẹ̀mú mi jẹ́, èyí tí mo pàṣẹ fún wọn pé kí wọn pamọ́. Wọ́n ti mú nínú ohun ìyàsọ́tọ̀, wọ́n ti jí, wọ́n pa irọ́, wọ́n ti fi wọ́n sí ara ohun ìní wọn.
12 Na reira nga tama a Iharaira te ahei ai te tu i te aroaro o o ratou hoariri, na hurihia ana o ratou tuara i te aroaro o o ratou hoariri, kua kanga hoki ratou: e kore ahau e haere i a koutou a muri atu, ki te kahore koutou e whakangaro i te mea k anga i roto i a koutou.
Ìdí nì èyí tí àwọn ará Israẹli kò fi lè dúró níwájú àwọn ọ̀tá wọn; wọ́n yí ẹ̀yìn wọn padà, wọ́n sì sálọ níwájú ọ̀tá a wọn nítorí pé àwọn gan an ti di ẹni ìparun. Èmi kì yóò wà pẹ̀lú u yín mọ́, bí kò ṣe pé ẹ̀yin pa ohun ìyàsọ́tọ̀ run kúrò ní àárín yín.
13 Whakatika, whakatapua te iwi, mea atu, whakatapu i a koutou mo apopo: ko te kupu hoki tenei a Ihowa, a te Atua o Iharaira, Kei roto i a koe, e Iharaira, te mea kanga: e kore koe e kaha ki te tu ki te aroaro o ou hoariri, kia tangohia atu ra ano e koutou te mea kanga i roto i a koutou.
“Lọ, ya àwọn ènìyàn náà sí mímọ́. Sọ fún wọn pé, ‘Ẹ ya ara yín sí mímọ́ fún ọ̀la, nítorí báyìí ni Olúwa, Ọlọ́run Israẹli wí, ohun ìyàsọ́tọ̀ kan ń bẹ ní àárín yín, Israẹli. Ẹ̀yin kì yóò lè dúró níwájú àwọn ọ̀tá a yín títí ẹ̀yin yóò fi mú kúrò.
14 Na i te ata me whakatata mai koutou, ara o koutou iwi; a tera ko te iwi e tango ai a Ihowa me whakatata mai a hapu; a ko te hapu e tango ai a Ihowa me whakatata a whare mai; a ko te whare e tango ai a Ihowa me whakatata mai ia tangata, ia tangat a.
“‘Ní òwúrọ̀, kí ẹ mú ará yín wá síwájú ní ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan. Ẹ̀yà tí Olúwa bá mú yóò wá sí iwájú ní agbo ilé kọ̀ọ̀kan, agbo ilé tí Olúwa bá mú yóò wá sí iwájú ní ìdílé kọ̀ọ̀kan, ìdílé tí Olúwa bá sì mú yóò wá sí iwájú ní ẹni kọ̀ọ̀kan.
15 A, ko te tangata e hopukia kei a ia te mea kanga, me tahu ki te ahi, a ia me ana mea katoa: mona i takahi i te kawenata a Ihowa, i mahi poauau hoki i roto i a Iharaira.
Ẹnikẹ́ni tí a bá ká mọ́ pẹ̀lú ohun ìyàsọ́tọ̀ náà, a ó fi iná pa á run, pẹ̀lú gbogbo ohun tí ó ní. Ó ti ba májẹ̀mú Olúwa jẹ́, ó sì ti ṣe nǹkan ìtìjú ní Israẹli!’”
16 Na ka maranga wawe a Hohua i te ata, a whakatataia mai ana e ia a Iharaira, ara ona iwi; na ka mau ko te iwi o Hura.
Ní kùtùkùtù òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, Joṣua mú Israẹli wá síwájú ní ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan, a sì mú ẹ̀yà Juda.
17 Na ka arahina mai e ia te hapu o Hura: a ka mau te hapu o nga Terahi: na ka arahina mai e ia te hapu o nga Terahi, tenei tangata, tenei tangata; a ka mau ko Taperi:
Àwọn agbo ilé e Juda wá sí iwájú, ó sì mú agbo ilé Sera. Ó sì mú agbo ilé Sera wá síwájú ní ìdílé kọ̀ọ̀kan, a sì mú ìdílé Sabdi.
18 Na ka arahi ia i tona whare, i tenei tangata, i tenei tangata; a ka mau ko Akana tama a Karami, tama a Taperi, tama a Tera, no te iwi o Hura.
Joṣua sì mú ìdílé Simri wá síwájú ní ọkùnrin kọ̀ọ̀kan, a sì mú Akani ọmọ Karmi, ọmọ Sabdi, ọmọ Sera ti ẹ̀yà Juda.
19 Katahi a Hohua ka mea ki a Akana, E taku tama, whakakororiatia a Ihowa, te Atua o Iharaira, a whakina ki a ia, whakaaturia mai hoki ki ahau, i aha koe; kaua e huna i ahau.
Nígbà náà ní Joṣua sọ fún Akani pé, “Ọmọ mi fi ògo fún Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, kí o sì fi ìyìn fún un. Sọ fún mi ohun tí ìwọ ti ṣe, má ṣe fi pamọ́ fún mi.”
20 Na ka whakautua e Akana ki a Hohua, ka mea, He pono i hara ahau ki a Ihowa, ki te Atua o Iharaira, a tenei taku i mea ai:
Akani sì dáhùn pé, “Òtítọ́ ni! Mo ti ṣẹ̀ sí Olúwa, Ọlọ́run Israẹli. Nǹkan tí mo ṣe nìyìí,
21 I taku kitenga i tetahi koroka whakapaipai no Papurona i roto i nga taonga, i nga hekere hiriwa e rua rau, i tetahi poro koura, e rima tekau hekere tona taimaha, na ka minamina ahau, ka tango; a tera kei te whenua i waenganui o toku teneti e hun a ana, me te hiriwa hoki kei raro iho.
nígbà tí mo rí ẹ̀wù Babeli kan tí ó dára nínú ìkógun, àti igba ṣékélì fàdákà àti odindi wúrà olóṣùnwọ́n àádọ́ta ṣékélì, mo ṣe ojúkòkòrò wọn mo sì mú wọn. Mo fi wọ́n pamọ́ ní abẹ́ àgọ́ mi àti fàdákà ní abẹ́ rẹ̀.”
22 Na ka tonoa atu e Hohua etahi tangata, a ko to ratou rerenga atu ki te teneti; na ko taua mea e huna ana i roto i tona teneti, me te hiriwa i raro iho.
Bẹ́ẹ̀ ni Joṣua ran àwọn òjíṣẹ́, wọ́n sì sáré wọ inú àgọ́ náà, ó sì wà níbẹ̀, a sì fi pamọ́ nínú àgọ́ ọ rẹ̀, àti fàdákà ní abẹ́ ẹ rẹ̀.
23 Na tangohia ana e ratou aua mea i waenganui o te teneti, a mauria ana ki a Hohua ratou ko nga tama katoa a Iharaira, a whakatakotoria ana ki te aroaro o Ihowa.
Wọ́n sì mú àwọn nǹkan náà jáde láti inú àgọ́ rẹ̀, wọ́n mú wọn wá fún Joṣua àti gbogbo àwọn ọmọ Israẹli, wọ́n sì fi wọ́n lélẹ̀ níwájú Olúwa.
24 Na ka tango a Hohua ratou tahi ko Iharaira katoa i a Akana tama a Tera, i te hiriwa, i te koroka, i te poro koura, i ana tama, i ana tamahine, i ana kau, i ana kaihe, i ana hipi, i tona teneti, i nga mea katoa hoki i a ia, a kawea ana ratou ki t e raorao o Akoro.
Nígbà náà ni Joṣua pẹ̀lú gbogbo Israẹli, mú Akani ọmọ Sera, fàdákà, ẹ̀wù àti wúrà tí a dà, àwọn ọmọ rẹ̀ ọkùnrin àti obìnrin, màlúù rẹ̀, kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ àti àgùntàn àgọ́ rẹ̀ àti gbogbo ohun tí ó ni, wọ́n sì kó wọn lọ sí ibi àfonífojì Akori.
25 Na ka mea a Hohua, Na te aha koe i whakararu ai i a tatou? ka whakararu hoki a Ihowa i a koe i tenei ra. Na akina ana ia e Iharaira katoa ki te kamaka, a tahuna ana ki te ahi i muri iho i ta ratou akinga i a ratou ki te kamaka.
Joṣua sì wí pé, “Èéṣe tí ìwọ mú wàhálà yìí wá sí orí wa? Olúwa yóò mú ìpọ́njú wá sí orí ìwọ náà lónìí.” Nígbà náà ni gbogbo Israẹli sọ ọ́ ní òkúta pa, lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n sọ àwọn tókù ní òkúta pa tán, wọ́n sì jó wọn níná.
26 A whakapurangatia ana e ratou etahi kohatu ki runga i a ia, he nui te ra. Katahi ka tahuri a Ihowa i te muranga o tona riri. Na reira i huaina ai te ingoa o taua wahi, Ko te raorao o Akoro a mohoa noa nei.
Wọ́n sì kó òkìtì òkúta ńlá lé Akani lórí títí di òní yìí. Nígbà náà ní Olúwa sì yí ìbínú gbígbóná rẹ̀ padà. Nítorí náà ni a ṣe ń pe orúkọ ibẹ̀ ní àfonífojì Akori láti ìgbà náà.

< Hohua 7 >