< Heremaia 7 >
1 Ko te kupu i a Heremaia, he mea na Ihowa; i ki mai ia,
Èyí ni ọ̀rọ̀ tó tọ Jeremiah wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa.
2 E tu ki te kuwaha o te whare o Ihowa, ka karanga i tenei kupu ki reira, ka mea, Whakarongo ki te kupu a Ihowa, e Hura katoa e tomo nei ki enei kuwaha ki te koropiko ki a Ihowa.
“Dúró ní ẹnu-ọ̀nà ilé Olúwa kí o sì kéde ọ̀rọ̀ yí: “‘Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa gbogbo ẹ̀yin ará Juda tí ń gba ọ̀nà yí wọlé láti wá sin Olúwa.
3 Ko te kupu tenei a Ihowa o nga mano, a te Atua o Iharaira, Whakapaia o koutou ara me a koutou mahi, a ka meinga e ahau kia noho koutou ki tenei wahi.
Èyí ni ọ̀rọ̀ tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí: Tún àwọn ọ̀nà yín ṣe, èmi yóò sì jẹ́ kí ẹ gbé ilẹ̀ yìí.
4 Kei whakawhirinaki ki nga kupu teka noa, kei ki, Ko te temepara o Ihowa, ko te temepara o Ihowa, ko te temepara o Ihowa enei.
Má ṣe gba ọ̀rọ̀ ẹ̀tàn gbọ́ kí ẹ sì wí pé, “Èyí ni tẹmpili Olúwa ilé tẹmpili Olúwa, ilé tẹmpili Olúwa!”
5 Ki te whakapaia rawatia hoki o koutou ara, me a koutou mahi; ki te mea ka tika rawa ta koutou whakarite whakawa i waenganui i te tangata raua ko tona hoa;
Bí ẹ̀yin bá tún ọ̀nà yín àti iṣẹ́ yín ṣe nítòótọ́, tí ẹ sì ń bá ara yín lò ní ọ̀nà tó tọ́.
6 Ki te kore koutou e tukino i te manene, i te pani, i te pouaru, a kahore e whakaheke i nga toto o te harakore ki tenei wahi, kahore hoki e haere, e whai i nga atua ke hei he mo koutou:
Bí ẹ kò bá fi ara ni àwọn àlejò, àwọn ọmọ aláìní baba àti àwọn opó tí ẹ kò sì ta ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sílẹ̀ ní ibí yìí, bí ẹ kò bá sì tọ ọlọ́run mìíràn lẹ́yìn sí ìpalára ara yín.
7 Katahi ahau ka mea i a koutou kia noho ki tenei wahi, ki te whenua i hoatu e ahau ki o koutou matua inamata ake ake.
Nígbà náà ni èmi yóò jẹ́ kí ẹ gbé ìbí yìí, nílẹ̀ tí mo fún àwọn baba ńlá yín títí láé.
8 Nana, kei te whakawhirinaki na koutou ki nga kupu teka, kahore nei he pai.
Ẹ wò ó, ẹ ń gba ọ̀rọ̀ ẹ̀tàn tí kò níláárí gbọ́.
9 E tahae ranei koutou, e patu tangata, e puremu? e oati teka ranei? e tahu whakakakara ranei ki a Paara, e whai ranei i nga atua ke kihai i matauria e koutou;
“‘Ẹ̀yin yóò ha jalè, kí ẹ pànìyàn, kí ẹ ṣe panṣágà, kí ẹ búra èké, kí ẹ sun tùràrí sí Baali, kí ẹ sì tọ ọlọ́run mìíràn tí ẹ̀yin kò mọ̀ lọ?
10 A ka haere mai, ka tu ki toku aroaro i tenei whare kua huaina nei ki toku ingoa, ka mea, Kua ora matou; kia mahi ai koutou i enei mea whakarihariha katoa?
Nígbà náà ni kí ó wá dúró ní iwájú nínú ilé yìí tí a fi orúkọ mi pè, “Kí ẹ wá wí pé àwa yè,” àwa yè láti ṣe gbogbo àwọn nǹkan ìríra wọ̀nyí bí?
11 Ki ta koutou titiro kua waiho koia hei ana mo nga kaipahua tenei whare kua huaina nei ki toku ingoa? Nana, kua kite ahau, ahau nei ano, e ai ta Ihowa.
Ṣé ilé yìí, tí a fi orúkọ mi pè ti di ihò àwọn ọlọ́ṣà lọ́dọ̀ yín ni? Èmi ti ń wò ó! ni Olúwa wí.
12 Engari haere ra ki toku wahi i Hiro, ki te wahi i whakanohoia mataatitia ai e ahau toku ingoa, tirohia taku i mea ai ki reira mo te kino o taku iwi, o Iharaira.
“‘Ẹ lọ nísinsin yìí sí Ṣilo níbi ti mo kọ́ fi ṣe ibùgbé fún orúkọ mi, kí ẹ sì rí ohun tí mo ṣe sí i nítorí ìwà búburú Israẹli tí í ṣe ènìyàn mi.
13 Na, inaianei, i ta koutou meatanga i enei mea katoa, e ai ta Ihowa, i korero ano ahau ki a koutou; maranga wawe ana ahau, korero ana, heoi kihai koutou i rongo mai; karanga ana ahau ki a koutou, a kihai i utua taku;
Nígbà tí ẹ̀yin ń ṣe àwọn nǹkan wọ̀nyí ni èmi bá a yín sọ̀rọ̀ léraléra ni Olúwa wí ẹ̀yin kò gbọ́, èmi pè yín, ẹ̀yin kò dáhùn.
14 Na, ko taku e mea ai ki tenei whare i huaina nei ki toku ingoa, ki ta koutou e whakawhirinaki nei, ki te wahi ano i hoatu nei e ahau ki a koutou, ki o koutou matua, ka rite ki taku i mea ai ki Hiro.
Nítorí náà, èmi yóò ṣe ohun tí mo ṣe sí Ṣilo sí ilé náà tí a fi orúkọ mi pè, ilé tẹmpili nínú èyí tí ẹ ní ìgbẹ́kẹ̀lé, ààyè tí mo fún ẹ̀yin àti àwọn baba yín.
15 Ka akiritia atu ano koutou e ahau i toku aroaro, ka peratia me taku akiritanga i o koutou teina katoa, i nga uri katoa o Eparaima.
Èmi yóò tú kúrò ní iwájú mi gẹ́gẹ́ bí mo ti ṣe sí àwọn arákùnrin yín, àwọn ará Efraimu.’
16 Heoi, kaua koe e inoi mo tenei iwi; kei ara hoki tetahi tangi, tetahi kupu wawao au mo ratou, kaua hoki ahau e whakamarietia, no te mea e kore ahau e rongo ki a koe.
“Nítorí náà má ṣe gbàdúrà fún àwọn ènìyàn wọ̀nyí tàbí kí o bẹ̀bẹ̀ fún wọn; ma ṣe bẹ̀ mí, nítorí èmi kì yóò tẹ́tí sí ọ.
17 Kahore ianei koe i te kite i ta ratou e mea nei i nga pa o Hura, i nga ara ano o Hiruharama?
Ṣé ìwọ kò rí ohun tí wọ́n ń ṣe ní àwọn ìlú Juda àti ní òpópó Jerusalẹmu?
18 Ko nga tamariki kei te kohikohi wahie, ko nga matua kei te whakau i te ahi, ko nga wahine kei te pokepoke i te paraoa hei hanga i etahi keke, he mea ki te kuini o te rangi, riringi tonu iho i te ringihanga ki nga atua ke, hei whakapataritari i a hau.
Àwọn ọmọ ṣa igi jọ, àwọn baba fi iná sí i, àwọn ìyá sì po ìyẹ̀fun láti ṣe àkàrà fún ayaba ọ̀run, wọ́n tú ẹbọ ọrẹ mímu sí àwọn ọlọ́run àjèjì láti ru bínú mi sókè.
19 He whakapataritari ranei ta ratou ki ahau? e ai ta Ihowa; te teka ianei ki a ratou ano, a whakama iho o ratou mata?
Ṣùgbọ́n ṣe èmi ni wọ́n fẹ́ mú bínú? ni Olúwa wí. Ǹjẹ́ kì í ṣe pé wọ́n kúkú ń pa ara wọn lára sí ìtìjú ara wọn?
20 Na, ko te kupu tenei a te Ariki, a Ihowa, Nana, ka ringihia toku riri, toku aritarita, ki runga ki tenei wahi, ki runga ki te tangata, ki te kararehe, ki te rakau o te mara, ki nga hua o te oneone; a ka ngiha, e kore ano e tineia.
“‘Nítorí náà, èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí, “Èmi yóò tú ìbínú àti ìrunú mi sí orílẹ̀ yìí ènìyàn àti ẹranko, igi, pápá àti èso orí ilẹ̀, yóò sì jó tí kò ní ṣe é pa.”
21 Ko te kupu tenei a Ihowa o nga mano, a te Atua o Iharaira, Ko a koutou tahunga tinana tapiritia iho ki runga ki a koutou patunga tapu, kainga hoki he kikokiko.
“‘Èyí ni Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run Israẹli wí: Tẹ̀síwájú kí ẹ kó ẹbọ sísun yín àti àwọn ẹbọ yòókù papọ̀ kí ẹ̀yin kí ó sì jẹ ẹran wọ́n fúnra yín.
22 Kahore hoki aku korero ki o koutou matua, kahore aku whakahau ki a ratou i te ra i kawea mai ai ratou e ahau i te whenua o Ihipa, mo nga tahunga tinana, mo nga patunga tapu.
Ní tòsí nígbà tí mo mú àwọn baba ńlá yín jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti tí mo sì bá wọn sọ̀rọ̀. N kò pàṣẹ fún wọn lórí ẹbọ sísun lásán.
23 Engari ko te kupu tenei i whakahaua e ahau ki a ratou; i ki ahau, Whakarongo ki toku reo, a hei Atua ahau mo koutou, ko koutou hoki hei iwi maku, me haere ano koutou i runga i te ara katoa ka whakahaua nei e ahau ki a koutou, kia whiwhi ai ki te pai.
Mo pàṣẹ fún wọn báyìí pé; gbọ́ tèmi, èmi yóò sì jẹ́ Ọlọ́run yín ẹ̀yin yóò sì jẹ́ ènìyàn mi. Máa rìn ní ojú ọ̀nà tí mo pàṣẹ fún yín, kí ó lè dára fún yín.
24 Otiia kihai ratou i rongo, kihai ano i tahuri to ratou taringa; na haere ana ratou i runga i o ratou ake whakaaro, i nga tikanga pakeke o o ratou ngakau kino; ko ta ratou he anga ki muri, kihai hoki i anga ki mua.
Ṣùgbọ́n wọn kò gbọ́, wọn kò sì fetísílẹ̀ dípò èyí wọ́n ń tẹ̀ sí ọ̀nà agídí ọkàn wọn. Dípò kí wọn tẹ̀síwájú wọ́n ń rẹ̀yìn.
25 No te ra i haere mai ai o koutou matua i te whenua o Ihipa tae mai ki tenei ra taku tononga atu i aku pononga katoa, i nga poropiti, ki a koutou, maranga wawe ana ahau i tenei ra, i tenei ra, unga ana ratou e ahau.
Láti ìgbà tí àwọn baba ńlá yín ti jáde ní Ejibiti títí di òní, ni èmi ti ń rán àwọn ìránṣẹ́ mi, àwọn wòlíì sí yín.
26 Heoi kihai ratou i rongo ki ahau, kihai ano i tahuri to ratou taringa; na whakapakeketia ana e ratou to ratou kaki: kino iho ta ratou i ta o ratou matua.
Wọn kò gbọ́ wọn kò sì fetísílẹ̀. Wọ́n wa ọrùn le, wọn wa ọrùn kì, wọ́n sì hu ìwà ìbàjẹ́ ju àwọn baba ńlá wọn.’
27 Na mau e korero enei kupu katoa ki a ratou, e kore ia ratou e rongo ki a koe: karanga ki a ratou; e kore ano e utua tau.
“Nígbà tí ìwọ bá sọ gbogbo èyí fún wọn, wọn kì yóò gbọ́ tirẹ̀, nígbà tí ìwọ bá sì pè wọ́n, wọn kì yóò dáhùn.
28 A me ki atu ki a ratou, Ko te iwi tenei kihai nei i rongo ki te reo o Ihowa, o to ratou Atua, kihai hoki i pai ki te ako: kua kore te pono, kua tapahia atu i to ratou mangai.
Nítorí náà, sọ fún wọn pé, ‘Èyí ni orílẹ̀-èdè tí kò gbọ́ ti Olúwa Ọlọ́run rẹ̀ tàbí kí ó ṣe ìgbọ́ràn sí ìbáwí. Ọ̀rọ̀ òtítọ́ kò sí ní ètè wọn.
29 Waruhia ou makawe, e Hiruharama, maka atu, anga atu ki te tangi ki runga ki nga wahi tiketike: kua paopaongia nei hoki e Ihowa, kua whakarerea te whakatupuranga i riri ai ia.
“‘Gé irun yín kí ẹ sì dàánù, pohùnréré ẹkún lórí òkè, nítorí Olúwa ti kọ ìran yìí tí ó wà lábẹ́ ìbínú rẹ̀ sílẹ̀.
30 He kino hoki te mahi a nga tama a Hura ki taku titiro, e ai ta Ihowa; whakaturia ake e ratou a ratou mea whakarihariha ki te whare kua huaina nei ki toku ingoa, whakapokea iho e ratou.
“‘Àwọn ènìyàn Juda ti ṣe búburú lójú mi, ni Olúwa wí. Wọ́n ti to àwọn ère ìríra wọn jọ sí ilé tí a fi orúkọ mi pè wọ́n sì ti sọ ọ́ di àìmọ́.
31 Hanga ake e ratou nga wahi tiketike o Topete, o tera i te raorao o te tama a Hinomo, hei tahunga mo a ratou tama, mo a ratou tamahine ki te ahi; he mea kihai nei i whakahaua e ahau, kihai ano i puta ake i roto i toku ngakau.
Wọ́n ti kọ́ àwọn ibi gíga ti Tofeti ní àfonífojì Beni-Hinnomu láti sun àwọn ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin wọn nínú iná èyí tí èmi kò pàṣẹ tí kò sì wá sí ọkàn mi.
32 Mo reira, na, kei te haere mai nga ra, e ai ta Ihowa, e kore ai e kiia i muri, Ko Topete, Ko te raorao o te tama a Hinomo, ranei; engari Ko te raorao i te parekura: ka tanu tangata hoki ratou ki Topete, a kia kore ra ano he wahi hei tanumanga.
Nítorí náà kíyèsára ọjọ́ ń bọ̀, ni Olúwa wí, nígbà tí àwọn ènìyàn kò ní pè é ní Tafeti tàbí àfonífojì ti Beni-Hinnomu; ṣùgbọ́n yóò ma jẹ àfonífojì ìparun, nítorí wọn yóò sin òkú sí Tofeti títí kò fi ní sí ààyè mọ́.
33 A ka waiho nga tinana o tenei iwi hei kai ma nga manu o te rangi, ma nga kararehe o te whenua; kahore hoki he kaiwhakawehi atu.
Nígbà náà ni òkú àwọn ènìyàn wọ̀nyí yóò di oúnjẹ fún àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run àti ẹranko ilẹ̀, kò sì ní sí ẹnìkan tí yóò dẹ́rùbà wọ́n.
34 Ka whakamutua ano e ahau i roto i nga pa o Hura, i nga ara ano o Hiruharama, te reo koa, te reo hari, te reo o te tane marena hou, te reo o te wahine marena hou: no te mea ka ururuatia te whenua.
Èmi yóò mú òpin bá ìró ayọ̀ àti ìdùnnú àti ohùn àwọn tọkọtaya ní àwọn ìlú Juda àti ní ìgboro Jerusalẹmu, nítorí tí ilẹ̀ náà yóò di ahoro.