< Heremaia 31 >

1 I taua wa, e ai ta Ihowa, ka waiho ahau hei Atua mo nga hapu katoa o Iharaira, ko ratou hoki hei iwi maku.
“Nígbà náà, Èmi yóò jẹ́ Ọlọ́run fún gbogbo ìdílé ìran Israẹli, àwọn náà yóò sì jẹ́ ènìyàn mi,” ni Olúwa wí.
2 Ko te kupu tenei a Ihowa, Ko te iwi i toe i te hoari, i kite i te manako ki te koraha; ara a Iharaira, i ahau i haere atu ai ki te mea tanga manawa mona.
Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Àwọn ènìyàn tí ó sá àsálà lọ́wọ́ idà yóò rí ojúrere Olúwa ní aṣálẹ̀, Èmi yóò sì fi ìsinmi fún Israẹli.”
3 I puta mai a Ihowa ki ahau i mua noa atu, i mea mai, Ae ra, he aroha pumau toku i aroha ai ahau ki a koe: na reira te atawhai i kukume ai ahau i a koe.
Olúwa ti fi ara rẹ̀ hàn wá ní ìgbà kan rí, ó wí pé: “Èmi ti nífẹ̀ẹ́ yín pẹ̀lú ìfẹ́ àìlópin; mo ti fi ìfẹ́ ńlá fà yín,
4 Ka hanga ano koe e ahau, a ka oti koe te hanga, e te wahine o Iharaira: tera ano koe ka whakapaipaia ki au timipera, a ka haere atu i roto i nga kanikani a te hunga harakoa.
Èmi yóò tún gbé e yín sókè, àní a ó tún gbé e yín ró ìwọ wúńdíá ilẹ̀ Israẹli. Àní ẹ ó tún tún ohun èlò orin yín gbé, ẹ ó sì jáde síta pẹ̀lú ijó àti ayọ̀.
5 Tera koe e whakato ano he mara waina ki runga ki nga maunga o Hamaria: ka whakato nga kaiwhakato, a ka kai i ona hua.
Ẹ ó tún gbin ọgbà àjàrà ní orí òkè Samaria; àwọn àgbẹ̀ yóò sì máa gbádùn èso oko wọn.
6 No te mea tena ano te ra, e karanga ai nga kaitiaki i runga i nga pukepuke o Eparaima, Whakatika, tatou ka haere ki runga, ki Hiona, ki a Ihowa, ki to tatou Atua.
Ọjọ́ kan máa wà tí àwọn olùṣọ́ yóò kígbe jáde lórí òkè Efraimu wí pé, ‘Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a gòkè lọ sí Sioni, ní ọ̀dọ̀ Olúwa Ọlọ́run wa.’”
7 Ko te kupu hoki tenei a Ihowa, Waiata i runga i te koa ki a Hakopa, hamama mo te metararahi o nga iwi: korerotia atu, whakamoemititia, mea atu, E Ihowa, whakaorangia tau iwi, te morehu o Iharaira.
Èyí ni ọ̀rọ̀ tí Olúwa sọ wí pé: “Ẹ fi ayọ̀ kọrin sí Jakọbu; ẹ hó sí olórí àwọn orílẹ̀-èdè gbogbo. Jẹ́ kí wọ́n gbọ́ ìyìn rẹ kí o sì wí pé, ‘Olúwa, gba àwọn ènìyàn rẹ là; àwọn tí ó ṣẹ́kù ní Israẹli.’
8 Nana, ka kawea mai ratou e ahau i te whenua ki te raki, ka kohikohia mai i nga topito o te whenua, me nga matapo, me nga kopa, me te wahine e hapu ana, me te wahine hoki e whakamamae ana, i o ratou taha; he hui nui tonu ratou e hoki mai ai ki kon ei.
Wò ó, Èmi yóò mú wọn wá láti ilẹ̀ àríwá; èmi yóò kó gbogbo wọn jọ láti òpin ayé. Lára wọn ni yóò jẹ́ afọ́jú àti arọ, aboyún àti obìnrin tí ń rọbí, ọ̀pọ̀ ènìyàn yóò wá.
9 Ka haere mai ratou me te tangi, a ka arahina ratou e ahau i runga i te inoi: ka meinga ratou e ahau kia haere i te taha o nga awa wai, ma te ara tika e kore ai o ratou waewae e tutuki i reira; no te mea he papa ahau ki a Iharaira, a ko Eparaima t aku matamua.
Wọn yóò wá pẹ̀lú ẹkún, wọn yóò gbàdúrà bí Èmi yóò ṣe mú wọn padà. Èmi yóò jẹ́ atọ́nà fún wọn ní ẹ̀bá odò omi; ní ọ̀nà tí ó tẹ́jú tí wọn kì yóò le ṣubú, nítorí èmi ni baba Israẹli, Efraimu sì ni àkọ́bí ọkùnrin mi.
10 Whakarongo ki te kupu a Ihowa, e nga iwi, korerotia hoki ki nga motu o tawhiti, mea atu, Ko te kaititaritari o Iharaira, mana ratou e whakawhaiti, mana ratou e tiaki, ka rite ki ta te hepara i tana kahui.
“Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa ẹ̀yin orílẹ̀-èdè ẹ kéde rẹ̀ ní erékùṣù jíjìn; ‘Ẹni tí ó bá tú Israẹli ká yóò kójọ, yóò sì ṣọ́ agbo rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí olùṣọ́-àgùntàn.’
11 Kua hokona nei hoki a Hakopa e Ihowa, utua ana e ia, tangohia mai ana i roto i te ringa o te mea i kaha rawa i a ia.
Nítorí Olúwa ti tú Jakọbu sílẹ̀, o sì rà á padà ní ọwọ́ àwọn tí ó lágbára jù ú lọ.
12 Na ka haere mai ratou ka waiata i te wahi tiketike o Hiona, ka rere huihui ki te pai o Ihowa, ki te witi, ki te waina, ki te hinu, a ki nga kuao hipi, kuao kau: a ka rite o ratou wairua ki te kari kua oti te whakamakuku; a ka tino mutu rawa ta r atou tangi.
Wọn yóò wá, wọn ó sì hó ìhó ayọ̀ lórí òkè Sioni; wọn yóò yọ ayọ̀ níbi oore Olúwa. Àlìkámà ni, ọtí wáìnì tuntun àti òróró ọ̀dọ́-àgùntàn àti ọ̀dọ́ ọ̀wọ́ ẹran. Wọn ó dàbí ọgbà àjàrà tí a bomirin, ìkorò kò ní bá wọn mọ́.
13 Katahi te wahine ka koa ki te kanikani, me nga taitama ngatahi ko nga kaumatua: ka meinga hoki e ahau ta ratou tangi hei koa, ka whakamarietia ratou, a ka meinga ratou kia hari i o ratou mamae.
Àwọn wúńdíá yóò jó, wọn ó sì kún fún ayọ̀, bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni ọkùnrin àti obìnrin. Èmi yóò sọ ọ̀fọ̀ wọn di ayọ̀, dípò ìkorò èmi yóò tù wọ́n nínú. Èmi ó sì fún wọn ní ayọ̀.
14 Ka whakatinaia e ahau te wairua o nga tohunga ki te ngako, ka makona ano toku iwi i toku pai, e ai ta Ihowa.
Èmi ó tẹ́ àwọn àlùfáà lọ́rùn pẹ̀lú ọ̀pọ̀; àwọn ènìyàn mi yóò sì kún fún oore mi,” ni Olúwa wí.
15 Ko te kupu tenei a Ihowa, I rangona he reo ki Rama, he uhunga, he tangi, tiwerawera ana, ko Rahera e tangi ana ki ana tamariki, a kihai i pai kia whakamarietia mo ana tamariki, kua kahore nei.
Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “A gbọ́ ohùn kan ní Rama tí ń ṣọ̀fọ̀ pẹ̀lú ẹkún kíkorò. Rakeli ń sọkún àwọn ọmọ rẹ̀; kò gbà kí wọ́n tu òun nínú, nítorí àwọn ọmọ rẹ̀ kò sí mọ́.”
16 Ko te kupu tenei a Ihowa, Whakamutua te tangi o tou reo, nga roimata hoki i ou kanohi; no te mea ka whai utu tau mahi, e ai ta Ihowa; a ka hoki mai ano ratou i te whenua o te hoariri.
Báyìí ni Olúwa wí: “Dá ohùn rẹ dúró nínú ẹkún àti ojú rẹ nínú omijé; nítorí a ó fi èrè sí iṣẹ́ rẹ,” ni Olúwa wí. “Wọn ó sì padà wá láti ilẹ̀ ọ̀tá.
17 Ka whai tumanakohanga hoki tou mutunga, e ai ta Ihowa, a ka hoki mai au tamariki ki to ratou ake rohe.
Nítorí ìrètí wà fún ọjọ́ iwájú rẹ,” ni Olúwa wí. “Àwọn ọmọ rẹ yóò padà wá sí ilẹ̀ wọn.
18 He pono kua rongo ahau i a Eparaima e tangi ana ki a ia ano, penei, Kua pakia ahau e koe, a i pakia ahau, pera i te kuao kau kihai i whakaakona ki te ioka: whakatahuritia ahau, a ka tahuri ahau; ko koe nei hoki a Ihowa, toku Atua.
“Nítòótọ́, èmi ti gbọ́ ìpohùnréré Efraimu wí pé, ‘Ìwọ ti bá mi wí gẹ́gẹ́ bí ọmọ màlúù tí a kò kọ́ èmi sì ti gbọ́ ìbáwí. Rà mí padà, èmi yóò sì yípadà, nítorí ìwọ ni Olúwa Ọlọ́run mi.
19 He pono i muri i toku tahuritanga, i ripeneta ahau; a i muri i toku whakaakoranga i papaki ahau ki toku huha: i whakama ahau, ae ra, i numinumi kau, no te mea e waha ana e ahau te ingoa kino o toku taitamarikitanga.
Lẹ́yìn tí èmi ti yípadà, mo ronúpìwàdà, lẹ́yìn tí èmi ti wá mọ̀, èmi lu àyà mi. Ojú tì mí, mo sì dààmú; nítorí èmi gba èrè ẹ̀gàn ìgbà èwe mi.’
20 He tamaiti matenui ianei a Eparaima naku? he tamaiti ahuareka ianei? no te mea ka korero ana ahau i te he mona, mau tonu toku maharahara ki a ia: no reira oku whekau i oho ai ki a ia; he pono ka tohungia ia e ahau, e ai ta Ihowa.
Efraimu kì í ha í ṣe ọmọkùnrin mi dáradára tí inú mi dùn sí bí? Bí èmi ti ń sọ̀rọ̀ sí i tó, síbẹ̀, èmi rántí rẹ̀. Nítorí náà, ọkàn mi ṣe ohun kan fún un, èmi káàánú gidigidi fún un,” ni Olúwa wí.
21 Whakaturia ake etahi tohu ara mau, hanga he pou waitohu: e anga tou ngakau ki te huanui, ki te ara i haere ai koe: hoki mai, e te wahine o Iharaira, hoki mai ano ki enei pa ou.
“Gbé àmì ojú ọ̀nà dìde, ṣe atọ́nà àmì, kíyèsi òpópó ọ̀nà geere ojú ọ̀nà tí ó ń gbà. Yípadà ìwọ wúńdíá Israẹli, padà sí àwọn ìlú rẹ.
22 Kia pehea te roa o tou kopikopiko, e te tamahine tahurihuri ke? kua hanga hoki e Ihowa he mea hou ki runga ki te whenua, Ka karapoti te wahine i te tane.
Ìwọ yóò ti ṣìnà pẹ́ tó, ìwọ aláìṣòótọ́ ọmọbìnrin; Olúwa yóò dá ohun tuntun lórí ilẹ̀, ọmọbìnrin kan yóò yí ọkùnrin kan ká.”
23 Ko te kupu tenei a Ihowa o nga mano, a te Atua o Iharaira, Tenei ake ka korerotia ano tenei kupu ki te whenua o Hura, ki ona pa hoki, ina whakahokia mai ratou e ahau i te whakarau: Kia manaaki a Ihowa i a koe, e te nohoanga o te tika, e te maung a o te tapu.
Báyìí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Israẹli wí: “Nígbà tí èmi bá kó wọn dé láti ìgbèkùn; àwọn ènìyàn tí ó wà ní ilẹ̀ Juda àti ní àwọn ìlú rẹ̀ yóò tún lo àwọn ọ̀rọ̀ yìí lẹ́ẹ̀kan sí i; wí pé, ‘Kí Olúwa kí ó bùkún fún ọ, ìwọ ibùgbé òdodo, ìwọ òkè ìwà mímọ́.’
24 A ka noho tahi a Hura me ona pa katoa ki reira; te hunga ngaki i te whenua me te hunga ano e haere tahi ana me nga kahui.
Àwọn ènìyàn yóò gbé papọ̀ ní Juda àti ní gbogbo àwọn ìlú rẹ̀; bákan náà ni àgbẹ̀ àti àwọn tí ń tẹ̀lé agbo ẹran wọn ká.
25 Kua tino whakamakonatia hoki e ahau te wairua ruha, kua whakakiia ano nga wairua katoa e pouri ana.
Èmi yóò sọ aláàárẹ̀ di ọ̀tun, èmi yóò sì tẹ́ gbogbo ọkàn tí ń káàánú lọ́rùn.”
26 I konei ka maranga ahau, a ka titiro; na he reka ki ahau taku moe.
Lórí èyí ni mo jí, mo sì wò yíká, oorun mi sì dùn mọ́ mi.
27 Nana, kei te haere mai nga ra, e ai ta Ihowa, e whakatokia ai e ahau te whare o Iharaira me te whare o Hura ki te purapura tangata, ki te purapura kararehe.
“Wò ó, ọjọ́ ń bọ̀,” ni Olúwa wí, “nígbà tí èmi yóò gbin ilé Israẹli àti ilé Juda pẹ̀lú irúgbìn ọmọ ènìyàn àti ẹranko.
28 Na ka pera i ahau i tiaki ai i a ratou i mua, he mea kia hutia ake, kia wahia iho, kia turakina ki raro, kia whakangaromia, kia tukinotia; ka pera ano taku tiaki i a ratou, he mea kia hanga, kia whakatokia, e ai ta Ihowa.
Gẹ́gẹ́ bí mo ṣe ń ṣọ́ wọn, láti fàtu, àti láti wó lulẹ̀, àti láti gba ìṣàkóso, láti bàjẹ́ àti láti mú ibi wá, bẹ́ẹ̀ ni èmi yóò ṣọ́ wọn láti kọ́ àti láti gbìn,” ni Olúwa wí.
29 I aua ra ka mutu ta ratou ki, Kua kai nga matua i nga karepe kaiota, a moniania ana nga niho o nga tamariki.
“Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì àwọn ènìyàn kò ní sọ mọ́ pé: “‘Àwọn baba ti jẹ èso àjàrà àìpọ́n àti pé eyín kan àwọn ọmọdé.’
30 Engari ka mate tenei, tenei, i runga i tona kino, i tona kino: ko nga tangata katoa e kai ana i te karepe kaiota, ko ona niho ano e moniania.
Ṣùgbọ́n olúkúlùkù ni yóò kú fún ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀, ẹnikẹ́ni tí ó bá jẹ èso kíkan ni eyín yóò kan.
31 Nana, kei te haere mai nga ra, e ai ta Ihowa, e whakaritea ai e ahau he kawenata hou ki te whare o Iharaira, ki te whare hoki o Hura:
“Ìgbà kan ń bọ̀,” ni Olúwa wí, “tí Èmi yóò bá ilé Israẹli àti ilé Juda dá májẹ̀mú tuntun.
32 E kore ano ia e rite ki te kawenata i whakaritea e ahau ki o ratou matua i te ra i pupuri ai ahau ki o ratou ringa, a kawea mai ana ratou i te whenua o Ihipa; whakataka ana e ratou taua kawenata aku, ahakoa i waiho ahau hei tahu marena ma ratou, e ai ta Ihowa.
Kò ní dàbí májẹ̀mú tí mo bá àwọn baba ńlá wọn dá, nígbà tí mo fà wọ́n lọ́wọ́, tí mo mú wọn jáde ní Ejibiti nítorí wọ́n da májẹ̀mú mi. Lóòótọ́ ọkọ ni èmi jẹ́ fún wọn,” ni Olúwa wí.
33 Engari ko te kawenata tenei e whakaritea e ahau ki te whare o Iharaira i muri i aua ra, e ai ta Ihowa; Ka hoatu e ahau taku ture ki o ratou wahi i roto, ka tuhituhia ano ki to ratou ngakau; a ko ahau hei Atua mo ratou, ko ratou hei iwi maku.
“Èyí ni májẹ̀mú tí èmi yóò bá ilé Israẹli dá lẹ́yìn ìgbà náà,” ni Olúwa wí pé: “Èmi yóò fi òfin mi sí ọkàn wọn, èmi ó sì kọ ọ́ sí àyà wọn. Èmi ó jẹ́ Olúwa wọn; àwọn ó sì jẹ́ ènìyàn mi.
34 I muri nei kahore he whakaako a tetahi i tona hoa tata, a tetahi i tona teina, kahore he ki atu, Kia mohio ki a Ihowa; ka mohio hoki ratou katoa ki ahau, i te iti o ratou tae noa ki te mea rahi rawa, e ai ta Ihowa: no te mea ka whakarerea noatia e ahau to ratou kino, a heoi ano oku mahara ki to ratou hara.
Kò ní sí pé ọkùnrin kan ń kọ́ àwọn ará ilé rẹ̀ tàbí ọkùnrin ń kọ́ arákùnrin rẹ̀ pé, ‘Ẹ mọ Olúwa,’ nítorí gbogbo wọn ni yóò mọ̀ mí láti ẹni kékeré wọn títí dé ẹni ńlá,” ni Olúwa wí. “Nítorí èmi ó dárí àìṣedéédéé wọn jì, èmi kò sì ní rántí ẹ̀ṣẹ̀ wọn mọ́.”
35 Ko te kupu tenei a Ihowa, nana nei i homai te ra hei whakamarama i te awatea, me nga tikanga o te marama, o nga whetu, hei whakamarama i te po, nana hoki i whakatutehu te moana, i nganga ai ona ngaru; ko Ihowa o nga mano tona ingoa:
Èyí ni ohun tí Olúwa wí: ẹni tí ó mú oòrùn tan ìmọ́lẹ̀ ní ọ̀sán, tí ó mú òṣùpá àti ìràwọ̀ ràn ní òru; tí ó rú omi Òkun sókè tó bẹ́ẹ̀ tí ìjì rẹ̀ fi ń hó Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni orúkọ rẹ̀.
36 Ki te mawehe atu enei tikanga i toku aroaro, e ai ta Ihowa, ko reira ano ka kore te uri o Iharaira hei iwi i toku aroaro a ake ake.
“Àyàfi tí ìlànà yìí bá kúrò níwájú mi,” ni Olúwa wí. “Ǹjẹ́ àwọn ọmọ Israẹli yóò dẹ́kun láti jẹ́ orílẹ̀-èdè níwájú mi láéláé.”
37 Ko te kupu tenei a Ihowa: Mehemea e taea ana te ruri te rangi i runga, te rapu hoki nga turanga o te whenua i raro, katahi hoki ahau ka paopao ki nga uri katoa o Iharaira mo nga mea katoa kua mahia e ratou, e ai ta Ihowa.
Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Àyàfi tí a bá lé àwọn ọ̀run lókè tí ìpìlẹ̀ ayé sì di àwárí ní ìsàlẹ̀, ni èmi yóò kọ àwọn Israẹli nítorí ohun gbogbo tí wọ́n ti ṣe,” ni Olúwa wí.
38 Nana, kei te haere mai nga ra, e ai ta Ihowa, e hanga ai te pa hei mea ki a Ihowa, i te pourewa atu o Hananeere tae noa ki te kuwaha o te koki.
“Ọjọ́ náà ń bọ̀,” ni Olúwa wí, “tí wọn yóò tún ìlú yìí kọ́ fún mi láti ilé ìṣọ́ Hananeli dé igun ẹnu ibodè.
39 A ka tae tonu atu te aho ruri, tika tonu atu ki te pukepuke ki Karepe, taiawhio tonu atu ki Koata.
Okùn ìwọ̀n yóò sì nà jáde láti ibi gígùn lọ sí òkè Garebu yóò sì lọ sí Goa.
40 Na, ko te raorao katoa i nga tupapaku, i nga pungarehu, a ko nga mara katoa hoki, a tae noa ki te awa, ki Kitirono, ki te koki i te kuwaha hoiho whaka te rawhiti, ka tapu katoa ki a Ihowa; e kore e hutia ake, e kore ano e wahia iho a ake ake.
Gbogbo àfonífojì níbi tí wọ́n ń da òkú àti eérú sí, àti gbogbo àfonífojì Kidironi ní ìhà ìlà-oòrùn títí dé igun ẹnu ibodè ẹṣin yóò jẹ́ mímọ́ sí Olúwa. A kì yóò fa ìlú náà tu tàbí kí a wó o palẹ̀.”

< Heremaia 31 >