< Heremaia 11 >

1 Ko te kupu i pa mai ki a Heremaia he mea na Ihowa; i ki ia,
Èyí ni ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó tọ Jeremiah wá:
2 Whakarongo koutou ki nga kupu o tenei kawenata, korero hoki ki nga tangata o Hura ratou ko te hunga e noho ana i Hiruharama;
“Fetísílẹ̀ sí ọ̀rọ̀ májẹ̀mú yìí, kí o sì sọ wọ́n fún àwọn ènìyàn Juda, àti gbogbo àwọn tó ń gbé ni Jerusalẹmu.
3 Mea atu ki a ratou, Ko te kupu tenei a Ihowa, a te Atua o Iharaira, Ka kanga te tangata e kore e whakarongo ki nga kupu o tenei kawenata,
Sọ fún wọn wí pé èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí: ‘Ègbé ni fún ẹni náà tí kò pa ọ̀rọ̀ májẹ̀mú yìí mọ́.
4 I whakahaua nei e ahau ki o koutou matua i te ra i kawea mai ai ratou e ahau i te whenua o Ihipa, i roto i te oumu rino; i ahau i ki ra, Whakarongo ki toku reo, mahia hoki aua mea, kia rite ki nga mea katoa i whakahaua e ahau ki a koutou; a ka wa iho koutou hei iwi maku, ko ahau hoki hei Atua mo koutou:
Àwọn májẹ̀mú tí mo pàṣẹ fún àwọn baba ńlá yín, nígbà tí mo mú wọn jáde láti Ejibiti, láti inú iná alágbẹ̀dẹ wá.’ Mo wí pé, ‘Ẹ gbọ́ tèmi, kí ẹ sì ṣe ohun gbogbo tí mo pàṣẹ fún un yín. Ẹ̀yin ó sì jẹ́ ènìyàn mi, Èmi ó sì jẹ́ Ọlọ́run yín.
5 Kia whakamana ai e ahau te oati i oatitia e ahau ki o koutou matua, kia hoatu ki a ratou he whenua e rerengia ana e te waiu, e te honi, penei me tenei ra. Katahi ka whakahoki ahau, ka mea, Koia ano tena, e Ihowa.
Nígbà náà ni Èmi ó sì mú ìlérí tí mo búra fún àwọn baba ńlá yín ṣẹ; láti fún wọn ní ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti fún oyin,’ ilẹ̀ tí ẹ ní lónìí.” Mo sì dáhùn wí pé, “Àmín, Olúwa.”
6 Na ka ki mai a Ihowa ki ahau, Karangatia enei kupu katoa ki nga pa o Hura, ki nga ara ano o Hiruharama, mea atu, Whakarongo ki nga kupu o tenei kawenata, mahia hoki.
Olúwa wí fún mi pé, “Kéde gbogbo ọ̀rọ̀ yìí ní àwọn ìlú Juda àti ní gbogbo òpópónà ìgboro Jerusalẹmu pé, ‘Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ májẹ̀mú yìí, kí ẹ sì se wọn.
7 I tino whakatupato hoki ahau i o koutou matua i te ra i kawea mai ai ratou e ahau i te whenua o Ihipa, a taea noatia tenei ra, maranga wawe ana ahau, whakatupato ana; mea ana, Whakarongo ki toku reo.
Láti ìgbà tí mo ti mú àwọn baba yín jáde láti ilẹ̀ Ejibiti wá títí di òní, mo kìlọ̀ fún wọn lọ́pọ̀ ìgbà wí pé, “Ẹ gbọ́ tèmi.”
8 Heoi kihai ratou i rongo, kihai i tahuri o ratou taringa; otiia haere ana ratou, ia tangata, ia tangata, i runga i nga tikanga pakeke a tona ngakau kino: mo reira ka takina e ahau ki a ratou nga kupu katoa o tenei kawenata i whakahaua nei e ahau kia mahia, a kihai nei i mahia e ratou.
Ṣùgbọ́n wọn kò gbọ́, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò kọbi ara sí i dípò èyí wọ́n tẹ̀síwájú ni agídí ọkàn wọn. Mo sì mú gbogbo ègún inú májẹ̀mú tí mo ti ṣèlérí, tí mo sì ti pàṣẹ fún wọn láti tẹ̀lé, tí wọn kò tẹ̀lé wa sórí wọn.’”
9 I mea ano a Ihowa ki ahau, Kua kitea te he e whakatakotoria ana e nga tangata o Hura, e te hunga e noho ana i Hiruharama.
Olúwa sì wí fún mi pé, “Ọ̀tẹ̀ kan wà láàrín àwọn ará Juda àti àwọn tí ń gbé ní Jerusalẹmu.
10 Kua hokia e ratou nga he o o ratou matua o mua, kihai nei i pai ki te whakarongo ki aku kupu, haere ana ratou ki te whai i nga atua ke, mahi ana ki a ratou: kua whakataka e te whare o Iharaira ratou ko te whare o Hura taku kawenata i whakaritea e ahau ki o ratou matua.
Wọ́n ti padà sí ìdí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn baba ńlá wọn tí wọn kọ̀ láti tẹ́tí sí ọ̀rọ̀ mi, wọ́n ti tẹ̀lé àwọn ọlọ́run mìíràn láti sìn wọ́n. Ilé Israẹli àti ilé Juda ti ba májẹ̀mú tí mo dá pẹ̀lú àwọn baba ńlá wọn jẹ́.
11 Mo reira ko te kupu tenei a Ihowa, Tenei te takina nei e ahau ki a ratou, he he; e kore ano ratou e mawhiti; ka karanga ano ratou ki ahau, otiia e kore ahau e rongo ki a ratou.
Nítorí náà, èyí ni ohun tí Olúwa wí: ‘Èmi yóò mu ibi tí wọn kò ní le è yẹ̀ wá sórí wọn, bí wọ́n tilẹ̀ ké pè mí èmi kì yóò fetí sí igbe wọn.
12 A ka haere nga pa o Hura me nga tangata o Hiruharama, ka karanga ki nga atua e tahu whakakakara nei ratou ki a ratou: hore rawa ia a ratou whakaora mo ratou i te wa e raru ai.
Àwọn ìlú Juda àti àwọn ará Jerusalẹmu yóò lọ kégbe sí àwọn òrìṣà tí wọ́n ń sun tùràrí sí; àwọn òrìṣà náà kò ní ràn wọ́n lọ́wọ́ ní ìgbà tí ìpọ́njú náà bá dé.
13 I rite hoki ou atua, e Hura, ki ou pa te maha; me nga aata i hanga e koutou ma taua mea whakama, rite tonu ki nga ara o Hiruharama te maha, ara nga aata tahu whakakakara ki a Paara.
Ìwọ Juda, bí iye àwọn ìlú rẹ, bẹ́ẹ̀ iye àwọn òrìṣà rẹ; bẹ́ẹ̀ ni iye pẹpẹ tí ẹ̀yin ti tẹ́ fún sísun tùràrí Baali ohun ìtìjú n nì ṣe pọ̀ bí iye òpópónà tí ó wà ní Jerusalẹmu.’
14 Heoi kaua e inoi mo tenei iwi; kei ara hoki tetahi tangi, tetahi kupu wawao mo ratou; no te mea e kore ahau e rongo i te wa e karanga ai ratou ki ahau, ina raru ratou.
“Má ṣe gbàdúrà fún àwọn ènìyàn wọ̀nyí tàbí kí o bẹ̀bẹ̀ fún wọn, nítorí pé, Èmi kì yóò dẹtí sí wọn nígbà tí wọ́n bá ké pè mí ní ìgbà ìpọ́njú.
15 Ko te aha ma taku wahine aroha i roto i toku whare, kua mahi he nei hoki ia, he tini nga hoa, a kua kore te kikokiko tapu i a koe? i tau mahinga i te kino, na, kei te whakamanamana koe.
“Kí ni olùfẹ́ mi ní í ṣe ní tẹmpili mi, bí òun àti àwọn mìíràn ṣe ń hu oríṣìíríṣìí ìwà àrékérekè? Ǹjẹ́ ẹran tí a yà sọ́tọ̀ lè mú ìjìyà kúrò lórí rẹ̀? Nígbà tí ó bá ń ṣe iṣẹ́ búburú rẹ̀, nígbà náà jẹ́ kí inú rẹ̀ kí ó dùn.”
16 I huaina e Ihowa tou ingoa, Ko te oriwa matomato, ataahua, hua papai: nui atu te reo ngangau i tahuna ai e ia te ahi mona, kua whatiwhatiia ona manga.
Olúwa pè ọ́ ní igi olifi pẹ̀lú èso rẹ tí ó dára ní ojú. Ṣùgbọ́n pẹ̀lú ìrọ́kẹ̀kẹ̀ ìjì líle ọ̀wọ́-iná ni yóò sun ún tí àwọn ẹ̀ka rẹ̀ yóò sì di gígé kúrò.
17 Kua korerotia nei hoki e Ihowa o nga mano, e tou kaiwhakato, he he mou, hei utu mo te kino o te whare o Iharaira raua ko te whare o Hura, i mahia nei e ratou hei he mo ratou, hei whakapatari i ahau, i a ratou ka tahu whakakakara nei ki a Paara.
Olúwa àwọn ọmọ-ogun tí ó dá ọ ti kéde ibi sí ọ, nítorí ilé Israẹli àti Juda ti ṣe ohun ibi, wọ́n sì ti mú inú bí mi, wọ́n ti ru ìbínú mi sókè nípa sísun tùràrí si Baali.
18 I meinga ano ahau e Ihowa kia mohio ki taua mea, a mohio ana ahau: i whakakitea mai ano e koe ki ahau a ratou mahi.
Nítorí Olúwa fi ọ̀tẹ̀ wọn hàn mí mo mọ̀ ọ́n; nítorí ní àsìkò náà ó fi ohun tí wọ́n ń ṣe hàn mí.
19 Ko ahau ia i rite ki te reme, e arahina ana kia patua; kihai i mohio, e hanga whakaaro ana ratou moku, e mea ana, Kia kore i a tatou te rakau me ona kua, kia tapahia atu ia i runga i te whenua o te hunga ora, kia kore ai he maharatanga ki tona i ngoa.
Mo ti dàbí ọ̀dọ́-àgùntàn jẹ́ẹ́jẹ́ tí a mú lọ fún pípa; n kò mọ̀ pé wọ́n ti gbìmọ̀ búburú sí mi wí pé: “Jẹ́ kí a run igi àti èso rẹ̀; jẹ́ kí a gé e kúrò ní orí ilẹ̀ alààyè, kí a má lè rántí orúkọ rẹ̀ mọ́.”
20 Tena, e Ihowa o nga mano, kei runga nei hoki i te tika tau whakawa, e whakamatau ana koe i nga whatumanawa, i te ngakau, kia kite ahau i tau rapunga utu i a ratou: kua whakakitea atu nei hoki e ahau taku totohe ki a koe.
Ṣùgbọ́n ìwọ Olúwa àwọn ọmọ-ogun, tí ó ń ṣe ìdájọ́ òdodo, tí ó ń ṣe àyẹ̀wò ẹ̀mí àti ọkàn, jẹ́ kí n rí ẹ̀san rẹ lórí wọn; nítorí ìwọ ni mo fi ọ̀rọ̀ mi lé lọ́wọ́.
21 Heoi ko te kupu tenei a Ihowa mo nga tangata o Anatoto e whai nei kia whakamatea koe, e mea nei, Kaua e poropiti i runga i te ingoa o Ihowa, kei mate koe i to matou ringa:
“Nítorí náà, èyí ni ohun tí Ọlọ́run sọ nípa àwọn arákùnrin Anatoti tí wọ́n ń lépa ẹ̀mí rẹ̀, tí wọ́n ń wí pé, ‘Má ṣe sọ àsọtẹ́lẹ̀ ní orúkọ Olúwa, bí bẹ́ẹ̀ kọ́ ìwọ ó kú láti ọwọ́ wa.’
22 Mo reira ko te kupu tenei a Ihowa o nga mano, Tenei ahau te whiu nei i a ratou: ka mate nga taitamariki i te hoari; ko a ratou tama, ko a ratou tamahine, ka mate i te hemokai.
Nítorí náà, èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun sọ pé, ‘Èmi yóò fì ìyà jẹ wọ́n, àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin wọn yóò tipasẹ̀ idà kú, ìyàn yóò pa àwọn ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin wọn.
23 E kore ratou e whai morehu; no te mea ka kawea e ahau he kino ki nga tangata o Anatoto, ara ko te tau e whiua ai ratou.
Kò ní ṣẹ́kù ohunkóhun sílẹ̀ fún wọn nítorí èmi yóò mú ibi wá sórí àwọn ènìyàn Anatoti ní ọdún ìbẹ̀wò wọn.’”

< Heremaia 11 >