< Ihaia 1 >

1 Ko te kite a Ihaia, a te tama a Amoho, i kite ai ia mo Hura, mo Hiruharama, i nga ra o nga kingi o Hura, o Utia, o Iotama, o Ahata, o Hetekia.
Ìran sí Juda àti Jerusalẹmu èyí tí Isaiah ọmọ Amosi rí ní àsìkò ìjọba Ussiah, Jotamu, Ahasi àti Hesekiah àwọn ọba Juda.
2 Whakarongo, e nga rangi, kia whai taringa ano, e te whenua, kua korero hoki a Ihowa: Kua atawhai tamariki ahau, kua whakatupu hoki, na kua tahuri mai ratou ki ahau.
Gbọ́ ẹ̀yin ọ̀run! Fi etí sílẹ̀, ìwọ ayé! Nítorí Olúwa ti sọ̀rọ̀: “Mo tọ́ àwọn ọmọ dàgbà, ṣùgbọ́n wọ́n ti ṣọ̀tẹ̀ sí mi.
3 E mohio ana te kau ki tona ariki, te kaihe ki te takotoranga kai a tona rangatira: ko Iharaira ia kahore e mohio, kahore taku iwi e whakaaro.
Màlúù mọ olówó rẹ̀, kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ sì mọ ibùjẹ olówó rẹ̀, ṣùgbọ́n Israẹli kò mọ̀, òye kò yé àwọn ènìyàn mi.”
4 Aue, e te iwi hara, he hunga taimaha i te kino, he uri no nga kaimahi i te he, he tamariki whakangau ke: kua whakarerea e ratou a Ihowa, kua whakahawea ki te Mea Tapu o Iharaira, kua tangata ke ratou a kua hoki whakamuri.
Á à! Orílẹ̀-èdè ẹlẹ́ṣẹ̀, àwọn ènìyàn tí ẹ̀bi ẹ̀ṣẹ̀ ń pa lẹ́rù, ìran àwọn aṣebi, àwọn ọmọ tó ti di aṣèbàjẹ́! Wọn ti kọ Olúwa sílẹ̀ wọn ti gan Ẹni Mímọ́ Israẹli, wọn sì ti kẹ̀yìn sí i.
5 Kia patua tonutia hoki koutou hei aha, i tutu tonu ai koutou? kei te mate katoa te mahunga, kei te ruhi katoa hoki te ngakau.
Èéṣe tí a ó fi tún lù yín mọ́? Èéṣe tí ẹ ò dẹ́kun ọ̀tẹ̀ ṣíṣe? Gbogbo orí yín jẹ́ kìkì ọgbẹ́, gbogbo ọkàn yín sì ti pòruurù.
6 Kahore ona wahi ora, ake i te kapu o tona waewae a tae noa ki te mahunga; he kaiakiko kau, he karawarawa, he whiunga kua pirau: kihai ena i romia, kihai i takaia, kihai ano hoki i whakangawaritia ki te hinu.
Láti àtẹ́lẹsẹ̀ yín dé àtàrí yín kò sí àlàáfíà rárá, àyàfi ọgbẹ́ òun ìfarapa àti ojú egbò, tí a kò nù kúrò tàbí kí á dì tàbí kí a kùn ún ní òróró.
7 Ko to koutou whenua kua ururuatia; ko o koutou pa kua wera i te ahi; he tangata ke kei te kai i to koutou oneone i to koutou aroaro, ururua ana, koia ano kei ta te tangata ke raupatutanga.
Orílẹ̀-èdè yín dahoro, a dáná sun àwọn ìlú yín, oko yín ni àwọn àjèjì ti jẹ run lójú ara yín náà, ni gbogbo rẹ̀ ṣòfò bí èyí tí àwọn àjèjì borí rẹ̀.
8 A ka mahue iho te tamahine a Hiona, ano he tihokahoka i te mara waina, ano he wharau i te mara kukamo, he pa e whakapaea ana.
Ọmọbìnrin Sioni ni a fi sílẹ̀ gẹ́gẹ́ bí àtíbàbà nínú ọgbà àjàrà, gẹ́gẹ́ bí abà nínú oko ẹ̀gúnsí, àti bí ìlú tí a dó tì.
9 Me i kahore a Ihowa o nga mano te waiho i tetahi toenga nohinohi rawa nei ki a tatou, kua pera tatou me Horoma, kua rite tatou ki Komora.
Àyàfi bí Olúwa àwọn ọmọ-ogun bá ṣẹ́ díẹ̀ kù fún wà, a ò bá ti rí bí Sodomu, a ò bá sì ti dàbí Gomorra.
10 Whakarongo ki te kupu a Ihowa, e nga rangatira o Horoma; kia whai taringa mai, e te iwi o Komora, ki te ture a to tatou Atua.
Gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa, ẹ̀yin aláṣẹ Sodomu, tẹ́tí sí òfin Ọlọ́run wa, ẹ̀yin ènìyàn Gomorra!
11 Hei aha maku a koutou patunga maha? e ai ta Ihowa: kua makona ahau i nga tahunga o nga tinana o nga hipi toa, i te ngako o nga kararehe whangai; kahore hoki aku manakohanga atu ki te toto o nga puru, o nga reme, o nga koati toa ranei.
“Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹbọ yín kín ni ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹbọ yín jásí fún mi?” ni Olúwa wí. “Mo ti ní ànító àti àníṣẹ́kù ẹbọ sísun ti àgbò àti ọ̀rá ẹran àbọ́pa, Èmi kò ní inú dídùn nínú ẹ̀jẹ̀ akọ màlúù, ti àgùntàn àti ti òbúkọ.
12 Ka haere mai koutou, ka whakakite mai ki toku aroaro, ko wai i ki atu ki tenei mea a o koutou ringa, kia takahia oku marae?
Nígbà tí ẹ wá farahàn níwájú mi, ta ni ó béèrè èyí lọ́wọ́ yín, gìrì gìrì ẹsẹ̀ nínú àgbàlá mi?
13 Kati te mau mai i nga whakahere horihori: he mea whakarihariha ki ahau te whakakakara; te kowhititanga marama, te hapati, te karangatanga o nga whakaminenga, e kore ahau e manawanui ki te kino, ki te huihui nui.
Ẹ má mú ọrẹ asán wá mọ́! Ìríra ni tùràrí yín jásí fún mi, oṣù tuntun àti ọjọ́ ìsinmi àti àwọn àpéjọ, Èmi kò lè faradà á, ẹ̀ṣẹ̀ ni àpéjọ yín wọ̀nyí.
14 Ko a koutou kowhititanga marama, ko a koutou hakari whakarite, e kino ana toku ngakau: he mea porearea ki ahau; he hanga whakahoha.
Ayẹyẹ oṣù tuntun yín àti àjọ̀dún tí a yàn, ni ọkàn mi kórìíra. Wọ́n ti di àjàgà sí mi ní ọrùn, Ó sú mi láti fi ara dà wọ́n.
15 Na ka wherahia mai o koutou ringa, ka huna e ahau oku kanohi ki a koutou; ae ra, ka whakanuia e koutou te inoi e kore ahau e rongo, kapi tonu o koutou ringa i te toto.
Nígbà tí ẹ bá tẹ́ ọwọ́ yín sókè ni àdúrà, Èmi yóò fi ojú mi pamọ́ fún un yín, kódà bí ẹ bá gba ọ̀pọ̀lọpọ̀ àdúrà, Èmi kò ni tẹ́tí sí i. “Ọwọ́ yín kún fún ẹ̀jẹ̀.
16 Horoi i a koutou, kia ma; whakarerea atu te kino o a koutou hanga i mua i oku kanohi; kati te mahi i te kino;
“Wẹ̀ kí ẹ sì jẹ́ kí ara yín mọ́. Ẹ mú ìwà ibi yín kúrò níwájú mi! Dáwọ́ àìṣedéédéé dúró,
17 Akona te mahi pai; rapua te whakawa; whakatikaia ta te tangata e tukinotia ana; whakawakia ta te pani; tohea ta te pouaru.
kọ́ láti ṣe rere! Wá ìdájọ́ òtítọ́, tu àwọn tí a ń pọ́n lójú nínú. Ṣàtìlẹyìn fún ẹ̀tọ́ aláìní baba, gbà ẹjọ́ opó rò.
18 Tena ra, tatou ka korerorero, e ai ta Ihowa; ahakoa i rite o koutou hara ki te mea ngangana, ka pera me te hukarere te ma; ahakoa i whero me te mea whakawhero, ka rite ki te huruhuru hipi.
“Ẹ wá ní ìsinsin yìí, ẹ jẹ́ kí a jọ ṣàṣàrò,” ni Olúwa wí. “Bí ẹ̀ṣẹ̀ yín bá rí bí osùn, wọn ó sì funfun bí i yìnyín, bí wọn bá sì pọ́n bí ẹ̀jẹ̀, wọn ó sì dàbí ẹ̀gbọ̀n òwú.
19 Ki te mea ka pai koutou, a ka rongo, ka kai koutou i nga mea pai o te whenua;
Tí ẹ̀yin bá fẹ́, tí ẹ sì gbọ́rọ̀, ẹ̀yin yóò sì jẹ ojúlówó adùn ilẹ̀ náà.
20 Ki te whakakahore koutou, a ka tutu, ka pau koutou i te hoari; kua korero hoki te mangai o Ihowa.
Ṣùgbọ́n tí ẹ bá kọ̀ tí ẹ sì ṣọ̀tẹ̀, idà ni a ó fi pa yín run.” Nítorí ẹnu Olúwa la ti sọ ọ́.
21 Aue! tona kairautanga o te pa pono! i ki nei ia i te whakawa! he nohoanga no te tika, inaianei ia no nga kaikohuru.
Wo bí ìlú òtítọ́ ṣe di àgbèrè! Ó ti kún fún ìdájọ́ òtítọ́ nígbà kan rí, òdodo ń gbé ibẹ̀ tẹ́lẹ̀ rí, ṣùgbọ́n báyìí àwọn apànìyàn!
22 Ko tau hiriwa kua meinga hei para, ko tau waina, kua whakaranua ki te wai.
Fàdákà rẹ ti di ìpẹ́pẹ́, ààyò wáìnì rẹ la ti bu omi là.
23 Ko ou rangatira kei te whakakeke, a he hoa ratou no te hunga tahae; e whakapai ana ratou ki te moni whakapati, e whai ana i te utu; kahore ratou e whakawa ana mo te pani, a kahore te tohe a te pouaru e tae ana ki a ratou.
Ọlọ̀tẹ̀ ni àwọn aláṣẹ yín, akẹgbẹ́ àwọn olè, gbogbo wọn ló fẹ́ràn àbẹ̀tẹ́lẹ̀ wọ́n sì ń wá ẹ̀bùn kiri. Wọ́n kì í ṣàtìlẹyìn fún ẹ̀tọ́ aláìní baba, ẹjọ́ opó kì í sì í dé iwájú wọn.
24 No reira ka mea te Ariki, a Ihowa o nga mano, te Mea Nui o Iharaira, Na! ka whai mamatanga ahau i oku hoariri, ka whai utu ahau i oku hoariri:
Nítorí náà ni Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun, alágbára kan ṣoṣo tí Israẹli sọ wí pé: “Á à! Èmi yóò ní ìfọ̀kànbalẹ̀ lórí àwọn ọ̀tá mi n ó sì gbẹ̀san lára àwọn ọ̀tá mi.
25 Ka tahuri atu hoki toku ringa ki a koe, a ka tahia rawatia tou para, ka wehea katoatia atu ano tou tine:
Èmi yóò pa ọwọ́ mi dà sí ọ, èmi ó sì ku ìpẹ́pẹ́ rẹ dànù, n ó sì mú gbogbo ìdọ̀tí rẹ kúrò.
26 A ka whakahokia mai e ahau ou kaiwhakawa kia rite ki o mua, me ou kaiwhakatakoto whakaaro, kia rite ki o te timatanga; muri iho ka kiia koe, Ko te pa o te tika, ko te pa piripono.
Èmi yóò mú àwọn adájọ́ rẹ bọ̀ sí ipò gẹ́gẹ́ bí i ti àtijọ́, àti àwọn olùdámọ̀ràn rẹ̀ bí i ti ìbẹ̀rẹ̀ pẹ̀pẹ̀. Lẹ́yìn náà ni a ó pè ọ ní ìlú òdodo, ìlú òtítọ́.”
27 Ka hokona a Hiona i runga i te whakawa, ana tangata hoki, e tahuri mai ana, i runga i te tika.
A ó fi ìdájọ́ òtítọ́ ra Sioni padà, àti àwọn tí ó ronúpìwàdà pẹ̀lú òdodo.
28 Ka huihuia ia kia kotahi tonu te whakangaromanga o te hunga poka ke, o te hunga hara, a ka whakamotitia te hunga e whakarere ana i a Ihowa.
Ṣùgbọ́n àwọn ọlọ̀tẹ̀ àti àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ ni a ó parun. Àwọn tí ó bá sì kọ Olúwa sílẹ̀ ni yóò ṣègbé.
29 Ka whakama hoki ratou i nga oki i matenuitia e koutou, numinumi kau koutou i nga kari i whiriwhiria e koutou.
“Ojú yóò tì yín nítorí igi óákù mímọ́ èyí tí ẹ ní inú dídùn sí, a ó kàn yín lábùkù nítorí àwọn ọgbà yìí tí ẹ ti yàn fúnra yín.
30 Ka rite hoki koutou ki te oki kua memenge ona rau, ki te kari ano hoki kahore nei ona wai.
Ẹ ó sì dàbí igi óákù tí ewé rẹ̀ ti rọ, bí ọgbà tí kò ní omi.
31 A hei muka te mea kaha, hei korakora ano tana mahi; na ka ngiha ngatahi raua, kahore hoki he tangata hei tinei.
Alágbára ọkùnrin náà yóò sì dàbí ohun ìdáná, iṣẹ́ rẹ̀ bí ẹ̀ṣẹ́-iná, àwọn méjèèjì ni yóò jóná papọ̀, láìsí ẹni tí yóò lè pa iná yìí.”

< Ihaia 1 >