< Ihaia 17 >

1 Ko te poropitianga mo Ramahiku. Nana, kua kore a Ramahiku hei pa; ka puranga kau.
Ọ̀rọ̀-ìmọ̀ tí ó kan Damasku: “Kíyèsi i, Damasku kò ní jẹ́ ìlú mọ́ ṣùgbọ́n yóò padà di ààtàn.
2 Kua mahue nga pa o Aroere; mo nga kahui era, ka takoto ratou, te ai he kaiwhakawehi.
Àwọn ìlú Aroeri ni a ó kọ̀sílẹ̀ fún àwọn agbo ẹran tí yóò máa sùn síbẹ̀, láìsí ẹni tí yóò dẹ́rùbà wọ́n.
3 Ka kore ano he pa kaha mo Eparaima, he kingitanga mo Ramahiku, he toenga ranei o Hiria: ka rite ratou ki te kororia o nga tama a Iharaira, e ai ta Ihowa o nga mano.
Ìlú olódi ni yóò pòórá kúrò ní Efraimu, àti agbára ọba kúrò ní Damasku; àwọn àṣẹ́kù Aramu yóò dá gẹ́gẹ́ bí ògo ti àwọn Israẹli,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
4 Na i taua ra ka meinga te kororia o Hakaopa kia tupuhi, ka hiroki haere hoki te ngako o ona kikokiko.
“Ní ọjọ́ náà ni ògo Jakọbu yóò sá; ọ̀rá ara rẹ̀ yóò ṣòfò dànù.
5 A ka rite ki ta te kaitapahi kohikohinga i te witi, ki te tapahanga hoki a ona ringa i nga hua witi; ae, ka rite ki te hamunga o nga hua witi i te raorao i Repaima.
Yóò sì dàbí ìgbà tí olùkórè kó àwọn irúgbìn tí ó dúró jọ tí ó sì ń kórè irúgbìn pẹ̀lú apá rẹ̀— àti gẹ́gẹ́ bí ìgbà tí ènìyàn pa ọkà ní àfonífojì ti Refaimu.
6 Otiia e toe ano etahi karepe hei hamunga; ka rite ki te ruiruinga o te oriwa; e rua, e toru nga oriwa i te pito o to runga rawa peka, e wha, e rima i te peka i waho rawa, i te mea whai hua, e ai ta Ihowa, ta te Atua o Iharaira.
Síbẹ̀síbẹ̀ irúgbìn díẹ̀ yóò ṣẹ́kù, gẹ́gẹ́ bí ìgbà tí a gbọn igi olifi, tí èso olifi méjì tàbí mẹ́ta ṣẹ́kù sórí ẹ̀ka tí ó ga jùlọ, mẹ́rin tàbí márùn-ún lórí ẹ̀ka tí ó so jù,” ni Olúwa wí, àní Ọlọ́run Israẹli.
7 I taua ra ka titiro he tangata ki tona Kaihanga, ka anga ona kanohi ki te Mea Tapu o Iharaira.
Ní ọjọ́ náà, àwọn ènìyàn yóò gbójú sókè sí Ẹlẹ́dàá wọn, wọn yóò sì síjú wo Ẹni Mímọ́ Israẹli.
8 E kore ano e titiro ki nga aata i hanga nei e ona ringa, e kore e anga ki te mea i mahia e ona maihao, ki nga Aherimi ranei, ki nga whakapakoko ranei.
Wọn kò ní wo àwọn pẹpẹ mọ́, èyí tí í ṣe iṣẹ́ ọwọ́ wọn, wọn kò sì ní kọbi ara sí ère Aṣerah mọ́ tàbí pẹpẹ tùràrí tí ìka ọwọ́ wọn ti ṣe.
9 I taua ra ka rite ona pa kaha ki te wahi i whakarerea i te ngahere, i te tihi ano o te maunga, i whakarerea ra i te aroaro o nga tama a Iharaira; na ko te ngaromanga.
Ní ọjọ́ náà àwọn ìlú alágbára rẹ̀, yóò dàbí ẹ̀ka ìkọ̀sílẹ̀, àti ẹ̀ka téńté òkè tí wọ́n fi sílẹ̀ nítorí àwọn ọmọ Israẹli. Gbogbo wọn yóò sì di ahoro.
10 Kua wareware hoki koe ki te Atua o tou whakaoranga, a kua kahore i mahara ki te kamaka o tou kaha, mo reira ka whakatupuria e koe he mea ataahua, ka whakatokia ano ki te peka ke:
Nítorí ìwọ ti gbàgbé Ọlọ́run ìgbàlà rẹ; tí ìwọ kò sì náání àpáta ìgbàlà rẹ̀, nítorí náà ni ìwọ ti gbin ọ̀gbìn dáradára ìwọ sì tọ́ àjèjì ẹ̀ka sínú rẹ̀.
11 I te ra e whakato ai koe, ka taiepatia e koe, a i te ata matomato tonu tau i whakato ai: i te ra ia o te pouri, o te mamae ngau kino, ka memeha atu te kotinga.
Nítorí náà, bí ẹ tilẹ̀ mú àṣàyàn igi tí ẹ sì gbin àjàrà tí ó ti òkèrè wá, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ọjọ́ tí ẹ kó wọn jáde ẹ mú wọn hù jáde, àti ní òwúrọ̀ tí ẹ gbìn wọ́n ẹ mú kí wọ́n rúdí, síbẹ̀síbẹ̀ ìkórè kò ní mú nǹkan wá ní ọjọ́ ààrùn àti ìrora tí kò gbóògùn.
12 Anana, te ngangau o nga iwi maha, e nge ana ano he haruru no nga moana! me te rere o nga iwi, e wawa ana koia ano kei te turituri o nga wai nunui!
Kíyèsi i, ìrunú àwọn orílẹ̀-èdè— wọ́n ń runú bí ìgbì Òkun! Kíyèsi i, rògbòdìyàn tí ogunlọ́gọ̀ ènìyàn wọ́n bú ramúramù gẹ́gẹ́ bí ariwo odò ńlá!
13 Ano ko te taheke o nga wai maha te haruru o nga iwi; otiia ka riria ratou e ia, a ka rere ki tawhiti, ka whaia, ano he papapa no nga maunga i te upoko o te hau, ano he puehu awhiowhio e aia ana e te tupuhi.
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn ènìyàn ń bú ramúramù gẹ́gẹ́ bí ìrúmi odò, nígbà tí ó bá wọn wí wọ́n sálọ jìnnà réré, a tì wọ́n lọ gẹ́gẹ́ bí ìyàngbò ní orí òkè, àti gẹ́gẹ́ bí ewéko níwájú ìjì líle.
14 I te ahiahi, na ko te pawera; kiano i puao kua kore ratou. Ko te wahi tenei ma te hunga e pahua ana i a tatou, ko te mea tenei e wehea ma te hunga e muru ana i a tatou.
Ní aginjù, ìpayà òjijì! Kí ó tó di òwúrọ̀, a ò rí wọn mọ́! Èyí ni ìpín àwọn tí ó jí wa lẹ́rù, àti ìpín àwọn tí ó fi ogun kó wa.

< Ihaia 17 >