< Hohea 5 >

1 Whakarongo ki tenei, e nga tohunga, mahara mai, e te whare o Iharaira, kia whai taringa mai hoki, e te whare o te kingi, mo koutou hoki te whakawa; no te mea kua waiho koutou hei rore ki Mihipa, hei kupenga horahora ki runga ki Taporo.
“Ẹ gbọ́ èyí, ẹ̀yìn àlùfáà! Ẹ fetísílẹ̀ ẹ̀yin ọmọ Israẹli! Ẹ gbọ́, ẹ̀yìn ilé ọba! Ìdájọ́ yìí kàn yín. Ẹ ti jẹ́ ẹ̀bìtì ní Mispa àwọ̀n ti a nà sílẹ̀ lórí Tabori.
2 A hohonu ana te hounga o te patu a te hunga tutu; ko ahau ia te kairiri i te he o ratou katoa.
Àwọn ọlọ̀tẹ̀ ti gbilẹ̀ nínú ìpànìyàn gbogbo wọn ni èmi ó bá wí,
3 E mohio ana ahau ki a Eparaima, kahore a Iharaira e ngaro i ahau; kei te moepuku nei hoki koe inaianei, e Eparaima, kua poke a Iharaira.
mo mọ ohun gbogbo nípa Efraimu Israẹli kò sì pamọ́ fún mi Efraimu, ní báyìí ó ti ṣe àgbèrè Israẹli sì ti díbàjẹ́.
4 E kore hoki ratou e tukua e a ratou mahi kia hoki ki to ratou Atua; kei roto hoki i a ratou te wairua moepuku, kahore o ratou mohio ki a Ihowa.
“Ìṣe wọn kò gbà wọ́n láààyè láti padà sí ọ̀dọ̀ Ọlọ́run wọn. Ẹ̀mí àgbèrè wà ni ọkàn wọn, wọn kò sì mọ Olúwa.
5 E whakaaturia ana ta Iharaira e tona whakapehapeha ki tona aroaro ano: na ka hinga a Iharaira raua ko Eparaima i runga i to raua he, me Hura, ka hinga ngatahi ratou.
Ìgbéraga Israẹli ń jẹ́rìí lé wọn; àwọn ọmọ Israẹli, àti Efraimu pàápàá kọsẹ̀ nínú ẹ̀ṣẹ̀ wọn. Juda náà sì kọsẹ̀ pẹ̀lú wọn.
6 Ka haere ratou me a ratou hipi, me a ratou kau, ki te rapu i a Ihowa; heoi e kore e kitea; kua mawehe atu ia i roto i a ratou.
Nígbà tí wọ́n bá lọ pẹ̀lú agbo ẹran àti ọ̀wọ́ ẹran wọn láti wá Olúwa, wọn kò ní rí i, ó ti yọ ara rẹ̀ kúrò láàrín wọn.
7 Kua tinihanga ratou ki a Ihowa: he tamariki tangata ke hoki a ratou tamariki: akuanei ka pau ratou me a ratou wahi i te marama kohiti.
Wọ́n jẹ́ aláìṣòótọ́ sí Olúwa wọ́n sì bí àwọn àjèjì ọmọ. Nísinsin yìí, ọdún oṣù tuntun wọn, ni yóò pa wọn run pẹ̀lú ìpín wọn.
8 Whakatangihia te koronete ki Kipea, te tetere ki Rama: whakatangihia he whakaoho ki Peteawene; i muri i a koe, e Pineamine.
“Fọn fèrè ní Gibeah, kí ẹ sì fun ìpè ní Rama. Ẹ pariwo ogun ní Beti-Afeni; máa wárìrì, ìwọ Benjamini.
9 Ka ururua a Eparaima i te ra e riria ai te he: takoto rawa te mea kua whakaaturia nei e ahau i roto i nga hapu o Iharaira.
Efraimu yóò di ahoro ní ọjọ́ ìbáwí láàrín àwọn ẹ̀yà Israẹli, Mo sọ ohun tí ó dájú.
10 E rite ana nga rangatira o Hura ki te hunga e whakaneke atu ana i te rohe; ka tahoroa e ahau toku riri ki runga ki a ratou ano he wai.
Àwọn olórí Juda dàbí àwọn tí í máa yí òkúta ààlà kúrò. Èmi ó tú ìbínú gbígbóná mi lé wọn lórí bí ìkún omi.
11 E tukinotia ana, e whakapetia ana a Eparaima i te whakawakanga, mona i pai ki te whai i te whakahau.
A ni Efraimu lára, a sì tẹ̀ ẹ́ mọ́lẹ̀ ní ìdájọ́, nítorí pé, ó pinnu láti tẹ̀lé òrìṣà.
12 Na reira, ka rite taku ki a Eparaima ki ta te purehurehu, ka rite hoki ki te pirau taku ki te whare o Hura.
Mo dàbí kòkòrò aṣọ sí Efraimu, Mo sì dàbí ìdin ara Juda.
13 I te wa i kite ai a Eparaima i tona mate, a Hura hoki i tona marutanga, na haere ana a Eparaima ki Ahiria, tuku tangata ana ia ki a Kingi Iarepe: heoi e kore koutou e taea e ia te rongoa, e kore hoki e ora i a ia to koutou marutanga.
“Nígbà ti Efraimu ri àìsàn rẹ̀, tí Juda sì rí ojú egbò rẹ̀ ni Efraimu bá tọ ará Asiria lọ, ó sì ránṣẹ́ sí ọba ńlá náà fún ìrànlọ́wọ́. Ṣùgbọ́n kò le è wò ó sàn bẹ́ẹ̀ ni kò le wo ojú egbò rẹ̀ jinná.
14 Ka rite hoki taku ki a Eparaima ki ta te raiona, taku ki te whare o Hura ka rite ki ta te kuao raiona: ka haehae ahau, ina, ahau ano, a ka haere; ka maua atu e ahau, a kahore he kaiwhakaora.
Nítorí pé, èmi ó dàbí kìnnìún sí Efraimu, bí i kìnnìún ńlá sí ilé Juda. Èmi ó fà wọ́n ya pẹ́rẹpẹ̀rẹ èmi ó sì lọ; Èmi ó gbé wọn lọ, láìsí ẹni tí yóò gbà wọ́n sílẹ̀.
15 Ka haere ahau ka hoki ki toku wahi, kia whakaae ra ano ratou ki to ratou he, kia rapua ra ano toku mata e ratou: a, i a ratou e mate ana, kaha tonu ta ratou rapu i ahau.
Nígbà náà ni èmi ó padà lọ sí ààyè mi títí di ìgbà tí wọn ó fi gbà pé àwọn jẹ̀bi wọn yóò sì wá ojú mi nínú ìpọ́njú wọn, wọn ó fi ìtara wá mi.”

< Hohea 5 >