< Kenehi 49 >
1 Na ka karanga a Hakopa ki ana tamariki, ka mea, Huihui mai, a ka korerotia e ahau ki a koutou nga mea e pono ki a koutou i nga ra o muri.
Nígbà náà ni Jakọbu ránṣẹ́ pe àwọn ọmọ rẹ̀, ó sì wí pé, “Ẹ kó ara yín jọ pọ̀, kí n le è sọ ohun tí yóò ṣẹlẹ̀ ní ọjọ́ iwájú fún un yín.
2 Huihui mai, whakarongo hoki, e nga tama a Hakopa; whakarongo hoki ki a Iharaira, ki to koutou papa.
“Ẹ kó ara yín jọ pọ̀, kí ẹ sì tẹ́tí, ẹ̀yin ọmọ Jakọbu; ẹ fetí sí Israẹli baba yín.
3 E Reupena, ko koe taku matamua, toku pakaritanga, me te timatanga o toku kaha; te hiranga ake o te kororia, te hiranga ake hoki o te kaha:
“Reubeni, ìwọ ni àkọ́bí mi, agbára mi, ìpilẹ̀ṣẹ̀ ipá mi, títayọ ní ọlá àti títayọ ní agbára.
4 He mea pokarekare, ano he wai, e kore koe e kaka; mo tou pikitanga i te moenga o tou papa; pokea iho e koe a reira: i pikitia e ia toku takotoranga.
Ẹni ríru bí omi Òkun, ìwọ kì yóò tayọ mọ́, nítorí pé ìwọ gun ibùsùn baba rẹ, lórí àkéte mi, ìwọ sì bà á jẹ́ (ìwọ bá ọ̀kan nínú àwọn aya baba rẹ lòpọ̀).
5 He tuakana, he teina, a Himiona raua ko Riwai; he rakau riri kino a raua hoari.
“Simeoni àti Lefi jẹ́ arákùnrin— idà wọn jẹ́ ohun èlò ogun alágbára.
6 Kaua e tomo, e toku wairua, ki to raua runanga; kaua e huihuia, e toku kororia, ki to raua whakaminenga: i patu tangata hoki raua i a raua e riri ana, a he hikaka no raua i kopa ai te kau.
Kí ọkàn mi má ṣe ni àṣepọ̀ pẹ̀lú wọn, kí n má sì ṣe dúró níbí ìpéjọpọ̀ wọn, nítorí wọ́n ti pa àwọn ènìyàn ní ìbínú wọn, wọ́n sì da àwọn màlúù lóró bí ó ti wù wọ́n.
7 Kia kanga to raua riri, i kaha nei; me to raua aritarita, no te mea he nanakia: ka wehea atu raua e ahau ki roto ki a Hakopa, ka whakamararatia hoki raua ki roto ki a Iharaira.
Ìfibú ni ìbínú wọn nítorí tí ó gbóná púpọ̀, àti fún ìrunú wọn nítorí tí ó kún fún ìkà! Èmi yóò tú wọn ká ní Jakọbu, èmi ó sì fọ́n wọn ká ní Israẹli.
8 E Hura, ko koe e whakamoemititia e ou tuakana, e ou teina: ka u tou ringa ki te kaki o ou hoariri: ka piko ki a koe nga tama a tou papa.
“Juda, àwọn arákùnrin rẹ yóò yìn ọ, ọwọ́ rẹ yóò wà ní ọrùn àwọn ọ̀tá rẹ, àwọn ọmọkùnrin baba rẹ yóò foríbalẹ̀ fún ọ.
9 He kuao raiona a Hura: i kake atu koe, e taku tama, i te haenga: i piko, i tapapa ia, i pera me te raiona, i pera hoki me te raiona katua; ma wai ia e whakaoho?
Ọmọ kìnnìún ni ọ́, ìwọ Juda, o darí láti igbó ọdẹ, ọmọ mi. Bí i kìnnìún, o ba mọ́lẹ̀, o sì sùn sílẹ̀ bí i abo kìnnìún, ta ni ó tó bẹ́ẹ̀, kí o lé e dìde?
10 E kore e riro ke te hepeta i a Hura, me te tokotoko o te kawana i waenganui o ona waewae, kia tae mai ra ano a Hiro; a ka rongo nga iwi katoa ki a ia.
Ọ̀pá oyè kì yóò kúrò ní Juda bẹ́ẹ̀ ni ọ̀pá-ìṣàkóso kì yóò kúrò láàrín ẹsẹ̀ rẹ̀, títí tí Ṣilo tí ó ni í yóò fi dé, tí gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè yóò máa wárí fún un.
11 Ka herea e ia tana kuao ki te waina, te tama hoki a tana kaihe ki te waina pai rawa; ka horoia e ia ona kakahu ki te waina, ona weruweru hoki ki te toto o te karepe:
Yóò má so ọmọ ẹṣin rẹ̀ mọ́ igi àjàrà, àti ọmọ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ̀ mọ́ ẹ̀ka tí ó dára jù. Yóò fọ aṣọ rẹ̀ nínú wáìnì àti ẹ̀wù rẹ̀ nínú omi-pupa ti èso àjàrà.
12 Ka mumura hoki ona kanohi i te waina, ka ma ona niho i te waiu.
Ojú rẹ̀ yóò rẹ̀ dòdò ju wáìnì lọ, eyín rẹ yóò sì funfun ju omi-ọyàn lọ.
13 Ka noho a Hepurona ki te wahapu o te moana; hei wahapu ano ia mo nga kaipuke; ka tutuki atu hoki tona rohe ki Hairona.
“Sebuluni yóò máa gbé ní etí Òkun, yóò sì jẹ́ èbúté fún ọkọ̀ ojú omi, agbègbè rẹ yóò tàn ká títí dé Sidoni.
14 He kaihe kaha a Ihakara, e tapapa ana i waenga o nga moenga hipi e rua:
“Isakari jẹ́ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ alágbára tí ó dùbúlẹ̀ láàrín agbo àgùntàn.
15 A, i tona kitenga i te okiokinga he pai, i te whenua hoki he ahuareka; na ka tukua iho e ia tona pokohiwi ki te pikaunga, a meinga ana ia hei pononga homai takoha.
Nígbà tí ó bá rí bí ibi ìsinmi òun ti dára tó, àti bí ilẹ̀ rẹ̀ ti ní ìdẹ̀ra tó, yóò tẹ èjìká rẹ̀ ba láti ru àjàgà, yóò sì fi ara rẹ̀ fún iṣẹ́ ipá.
16 Ka whakawa a Rana i tona iwi, ka pera ano me tetahi o nga iwi o Iharaira.
“Dani yóò ṣe ìdájọ́ àwọn ènìyàn rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọ̀kan nínú àwọn ẹ̀yà Israẹli.
17 Hei nakahi a Rana ki te ara, hei neke hoki ki te huarahi, e ngau ai i te rekereke o te hoiho, a ka taka whakamuri tona kaieke.
Dani yóò jẹ́ ejò ni pópónà àti paramọ́lẹ̀ ní ẹ̀bá ọ̀nà, tí ó bu ẹṣin jẹ ní ẹsẹ̀, kí ẹni tí ń gùn ún bá à le è ṣubú sẹ́yìn.
18 Kua tatari atu ahau ki tau whakaoranga, e Ihowa.
“Mo ń dúró de ìtúsílẹ̀ rẹ, Olúwa.
19 Ko Kara, ka aki te ope ki runga ki a ia: otiia ka aki ia ki to ratou rekereke.
“Ẹgbẹ́ ogun àwọn ẹlẹ́ṣin yóò kọlu Gadi, ṣùgbọ́n yóò kọlu wọ́n ní gìgísẹ̀ wọn.
20 Ko ta Ahera, ka momona tana taro, a he kai kingi ona hua.
“Oúnjẹ Aṣeri yóò dára; yóò ṣe àsè tí ó yẹ fún ọba.
21 Ko Napatari, he hata kua tukua kia haere: e homai ana e ia nga kupu papai.
“Naftali yóò jẹ́ abo àgbọ̀nrín tí a tú sílẹ̀ tí ó ń bí ọmọ dáradára.
22 Ko Hohepa he peka hua, he peka hua i te taha o te puna; e toro atu ana ona manga ki tua o te taiepa:
“Josẹfu jẹ́ àjàrà eléso, àjàrà eléso ní etí odò, tí ẹ̀ka rẹ̀ gun orí odi.
23 I whakatupu kino nga kaikopere i a ia, i pere mai hoki, i kino hoki ki a ia:
Pẹ̀lú ìkorò, àwọn tafàtafà dojú ìjà kọ ọ́, wọ́n tafà sí í pẹ̀lú ìkanra.
24 Otiia i mau tana kopere i runga i te kaha, a i whakapakaritia nga takakau o ona ringa e nga ringa o te Mea Kaha o Hakopa, no reira nei te hepara, te kamaka o Iharaira,
Ṣùgbọ́n ọrun rẹ̀ dúró ni agbára, ọwọ́ agbára rẹ̀ ni a sì mu lára le, nítorí ọwọ́ alágbára Jakọbu, nítorí olùtọ́jú àti aláàbò àpáta Israẹli,
25 Ara e te Atua o tou papa, mana ano koe e awhina; e te Kaha Rawa hoki, mana e tuku mai ki a koe nga manaaki o te rangi i runga, nga manaaki hoki o te rire e takoto ana i raro, nga manaaki o nga u, o te kopu hoki:
nítorí Ọlọ́run baba rẹ tí ó ràn ọ́ lọ́wọ́, nítorí Olódùmarè tí ó bùkún ọ pẹ̀lú láti ọ̀run wá, ìbùkún ọ̀gbìn tí ó wà ní ìsàlẹ̀, ìbùkún ti ọmú àti ti inú.
26 Hira ake nga manaaki a tou papa i nga manaaki a oku tupuna, tae atu ana ki tera taha rawa o nga pukepuke tu tonu: ka tau iho ena mea ki runga ki te matenga o Hohepa, ki te tumuaki hoki ona i motuhia atu nei i ona tuakana.
Ìbùkún baba rẹ pọ̀ púpọ̀ ju ìbùkún àwọn òkè ńlá ìgbàanì, ju ẹ̀bùn ńlá àwọn òkè láéláé. Jẹ́ kí gbogbo èyí sọ̀kalẹ̀ sí orí Josẹfu, lé ìpéǹpéjú ọmọ-aládé láàrín arákùnrin rẹ̀.
27 Ka haehae a Pineamine ano he wuruhi: ka kainga e ia te tupapaku i te ata, a i te ahiahi ka tuwhaina e ia nga taonga parakete.
“Benjamini jẹ́ ìkookò tí ó burú; ní òwúrọ̀ ni ó jẹ ẹran ọdẹ rẹ, ní àṣálẹ́, ó pín ìkógun.”
28 Ko enei katoa nga iwi kotahi tekau ma rua o Iharaira: ko te korero hoki tenei a to ratou papa ki a ratou, ko tana manaaki i a ratou: i manaakitia ratou e ia, tenei, tenei, me tona manaaki ano.
Gbogbo ìwọ̀nyí ni àwọn ẹ̀yà Israẹli méjìlá, èyí sì ni ohun tí baba wọn sọ fún wọn nígbà tí ó súre fún wọn, tí ó sì fún ẹnìkọ̀ọ̀kan ní ìbùkún tí ó tọ́ sí i.
29 A i whakahau ia ki a ratou, i mea ki a ratou, Ka kohia atu ahau ki toku iwi: tanumia ahau ki oku matua, ki te ana i te parae o Eperona Hiti,
Nígbà náà ni ó fún wọn ní àwọn ìlànà yìí, “Ọjọ́ ikú mi kù fẹ́ẹ́rẹ́. Kí ẹ sin mí sí ibojì pẹ̀lú àwọn baba mi ní inú àpáta ní ilẹ̀ Hiti ará Efroni.
30 Ki te ana i te parae o Makapera, i te ritenga o Mamere, i te whenua o Kanaana, i hokona, me te parae ano, e Aperahama i a Eperona Hiti, kia puritia hei tanumanga.
Ihò àpáta tí ó wà ní ilẹ̀ Makpela, nítòsí Mamre ní Kenaani, èyí tí Abrahamu rà gẹ́gẹ́ bí ilẹ̀ ìsìnkú lọ́wọ́ Efroni ará Hiti pẹ̀lú ilẹ̀ rẹ̀.
31 I tanumia a Aperahama raua ko Hara, ko tana wahine, ki reira; i tanumia a Ihaka raua ko Ripeka, ko tana wahine, ki reira; i tanumia hoki a Rea e ahau ki reira.
Níbẹ̀ ni a sin Abrahamu àti aya rẹ̀ Sara sí, níbẹ̀ ni a sin Isaaki àti Rebeka aya rẹ̀ sí, níbẹ̀ sì ni mo sìnkú Lea sí.
32 I hokona te parae me te ana i reira i nga tama a Hete.
Ilẹ̀ náà àti ihò àpáta tí ó wà nínú rẹ̀ ni a rà lọ́wọ́ ará Hiti.”
33 A, ka mutu te whakahau a Hakopa ki ana tama, ka pepeke ake ona waewae ki roto ki te moenga, a ka hemo, ka kohia atu ki tona iwi.
Nígbà tí Jakọbu ti pàṣẹ yìí fún àwọn ọmọ rẹ̀, ó gbé ẹsẹ̀ rẹ̀ sókè sórí ibùsùn, ó sì kú, a sì ko jọ pọ̀ mọ́ àwọn ènìyàn rẹ̀.