< Kenehi 26 >

1 Na ka matekai te whenua, haunga te matekai tuatahi i puta mai i nga ra o Aperahama. A ka haere a Ihaka ki a Apimereke, kingi o nga Pirihitini, ki Kerara.
Ìyàn kan sì mú ní ilẹ̀ náà, yàtọ̀ fún èyí tí ó mú ní ìgbà ayé Abrahamu, Isaaki sì lọ sọ́dọ̀ Abimeleki ọba àwọn Filistini ni Gerari.
2 Na ka puta mai a Ihowa ki a ia, ka mea, Kaua e haere ki raro, ki Ihipa; e noho ki te whenua e korero ai ahau ki a koe:
Olúwa sì fi ara han Isaaki, ó sì wí pé, “Má ṣe sọ̀kalẹ̀ lọ sí Ejibiti, jókòó ní ilẹ̀ tí èmi ó fún ọ.
3 E noho i tenei whenua, a ka tata ahau ki a koe, ka manaaki hoki i a koe; ka hoatu nei hoki e ahau enei whenua katoa ki a koutou ko ou uri, a ka whakapumautia te oati i oati ai ahau ki a Aperahama, ki tou papa;
Máa ṣe àtìpó ní ilẹ̀ yìí fún ìgbà díẹ̀, èmi ó sì wà pẹ̀lú rẹ, èmi yóò sì bùkún fún ọ. Nítorí ìwọ àti irú-ọmọ rẹ ni èmi yóò fi gbogbo àwọn ilẹ̀ wọ̀nyí fún, èmi yóò sì fi ìdí ìbúra tí mo ṣe fún Abrahamu baba rẹ múlẹ̀.
4 A ka whakanuia e ahau ou uri kia pera me nga whetu o te rangi, ka hoatu hoki e ahau enei whenua katoa ki ou uri; a ma tou uri ka manaakitia ai nga iwi katoa o te whenua;
Èmi yóò sọ ìran rẹ di púpọ̀ bí ìràwọ̀ ojú ọ̀run, èmi yóò sì fi gbogbo ilẹ̀ yìí fún irú àwọn ọmọ rẹ, àti nípasẹ̀ irú-ọmọ rẹ ni a ó bùkún fún gbogbo orílẹ̀-èdè ayé,
5 No te mea i rongo a Aperahama ki toku reo, i mau ki aku ako, ki aku whakahau, ki aku tikanga, ki aku ture.
nítorí tí Abrahamu gba ohùn mi gbọ́, ó sì pa gbogbo ìkìlọ̀, àṣẹ, ìlànà àti òfin mi mọ́.”
6 Na ka noho a Ihaka i Kerara:
Nítorí náà Isaaki jókòó ní Gerari.
7 A ka ui nga tangata o taua wahi ki tana wahine; a ka mea ia, Ko toku tuahine ia: i wehi hoki ia, te mea ai, Ko taku wahine; i mea hoki, Kei patua ahau e nga tangata o tenei wahi mo Ripeka; he ataahua hoki ia ki te titiro atu.
Nígbà tí àwọn ọkùnrin ìlú náà bi í léèrè ní ti aya rẹ̀, ó sì wí pé, “Arábìnrin mi ní í ṣe,” nítorí tí ó bẹ̀rù láti jẹ́wọ́ wí pé, “Aya mi ni.” Ó ń rò wí pé, “Kí àwọn ọkùnrin ibẹ̀ náà má ba à pa mí nítorí Rebeka, nítorí tí òun ní ẹwà púpọ̀.”
8 A ka maha ona ra ki reira, ka titiro atu a Apimereke, kingi o nga Pirihitini, i te matapihi, a ka kite, na, ko Ihaka e takaro ana ki a Ripeka, ki tana wahine.
Nígbà tí Isaaki sì ti wà níbẹ̀ fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọjọ́, Abimeleki ọba Filistini yọjú lójú fèrèsé, ó sì rí Isaaki ń bá Rebeka aya rẹ̀ tage.
9 Na ka karangatia e Apimereke a Ihaka, ka mea atu, Koia ano, ko tau wahine tonu ia: na te aha koe i mea ia, Ko taku tuahine ia? Ka mea a Ihaka ki a ia, I mea hoki ahau, Kei mate ahau mona.
Nígbà náà ni Abimeleki ránṣẹ́ pe Isaaki ó sì wí fun pé, “Nítòótọ́, aya rẹ ni obìnrin yìí í ṣe, èéṣe tí ìwọ fi wí fún wa pé arábìnrin mi ni?” Isaaki sì fèsì pé, “Nítorí mo rò pé mo le pàdánù ẹ̀mí mi nítorí rẹ̀.”
10 Na ka mea a Apimereke, He aha tenei mahi au ki a matou? wahi iti kua takoto tetahi o te iwi nei ki tau wahine, a kua takina mai e koe he hara ki runga ki a matou.
Nígbà náà ni Abimeleki dáhùn pé, “Èwo ni èyí tí ìwọ ṣe sí wa yìí? Bí ọ̀kan nínú àwọn ènìyàn wọ̀nyí bá ti bá a lòpọ̀ ń kọ́? Ìwọ ìbá wá mú ẹ̀bi wá sórí wa.”
11 Na ka whakatupato a Apimereke ki tona iwi katoa, ka mea, Ko te tangata e pa ki tenei tangata, ki tana wahine ranei, he pono ka mate ia.
Nígbà náà ni Abimeleki pàṣẹ fún gbogbo ènìyàn pé, “Ẹnikẹ́ni tí ó bá fọwọ́ kan ọkùnrin yìí tàbí aya rẹ̀ yóò jẹ̀bi ikú.”
12 A i rui a Ihaka ki taua whenua, a maea ake i taua tau ano kotahi rau: i manaakitia hoki ia e Ihowa:
Ní ọdún náà, Isaaki gbin ohun ọ̀gbìn sí ilẹ̀ náà, ó sì kórè rẹ̀ ní ìlọ́po ọgọ́rùn-ún ọdún ni ọdún kan náà, nítorí Olúwa bùkún un.
13 Na ka kake taua tangata, ka tino nui haere, no ka nui noa ake ia:
Ọkùnrin náà sì di ọlọ́rọ̀ púpọ̀, ọrọ̀ rẹ̀ sì ń pọ̀ si, títí ó fi di ènìyàn ńlá.
14 A ka whiwhi ia i nga kahui hipi, i nga kahui kau, i te tini o te pononga: a ka hae nga Pirihitini ki a ia.
Ó ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹran ọ̀sìn àti agbo ẹran àti àwọn ìránṣẹ́ tó bẹ́ẹ̀ tí àwọn Filistini ń ṣe ìlara rẹ̀.
15 Na ko nga poka katoa i keria e nga pononga a tona papa i nga ra o Aperahama, o tona papa, i tanumia era e nga Pirihitini, i whakakiia hoki ki te oneone.
Nítorí náà àwọn ará Filistini ru erùpẹ̀ di gbogbo kànga tí àwọn ìránṣẹ́ Abrahamu baba rẹ̀ ti gbẹ́.
16 Na ka mea a Apimereke ki a Ihaka, Haere atu i roto i a matou; he kaha rawa hoki koe i a matou.
Nígbà náà ni Abimeleki wí fún Isaaki pé, “Jáde kúrò ní ilẹ̀ wa, nítorí tí ìwọ ti di alágbára púpọ̀ jù wá lọ.”
17 Na haere atu ana a Ihaka i reira, a whakaturia ana tona puni ki te awaawa o Kerara, a noho ana i reira.
Isaaki sì ṣí kúrò níbẹ̀, ó sì pàgọ́ sí àfonífojì Gerari ó sì ń gbé ibẹ̀.
18 Na ka keria ano e Ihaka nga poka wai i keria ra i nga ra o Aperahama, o tona papa; i tanumia hoki e nga Pirihitini i muri i te matenga o Aperahama: a huaina ana e ia hei ingoa mo aua poka ko nga ingoa i huaina iho e tona papa.
Isaaki sì ṣe àtúngbẹ́ àwọn kànga tí Abrahamu baba rẹ̀ ti gbẹ́ nígbà ayé rẹ̀, èyí tí àwọn Filistini ti dí lẹ́yìn ikú Abrahamu baba rẹ̀, ó sì fún wọn lórúkọ tí baba rẹ̀ ti sọ wọ́n tẹ́lẹ̀.
19 Na ka keri nga pononga a Ihaka ki te awaawa, a ka kitea e ratou i reira he puna manawa whenua.
Àwọn ìránṣẹ́ Isaaki sì gbẹ́ kànga ní àfonífojì náà, wọ́n kan ìsun omi níbẹ̀.
20 Na ka tautohe nga hepara o Kerara ki nga hepara a Ihaka, ka mea, Na matou tenei wai: a huaina ana e ia te ingoa o te poka ko Eheke; mo ratou hoki i whakatetete ki a ia.
Ṣùgbọ́n àwọn darandaran Gerari ń bá àwọn darandaran Isaaki jà sí kànga náà pé àwọn ni àwọn ni í. Nítorí náà ni ó fi pe orúkọ kànga náà ní Eseki, nítorí pé wọ́n bá a jà sí kànga náà.
21 Na ka keri ratou i tetahi atu poka, ka tautohetia ano tera e ratou: a huaina iho e ia tona ingoa ko Hitina.
Àwọn ìránṣẹ́ Isaaki tún gbẹ́ kànga mìíràn, wọ́n sì tún jà nítorí rẹ̀ pẹ̀lú, ó sì sọ orúkọ rẹ̀ ní Sitna.
22 Na ka neke atu ia i reira, a ka keri i tetahi atu poka; kihai tera i tautohetia e ratou: na ka huaina e ia tona ingoa ko Rehopoto; i mea hoki ia, Katahi nei hoki a Ihowa ka whakawatea i tetahi nohoanga mo tatou, a ka hua tatou ki runga ki te whe nua.
Ó sì tún kúrò níbẹ̀, ó sì gbẹ́ kànga mìíràn, wọn kò sì jásí èyí rárá, ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Rehoboti, ó wí pé, “Nísinsin yìí, Olúwa ti fi ààyè gbà wá, a ó sì gbilẹ̀ si ní ilẹ̀ náà.”
23 Na ka haere atu ia i reira ki runga, ki Peerehepa.
Láti ibẹ̀, ó kúrò lọ sí Beerṣeba.
24 A ka puta mai a Ihowa ki a ia i taua po ano, ka mea, Ko ahau te Atua o Aperahama, o tou papa: kaua e wehi, kei a koe nei hoki ahau, a ka manaaki ahau i a koe, ka whakanui hoki i ou uri, he whakaaro ki a Aperahama, ki taku pononga.
Ní òru ọjọ́ tí ó dé ibẹ̀, Olúwa sì fi ara hàn án, ó sì wí pé, “Èmi ni Ọlọ́run Abrahamu baba rẹ. Má ṣe bẹ̀rù nítorí èmi wà pẹ̀lú rẹ, èmi yóò sì bùsi fún ọ, èmi yóò sì sọ iye ìran rẹ di púpọ̀, nítorí Abrahamu ìránṣẹ́ mi.”
25 Na ka hanga e ia he aata ki reira, a ka karanga ki te ingoa o Ihowa, a whakaturia ana hoki e ia tona teneti ki reira: a ka keria tetahi poka ki reira e nga pononga a Ihaka.
Isaaki sì kọ́ pẹpẹ kan síbẹ̀, ó sì pe orúkọ Olúwa. Níbẹ̀ ni ó pàgọ́ rẹ̀ sí, àwọn ìránṣẹ́ rẹ sì gbẹ́ kànga kan níbẹ̀.
26 Na ka haere mai a Apimereke i Kerara ki a ia, ratou ko Ahutata ko tetahi o ona hoa, ko Pikora hoki, ko te rangatira o tana ope.
Nígbà náà ni Abimeleki tọ̀ ọ́ wá láti Gerari, àti Ahussati, olùdámọ̀ràn rẹ̀ àti Fikoli, olórí ogun rẹ̀.
27 A ka mea a Ihaka ki a ratou, I haere mai koutou ki ahau ki te aha, ina hoki kua kino koutou ki ahau, kua pei hoki i ahau i roto i a koutou?
Isaaki sì bi wọ́n léèrè pé, “Èéṣe tí ẹ̀yin tọ̀ mí wá, níwọ̀n ìgbà tí ẹ̀yin kórìíra mi tí ẹ sì lé mi jáde kúrò lọ́dọ̀ yín?”
28 A ka mea ratou, I kite marama matou, kei a koe a Ihowa: koia matou i mea ai, Kia takoto aianei he oati ki waenganui i a tatou, ki waenganui o matou, ou, kia whakarite kawenata hoki matou ki a koe;
Wọ́n dáhùn pé, “A rí i dájú pé Olúwa wà pẹ̀lú rẹ, nítorí náà ni a fi rò ó wí pé, ó yẹ kí májẹ̀mú kí o wà láàrín àwa àti ìwọ. Jẹ́ kí a ṣe àdéhùn
29 Kia kaua koe e tukino i a matou, kia penei me matou kihai nei i pa ki a koe, kihai hoki i aha ki a koe, heoi ko te pai anake, i ata tuku ano i a koe: inaianei ko koe te manaakitanga a Ihowa.
pé ìwọ kì yóò ṣe wá ní ibi, bí àwa pẹ̀lú kò ti ṣe ọ́ ní aburú, tí a sì ń ṣe ọ́ dáradára, tí a sì rán ọ jáde ní àlàáfíà láìṣe ọ́ ní ibi, kíyèsi Olúwa sì ti bùkún fún ọ.”
30 Na ka tukua e ia he hakari ma ratou, a ka kai ratou, ka inu.
Isaaki sì ṣe àsè fún wọn, wọn sì jẹ, wọ́n sì mu.
31 Na ka maranga wawe ratou i te ata, ka oati ratou tetahi ki tetahi: a tukua ana ratou e Ihaka kia haere, a hoki marie atu ana ratou i a ia.
Ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì wọn búra fún ara wọn. Isaaki sì rán wọn lọ, wọ́n sì lọ ní àlàáfíà.
32 A i taua rangi ano ka haere mai nga pononga a Ihaka, ka korero ki a ia i te poka i keria e ratou, a ka mea ki a ia, Kua kitea e matou he wai.
Ní ọjọ́ náà gan an ni àwọn ìránṣẹ́ Isaaki wá sọ fún un pé àwọn ti kan omi ní kànga kan tí àwọn gbẹ́.
33 A huaina iho e ia taua poka ko Hepaha: no kona te ingoa o tena pa, o Peerehepa, a mohoa noa nei.
Ó sì pe orúkọ kànga náà ní Ṣiba, títí di òní olónìí, orúkọ ìlú náà ni Beerṣeba.
34 A, ka wha tekau nga tau o Ehau, ka tango ia i a Iuriti tamahine a Peeri Hiti, hei wahine mana, rauako Pahemata tamahine a Erona Hiti:
Nígbà tí Esau pé ọmọ ogójì ọdún ó fẹ́ ọmọbìnrin kan tí a ń pè ní Juditi, ọmọ Beeri, ará Hiti, ó sì tún fẹ́ Basemati, ọmọ Eloni ará Hiti.
35 A ka waiho raua hei mea pouri ki nga ngakau o Ihaka raua ko Ripeka.
Fífẹ́ tí a fẹ́ àwọn obìnrin wọ̀nyí jẹ́ ìbànújẹ́ fún Isaaki àti Rebeka.

< Kenehi 26 >