< Kenehi 18 >

1 A ka puta ano a Ihowa ki a ia i nga oki o Mamere, i a ia e noho ana i te kuwaha o te teneti i te tikakatanga o te ra;
Olúwa sì farahan Abrahamu nítòsí àwọn igi ńlá Mamre, bí ó ti jókòó ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ rẹ̀, nígbà tí ọjọ́-kanrí tí oòrùn sì mú.
2 A ka anga ake ona kanohi, ka titiro, na ko nga tangata tokotoru e tu ana i tona taha: a, no tona kitenga atu, ka rere atu ia i te kuwaha o te teneti ki te whakatau i a ratou, a ka piko ki te whenua,
Abrahamu gbójú sókè, ó sì rí àwọn ọkùnrin mẹ́ta tí wọn dúró nítòsí rẹ̀. Nígbà tí ó rí wọn, ó sáré láti lọ pàdé wọn, ó sì tẹríba bí ó ti ń kí wọn.
3 Ka mea, E toku Ariki, ki te mea he pai toku ki tau titiro, kaua ra e kapea tau pononga:
Ó wí pé, “Bí mo bá rí ojúrere yín Olúwa mi, ẹ má ṣe lọ láì yà sọ́dọ̀ ìránṣẹ́ yín.
4 Kia tikina koa tetahi wai, ka horoi i o koutou waewae, a ka okioki koutou i raro i te rakau:
Ẹ jẹ́ kí a bu omi díẹ̀ wá kí ẹ̀yin kí ó wẹ ẹsẹ̀ yín, kí ẹ sì sinmi lábẹ́ igi níhìn-ín.
5 A maku e tiki tetahi wahi taro hei oranga mo o koutou ngakau; hei muri ra ka haere ai koutou: he mea hoki kua tae mai nei koutou ki ta koutou pononga. A ka mea ratou, Penatia me tau i ki na.
Ẹ jẹ́ kí n wá oúnjẹ wá fún un yín, kí ẹ̀yin kí ó lè jẹ, kí ara sì tù yín, kí ẹ si tẹ̀síwájú ní ọ̀nà yín, nígbà tí ẹ ti yà ní ọ̀dọ̀ ìránṣẹ́ yín.” Wọn sì wí pé “Ó dára.”
6 Na ka hohoro a Aperahama ki te teneti ki a Hara, a ka mea, Kia hohoro te pokepoke i tetahi paraoa pai, kia toru nga mehua, ka hanga i etahi keke.
Abrahamu sì yára tọ Sara aya rẹ̀ lọ nínú àgọ́, ó wí pé, “Tètè mú òsùwọ̀n ìyẹ̀fun dáradára mẹ́ta kí o sì pò ó pọ̀, kí o sì ṣe oúnjẹ.”
7 Na ka rere a Aperahama ki te kahui, a hopukia ana e ia tetahi kuao kau, he kiri ngawari, he mea pai, a hoatu ana e ia ki tetahi taitamariki; a hohoro ana ia te taka i taua mea.
Abrahamu sì tún sáré lọ sí ibi agbo ẹran, ó sì mú ọmọ màlúù kan fún ìránṣẹ́ rẹ̀, ìránṣẹ́ náà sì tètè ṣè é.
8 Na ka tikina e ia he pata, he waiu, me te kuao i raweketia e ia, a whakatakotoria ana ki to ratou aroaro; me te tu ano ia i to ratou taha i raro i te rakau, a ka kai ratou.
Ó sì mú wàrà àti mílíìkì àti màlúù tí ó ti pèsè, ó sì gbé síwájú wọn. Ó sì dúró nítòsí wọn lábẹ́ igi bí wọn ti ń jẹ ẹ́.
9 Na ka mea ratou ki a ia, Kei hea a Hara, tau wahine? A ka mea ia, Ara, kei te teneti.
Wọn béèrè pé, “Sara aya rẹ ń kọ́?” Ó dáhùn pé, “Ó wà nínú àgọ́.”
10 Na ka mea ia, He pono ka hoki mai ano ahau ki a koe a te huringa mai ano o te wa; a ka whai tama tau wahine, a Hara. Na ka rongo atu a Hara i te kuwaha o te teneti, i muri i a ia.
Nígbà náà ni Olúwa wí fún un pé, “Èmi yóò sì tún padà tọ̀ ọ́ wá nítòótọ́ ní ìwòyí àmọ́dún; Sara aya rẹ yóò sì bí ọmọkùnrin kan.” Sara sì ń dẹtí gbọ́ láti ẹnu-ọ̀nà àgọ́ tí ó wà lẹ́yìn ọkùnrin náà.
11 Na, kua koroheke rawa a Aperahama raua ko Hara, kua maha o raua ra; kua mutu a Hara te pera me etahi wahine.
Abrahamu àti Sara sì ti di arúgbó, Sara sì ti kọjá àsìkò ìbímọ.
12 Na ka kata a Hara i roto i a ia, ka mea, Ka ruruhitia nei ahau, a tera ranei ahau e whai koa, he koroheke nei ano hoki toku ariki?
Nítorí náà, Sara rẹ́rìn-ín nínú ara rẹ̀ bí ó ti ń rò ó lọ́kàn rẹ̀ pé, “Lẹ́yìn ìgbà tí mo ti di arúgbó tán tí olúwa mi pẹ̀lú sì ti gbó jọ̀kújọ̀kú, èmi yóò ha tún lè bímọ?”
13 Na ka mea a Ihowa ki a Aperahama, He aha a Hara i kata ai, i mea ai, He pono, ka whanau tamariki ranei ahau, he ruruhi nei hoki ahau?
Nígbà náà ni Olúwa wí fún Abrahamu pé, “Kín ló dé tí Sara fi rẹ́rìn-ín tí ó sì wí pé, ‘Èmi yóò ha bímọ nítòótọ́, nígbà tí mo di ẹni ogbó tán?’
14 He pakeke rawa ranei tetahi mea ki a Ihowa? Kei te taima i whakaritea, kei te hurihanga mai o te wa, ka hoki mai ahau ki a koe, a ka whai tamaiti a Hara.
Ǹjẹ́ ohunkóhun wà tí ó ṣòro jù fún Olúwa? Èmi ó padà tọ̀ ọ́ wá ní ìwòyí àmọ́dún, Sara yóò sì bí ọmọkùnrin.”
15 Na ka whakawareware a Hara, ka mea, Kihai ahau i kata: i wehi hoki ia. A ka mea ia, Kahore; i kata tonu koe.
Ẹ̀rù sì ba Sara, ó sì sẹ́ pé òun kò rẹ́rìn-ín. Ṣùgbọ́n Olúwa wí fún un pé, “Dájúdájú ìwọ rẹ́rìn-ín.”
16 Na ka whakatika atu nga tangata ra i reira, a ka titiro ki te ritenga mai o Horoma: i haere ano a Aperahama i a ratou, ki te tuku i a ratou kia haere.
Nígbà tí àwọn ọkùnrin náà dìde láti máa lọ, wọn kọjú sí ọ̀nà Sodomu, Abrahamu sì sìn wọ́n dé ọ̀nà.
17 A ka mea a Ihowa, Me huna ranei e ahau i a Aperahama taku e mea ai;
Nígbà náà ni Olúwa wí pé, “Ǹjẹ́ èmi yóò ha pa ohun tí mo fẹ́ ṣe mọ́ fún Abrahamu bí?
18 Ka meinga nei hoki a Aperahama hei iwi nui, hei iwi kaha, a mana ka manaakitia ai nga iwi katoa o te ao?
Dájúdájú Abrahamu yóò sá à di orílẹ̀-èdè ńlá àti alágbára, àti gbogbo orílẹ̀-èdè ayé ni a ó bùkún fún nípasẹ̀ rẹ̀.
19 E mohio ana hoki ahau ki a ia, hei mea kia whakahaua iho ai e ia ana tama, me tona whare, i muri i a ia, a kia whakaritea e ratou te ara o Ihowa, ka mahi hoki i te tika, i te whakawa; a kia kawea mai ai e Ihowa ki runga ki a Aperahama nga mea ka toa i korerotia e ia mona.
Nítorí tí èmi ti yàn án láti kọ́ àwọn ọmọ rẹ̀ àti àwọn ará ilé rẹ̀ lẹ́yìn rẹ̀, láti máa pa ọ̀nà Olúwa mọ nípa ṣíṣe olóòtítọ́ àti olódodo: kí Olúwa le è mú ìlérí rẹ̀ fún Abrahamu ṣẹ.”
20 Na ka mea a Ihowa, i te mea he nui te karanga o Horoma, o Komora, he taimaha rawa hoki o raua kino;
Olúwa sì wí pé, igbe Sodomu àti Gomorra pọ̀ púpọ̀ àti pé ẹ̀ṣẹ̀ wọn burú jọjọ.
21 Me haere tenei ahau kia kite he mea rite ranei ta raua mahi ki tona karanga kua tae ake nei ki ahau; a ki te kahore, ka mohio ahau.
“Èmi yóò sọ̀kalẹ̀ síbẹ̀ láti ṣe ìwádìí igbe tí ó dé sí etí ìgbọ́ mi nípa wọn, kí èmi sì mọ òtítọ́ tí ó wà níbẹ̀.”
22 Na ka tahuri nga tangata ra i reira, a ka ahu ki Horoma: ko Aperahama ia i tu tonu i te aroaro o te Atua.
Àwọn ọkùnrin náà yí padà, wọ́n sì ń lọ sí ìhà Sodomu. Ṣùgbọ́n Abrahamu dúró níbẹ̀ níwájú Olúwa.
23 Na ka whakatata a Aperahama, ka mea, Ka whakangaromia ano hoki e koe te tangata tika raua ko te tangata kino?
Nígbà náà ni Abrahamu súnmọ́ ọ̀dọ̀ Olúwa, ó sì wí pé, “Ìwọ yóò ha pa olódodo ènìyàn àti ènìyàn búburú run papọ̀ bí?”
24 Akuanei pea e rima tekau nga tangata tika i roto i te pa: ka whakangaromia ranei e koe, e kore ranei koe e tohu i taua wahi mo nga tangata tika e rima tekau i roto?
“Bí ó bá ṣe pé ìwọ rí àádọ́ta olódodo nínú ìlú náà, ìwọ yóò ha run ún, ìwọ kì yóò ha dá ìlú náà sí nítorí àwọn àádọ́ta olódodo tí ó wà nínú rẹ̀ náà?
25 Kaua ra tena e waiho hei tikanga mo tau mahi, te whakamate ngatahi i te tangata tika raua ko te tangata kino; penei ka rite te tangata tika ki te tangata kino; kaua ra koe e pera: e kore ranei e tika te mahi a te Kaiwhakawa o te whenua katoa?
Kò jẹ́ rí bẹ́ẹ̀! Dájúdájú ìwọ kì yóò ṣe ohun tí ó jọ bẹ́ẹ̀, láti pa olódodo pẹ̀lú àwọn ènìyàn rere àti àwọn ènìyàn búburú. Dájúdájú, ìwọ kì yóò ṣe èyí tí ó tọ́ bi?”
26 Na ka mea a Ihowa, Ki te kitea e ahau i Horoma e rima tekau nga tangata tika i roto i te pa, ka tohungia e ahau tena wahi katoa, ka whakaaro hoki ki a ratou.
Olúwa wí pé, “Bí mo bá rí àádọ́ta olódodo ní ìlú Sodomu, èmi yóò dá ìlú náà sí nítorí tiwọn.”
27 Na ka whakahoki a Aperahama, ka mea, Na, kua timata nei ahau te korero ki te Ariki; he puehu nei ahau, he pungarehu:
Abrahamu sì tún tẹ̀síwájú pé, “Wò ó nísinsin yìí, níwọ̀n bí èmi ti ní ìgboyà láti bẹ̀rẹ̀ sí sọ̀rọ̀ níwájú Olúwa, èmi ẹni tí í ṣe erùpẹ̀ àti eérú,
28 Tera pea e kore te tokorima o te rima tekau o nga tangata tika ka kore te tokorima, e whakangaro ranei koe i te pa katoa? Ka mea ia, E kore e whakangaromia e ahau ki te mea ka kitea e ahau i reira nga tangata e wha tekau ma rima.
bí ó bá ṣe pe olódodo márùndínláàádọ́ta ni ó wà nínú ìlú, ìwọ yóò ha pa ìlú náà run nítorí ènìyàn márùn-ún bí?” Olúwa dáhùn pé, “Èmi kì yóò pa ìlú náà run bí mo bá rí olódodo márùndínláàádọ́ta nínú rẹ̀.”
29 Na ka korero atu ano ia ki a ia, ka mea, Tera pea e kitea e wha tekau kei reira. Ka mea ia, Ka whakaaro ahau ki te wha tekau, a e kore e meatia e ahau.
Òun sì tún wí lẹ́ẹ̀kan si pé, “Bí ó bá ṣe pé ogójì ni ń kọ́?” Olúwa sì tún wí pé, “Èmi kì yóò pa ìlú náà run bí mo bá rí olódodo ogójì nínú rẹ̀.”
30 Ano ra ko ia, Kaua ra e riri te Ariki, a ka korero ahau: Tera pea e kitea e toru tekau kei reira. Ka mea ia, E kore e meatia e ahau, ki te kitea e ahau e toru tekau kei reira.
Abrahamu sì tún bẹ Olúwa pé, “Kí Olúwa má ṣe bínú, ṣùgbọ́n èmi yóò sọ̀rọ̀. Bí ó bá ṣe pé ọgbọ̀n ni a rí níbẹ̀ ń kọ́?” Olúwa dáhùn pé, “Bí mó bá rí ọgbọ̀n, èmi kì yóò pa ìlú run.”
31 A ka mea ia, Na, kua whakapakari nei ahau ki te korero ki te Ariki: Tera pea e kitea e rua tekau kei reira. Ka mea ia, Ka whakaaro ahau ki nga tekau e rua, a e kore e whakangaromia e ahau.
Abrahamu wí pé, “Níwọ́n bí mo ti ní ìgboyà láti bá Olúwa sọ̀rọ̀ báyìí, jẹ́ kí n tẹ̀síwájú. Bí o bá ṣe pé olódodo ogún péré ni ó wà nínú ìlú náà ń kọ́?” Olúwa sì dáhùn pé, “Èmi kì yóò pa á run nítorí ogún ènìyàn náà.”
32 Na ka mea ia, Kaua e riri te Ariki ki te korero ahau, heoi ano ko tenei korerotanga: Tera pea e kitea kotahi tekau kei reira. Ka mea ia, Ka whakaaro ahau ki te tekau kotahi, a e kore e whakangaromia e ahau.
Abrahamu sì wí pé, “Jọ̀wọ́ má ṣe bínú Olúwa. Jẹ́ kí ń béèrè lẹ́ẹ̀kan si. Bí ó bá ṣe pé ènìyàn mẹ́wàá ni ó jẹ́ olódodo ń kọ́?” Olúwa wí pé, “Nítorí ènìyàn mẹ́wàá náà, èmi kì yóò pa á run.”
33 Na ka haere a Ihowa i te mutunga o tana korero ki a Aperahama: a hoki ana a Aperahama ki tona wahi.
Olúwa sì bá tirẹ̀ lọ, nígbà tí ó bá Abrahamu sọ̀rọ̀ tán, Abrahamu sì padà sílé.

< Kenehi 18 >