< Ehekiera 30 >

1 I puta mai ano te kupu a Ihowa ki ahau, i mea,
Ọ̀rọ̀ Olúwa tún tọ̀ mí wá: wí pé:
2 E te tama a te tangata, poropiti, mea atu, Ko te kupu tenei a te Ariki, a Ihowa; Aue koutou, Taukiri e, taua ra nei!
“Ọmọ ènìyàn, sọtẹ́lẹ̀ kí o sì wí pé: ‘Báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí: “‘Hu, kí o sì wí pé, “Ó ṣe fún ọjọ́ náà!”
3 Kua tata mai hoki te ra, te ra o Ihowa kua tata mai, he rangi tukupu, ko te wa ia o nga iwi.
Nítorí ọjọ́ náà súnmọ́ tòsí àní ọjọ́ Olúwa súnmọ́ tòsí, ọjọ́ tí ọjọ́ ìkùùkuu ṣú dúdú, àsìkò ìparun fún àwọn kèfèrí.
4 A ka tae mai te hoari ki Ihipa, ka nui ano te mamae o Etiopia, ina hinga nga tupapaku ki Ihipa; a ka riro atu i a ratou ona mano, ka wahia hoki ona turanga.
Idà yóò wá sórí Ejibiti ìrora ńlá yóò sì wá sórí Kuṣi. Nígbà tí àwọn tí a pa yóò ṣubú ní Ejibiti wọn yóò kò ọrọ̀ rẹ̀ lọ ìpìlẹ̀ rẹ̀ yóò sì wó lulẹ̀.
5 Ko Etiopia, ko Putu, ko Ruru, ko te iwi whakauru katoa, ko Kupu, ko nga tangata ano o te whenua o te kawenata, ka hinga ngatahi ratou i te hoari.
Kuṣi àti Puti, Libia, Ludi àti gbogbo Arabia, Kubu àti àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà tí ó mulẹ̀ yóò ṣubú nípa idà pẹ̀lú Ejibiti.
6 Ko te kupu tenei a Ihowa; Ka hinga ano nga kaiawhina o Ihipa; ka riro iho ano te whakapehapeha o tona kaha; ka hinga ratou i te hoari i reira, i te taumaihi atu o Hewene, e ai ta te Ariki, ta Ihowa.
“‘Èyí yìí ní Olúwa wí: “‘Àwọn àlejò Ejibiti yóò ṣubú agbára ìgbéraga rẹ yóò kùnà láti Migdoli títí dé Siene, wọn yóò ti ipa idà ṣubú nínú rẹ; ní Olúwa Olódùmarè wí.
7 Ka noho kau noa iho ratou i waenganui o nga whenua tuhea, ka tu ano ona pa i waenganui i nga pa kua ururuatia.
Wọn yóò sì wà lára àwọn ilẹ̀ tí ó di ahoro, ìlú rẹ yóò sì wà ní ara àwọn ìlú tí ó di ahoro.
8 A ka mohio ratou ko Ihowa ahau, ina tukua e ahau he ahi ki Ihipa, ina whakamotitia ona kaiawhina katoa.
Lẹ́yìn náà wọn yóò mọ̀ pé èmi ní Olúwa, nígbà tí mo bá gbé iná kalẹ̀ ní Ejibiti tí gbogbo àwọn olùrànlọ́wọ́ rẹ̀ bá parun.
9 I taua ra ka haere atu nga karere i toku aroaro i runga i nga kaipuke, ki te whakawehi i nga Etiopiana kahore nei e ohooho; ka nui ano to ratou mamae, ka rite ki to te ra o Ihipa: nana, te haere mai nei!
“‘Ní ọjọ́ náà oníṣẹ́ yóò ti ọ̀dọ̀ mi jáde nínú ọkọ̀ ojú omi láti dẹ́rùbà Kuṣi tí ó wà nínú àlàáfíà. Ìrora yóò wá sórí wọn gẹ́gẹ́ bí ti ọjọ́ ìparun Ejibiti. Kíyèsi i, ó dé.
10 Ko te kupu tenei a te Ariki, a Ihowa; Ka meinga ano e ahau te ringa o Nepukareha kingi o Papurona hei whakamutu i nga mano tini o Ihipa.
“‘Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: “‘Èmi yóò mú òpin bá ọ̀gọ̀ọ̀rọ̀ àwọn ènìyàn Ejibiti láti ọwọ́ Nebukadnessari ọba Babeli.
11 Ka kawea mai ia, ratou ano ko tona iwi, ko te hunga nanakia o nga iwi, ki te huna i te whenua: ka maunu ano a ratou hoari ki Ihipa, a ka kapi te whenua i te tupapaku.
Òun àti àwọn ológun rẹ̀ ẹ̀rù àwọn orílẹ̀-èdè ní a o mú wá láti pa ilẹ̀ náà run. Wọn yóò fa idà wọn yọ sí Ejibiti ilẹ̀ náà yóò sì kún fún àwọn tí a pa.
12 Ka maroke ano nga awa i ahau, ka hokona atu ano te whenua ki te ringa o te hunga kino: ka ururua ano i ahau te whenua, me ona tini mea, mea rawa ki te ringa o nga tautangata: naku, na Ihowa te kupu.
Èmi yóò mú kí àwọn odò Naili gbẹ, Èmi yóò sì ta ilẹ̀ náà fún àwọn ènìyàn búburú: láti ọwọ́ àwọn àjèjì ènìyàn, Èmi yóò jẹ́ kí ilẹ̀ náà àti gbogbo ohun tí ó wá nínú rẹ ṣòfò. Èmi Olúwa ni ó ti sọ ọ́.
13 Ko te kupu tenei a te Ariki, a Ihowa; Ka ngaro i ahau nga whakapakoko, ka mutu ano i ahau nga whakaahua o Nopo; kore ake e mea mai he rangatira i te whenua o Ihipa: ka tukua ano e ahau he wehi ki te whenua o Ihipa.
“‘Báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí: “‘Èmi yóò pa àwọn òrìṣà run, Èmi yóò sì mú kí òpin dé bá ère gbígbẹ́ ni Memfisi. Kò ní sí ọmọ-aládé mọ́ ní Ejibiti, Èmi yóò mú kí ìbẹ̀rù gba gbogbo ilẹ̀ náà.
14 Ka ururua ano i ahau a Patoro, ka tukua he ahi ki Toana, ka mahia ano e ahau he whakawa ki No.
Èmi yóò sì mú kí Paturosi di ahoro, èmi yóò fi iná sí Ṣoani, èmi yóò sì fi ìyà jẹ Tebesi.
15 Ka ringihia ano e ahau toku weriweri ki Hini, ki to Ihipa kaha; ka hatepea atu ano e ahau nga mano tini o No.
Èmi yóò tú ìbínú mi jáde sórí Pelusiumu ìlú odi Ejibiti èmi yóò sì ké àkójọpọ̀ Tebesi kúrò.
16 Ka tukua ano e ahau he ahi ki Ihipa; ka nui noa atu te mamae o Hini, ka haehaea putia a No; ka whai hoariri ano a Nopo i ia ra, i ia ra.
Èmi yóò ti iná bọ Ejibiti Pelusiumu yóò japoró ní ìrora. Ìjì líle yóò jà ní Tebesi Memfisi yóò wà ìpọ́njú ní ìgbà gbogbo.
17 Ka hinga nga taitama o Awene, o Pipehete i te hoari: a ka riro enei pa i te whakarau.
Àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin ní Heliopolisi àti Bubasiti yóò ti ipa idà ṣubú wọn yóò sì kó àwọn ìlú wọn ní ìgbèkùn.
18 Ka whakapouritia ano te ra ki Tehapanehe ina pakaru i ahau nga ioka o Ihipa ki reira: a ka mutu i roto i a ia te whakapehapeha o tona kaha: ko ia ano ka taupokina e te kapua, ka riro ana tamahine i te whakarau.
Ojú ọjọ́ yóò ṣókùnkùn ní Tafanesi nígbà tí mo bá já àjàgà Ejibiti kúrò; níbẹ̀ agbára iyì rẹ̀ yóò dópin wọn yóò fi ìkùùkuu bò ó àwọn abúlé rẹ ní wọn yóò lọ sí ìgbèkùn.
19 Heoi ka mahia e ahau he whakawa ki Ihipa; a ka mohio ratou ko Ihowa ahau.
Nítorí náà, Èmi yóò mú ki ìjìyà wá sórí Ejibiti, wọn yóò sì mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.’”
20 Na, i te tekau ma tahi o nga tau, i te marama tuatahi, i te whitu o nga ra o te marama, ka puta te kupu a Ihowa ki ahau; i mea,
Ní ọjọ́ keje oṣù kìn-ín-ní ọdún kọkànlá ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá,
21 E te tama a te tangata, kua whati i ahau te ringa o Parao kingi o Ihipa; nana, kahore i takaia hei meatanga iho mo te rongoa, kahore i meatia iho te takai hei takai, e kaha ai ki te pupuri hoari.
“Ọmọ ènìyàn, Èmi ti ṣẹ́ apá Farao ọba Ejibiti. A kò ì tí ì di apá náà papọ̀ láti mu kí ó san, a kò sì ti di i si àárín igi pẹlẹbẹ kí o lè ni agbára tó láti di idà mú.
22 Mo reira ko te kupu tenei a te Ariki, a Ihowa; Nana, hei hoariri ahau mo Parao kingi o Ihipa, ka whati ano i ahau ona ringa, te mea kaha, te mea ano i whati; ka meinga ano e ahau te hoari kia marere i tona ringa.
Nítorí náà, báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí: Èmi lòdì sí Farao ọba Ejibiti. Èmi yóò sẹ́ apá rẹ̀ méjèèjì, èyí tí ó dára àti èyí tí a ti ṣẹ́ pẹ̀lú, yóò sì mú kí idà bọ́ sọnù ní ọwọ́ rẹ̀.
23 Ka marara ano i ahau nga Ihipiana ki roto ki nga tauiwi, ka titaria ki nga whenua.
Èmi yóò sì fọ́n àwọn ènìyàn Ejibiti ká sí àárín àwọn orílẹ̀-èdè, èmi yóò sì tú wọn ká gbogbo ilẹ̀.
24 Ka kaha ano i ahau nga ringa o te kingi o Papurona, ka hoatu ano e ahau taku hoari ki tona ringa: ka whati ia i ahau nga ringa o Parao, a no te tangata i werohia nga aue e aue ai ia ki tona aroaro.
Èmi yóò mú kí apá ọba Babeli ní agbára, èmi yóò sì fi idà mi sí ọwọ́ rẹ, ṣùgbọ́n èmi yóò ṣẹ́ apá Farao, yóò sì kérora níwájú rẹ̀ bí ọkùnrin tí a sá ní àṣápa.
25 A ka kaha i ahau nga ringa o te kingi o Papurona, a ka tukua iho nga ringa o Parao; a ka mohio ratou ko Ihowa ahau, ina hoatu e ahau taku hoari ki te ringa o te kingi o Papurona, a ka whakatorona atu e ia ki runga ki te whenua o Ihipa.
Èmi yóò mú kí apá ọba Babeli lé, ṣùgbọ́n apá Farao yóò sì rọ. Nígbà náà wọn yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa, nígbà tí mo bá mú idà mi sí ọwọ́ ọba Babeli yóò sì fi idà náà kọlu Ejibiti.
26 Ka marara ano i ahau nga Ihipiana ki roto ki nga iwi, ka titaria ki nga whenua; a ka mohio ratou ko Ihowa ahau.
Èmi yóò fọ́n àwọn ara Ejibiti ká sí àárín orílẹ̀-èdè, èmi yóò sì tú wọn ká sí àárín orílẹ̀-èdè, èmi yóò sì tú wọn ká sí gbogbo ilẹ̀. Nígbà náà wọn yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa.”

< Ehekiera 30 >