< Ekoruhe 5 >

1 A muri iho, ka haere a Mohi raua ko Arona, ka korero ki a Parao, Ko te kupu tenei a Ihowa, a te Atua o Iharaira, Tukua taku iwi kia haere ki te taka hakari ki ahau i te koraha.
Lẹ́yìn náà ni Mose àti Aaroni tọ Farao lọ, wọ́n sì wí pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa, Ọlọ́run Israẹli sọ, ‘Jẹ́ kí àwọn ènìyàn mi kí ó lọ, kí wọn kí ó lè ṣe àjọ mi ní ijù.’”
2 Na ka mea a Parao, Ko wai a Ihowa, kia rongo ahau ki tona reo, kia tukua a Iharaira? Kahore ahau e mohio ki a Ihowa, e kore hoki e tukua atu e ahau a Iharaira.
Farao dáhùn wí pé, “Ta ni Olúwa, tí èmi yóò fi gbọ́rọ̀ sí i lẹ́nu, tí èmi yóò fi jẹ́ kí Israẹli ó lọ? Èmi kò mọ Olúwa, èmi kò sì ní jẹ́ kí Israẹli ó lọ.”
3 A ka mea raua, Kua tutaki te Atua o nga Hiperu ki a matou: kia haere ra matou, kia toru nga ra ki te ara i te koraha, ka mea patunga tapu ai matou ki a Ihowa, ki to matou Atua; kei torere mai ia ki a matou i te mate uruta ranei, i te hoari ranei.
Lẹ́yìn náà ni wọ́n wí pé, “Ọlọ́run àwọn Heberu tí pàdé wa. Ní ìsinsin yìí, jẹ́ kí a lọ ní ìrìn ọjọ́ mẹ́ta sínú aginjù láti rú ẹbọ sí Olúwa Ọlọ́run wa, kí Ó má ba á fi àjàkálẹ̀-ààrùn tàbí idà bá wa jà.”
4 Na ka mea te kingi o Ihipa ki a raua, He aha korua, e Mohi korua ko Arona, i whakaware ai i te iwi ki a ratou mahi? haere ki a koutou kawenga.
Ṣùgbọ́n ọba Ejibiti sọ wí pé, “Mose àti Aaroni, èéṣe ti ẹ̀yin fi mú àwọn ènìyàn kúrò lẹ́nu iṣẹ́ wọn? Ẹ padà sẹ́nu iṣẹ́ yín.”
5 I mea ano a Parao, Nana, ka tini nei nga tangata o te whenua, na korua hoki ratou i noho ai i a ratou kawenga.
Nígbà náà ni Farao sọ pé, “Ẹ wò ó àwọn ènìyàn náà ti pọ̀ sí ì nílẹ̀ yìí ní ìsinsin yìí, ẹ̀yin sì ń dá wọn dúró láti máa bá iṣẹ́ lọ.”
6 Na ka ako a Parao i taua ra ki nga kaiakiaki o te iwi, ki o ratou rangatira, ka mea,
Ní ọjọ́ yìí kan náà ni Farao pàṣẹ fún àwọn akóniṣiṣẹ́ àti àwọn ti ń ṣe alábojútó iṣẹ́ lórí àwọn ènìyàn.
7 Kaua e hoatu he takakau ki te iwi a muri ake nei, hei hanga pereki, pera i o mua ra: me haere ratou ki te kohikohi takakau ma ratou.
“Ẹ̀yin kò ní láti pèsè koríko gbígbẹ fún bíríkì sísun mọ́ fún àwọn ènìyàn wọ̀nyí; ẹ jẹ́ kí wọn máa wá koríko gbígbẹ fún ara wọn.
8 Otiia, whakaritea ki a ratou kia rite tonu nga pereki te maha ki era i hanga e ratou i mua; kaua e whakahokia iho te maha; he mangere hoki ratou; koia ratou i karanga ai, i mea ai, Kia haere matou ki te mea patunga tapu ki to matou Atua.
Ṣùgbọ́n ẹ jẹ́ kí wọn ó ṣe iye bíríkì kan náà bí ì ti àtẹ̀yìnwá, kí ẹ má ṣe dín iye rẹ̀ kú. Ọ̀lẹ ni wọ́n, ìwà ọ̀lẹ yìí náà ló mú wọn pariwo pé, ‘Ẹ jẹ́ kí a lọ, kí a sì rú ẹbọ sí Ọlọ́run wa.’
9 Whakanuia te mahi ma nga tangata ra, a ko tena hei mahi ma ratou; kaua hoki ratou e whakarongo ki nga kupu horihori.
Ẹ mú iṣẹ́ náà le fún wọn, kí wọn bá a le è tẹramọ́ iṣẹ́ wọn, ẹ má fi ààyè gba irọ́ wọn.”
10 Na ka haere nga kaiakiaki o te iwi, me o ratou rangatira, ka korero ki te iwi, ka mea, Ko te kupu tenei a Parao, e kore e hoatu e ahau he takakau ki a koutou.
Ní ìgbà náà ni àwọn akóniṣiṣẹ́ àti àwọn tí ń ṣe alábojútó iṣẹ́ jáde tọ̀ wọ́n lọ láti sọ fún àwọn ènìyàn náà pé, “Èyí ni ohun tí Farao sọ, ‘Èmi kò ní fún un yín ni koríko gbígbẹ mọ́.
11 Haere ki te kohikohi takakau ma koutou i te wahi e kitea ai e koutou: otiia, kaua e whakahokia iho tetahi wahi o ta koutou e mahi ai.
Ẹ lọ wá koríko gbígbẹ ni ibi tí ẹ bá ti lè rí i, ṣùgbọ́n iṣẹ́ yín kí yóò dínkù.’”
12 Na ka marara noa atu te iwi ki te whenua katoa o Ihipa, ki te kohikohi putake witi hei takakau.
Gbogbo wọn sí fọ́n káàkiri ni ilẹ̀ Ejibiti láti sa ìdì koríko tí wọn yóò lò bí ì koríko gbígbẹ fún sísun bíríkì.
13 A ka whakatatutatu nga kaiakiaki, ka mea, Whakaotia a koutou mahi, to tenei rangi, to tenei rangi, kia rite ki o te wa i whai takakau ai.
Àwọn akóniṣiṣẹ́ sì ń ni wọ́n lára, wọ́n wí pé, “Ẹ parí iṣẹ́ tí ẹ ni láti ṣe fún ọjọ́ kan bí ìgbà ti a ń fún un yin ní koríko gbígbẹ.”
14 Na ka whiua nga rangatira o nga tama a Iharaira i whakaritea mo ratou e nga kaiakiaki a Parao, ka mea ratou, He aha te whakaotia ai inanahi, inaianei, a koutou pereki i whakaritea ki a koutou, te pera ai me o mua ra?
Àwọn alábojútó iṣẹ́ tí àwọn akóniṣiṣẹ́ Farao yàn lára ọmọ Israẹli ni wọn ń lù, tí wọn sì ń béèrè lọ́wọ́ wọn pé, “Èéṣe tí ẹ̀yin kò ṣe iye bíríkì ti ẹ̀yin ń ṣe ní àná ní òní bí i tí àtẹ̀yìnwá?”
15 Na ka haere nga rangatira o nga tama a Iharaira, me te tangi ano, ki a Parao, ka mea, He aha koe i penei ai ki au pononga?
Nígbà náà ni àwọn alábojútó iṣẹ́ tí a yàn lára àwọn ọmọ Israẹli tọ Farao lọ láti lọ bẹ̀bẹ̀ pé, “Èéṣe tí ìwọ fi ọwọ́ líle mú àwa ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ báyìí?
16 Kahore he takakau i homai ki au pononga, a e mea ana ratou ki a matou, Hanga he pereki: na ka whiua au pononga; no au tangata ia te he.
Wọn kò fún àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ ni koríko gbígbẹ, síbẹ̀ wọn sọ fún wa pé, ‘Ẹ ṣe bíríkì!’ Wọ́n na àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ, ṣùgbọ́n ẹ̀bi náà wá láti ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn rẹ.”
17 Na ka mea ia, He mangere koutou, he mangere; na reira koutou ka mea ai, Tukua matou kia haere ki te mea patunga tapu ki a Ihowa.
Farao sí dáhùn wí pé, “Ọ̀lẹ ni yín, ọ̀lẹ! Èyí ni ó mú kí ẹ̀yin máa sọ ní ìgbà gbogbo pé, ‘Ẹ jẹ́ kí a lọ, kí a sì rú ẹbọ sí Olúwa.’
18 Na, haere, e mahi; e kore hoki e hoatu he takakau ki a koutou; otiia me homai ano nga pereki i whakaritea ra.
Nísinsin yìí ẹ padà lọ sí ẹnu iṣẹ́ yín, a kò ní fún un yín ni koríko gbígbẹ, síbẹ̀ ẹ gbọdọ̀ ṣe iye bíríkì tí ó yẹ kí ẹ ṣe.”
19 Na, ka kite nga rangatira o nga tama a Iharaira i te kino mo ratou, i te kianga ra, Kaua e whakaokuokutia iho a koutou pereki, hei mahinga ma koutou i tenei ra, i tenei ra.
Àwọn ọmọ Israẹli tí ó jẹ́ alábojútó iṣẹ́ mọ̀ dájú wí pé àwọn ti wà nínú wàhálà ńlá ní ìgbà tí a sọ fún wọn pé, “Ẹ kò ní láti dín iye bíríkì tí ẹ ń ṣe ni ojoojúmọ́ kù.”
20 A ka tutaki ratou ki a Mohi raua ko Arona, e tu mai ana i mua i a ratou, i to ratou haerenga mai i a Parao:
Ní ìgbà tí wọ́n kúrò ni ọ̀dọ̀ Farao wọ́n rí Mose àti Aaroni tí ó dúró láti pàdé wọn.
21 A ka mea ki a raua, Ma Ihowa e titiro ki a korua, e whakawa; na korua hoki matou i piro whakarihariha ai ki te aroaro o Parao, ki te aroaro hoki o ana pononga, na korua i hoatu he hoari ki o ratou ringa hei patu i a matou.
Wọn sì wí pé, “Kí Olúwa kí ó wò yín, kí ó sì ṣe ìdájọ́! Ẹ̀yin ti mú wa dàbí òórùn búburú fún Farao àti àwọn òṣìṣẹ́ rẹ̀, ẹ sì ti fún wọn ni idà láti fi pa wá.”
22 Na ka hoki a Mohi ki a Ihowa, a ka mea, E te Ariki, he aha koe i mahi he ai ki tenei iwi? he aha koe i unga ai i ahau?
Mose padà tọ Olúwa lọ, ó sì wí pé, “Olúwa, èéṣe tí ìwọ fi mú ìyọnu wá sí orí àwọn ènìyàn wọ̀nyí? Ṣe torí èyí ni ìwọ fi rán mi?
23 No toku haerenga atu hoki ki a Parao ki te korero i runga i tou ingoa, i kino ai ia ki tenei iwi; kahore ano hoki koe kia whakaora noa i tau iwi, kahore rawa.
Láti ìgbà ti mo ti tọ Farao lọ láti bá a sọ̀rọ̀ ni orúkọ rẹ ni ó ti mú ìyọnu wá sí orí àwọn ènìyàn wọ̀nyí, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kò sì gba àwọn ènìyàn rẹ sílẹ̀ rárá.”

< Ekoruhe 5 >