< Ekoruhe 10 >

1 Na ka mea a Ihowa ki a Mohi, Haere ki a Parao; kua whakapakeke hoki ahau i tona ngakau, i te ngakau hoki o ona tangata, kia whakakite ai ahau i enei tohu aku ki tona aroaro;
Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Mose pé, “Lọ sí ọ̀dọ̀ Farao, mo ti ṣé àyà Farao le àti àyà àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, kí èmi kí o ba le ṣe àwọn iṣẹ́ ìyanu mi láàrín wọn.
2 Kia korero ai hoki koe ki nga taringa o tau tama, o te tama hoki a tau tama, i taku i mahi ai ki Ihipa, i aku tohu hoki i meatia e ahau i roto i a ratou; kia mohio ai koutou ko Ihowa ahau.
Kí ẹ̀yin ki ó le sọ fún àwọn ọmọ yín àti àwọn ọmọ ọmọ yín; bí mo ti jẹ àwọn ará Ejibiti ní yà àti bí mo ti ṣe àwọn iṣẹ́ ìyanu láàrín wọn. Kí ìwọ ba á le mọ̀ pé Èmi ni Olúwa.”
3 A haere ana a Mohi raua ko Arona ki a Parao, mea ana ki a ia, Ko te kupu tenei a Ihowa, a te Atua o nga Hiperu, Kia pehea te roa ou kahore nei e ngohengohe ki toku aroaro? Tukua taku iwi kia haere, kia mahi ki ahau.
Nígbà náà ni Mose àti Aaroni tọ Farao lọ, tiwọn sí wí fún un pé, “Èyí ni Olúwa, Ọlọ́run àwọn Heberu sọ, ‘Yóò ti pẹ́ to ti ìwọ yóò kọ̀ láti tẹrí ara rẹ ba ní iwájú mi? Jẹ́ kí àwọn ènìyàn mi kí ó lọ, kí wọn kí ó sìn mi.
4 Ko tenei, ka kore koe e rongo ki te tuku i taku iwi, nana, apopo ahau kawe mai ai i te mawhitiwhiti ki tou rohe:
Bí ìwọ bá kọ̀ láti jẹ́ kí wọn lọ, èmi yóò mú eṣú wa sí orílẹ̀-èdè rẹ ní ọ̀la.
5 A e kapi i a ratou te mata o te whenua, e kore ano e ahei te kite i te whenua; a e kai ratou i nga toenga i mahue, i toe ma koutou i te whatu, e kai hoki ratou i nga rakau katoa e tupu ana ma koutou i te mara:
Wọn yóò bo gbogbo ilẹ̀. Wọn yóò ba ohun gbogbo tí ó kù fún ọ lẹ́yìn òjò yìnyín jẹ́, tí ó fi dórí gbogbo igi tí ó ń dàgbà ni ilẹ̀ rẹ.
6 A e ki i a ratou ou whare, me nga whare o ou tangata katoa, me nga whare o nga Ihipiana katoa; he mea kihai nei i kitea e ou matua, e nga matua ranei o ou matua, o te ra iho ano i noho ai ratou ki te whenua a moroki noa nei. A tahuri ana ia, haer e atu ana i a Parao.
Wọn yóò kún gbogbo ilé rẹ àti ilé àwọn ìjòyè rẹ àti ilé gbogbo àwọn ará Ejibiti. Ohun ti baba rẹ tàbí baba baba rẹ kò tí ì rí láti ìgbà tí wọ́n ti wà ní ilẹ̀ náà títí di àkókò yìí.’” Nígbà náà ni Mose pẹ̀yìndà kúrò níwájú Farao.
7 A ka mea nga tangata a Parao ki a ia, Kia pehea te roa o tenei tangata ka waiho nei hei rore ki a tatou? tukua nga tangata ki te mahi ki a Ihowa, ki to ratou Atua: kiano koe i mohio noa kua ngaro a Ihipa?
Àwọn ìjòyè Farao sọ fún un, “Yóò ti pẹ́ to tí ọkùnrin yìí yóò máa jẹ́ ìkẹ́kùn fún wa? Jẹ́ kí àwọn ènìyàn yìí lọ, kí wọn kí ó le sìn Olúwa Ọlọ́run wọn. Ṣe ìwọ kò ṣe àkíyèsí síbẹ̀ pé, ilẹ̀ Ejibiti ti parun tán?”
8 Na ka whakahokia a Mohi raua ko Arona ki a Parao; a ka mea ia ki a raua, Haere, e mahi ki a Ihowa, ki to koutou Atua: ko wai ma oti e haere?
Nígbà náà ni a mú Aaroni àti Mose padà wá sí iwájú Farao ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ lọ sìn Olúwa Ọlọ́run yín. Ṣùgbọ́n àwọn ta ni nínú yín ni yóò ha lọ.”
9 A ka mea a Mohi, E haere ra matou me a matou taitamariki, me o matou koroheke, me a matou tama, me a matou tamahine, e haere me a matou hipi, me a matou kau; he hakari hoki ta matou ki a Ihowa.
Mose dáhùn ó wí pé, “A ó lọ pẹ̀lú àwọn ọmọdé àti àgbà wa, pẹ̀lú àwọn ọmọ wa ọkùnrin àti ọmọ wa obìnrin pẹ̀lú agbo àgùntàn wa àti agbo màlúù wa nítorí pé a gbọdọ̀ ṣe àjọ fún Olúwa.”
10 Na ka mea ia ki a raua, Kia pena te noho o Ihowa ki a koutou, me ahau ka tuku nei i a koutou me a koutou potiki: ma koutou e titiro; he kino hoki kei mua i a koutou.
Farao sì wí pé, “Mo fi Olúwa búra pé èmi kí yóò jẹ́ kí ẹ lọ, pẹ̀lú àwọn obìnrin yín àti àwọn ọmọ wẹ́wẹ́, dájúdájú èrò ibi ní ń bẹ nínú yín.
11 Kahore ra hoki: haere e nga tane, e mahi ki a Ihowa; ko ta koutou hoki tena i whai na. A peia ana raua i te aroaro o Parao.
Rárá! Ọkùnrin yín nìkan ni kí ó lọ, láti lọ sin Olúwa, níwọ̀n ìgbà tí ó jẹ́ pé èyí ni ẹ̀yin ń béèrè fún.” Wọ́n sì lé Mose àti Aaroni kúrò ní iwájú Farao.
12 Na ka mea a Ihowa ki a Mohi, Totoro atu tou ringaringa ki te whenua o Ihipa mo te mawhitiwhiti kia puta ki te whenua o Ihipa, ki te kai i nga otaota katoa o te whenua, i nga mea katoa i toe i te whatu.
Ní ìgbà náà ni Olúwa sọ fún Mose, “Gbé ọwọ́ rẹ sókè lórí Ejibiti kí ọ̀pọ̀lọpọ̀ eṣú bo gbogbo ilẹ̀, kí ó sì ba gbogbo ohun ọ̀gbìn tí ó wà ni inú oko wọn jẹ́, àní gbogbo ohun tí òjò yìnyín kò bàjẹ́ tan.”
13 Na ka toro atu te tokotoko a Mohi ki runga i te whenua o Ihipa, a kua puta he hau i a Ihowa, he marangai, ki te whenua, a pau katoa taua rangi, pau katoa taua po; a huaki ake te ata, na, kua kawea mai nga mawhitiwhiti e te marangai:
Nígbà náà ni Mose na ọ̀pá ọwọ́ rẹ̀ sórí ilẹ̀ Ejibiti, Olúwa sì mú kí afẹ́fẹ́ láti ìlà-oòrùn fẹ́ kọjá lórí ilẹ̀ náà ni gbogbo ọ̀sán àti ni gbogbo òru ni ọjọ́ náà. Ní òwúrọ̀ afẹ́fẹ́ náà ti gbá ọ̀pọ̀lọpọ̀ eṣú wá;
14 A puta ake ana te mawhitiwhiti ki te whenua katoa o Ihipa, a tau iho ki nga rohe katoa o Ihipa: he nanakia rawa; kahore he mawhitiwhiti o mua atu hei rite mo enei, e kore ano hoki e rite a muri ake nei.
wọ́n sì bo gbogbo ilẹ̀ Ejibiti, wọ́n wà ní ibi gbogbo ní orí ilẹ̀ ní àìmoye, ṣáájú àkókò yìí kò sí irú ìyọnu eṣú bẹ́ẹ̀ rí, kò sì ní sí irú rẹ mọ́ lẹ́yìn èyí.
15 Ngaro ana hoki i a ratou te mata o te whenua katoa, pouri ana te whenua; a kainga ake e ratou nga otaota katoa o te whenua, me nga hua katoa o nga rakau i toe i te whatu: kihai i mahue tetahi tupu o nga rakau, o nga otaota ranei o te mara, i te whenua katoa o Ihipa.
Wọ́n bo gbogbo ilẹ̀ tí ilẹ̀ fi di dúdú. Wọ́n ba gbogbo ohun tókù ní orí ilẹ̀ lẹ́yìn òjò yìnyín jẹ́; gbogbo ohun ọ̀gbìn tí ó wà ní inú oko àti gbogbo èso tí ó wà lórí igi. Kò sí ewé tí ó kù lórí igi tàbí lórí ohun ọ̀gbìn ní gbogbo ilẹ̀ Ejibiti.
16 Na ka hohoro a Parao te karanga ki a Mohi raua ko Arona ka mea, Kua hara ahau ki a Ihowa, ki to koutou Atua, ki a korua hoki.
Farao yára ránṣẹ́ pe Mose àti Aaroni, ó sì sọ fún wọn pé, “Èmi ti ṣẹ̀ sí Olúwa Ọlọ́run yín àti sí i yín pẹ̀lú.
17 Na, whakarerea toku hara, heoi rawa ano ko to tenei taima, a inoi ki a Ihowa, ki to koutou Atua, kia tangohia atu e ia ko tenei mate anake i ahau.
Nísinsin yìí ẹ dáríjì mi lẹ́ẹ̀kan sí i kí ẹ sì gbàdúrà sí Olúwa Ọlọ́run yín kí ó lè mú ìpọ́njú yìí kúrò ní ọ̀dọ̀ mi.”
18 A mawehe ana ia i a Parao, inoi ana ki a Ihowa.
Nígbà náà ni Mose kúrò ní iwájú Farao ó sì gbàdúrà sí Olúwa.
19 Na whakataka ana e Ihowa he hauauru nui rawa nana i kahaki atu nga mawhitiwhiti, i whiu ki te Moana Whero; kihai i toe tetahi mawhitiwhiti i nga rohe katoa o Ihipa.
Olúwa sì yí afẹ́fẹ́ náà padà di afẹ́fẹ́ líle láti apá ìwọ̀-oòrùn wá láti gbá àwọn eṣú náà kúrò ní orí ilẹ̀ Ejibiti lọ sínú Òkun Pupa. Bẹ́ẹ̀ ni ẹyọ eṣú kan kò ṣẹ́kù sí orí ilẹ̀ Ejibiti.
20 Otiia whakapakeke ana a Ihowa i te ngakau o Parao, a kihai ia i tuku i nga tama a Iharaira.
Síbẹ̀ Olúwa ṣe àyà Farao le, kò sì jẹ́ kí àwọn ọmọ Israẹli lọ.
21 A ka mea a Ihowa ki a Mohi, Totoro ake tou ringaringa ki te rangi, kia whai pouri ai ki te whenua o Ihipa, he pouri e hakiri mai ana ki te ringa.
Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Mose pé, “Gbé ọwọ́ rẹ sókè sí ojú ọ̀run kí òkùnkùn bá à le bo gbogbo ilẹ̀ Ejibiti; àní òkùnkùn biribiri.”
22 Na ka toro atu te ringa o Mohi ki te rangi, a kua pouri kerekere i te whenua katoa o Ihipa, e toru nga ra:
Nígbà náà ni Mose gbé ọwọ́ rẹ sókè sí ojú ọ̀run, òkùnkùn biribiri sì bo gbogbo ilẹ̀ Ejibiti fún ọjọ́ mẹ́ta. Ṣùgbọ́n àwọn ọmọ Israẹli ní ìmọ́lẹ̀ ní ibi tí wọn ń gbé.
23 Kahore tetahi i kite i tetahi, kihai ano hoki i whakatika atu tetahi i tona wahi i nga ra e toru: tena ko nga tama a Iharaira, marama ana o ratou na nohoanga.
Kò sí ẹni tí ó le è ríran rí ẹlòmíràn tàbí kí ó kúrò ní ibi tí ó wà fún ọjọ́ mẹ́ta. Síbẹ̀ àwọn ọmọ Israẹli ni ìmọ́lẹ̀ ni gbogbo ibi tí wọ́n ń gbé.
24 Na ka karanga a Parao ki a Mohi, ka mea, Haere, e mahi ki a Ihowa; otiia me waiho a koutou hipi me a koutou kau: ko a koutou tamariki nonohi hoki me haere tahi i a koutou.
Farao sì ránṣẹ́ pe Mose ó sì wí fún un pé, “Lọ sin Olúwa, kódà àwọn obìnrin àti àwọn ọmọdé lè lọ pẹ̀lú yín, ṣùgbọ́n kí ìwọ kí ó fi agbo àgùntàn àti agbo màlúù yín sílẹ̀.”
25 A ka mea a Mohi, Me homai ano e koe ki a matou he patunga tapu, he tahunga tinana, hei mahinga ma matou ki a Ihowa, ki to matou Atua.
Ṣùgbọ́n Mose sọ pé, “Ìwọ gbọdọ̀ fún wa láààyè láti rú ẹbọ àti ọrẹ ẹbọ sísun ní iwájú Olúwa Ọlọ́run wa.
26 Me haere ano a matou kararehe i a matou; e kore tetahi maikuku e mahue; ka tangohia hoki e matou etahi o ena hei mahinga ki a Ihowa, ki to matou Atua; e kore hoki matou e mohio ki ta matou e mahi ai ki a Ihowa, kia tae ra ano ki reira.
Àwọn ohun ọ̀sìn wa gbọdọ̀ lọ pẹ̀lú wa, a kì yóò fi pátákò ẹsẹ̀ ẹran sílẹ̀. A ní láti lò lára wọn fún sínsin Olúwa Ọlọ́run wa, ìgbà tí a bá sì dé ibẹ̀ ni a ó to mọ̀ ohun ti a ó lò láti fi sin Olúwa.”
27 Otiia whakapakeketia ana e Ihowa te ngakau o Parao, a kihai ia i pai ki te tuku i a ratou.
Ṣùgbọ́n Olúwa sé ọkàn Farao le, kò sì ṣetán láti jẹ́ kí wọn lọ.
28 Na ka mea a Parao ki a ia, Mawehe atu i ahau, kia tupato kei kite koe i toku kanohi a muri ake nei; ko te ra hoki e kite ai koe i toku kanohi, ka mate koe.
Farao sọ fún Mose pé, “Kúrò ní iwájú mi! Rí i dájú pé o kò wá sí iwájú mi mọ́! Ọjọ́ tí ìwọ bá rí ojú mi ni ìwọ yóò kùú.”
29 Ano ra ko Mohi, Ka tika tau korero, heoi ano taku kitenga i tou kanohi ki muri ake nei.
Mose sì dáhùn pé, gẹ́gẹ́ bí ìwọ ti wí, “Èmi kí yóò wá sí iwájú rẹ mọ́.”

< Ekoruhe 10 >