< Ekoruhe 1 >

1 Na ko nga ingoa enei o nga tama a Iharaira i haere ki Ihipa; i haere tahi mai ratou me Hakopa, me te whare o tenei, o tenei.
Ìwọ̀nyí ni àwọn orúkọ ọmọ Israẹli tí wọ́n bá Jakọbu lọ sí Ejibiti, ẹnìkọ̀ọ̀kan pẹ̀lú ìdílé rẹ̀:
2 Ko Reupena, ko Himiona, ko Riwai, ko Hura,
Reubeni, Simeoni, Lefi àti Juda;
3 Ko Ihakara, ko Hepurona, ko Pineamine,
Isakari, Sebuluni àti Benjamini;
4 Ko Rana, ko Napatari, ko Kara, ko Ahera.
Dani àti Naftali; Gadi àti Aṣeri.
5 Na, ko nga wairua katoa i puta mai i te hope o Hakopa, e whitu tekau wairua: i Ihipa hoki a Hohepa.
Àwọn ìran Jakọbu sì jẹ́ àádọ́rin ní àpapọ̀; Josẹfu sì ti wà ní Ejibiti.
6 Na kua mate a Hohepa, me ona tuakana katoa, me tera whakapaparanga katoa.
Wàyí o, Josẹfu àti gbogbo àwọn arákùnrin rẹ̀ àti gbogbo ìran náà kú,
7 A ka tupu nga tama a Iharaira, ka tini haere, ka hira rawa, ka kaha noa atu; a kapi ana te whenua i a ratou.
ṣùgbọ́n àwọn ará Israẹli ń bí sí i, wọ́n ń pọ̀ sí i gidigidi, wọ́n kò sì ní òǹkà tí ó fi jẹ́ pé wọ́n kún ilẹ̀ náà.
8 Na kua puta he kingi hou mo Ihipa, kihai i mohio ki a Hohepa.
Nígbà náà ni ọba tuntun mìíràn tí kò mọ Josẹfu jẹ ní ilẹ̀ Ejibiti.
9 A ka ki ia ki tona iwi, Nana, hira ake, kaha ake i a tatou te iwi o nga tama a Iharaira.
Ó sọ fún àwọn ènìyàn rẹ̀, “Ẹ wò ó, àwọn ará Israẹli ti pọ̀ ní iye àti agbára jù fún wa.
10 Tena, kia ata ngarahu tatou ki a ratou; kei tini haere, a tenei ake, ki te ara he pakanga, na, ka uru hoki ratou ki o tatou hoariri, ka whawhai ki a tatou, a ka maunu atu i te whenua.
Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a lo ọgbọ́n àlùmọ̀kọ́rọ́yí láti dá wọn lẹ́kun, bí kò ṣe bẹ́ẹ̀ wọn yóò túbọ̀ máa pọ̀ sí i. Bí ogun bá sì bẹ́ sílẹ̀, wọn yóò darapọ̀ mọ́ àwọn ọ̀tá wa, wọn yóò sì da ojú ìjà kọ wá, wọn yóò sì sá àsálà kúrò ní ilẹ̀ yìí.”
11 Na ka whakaritea he rangatira akiaki mo ratou, hei whakawhui mo ratou ki a ratou kawenga. A hanga ana e ratou nga pa takotoranga taonga mo Parao, a Pitoma, a Raamahehe.
Nítorí náà, wọ́n yan àwọn ọ̀gá akóniṣiṣẹ́ lé wọn lórí láti máa ni wọ́n lára pẹ̀lú iṣẹ́ àṣekára. Wọ́n sì kọ́ Pitomi àti Ramesesi gẹ́gẹ́ bí ìlú ìṣúra pamọ́ sí fún Farao.
12 Engari whakawhiu noa ratou i a ratou, e hua tonu mai ana, e tupu ana. A pawera ana ratou i nga tama a Iharaira.
Ṣùgbọ́n bí a ti ń ni wọ́n lára tó, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n ń pọ̀ sí i, tí wọ́n sì ń tànkálẹ̀. Nítorí náà, àwọn ará Ejibiti bẹ̀rù nítorí àwọn ará Israẹli.
13 A nanakia noa iho te whakamahinga a nga Ihipiana i nga tama a Iharaira:
Àwọn ará Ejibiti sì mú àwọn ọmọ Israẹli sìn ní àsìnpa.
14 A meatia ana e ratou kia kawa ake ratou ki te ora, i te nui o te mahi, i te paru pokepoke, i te pereki, i nga mahi katoa o te mara, a ratou mahi katoa, i whakawhiua ai ratou ki te mahi.
Wọ́n mú wọn gbé ìgbé ayé kíkorò nípa iṣẹ́ bíríkì àti àwọn onírúurú iṣẹ́ oko; àwọn ará Ejibiti ń lò wọ́n ní ìlòkulò.
15 Na ka mea te kingi o Ihipa ki nga wahine whakawhanau i nga wahine a nga Hiperu; ko te ingoa o tetahi ko hipera, ko te ingoa hoki o tetahi ko Pua:
Ọba Ejibiti sọ fún àwọn agbẹ̀bí Heberu ti orúkọ wọn ń jẹ́ Ṣifura àti Pua pé,
16 I ki ia, E whakawhanau korua i nga wahine a nga Hiperu, a ka kite i a ratou i runga i nga kumete, ki te mea he tamaiti tane, whakamatea; he kotiro ia, kia ora tena.
“Nígbà ti ẹ̀yin bá ń gbẹ̀bí àwọn obìnrin Heberu, tí ẹ sì kíyèsi wọn lórí ìkúnlẹ̀ ìrọbí wọn, bí ó bá jẹ́ ọkùnrin ni ọmọ náà, ẹ pa á; ṣùgbọ́n bí ó bá jẹ́ obìnrin, ẹ jẹ́ kí ó wà láààyè.”
17 Otira i wehi nga kaiwhakawhanau ki te Atua, kihai hoki i mea i ta te kingi o Ihipa i mea ai ki a raua, a whakaorangia ana e raua nga tamariki tane.
Ṣùgbọ́n àwọn agbẹ̀bí bẹ̀rù Ọlọ́run, wọn kò sì ṣe gẹ́gẹ́ bí ọba Ejibiti ti wí fún wọn; wọ́n jẹ́ kí àwọn ọmọkùnrin wà láààyè.
18 Na ka karangatia nga kaiwhakawhanau e te kingi o Ihipa, a ka mea ki a raua, Na te aha tenei mahi a korua, i whakaora ai korua i nga tamariki tane?
Ọba Ejibiti pe àwọn agbẹ̀bí ó sì béèrè lọ́wọ́ wọn pé, “Èéṣe tí ẹ̀yin fi ṣe èyí? Èéṣe tí ẹ̀yin fi dá àwọn ọmọkùnrin si?”
19 A ka mea nga kaiwhakawhanau ki a Parao, No te mea ra, ehara nga wahine a nga Hiperu i te pena me nga wahine a nga Ihipiana; e maia ana hoki ratou, kahore ano kia tae atu te kaiwhakawhanau ki a ratou kua whanau.
Àwọn agbẹ̀bí náà sì dá Farao lóhùn pé, “Àwọn obìnrin Heberu kò rí bí àwọn obìnrin Ejibiti, wọ́n ní agbára, wọ́n sì ti máa ń bí ọmọ kí àwọn agbẹ̀bí tó dé ọ̀dọ̀ wọn.”
20 Na ka atawhai te Atua ki nga kaiwhakawhanau; a ka nui haere te iwi, a kaha rawa ana.
Nítorí náà Ọlọ́run ṣàánú fún àwọn agbẹ̀bí náà, àwọn ọmọ Israẹli sì ń le sí i, wọ́n sì ń pọ̀ sí i jọjọ.
21 A, no te mea i wehi nga kaiwhakawhanau ki te Atua, ka hanga e ia he whare mo raua.
Nítorí pé àwọn agbẹ̀bí bẹ̀rù Ọlọ́run, Ọlọ́run sì fún wọn ni ìdílé tiwọn.
22 Na ka ako a Parao ki tona iwi katoa, ka mea, Ko nga tamariki tane katoa e whanau mai, maka atu e koutou ki te awa, ko nga kotiro katoa ia, me whakaora.
Nígbà náà ni Farao pàṣẹ yìí fún gbogbo àwọn ènìyàn rẹ̀ pé, “Gbogbo ọmọkùnrin tí a bí ni kí ẹ gbé jù sínú odò Naili, ṣùgbọ́n gbogbo àwọn ọmọbìnrin ni kí ẹ jẹ́ kí wọn ó wà láààyè.”

< Ekoruhe 1 >