< Tiuteronomi 31 >

1 A i haere a Mohi, i korero i enei kupu ki a Iharaira katoa.
Nígbà náà ni Mose jáde tí ó sì sọ àwọn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí sí gbogbo Israẹli pé,
2 I mea ia ki a ratou, Ko toku kaumatua i tenei ra ka kotahi rau e rua tekau nga tau; e kore ahau e ahei ano te kopiko atu, te kopiko mai: kua mea mai hoki a Ihowa ki ahau, E kore koe e whiti i tenei Horano.
“Mo jẹ́ ọmọ ọgọ́fà ọdún báyìí àti pé èmi kò ni lè darí i yín mọ́. Olúwa ti sọ fún mi pé, ‘Ìwọ kò ní kọjá Jordani.’
3 Ko Ihowa, ko tou Atua, ko ia e whakawhiti ki mua i a koe; mana e whakangaro atu enei iwi i mua i a koe, a ka riro ratou i a koe: a ko Hohua, ko ia e whiti atu i mua i a koe, ka rite ki ta Ihowa i korero ai.
Olúwa Ọlọ́run rẹ fúnra rẹ̀ ni yóò rékọjá fún ọ. Yóò pa àwọn orílẹ̀-èdè yìí run níwájú rẹ, ìwọ yóò sì mú ìní ilẹ̀ wọn, Joṣua náà yóò rékọjá fún ọ, bí Olúwa ti sọ.
4 A ka rite ta Ihowa e mea ai ki a ratou ki tana i mea ai ki a Hihona raua ko Oka, ki nga kingi o nga Amori, ki to ratou whenua hoki; i huna nei e ia.
Olúwa yóò sì ṣe fún wọn ohun tí ó ti ṣe sí Sihoni àti sí Ogu ọba Amori, tí ó parun pẹ̀lú ilẹ̀ ẹ wọn.
5 A ka homai ratou e Ihowa ki to koutou aroaro, a ka rite ta koutou e mea ai ki a ratou ki nga whakahau katoa i whakahau ai ahau ki a koutou.
Olúwa yóò fi wọ́n fún ọ, kí o sì ṣe sí wọn gbogbo èyí tí mo ti pàṣẹ fún ọ.
6 Kia maia, kia toa, kaua e wehi, kaua e pawera i a ratou: no te mea ko Ihowa, ko tou Atua, ko ia te haere tahi ana i a koe; e kore ia e whakarere i a koe, e kore hoki e mawehe atu i a koe.
Jẹ́ alágbára kí o sì ní ìgboyà. Má ṣe bẹ̀rù tàbí jáyà nítorí i wọn, nítorí Olúwa Ọlọ́run rẹ ń lọ pẹ̀lú rẹ, Òun kò ní fi ọ́ sílẹ̀ tàbí kọ̀ ọ́ sílẹ̀.”
7 Na ka karanga a Mohi ki a Hohua, a ka mea ki a ia i te tirohanga a Iharaira katoa, Kia maia, kia toa: ko koe hoki e haere tahi me tenei iwi ki te whenua i oati ai a Ihowa ki o ratou matua kia homai ki a ratou; mau ano ratou e whakawhiwhi ki taua wahi.
Nígbà náà ni Mose pe Joṣua ó sì wí fún un níwájú gbogbo Israẹli pé, “Jẹ́ alágbára àti onígboyà, nítorí o ní láti lọ pẹ̀lú àwọn ènìyàn wọ̀nyí sí ilẹ̀ tí Olúwa búra fún àwọn baba ńlá a wọn láti fún wọn, kí o sì pín ilẹ̀ náà láàrín wọn bí ogún wọn.
8 Ko Ihowa ano, ko ia te haere ana i tou aroaro, hei tou taha ia, e kore ia e whakarere i a koe, e kore hoki e mawehe atu i a koe: kaua e wehi, kaua hoki e pawera.
Olúwa fúnra rẹ̀ ń lọ níwájú rẹ yóò sì wà pẹ̀lú rẹ; kò ní fi ọ́ sílẹ̀ tàbí kọ̀ ọ́ sílẹ̀. Má ṣe bẹ̀rù má sì ṣe fòyà.”
9 A tuhituhia iho e Mohi tenei ture, hoatu ana ki nga tohunga, ki nga tama a Riwai, ko ratou nei nga kaiamo i te aaka o te kawenata a Ihowa, ki nga kaumatua katoa ano hoki o Iharaira.
Nígbà náà ni Mose kọ òfin yìí kalẹ̀ ó sì fi fún àwọn àlùfáà, àwọn ọmọ Lefi, tí ń gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa, àti fún gbogbo àwọn àgbàgbà ní Israẹli.
10 I ako ano a Mohi ki a ratou, i mea, Hei te mutunga o nga tau e whitu, hei te wa ano e rite ai i te tau tuku noa, i te hakari o nga whare wharau,
Nígbà náà ni Mose pàṣẹ fún wọn, “Ní òpin ọdún méje méje, ní àkókò ọdún ìdásílẹ̀, nígbà àjọ àwọn àgọ́.
11 I te wa e tae ai a Iharaira katoa ki te whakakite i a ratou ki te aroaro o Ihowa, o tou Atua, ki te wahi e whiriwhiri ai ia, ka korero ai koe i tenei ture ki te aroaro o Iharaira katoa, kia rongo ai ratou.
Nígbà tí gbogbo Israẹli bá wá láti fi ara hàn níwájú Olúwa Ọlọ́run wa ní ibi tí yóò yàn, ìwọ yóò ka òfin yìí níwájú wọn sí etí ìgbọ́ wọn.
12 Whakaminea te iwi, nga tane, nga wahine, nga tamariki, me tou tangata iwi ke i roto i ou kuwaha, kia rongo ai ratou, kia whakaakona ai, kia wehi ai i a Ihowa, i to koutou Atua, kia mau ai ki te mahi i nga kupu katoa o tenei ture:
Pe àwọn ènìyàn jọ àwọn ọkùnrin, àwọn obìnrin àti àwọn àjèjì tí ń gbé àwọn ìlú u yín kí wọn lè fetí sí i kí wọn sì lè kọ́ láti bẹ̀rù Olúwa Ọlọ́run rẹ kí wọn sì rọra tẹ̀lé gbogbo ọ̀rọ̀ òfin yìí.
13 Kia rongo ai hoki a ratou tamariki, kihai nei i mohio, kia whakaakona ai kia wehi i a Ihowa, i to koutou Atua, i nga ra katoa e ora ai koutou ki te whenua e whiti atu nei koutou i Horano ki reira ki te tango.
Àwọn ọmọ wọn tí wọn kò mọ òfin yìí, gbọdọ̀ gbọ́ kí wọn sì kọ́ láti bẹ̀rù Olúwa Ọlọ́run rẹ níwọ̀n ìgbà tí o tí ń gbé ní ilẹ̀ tí ò ń kọjá la Jordani lọ láti ni.”
14 Na ka mea a Ihowa ki a Mohi, Nana, ka tata ou ra e mate ai koe: karangatia atu a Hohua, e tu hoki korua ki roto ki te tapenakara o te whakaminenga, a maku e ako ki a ia. Na ka haere a Mohi raua ko Hohua, a tu ana raua i roto i te tapenakara o te whakaminenga.
Olúwa sọ fún Mose pé, “Ọjọ́ ikú rẹ ti súnmọ́ etílé báyìí. Pe Joṣua kí ẹ sì fi ara yín hàn nínú àgọ́ àjọ, níbi tí èmi yóò ti fi àṣẹ fún un.” Nígbà náà ni Mose àti Joṣua wá, wọ́n sì fi ara wọn hàn níbi àgọ́ àjọ.
15 Na ka puta mai a Ihowa ki te tapenakara i roto ano i te pou kapua: a tu ana te pou kapua i runga i te kuwaha o te tapenakara.
Nígbà náà ni Olúwa farahàn níbi àgọ́ ní ọ̀wọ́ àwọsánmọ̀, àwọsánmọ̀ náà sì dúró sókè ẹnu-ọ̀nà àgọ́.
16 Katahi ka mea a Ihowa ki a Mohi, Nana, ka takoto koe ki ou matua; a ka whakatika te iwi nei, ka whai atu, ka puremu ki nga atua ke o te whenua, e haere na ratou ki reira noho ai ki waenganui i a ratou; ka whakarere i ahau, ka whakataka hoki i ta ku kawenata i whakaritea atu e ahau ki a ratou.
Olúwa sì sọ fún Mose pé, “Ìwọ ń lọ sinmi pẹ̀lú àwọn baba à rẹ, àwọn wọ̀nyí yóò sì ṣe àgbèrè ara wọn sí ọlọ́run àjèjì ilẹ̀ tí wọn ń wọ̀ lọ láìpẹ́. Wọn yóò kọ̀ mí sílẹ̀ wọn yóò sì da májẹ̀mú tí mo bá wọn dá.
17 A ka mura toku riri ki a ratou i taua ra, a ka whakarere ahau i a ratou, ka huna hoki i toku kanohi i a ratou, a ka pau ratou, ka pa ano hoki nga kino maha me nga matenga ki a ratou; a ka mea ratou i taua ra, Kahore ianei enei kino i pa mai ki a tatou, no te mea kahore to tatou Atua i roto i a tatou?
Ní ọjọ́ náà ni èmi yóò bínú sí wọn èmi yóò sì kọ̀ wọ́n sílẹ̀; èmi yóò pa ojú mi mọ́ kúrò fún wọn, wọn yóò sì parun. Ọ̀pọ̀lọpọ̀ àjálù àti ìṣòro yóò wá sórí wọn, àti ní ọjọ́ náà ni wọn yóò béèrè pé, ‘Ǹjẹ́ ìpọ́njú wọ̀nyí kò wá sórí i wa nítorí Ọlọ́run wa kò sí pẹ̀lú u wa?’
18 Ko ahau ia, ka huna rawa ahau i toku kanohi i taua ra, mo nga kino katoa i meatia e ratou, mo ratou i tahuri ki nga atua ke.
Èmi yóò sì pa ojú mi mọ́ dájúdájú ní ọjọ́ náà nítorí i gbogbo ìwà búburú wọn ní yíyípadà sí ọlọ́run mìíràn.
19 Na tuhituhia tenei hei waiata ma korua, ka whakaako hoki ki nga tama a Iharaira: hoatu hoki ki roto ki o ratou waha, kia ai tenei waiata hei kaiwhakaatu moku ki nga tama a Iharaira.
“Ní báyìí kọ ọ́ kalẹ̀ fúnra à rẹ orin yìí kí o sì kọ ọ́ sí Israẹli kí o sì jẹ́ kí wọn kọ ọ́ kí ó lè jẹ́ ẹ̀rí ì mi sí wọn.
20 No te mea ka oti ratou te kawe e ahau ki te whenua i oati ai ahau ki o ratou matua, e rerengia nei e te waiu, e te honi; a ka kai ratou, ka makona, ka momona hoki; ko reira ratou tahuri ai ki nga atua ke, mahi ai ki a ratou, a ka whakahawea rato u ki ahau, ka whakataka hoki i taku kawenata.
Nígbà tí mo ti mú wọn wá sí ilẹ̀ tí ń sàn fún wàrà àti fún oyin, ilẹ̀ tí mo ti ṣe ìlérí ní ìbúra fún àwọn baba ńlá wọn, àti nígbà tí wọ́n bá jẹ, tí ó sì tẹ́ wọn lọ́rùn, tí wọ́n sì gbilẹ̀, wọn yóò yí padà sí ọlọ́run mìíràn wọn yóò sì sìn wọ́n, wọn yóò kọ̀ mí sílẹ̀, wọn yóò sì da májẹ̀mú mi.
21 A, tenei ake, hei te panga o nga kino maha, o nga mate maha ki a ratou, na ma tenei waiata e whakaatu ki to ratou aroaro; no te mea e kore e mahue i nga waha o o ratou uri: e mohio ana hoki ahau ki o ratou whakaaro e tito nei ratou inaianei nei ano, i te mea kiano ahau i kawe noa i a ratou ki te whenua i oati ai ahau.
Àti nígbà tí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìpọ́njú àti ìṣòro bá wá sórí i wọn, orin yìí yóò jẹ́ ẹ̀rí sí wọn, nítorí kò ní di ìgbàgbé fún àwọn ọmọ wọn. Mo mọ̀ ohun tí wọ́n ní inú dídùn sí láti ṣe, pàápàá kí èmi tó mú wọn wá sí ilẹ̀ tí mo ṣe ìlérí fún wọn lórí ìbúra.”
22 Na tuhituhia ana e Mohi tenei waiata i taua rangi ano, a whakaakona ana ki nga tama a Iharaira.
Nígbà náà ni Mose kọ orin yìí kalẹ̀ ní ọjọ́ náà ó sì kọ ọ́ sí Israẹli.
23 A i whakahau ano ia i a Hohua, i te tama a Nunu, i mea, Kia maia, kia toa: mau hoki e kawe nga tama a Iharaira ki te whenua i oati ai ahau ki a ratou: a hei a koe ahau.
Olúwa sì fún Joṣua ọmọ Nuni ní àṣẹ yìí: “Jẹ́ alágbára àti onígboyà, nítorí ìwọ yóò mú Israẹli wá sí ilẹ̀ tí mo ṣèlérí fún wọn lórí ìbúra, èmi fúnra à mi yóò sì wà pẹ̀lú rẹ.”
24 A, ka oti i a Mohi te tuhi nga kupu o tenei ture ki tetahi pukapuka, a poto noa,
Lẹ́yìn ìgbà tí Mose ti parí i kíkọ ọ̀rọ̀ òfin yìí sínú ìwé láti ìbẹ̀rẹ̀ dé òpin,
25 Na, ka whakahau a Mohi i nga Riwaiti, i nga kaiamo i te aaka o te kawenata a Ihowa, ka mea,
ó sì fi àṣẹ yìí fún àwọn ọmọ Lefi tí wọ́n ń gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa:
26 Tangohia tenei pukapuka o te ture, hoatu ki te taha o te aaka o te kawenata a Ihowa, a to koutou atua, a hei reira takoto ai, hei whakaatu ki a koe.
“Gba ìwé òfin yìí kí o sì fi sí ẹ̀gbẹ́ àpótí ẹ̀rí Olúwa Ọlọ́run rẹ. Níbẹ̀ ni yóò wà bí ẹ̀rí sí ọ.
27 No te mea e mohio ana ahau ki tou tutu, ki tou kaki maro: nana, i ahau e ora nei ano i a koutou i tenei ra, e tutu ana ano koutou ki a Ihowa; a ka mate ahau, tera noa ake!
Nítorí mo mọ irú ọlọ̀tẹ̀ àti ọlọ́rùn líle tí ẹ jẹ́. Bí o bá ṣe ọlọ̀tẹ̀ sí Olúwa nígbà tí mo pàpà wà láyé pẹ̀lú yín, báwo ní ẹ ó ti ṣe ọlọ̀tẹ̀ tó nígbà tí mo bá kú tán!
28 Huihuia mai ki ahau nga kaumatua katoa o o koutou iwi, me o koutou rangatira, a ka korero ahau i enei kupu ki o ratou taringa, ka waiho hoki i te rangi, i te whenua hei kaititiro mo ratou.
Ẹ péjọpọ̀ síwájú mi gbogbo àgbà ẹ̀yà yín àti àwọn aláṣẹ yín, kí èmi lè sọ àwọn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí sí etí ìgbọ́ ọ́ wọn.
29 No te mea e mohio ana ahau, ko muri i toku matenga taka rawa ai koutou, peka ke ai i te huarahi i kiia atu e ahau ki a koutou; a ka pono mai te kino ki a koutou i nga ra whakamutunga; mo koutou ka mahi i te kino i te tirohanga a Ihowa, hei whaka pataritari i a ia ki te mahi a o koutou ringa.
Nítorí tí mo mọ̀ pé lẹ́yìn ikú mi, ó dájú pé ìwọ yóò padà di ìbàjẹ́ pátápátá, ẹ ó sì yípadà kúrò ní ọ̀nà tí mo ti pàṣẹ fún un yín. Ní ọjọ́ tó ń bọ̀, ìpọ́njú yóò sọ̀kalẹ̀ sórí i yín nítorí ẹ̀yin yóò ṣe búburú níwájú Olúwa ẹ ó sì mú u bínú nípa ohun tí ọwọ́ yín ti ṣe.”
30 A korerotia ana e Mohi nga kupu o tenei waiata ki nga taringa o te huihuinga katoa o Iharaira a poto noa.
Mose sì ka ọ̀rọ̀ inú orin yìí láti ìbẹ̀rẹ̀ títí dé òpin sí etí ìgbọ́ ọ gbogbo ìjọ Israẹli:

< Tiuteronomi 31 >