< Amoho 6 >
1 Aue, te mate mo te hunga e noho humarie ana i Hiona, mo te hunga hoki e whakawhirinaki ana ki te maunga o Hamaria, nga tangata whai ingoa o te tuatahi o nga iwi, i tae atu nei te whare o Iharaira ki a ratou.
Ègbé ni fún ẹ̀yin tí ará rọ̀ ní Sioni àti ẹ̀yin tí ẹ wà ní abẹ́ ààbò ní òkè Samaria àti ẹ̀yin olókìkí orílẹ̀-èdè tí ẹ̀yin ènìyàn Israẹli máa ń tọ̀ ọ́ wá.
2 Haere tonu ki Karane titiro ai, haere atu i reira ki Hamata nui; haere tonu atu ki Kata o nga Pirihitini: he pai atu ranei i enei kingitanga? nui atu ranei to ratou rohe i to koutou rohe?
Ẹ lọ Kalne kí ẹ lọ wò ó kí ẹ sí tí ibẹ̀ lọ sí Hamati ìlú ńlá a nì. Kí ẹ sì tún sọ̀kalẹ̀ lọ Gati ní ilẹ̀ Filistini. Ǹjẹ́ wọ́n ha dára ju ìpínlẹ̀ yín méjèèjì lọ? Ǹjẹ́ a ha rí ilẹ̀ tó tóbi ju tiyín lọ bí?
3 E te hunga e whakamatara atu na i te ra kino, e mea na i te nohoanga o te tutu kia tata mai;
Ẹ̀yin sún ọjọ́ ibi síwájú, ẹ sì mú ìjọba òǹrorò súnmọ́ tòsí.
4 E takoto na i runga i te moenga rei, e wharoro na i runga i o ratou takotoranga, e kai na i nga reme o te kahui, i nga kuao kau o waenganui i te turanga kau;
Ẹ̀yin sùn lé ibùsùn tí a fi eyín erin ṣe ẹ sì tẹ́ ara sílẹ̀ ni orí àwọn ibùsùn ẹyin pa èyí tí o dára nínú àwọn ọ̀dọ́-àgùntàn yín jẹ ẹ sì ń pa àwọn ọ̀dọ́ màlúù láàrín agbo wọn jẹ.
5 E waiata na i nga waiata poauau ki te rangi hatere; e whakaaroa ana hoki e ratou nga mea whakatangi, e pera ana me Rawiri;
Ẹ̀yin ń lo ohun èlò orin bí i Dafidi ẹ sì ń ṣe àwọn àpilẹ̀rọ àwọn ohun èlò orin.
6 E inu ana i te waina o nga peihana, a e whakawahi ana i a ratou ki nga hinu pai rawa; kahore ia o ratou pouri mo te aitua o Hohepa.
Ẹ̀yin mu wáìnì ẹ̀kún ọpọ́n kan àti ìkunra tí o dára jùlọ ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò káàánú ilé Josẹfu tí ó di ahoro.
7 Na aianei ko ratou ki mua ka whakaraua atu o te hunga e whakaraua ana, a ka kore te hakari a te hunga i wharoro ra.
Nítorí náà, àwọn ni yóò lọ sí ìgbèkùn pẹ̀lú àwọn tí ó ti kó lọ sí ìgbèkùn àsè àwọn tí ń ṣe àṣelékè ni a ó mú kúrò.
8 Kua oatitia te Ariki, a Ihowa, e ia ano, e ai ta Ihowa, ta te Atua o nga mano, E whakarihariha ana ahau ki ta Hakopa e whakai na, e kino ana ki ona whare kingi: mo reira ka tukua atu e ahau te pa me nga mea i roto.
Olúwa Olódùmarè ti búra fúnra rẹ̀, Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun sì ti wí pé: “Mo kórìíra ìgbéraga Jakọbu n kò sì ní inú dídùn sí odi alágbára rẹ̀, Èmi yóò sì fa ìlú náà lé wọn lọ́wọ́ àti ohun gbogbo tí ó wà nínú rẹ̀.”
9 Na, ki te toe nga tangata kotahi tekau i roto i te whare kotahi, ka mate ratou.
Bí ọkùnrin mẹ́wàá bá ṣẹ́kù nínú ilé kan, àwọn náà yóò kú.
10 A, ki te tangohia ake tetahi e tona matua keke, ara e te kaitahu mona, kia maua mai ai nga wheua i roto i te whare, a ka mea ia ki te tangata i roto rawa i te whare, He tangata ano ranei tena kei a koe na? a ka mea ia, Kahore; katahi ia ka mea, Whakarongoa; e kore hoki tatou e whakahua i te ingoa o Ihowa.
Bí ẹbí tí ó yẹ kí ó gbé òkú wọn jáde fún sínsin bá wọlé, bí o ba sì béèrè pé ǹjẹ́ ẹnìkan wa tí ó fi ara pamọ́ níbẹ̀, “Ǹjẹ́ ẹnìkankan wà lọ́dọ̀ yín?” tí ó bá sì dáhùn wí pé, “Rárá,” nígbà náà ni yóò wí pé, “Pa ẹnu rẹ mọ́ àwa kò gbọdọ̀ dárúkọ Olúwa.”
11 No te mea, nana, kei te whakahau a Ihowa, a ka patua te whare nui ki nga pakaru, te whare iti ki nga ngatata.
Nítorí Olúwa tí pa àṣẹ náà, Òun yóò sì wó ilé ńlá náà lulẹ̀ túútúú, àti àwọn ilé kéékèèké sí wẹ́wẹ́.
12 E rere ranei te hoiho i runga i te kamaka? e parautia ranei a reira ki te kau? i whakaputaina ketia ai e koutou te whakawa hei au, nga hua hoki o te tika hei taru kawa.
Ǹjẹ́ ẹṣin a máa sáré lórí àpáta bí? Ǹjẹ́ ènìyàn a máa fi akọ màlúù kọ ilẹ̀ níbẹ̀? Ṣùgbọ́n ẹ̀yin ti yí òtítọ́ padà sí májèlé ẹ sì ti sọ èso òdodo di ìkorò.
13 E koa na hoki koutou ki te kahore noa iho, e mea na, He teka ianei kua riro mai he haona i a tatou, he mea na to tatou uaua?
Ẹ̀yin yọ̀ torí ìṣẹ́gun lórí Lo-Debari, ẹ̀yin sì wí pé, “Ṣé kì í ṣe agbára wa ni àwa fi gba Karnaimu?”
14 Otiia, nana, ka ara i ahau tetahi iwi ki a koutou, e te whare o Iharaira, e ai ta Ihowa, ta te Atua o nga mano, a ka whakatupuria kinotia koutou e ratou i te haerenga atu ki Hamata a tae noa ki te awa o te Arapa.
Nítorí Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun wí pé, “Èmi yóò gbé orílẹ̀-èdè kan dìde sí ọ ìwọ Israẹli, wọn yóò pọ́n yín lójú ní gbogbo ọ̀nà, láti Lebo-Hamati, títí dé pẹ̀tẹ́lẹ̀ Arabah.”