< Mahi 8 >

1 A i reira a Haora e whakaae ana ki tona matenga. Na i taua ra ka oho he whakatoinga nui ki te hahi i Hiruharama: a marara katoa ana ratou, puta noa i nga wahi o Huria, o Hamaria; kahore ia nga apotoro.
Saulu sì wà níbẹ̀, ó sì fi àṣẹ sí ikú rẹ̀. Ní àkókò náà, inúnibíni ńlá kan dìde sí ìjọ tí ó wà ni Jerusalẹmu, gbogbo wọn sì túká káàkiri agbègbè Judea àti Samaria, àyàfi àwọn aposteli.
2 A na te hunga whakaaro a Tepene i tana, a he nui ta ratou tangihanga mona.
Àwọn ènìyàn olùfọkànsìn kan sì gbé òkú Stefanu lọ sin, wọ́n sì pohùnréré ẹkún kíkan sórí rẹ̀.
3 Ko Haora ia, tahoroa ana e ia te hahi, tomo ana ki tena whare, ki tena whare, toia atu ana nga tane me nga wahine, hoatu ana ki roto ki te whare herehere.
Ṣùgbọ́n Saulu bẹ̀rẹ̀ sí da ìjọ ènìyàn Ọlọ́run rú. Ó ń wọ ilé dé ilé, ó sì ń mú àwọn ọkùnrin àti obìnrin, ó sì ń fi wọn sínú túbú.
4 No reira ko ratou tonu, ko nga mea i whakamararatia ra, i haereere ki te kauwhau i te kupu.
Àwọn tí wọ́n sì túká lọ sí ibi gbogbo ń wàásù ọ̀rọ̀ náà.
5 Na ko Piripi i heke atu ki te pa o Hamaria, a kauwhau ana i a te Karaiti ki a ratou.
Filipi sì sọ̀kalẹ̀ lọ sí ìlú Samaria, ó ń wàásù Kristi fún wọn.
6 A kotahi tonu te whakaaro o nga mano ki te whakarongo ki nga mea i korero ai a Piripi, i a ratou e rongo ana, e kite ana i nga tohu i mea ai ia.
Nígbà tí ìjọ àwọn ènìyàn gbọ́, tí wọn sì rí iṣẹ́ àmì tí Filipi ń ṣe, gbogbo wọn sì fi ọkàn kan fiyèsí ohun tí ó ń sọ.
7 I puta mai hoki nga wairua poke i roto i te tini o nga mea e nohoia ana, he nui te reo ki te karanga: he tokomaha ano nga pararutiki, nga kopa i whakaorangia.
Nítorí tí àwọn ẹ̀mí àìmọ́ ń kígbe sókè bí wọ́n ti ń jáde kúrò lára àwọn ènìyàn, ọ̀pọ̀ àwọn arọ àti amúnkùn ún ni ó sì gba ìmúláradá.
8 A nui atu te hari o taua pa.
Ayọ̀ púpọ̀ sì wà ni ìlú náà.
9 Na i reira tetahi tangata, ko Haimona te ingoa, he mahi makutu tana i mua atu i roto i taua pa, a miharo ana te iwi o Hamaria, i mea hoki ia i a ia he tangata nui.
Ṣùgbọ́n ọkùnrin kan wà, tí a ń pè ní Simoni, tí ó ti máa ń pa idán ní ìlú náà, ó sì mú kí ẹnu ya àwọn ará Samaria. Ó sì máa ń fọ́nnu pé ènìyàn ńlá kan ni òun.
10 I whakarongo katoa hoki ratou ki a ia te iti me te rahi, i mea, Ko taua kaha o te Atua tenei tangata, e kiia nei ko te nui.
Ẹni tí gbogbo èwe àti àgbà fiyèsí tí wọ́n sì ń bu ọlá fún wí pé, “Ọkùnrin yìí ní agbára Ọlọ́run ti ń jẹ́ ńlá.”
11 A i whakarongo ratou ki a ia, no te mea kua roa ke ratou e miharo ana ki ana mahi makutu.
Wọ́n bu ọlá fún un, nítorí ọjọ́ pípẹ́ ni ó ti ń pa idán fún ìyàlẹ́nu wọn.
12 A, no ratou ka whakapono ki a Piripi; e kauwhau ana i te rongopai o te rangatiratanga o te Atua, i te ingoa hoki o Ihu Karaiti, ka iriiria ratou, nga tane me nga wahine.
Ṣùgbọ́n nígbà tí wọ́n gba Filipi gbọ́ bí ó ti ń wàásù ìyìnrere ti ìjọba Ọlọ́run, àti orúkọ Jesu Kristi, a bamitiisi wọn.
13 Ko Haimona tonu tetahi i whakapono: a ka iriiria, ka piri tahi ki a Piripi; a, no tona kitenga i nga tohu me nga merekara nunui i mahia, ka miharo.
Simoni tìkára rẹ̀ sì gbàgbọ́ pẹ̀lú nígbà ti a sì bamitiisi rẹ̀, ó sì tẹ̀síwájú pẹ̀lú Filipi, ó wo iṣẹ́ àmì àti iṣẹ́ agbára tí ń ti ọwọ́ Filipi ṣe, ẹnu sì yà á.
14 A, i te rongonga o nga apotoro i Hiruharama kua tango a Hamaria i te kupu a te Atua, ka tonoa atu e ratou a Pita raua ko Hoani ki a ratou:
Nígbà tí àwọn aposteli tí ó wà ní Jerusalẹmu sí gbọ́ pé àwọn ara Samaria ti gba ọ̀rọ̀ Ọlọ́run, wọ́n rán Peteru àti Johanu sí wọn.
15 No to raua taenga iho, ka inoi mo ratou, kia riro te Wairua Tapu i a ratou:
Nígbà tí wọ́n sì lọ, wọ́n gbàdúrà fún wọn, kí wọn bá à lè gba Ẹ̀mí Mímọ́,
16 Kahore ano hoki ia i tau noa ki tetahi o ratou: he mea iriiri kau i runga i te ingoa o te Ariki, o Ihu.
nítorí títí ó fi di ìgbà náà Ẹ̀mí Mímọ́ kò tí ì bà lé ẹnikẹ́ni nínú wọn; kìkì pè a bamitiisi wọn lórúkọ Jesu Olúwa ni.
17 Me i reira ka whakapakia iho o ratou ringa ki a ratou, a ka riro mai te Wairua Tapu i a ratou.
Nígbà náà ni Peteru àti Johanu gbé ọwọ́ lé wọn, wọn sí gba Ẹ̀mí Mímọ́.
18 A, no te kitenga o Haimona, na te whakapanga iho o nga ringa o nga apotoro i homai ai te Wairua tapu, ka mea ki te hoatu moni ki a raua,
Nígbà tí Simoni rí i pé nípa gbígbé ọwọ́ lé ni ni a ń ti ọwọ́ àwọn aposteli fi Ẹ̀mí Mímọ́ fún ni, ó fi owó lọ̀ wọ́n,
19 Ka ki, Homai hoki ki ahau tenei mana, kia riro ai te Wairua Tapu i te tangata e whakapakia iho ai e ahau oku ringa.
ó wí pé, “Ẹ fún èmi náà ni àṣẹ yìí pẹ̀lú, kí ẹnikẹ́ni tí èmi bá gbé ọwọ́ lé lè gba Ẹ̀mí Mímọ́.”
20 Na ko te meatanga a Pita ki a ia, Kia pirau ngatahi korua ko tau moni, ina koe ka whakaaro ma te moni ka whiwhi ai ki te mea homai noa a te Atua.
Ṣùgbọ́n Peteru dá a lóhùn wí pé, “Kí owó rẹ ṣègbé pẹ̀lú rẹ, nítorí tí ìwọ rò láti fi owó ra ẹ̀bùn Ọlọ́run!
21 Kahore he wahi mau, kahore he taunga mou i tenei mea: kahore hoki i tika tou ngakau i te aroaro o te Atua.
Ìwọ kò ni ipa tàbí ìpín nínú ọ̀ràn yìí, nítorí ọkàn rẹ kò ṣe déédé níwájú Ọlọ́run.
22 Na, ripenetatia tenei kino ou, a inoi ki te Atua, me kore noa e murua te whakaaro o tou ngakau.
Nítorí náà ronúpìwàdà ìwà búburú rẹ yìí, kí ó sì gbàdúrà sọ́dọ̀ Ọlọ́run bóyá yóò dárí ète ọkàn rẹ jì ọ́.
23 Kua kite hoki ahau i a koe, kei roto koe i te au kawa, kei te here o te kino.
Nítorí tí mo wòye pé, ìwọ wa nínú òróǹró ìkorò, àti ní ìdè ẹ̀ṣẹ̀.”
24 Na ka whakahoki a Haimona, ka mea, Ma korua e inoi moku ki te Ariki, kei pa ki ahau tetahi o nga mea kua korerotia mai na e korua.
Nígbà náà ni Simoni dáhùn, ó sì wí pé, “Ẹ gbàdúrà sọ́dọ̀ Olúwa fún mi, kí ọ̀kan nínú ohun tí ẹ̀yin tí sọ má ṣe bá mi.”
25 A, ka mutu ta raua whakaatu, ta raua kauwhau i te kupu a te Ariki, ka hoki ki Hiruharama, he maha hoki nga kainga o nga Hamari i kauwhautia ai e raua te rongopai.
Nígbà tí wọn sì ti jẹ́rìí, tiwọn ti sọ ọ̀rọ̀ Olúwa, Peteru àti Johanu padà lọ sí Jerusalẹmu, wọ́n sì wàásù ìyìnrere ni ìletò púpọ̀ ti àwọn ará Samaria.
26 Na ka korero tetahi anahera a te Ariki ki a Piripi, ka mea, Whakatika, haere ki te tonga, ki te ara e heke atu ana i Hiruharama ki Kaha; he koraha tera.
Angẹli Olúwa sì sọ fún Filipi pé, “Dìde kí ó sì máa lọ sí ìhà gúúsù, sí ọ̀nà ijù, tí ó ti Jerusalẹmu lọ sí Gasa.”
27 Whakatika ana ia, haere ana: na ko tetahi tangata o Etiopia, he unaka, he tangata nui na Kanarahi, kuini o nga Etiopiana, ko te kaitiaki ia o ana taonga katoa, i haere ki Hiruharama ki te karakia;
Nígbà tí ó sì dìde, ó lọ; sí kíyèsi, ọkùnrin kan ará Etiopia, ìwẹ̀fà ọlọ́lá púpọ̀ lọ́dọ̀ Kandake ọbabìnrin àwọn ara Etiopia, ẹni tí í ṣe olórí ìṣúra rẹ̀, tí ó sì ti wá sí Jerusalẹmu láti jọ́sìn,
28 A e hoki mai ana, e noho ana i runga i tona hariata, e korero ana i a Ihaia poropiti.
Òun sì ń padà lọ, ó sì jókòó nínú kẹ̀kẹ́ rẹ̀, ó ń ka ìwé wòlíì Isaiah.
29 Na ka mea te Wairua ki a Piripi, Whakatata atu, ka haere atu koe ki te hariata ra.
Ẹ̀mí sì wí fún Filipi pé, “Lọ kí ó si da ara rẹ pọ̀ mọ́ kẹ̀kẹ́ yìí.”
30 Katahi a Piripi ka oma atu ki a ia, ka rongo i a ia e korero ana i a Ihaia poropiti, ka mea atu, E matau ana ranei koe ki tau e korero na?
Filipi si súré lọ, ó gbọ́ ti ó ń ka ìwé wòlíì Isaiah, Filipi sì bí i pé, “Ohun tí ìwọ ń kà yìí ha yé ọ bí?”
31 Ano ra ko ia, Me pehea koia, ki te kore tetahi hei arataki i ahau? Na ka mea ia ki a Piripi kia eke ki runga kia noho tahi me ia.
Ó sì dáhùn wí pé, “Yóò ha ṣe yé mi, bí kò ṣe pé ẹnìkan tọ́ mí sí ọ̀nà?” Ó sì bẹ Filipi kí ó gòkè wá, kí ó sì bá òun jókòó.
32 Na, ko te wahi o te karaipiture e korero nei ia, ko tenei, I arahina ia ano he hipi kia patua; a, me te reme e wahangu ana i te aroaro o tona kaikutikuti, kihai i kuihi tona waha;
Ibi ìwé mímọ́ tí ìwẹ̀fà náà ń kà náà ni èyí: “A fà á bí àgùntàn lọ fún pípa; àti bí ọ̀dọ́-àgùntàn tí ń dákẹ́ níwájú olùrẹ́run rẹ̀, bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni kò wí ohun kan.
33 I ona whakaitinga i whakakorea he whakawa mona: ma wai hoki tona whakatupuranga e korero? Kua tangohia atu nei tona ora i te whenua.
Nínú ìwà ìrẹ̀lẹ̀ rẹ̀ a fi ìdájọ́ òdodo dùn ún. Ta ni ó le sọ̀rọ̀ nípa ti àwọn ìran rẹ̀? Nítorí tí a gba ẹ̀mí rẹ̀ kúrò ní ayé.”
34 Na ka whakahoki te unaka ki a Piripi, ka mea, Tena koa, mo wai tenei korero a te poropiti? mona ake ano, mo tetahi atu ranei?
Ìwẹ̀fà náà sì sọ fún Filipi pé, “Mo bẹ̀ ọ́ sọ fún mi, nípa ta ni wòlíì náà ń sọ ọ̀rọ̀ yìí, nípa ara rẹ̀ tàbí nípa ẹlòmíràn?”
35 Na ka puaki te mangai o Piripi, a, timata mai i taua karaipiture, kauwhautia ana e ia a Ihu ki a ia.
Filipi sí ya ẹnu rẹ̀, bẹ̀rẹ̀ láti ibi ìwé mímọ́ yìí, ó sí wàásù ìyìnrere ti Jesu fún un.
36 A, i a raua e haere ana i te ara, ka tae atu raua ki tetahi wai, ka mea te unaka, Na, he wai tenei: he aha te mea e kore ai ahau e iriiria?
Bí wọ́n sì tí ń lọ lọ́nà, wọ́n dé ibi omi kan; ìwẹ̀fà náà sì wí pé, “Wò ó, omi nìyí. Kín ni ó dá mi dúró láti se ìrìbọmi?”
37 Mea atu ana a Piripi, Ki te whakapono tou ngakau katoa, e ahei ano koe. na ka whakahoki ia, ka mea, E whakapono ana ahau ko Ihu Karaiti te Tama a te Atua.
38 Katahi ia ka whakahau i te haraiata kia tu: ka haere atu raua tokorua ki roto i te wai, a Piripi raua ko te unaka; a iriiria ana ia e ia.
Ó sì pàṣẹ kí kẹ̀kẹ́ dúró jẹ́; àwọn méjèèjì Filipi àti ìwẹ̀fà sì sọ̀kalẹ̀ lọ sínú omi, Filipi sì bamitiisi rẹ̀.
39 A, i to raua putanga ake i te wai, kahakina atu ana a Piripi e te Wairua o te Ariki: a mutu tonu te kitenga atu o te unaka i a ia, heoi haere hari atu ana ia i tona ara.
Nígbà tí wọ́n sí jáde kúrò nínú, omi Ẹ̀mí Olúwa gbé Filipi lọ, ìwẹ̀fà kò sì rí i mọ́; nítorí tí ó ń bá ọ̀nà rẹ̀ lọ, ó ń yọ̀.
40 Ko Piripi ia i kitea ki Ahota; a, i a ia e haere ana, kauwhautia ana e ia te rongopai ki nga pa katoa, a tae noa ia ki Hiharia.
Filipi sì bá ara rẹ̀ ní ìlú Asotu, bí ó ti ń kọjá lọ, o wàásù ìyìnrere ní gbogbo ìlú, títí ó fi dé Kesarea.

< Mahi 8 >