< 2 Hamuera 7 >

1 A, i te kingi e noho ana i tona whare, a ka meinga ia e Ihowa kia okioki i ona hoariri katoa a tawhio noa,
Ó sì ṣe, nígbà tí ọba ń gbé ní ilé rẹ̀, tí Olúwa sì fún un ní ìsinmi yíkákiri kúrò lọ́wọ́ gbogbo àwọn ọ̀tá rẹ̀.
2 Na ka mea te kingi ki a Natana poropiti, Na, titiro, kei te noho nei ahau i te whare hita, ko te aaka ia a te Atua e noho ana i roto i te kakahu.
Ọba sì wí fún Natani wòlíì pé, “Sá wò ó, èmi ń gbé inú ilẹ̀ tí a fi kedari kọ́, ṣùgbọ́n àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run ń gbé inú ibi tí a fi aṣọ gé.”
3 Na ka mea a Natana ki te kingi, Haere, meatia nga mea katoa i tou ngakau; kei a koe hoki a Ihowa.
Natani sì wí fún ọba pé, “Lọ, kí o sì ṣe gbogbo èyí tí ó wà ní ọkàn rẹ, nítorí pé Olúwa wà pẹ̀lú rẹ.”
4 Na i taua po ano ka puta te kupu a Ihowa ki a Natana, ka mea,
Ó sì ṣe ní òru náà, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Natani wá pé,
5 Haere, mea atu ki taku pononga, ki a Rawiri, Ko te kupu tenei a Ihowa, Mau koia e hanga he whare hei nohoanga moku?
“Lọ, sọ fún ìránṣẹ́ mi, fún Dafidi pé, ‘Báyìí ni Olúwa wí, ìwọ ó ha kọ́ ilé fún mi tí èmi yóò gbé.
6 Kahore nei hoki ahau i noho whare no te ra ano i kawea mai ai e ahau nga tama a Iharaira i Ihipa a taea noatia tenei ra; he noho haere ia toku i roto i te teneti, i te tapenakara.
Nítorí pé, èmi kò ì ti gbé inú ilé kan láti ọjọ́ tí èmi ti mú àwọn ọmọ Israẹli gòkè ti ilẹ̀ Ejibiti wá, títí di òní yìí, ṣùgbọ́n èmi ti ń rìn nínú àgọ́, fún ibùgbé mi.
7 I oku haereerenga katoa i roto i nga tamariki katoa a Iharaira, i puaki ranei tetahi kupu aku ki tetahi o nga iwi o Iharaira i whakaritea e ahau hei hepara mo taku iwi, mo Iharaira, i mea ranei ahau, He aha koutou te hanga ai i tetahi whare hita moku?
Ní ibi gbogbo tí èmi ti ń rìn pẹ̀lú gbogbo àwọn ọmọ Israẹli, ǹjẹ́ èmi ti bá ọ̀kan nínú ẹ̀yà Israẹli, tí èmi pa àṣẹ fún láti máa bọ́ àwọn ènìyàn mi àní Israẹli, sọ̀rọ̀ pé, “Èéṣe tí ẹ̀yin kò fi kedari kọ́ ilé fún mi.”’
8 Na, tena kia penei tau ki aianei ki taku pononga ki a Rawiri, Ko te kupu tenei a Ihowa o nga mano, Naku koe i tango mai i te nohoanga hipi, i te whai hipi, hei rangatira mo taku iwi, mo Iharaira.
“Ǹjẹ́, nítorí náà, báyìí ni ìwọ yóò sì wí fún ìránṣẹ́ mi àní Dafidi pé, ‘Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, Èmi ti mú ìwọ kúrò láti inú agbo àgùntàn wá láti má tẹ̀lé àwọn àgùntàn, mo sì fi ọ́ jẹ olórí àwọn ènìyàn mi, àní Israẹli.
9 I a koe ano ahau i ou haerenga katoa, hautopea atu ana e ahau ou hoariri katoa i tou aroaro, a meinga ana koe e ahau hei ingoa nui, hei pera ano me te ingoa o nga mea nunui o te whenua.
Èmi sì wà pẹ̀lú rẹ níbikíbi tí ìwọ ń lọ, èmi sá à gé gbogbo àwọn ọ̀tá rẹ kúrò níwájú rẹ, èmi sì ti sọ orúkọ rẹ di ńlá, gẹ́gẹ́ bí orúkọ àwọn ènìyàn ńlá tí ó wà ní ayé.
10 Na maku e whakarite he wahi mo taku iwi, mo Iharaira, a ka whakatokia ratou e ahau kia noho ki to ratou ake wahi, kia kore e nekehia a muri ake nei; kia mutu ai te tukino a nga tamariki a te kino i a ratou, kei pera me to mua,
Èmi ó sì yan ibìkan fún àwọn ènìyàn mi, àní Israẹli, èmi ó sì gbìn wọ́n, wọn ó sì má gbé bí ibùjókòó tiwọn, wọn kì yóò sì sípò padà mọ́; àwọn ọmọ ènìyàn búburú kì yóò sì pọ́n wọn lójúmọ́, bí ìgbà àtijọ́.
11 Me to te wa i whakaritea ai e ahau he kaiwhakarite mo taku iwi, mo Iharaira, i meinga ai hoki koe kia okioki i ou hoariri katoa. Na ko ta Ihowa kupu tenei ki a koe, Ma Ihowa e hanga he whare mou.
Àti gẹ́gẹ́ bí àkókò ìgbà tí èmi ti fi àṣẹ fún àwọn onídàájọ́ lórí àwọn ènìyàn mi, àní Israẹli, èmi fi ìsinmi fún ọ lọ́wọ́ gbogbo àwọn ọ̀tá rẹ. “‘Olúwa sì wí fún ọ pé Olúwa yóò kọ ilé kan fún ọ.
12 A ka tutuki ou ra, a ka moe ki ou matua, a ka whakaarahia e ahau i muri i a koe tou whanau e puta mai i roto i ou whekau, a ka whakapumautia tona kingitanga.
Nígbà tí ọjọ́ rẹ bá pé, tí ìwọ ó sì sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ, èmi yóò sì gbé irú-ọmọ rẹ lékè lẹ́yìn rẹ, èyí tí ó ti inú rẹ jáde wá, èmi yóò sì fi ìdí ìjọba rẹ kalẹ̀.
13 Nana e hanga he whare mo toku ingoa, a ka whakapumautia e ahau te torona o tona kingitanga a ake ake.
Òun ó sì kọ́ ilé fún orúkọ mi, èmi yóò sì fi ìdí ìjọba rẹ kalẹ̀ láéláé.
14 Ko ahau hei matua ki a ia, ko ia hei tama ki ahau. Ki te ngau ke tana mahi, ka whiu ahau i a ia ki te whiu a te tangata, ki nga whakapanga a nga tama a te tangata.
Èmi ó máa ṣe baba fún un, òun yóò sì máa jẹ́ ọmọ mi. Bí òun bá dẹ́ṣẹ̀, èmi yóò sì fi ọ̀pá ènìyàn nà án, àti ìnà àwọn ọmọ ènìyàn.
15 E kore ia e mutu toku aroha ki a ia, e kore e pera me toku ki a Haora i peia atu na e ahau i tou aroaro.
Ṣùgbọ́n àánú mi kì yóò yípadà kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí èmi ti mú un kúrò lọ́dọ̀ Saulu, tí èmi ti mú kúrò níwájú rẹ.
16 Ka tuturu tonu hoki tou whare me tou kingitanga a ake ake, ki tou aroaro: ka mau tonu tou torona a ake ake.
A ó sì fi ìdílé rẹ àti ìjọba rẹ múlẹ̀ níwájú rẹ títí láé, a ó sì fi ìdí ìtẹ́ rẹ múlẹ̀ títí láé.’”
17 Rite tonu ki enei kupu katoa, ki tenei kitenga katoa, nga kupu a Natana ki a Rawiri.
Gẹ́gẹ́ bí gbogbo ọ̀rọ̀ wọ̀nyí, àti gẹ́gẹ́ bí gbogbo ìran yìí, bẹ́ẹ̀ ni Natani sì sọ fún Dafidi.
18 Katahi a Kingi Rawiri ka haere, a noho ana ki te aroaro o Ihowa, ka mea, Ko wai ahau, e te Ariki, e Ihowa? he aha hoki toku whare, i kawea mai ai ahau e koe a mohoa noa nei?
Dafidi ọba sì wọlé lọ, ó sì dúró níwájú Olúwa, ó sì wí pé, “Olúwa Olódùmarè, ta ni èmi, àti kí sì ni ìdílé mi, tí ìwọ fi mú mi di ìsinsin yìí?
19 He mea iti ano tenei ki tau titiro, e te Ariki, e Ihowa, na kua korerotia nei e koe te whare o tau pononga mo nga tau e maha. Ko ta te tangata tikanga ranei tenei, e te Ariki, e Ihowa?
Nǹkan kékeré ni èyí sá à jásí lójú rẹ, Olúwa Olódùmarè; ìwọ sì ti sọ nípa ìdílé ìránṣẹ́ rẹ pẹ̀lú ní ti àkókò tí o jìnnà. Èyí ha ṣe ìwà ènìyàn bí, Olúwa Olódùmarè?
20 Na ko te aha ake hei korerotanga ma Rawiri ki a koe? e mohio ana hoki koe, e te Ariki, e Ihowa, ki tau pononga.
“Àti kín ní ó tún kù tí Dafidi ìbá tún máa wí fún ọ? Ìwọ, Olúwa Olódùmarè mọ̀ ìránṣẹ́ rẹ.
21 He whakaaro ki tau kupu, na tou ngakau ano, i mea ai koe i enei mea nunui katoa, kia mohio ai tau pononga.
Nítorí ọ̀rọ̀ rẹ, àti gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ ọkàn rẹ, ni ìwọ ṣe ṣe gbogbo nǹkan ńlá wọ̀nyí, kí ìránṣẹ́ rẹ lè mọ̀.
22 Na he nui koe, e Ihowa, e te Atua: kahore hoki he rite mou, kahore atu hoki he Atua; ko koe anake: e rite ana ki nga mea katoa i rongo ai o matou taringa.
“Ìwọ sì tóbi, Olúwa Olódùmarè! Kò sì sí ẹni tí ó dàbí rẹ, kò sì sí Ọlọ́run kan lẹ́yìn rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí gbogbo èyí tí àwa fi etí wá gbọ́.
23 Ko tehea iwi kotahi hoki o te whenua hei rite mo tau iwi, ara mo Iharaira, i haere nei te Atua ki te hoki hei iwi mana ake, hei mea ingoa mona, ki te mahi ano i nga mea nunui mou, i nga mea whakamataku hoki mo tou whenua, i te aroaro o tau iwi i hokona nei e koe mau i Ihipa, i nga tauiwi, i o ratou atua ano hoki?
Orílẹ̀-èdè kan wo ni ó sì ń bẹ ní ayé tí ó dàbí àwọn ènìyàn rẹ, àní Israẹli, àwọn tí Ọlọ́run lọ rà padà láti sọ wọ́n di ènìyàn rẹ̀, àti láti sọ wọ́n ní orúkọ, àti láti ṣe nǹkan ńlá fún un yín, àti nǹkan ìyanu fún ilé rẹ̀, níwájú àwọn ènìyàn rẹ, tí ìwọ ti rà padà fún ara rẹ láti Ejibiti wá, àní àwọn orílẹ̀-èdè àti àwọn òrìṣà wọn.
24 Kua whakapumautia nei hoki e koe mau tau iwi, a Iharaira, hei iwi mau a ake ake: a ko koe hoki, e Ihowa, hei Atua mo ratou.
Ìwọ sì fi ìdí àwọn ènìyàn rẹ, àní Israẹli kalẹ̀ fún ara rẹ láti sọ wọ́n di ènìyàn rẹ títí láé; ìwọ Olúwa sì wá di Ọlọ́run fún wọn.
25 Na whakamana hoki aianei, e Ihowa, e te Atua, te kupu i korerotia e koe mo tau pononga ratou ko tona whare a ake ake, meatia ano tau i korero ai.
“Ǹjẹ́, Olúwa Ọlọ́run, jẹ́ kí ọ̀rọ̀ náà tí ìwọ sọ ní ti ìránṣẹ́ rẹ, àti ní ti ìdílé rẹ̀, kí ó dúró títí láé, kí ó sí ṣe bí ìwọ ti wí.
26 Kia whakanuia ano tou ingoa a ake ake, kia korerotia, Ko Ihowa o nga mano te Atua o Iharaira. Kia tuturu tonu ano te whare o tau pononga, o Rawiri, ki tou aroaro.
Jẹ́ kí orúkọ rẹ ó ga títí láé, pé, ‘Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni Ọlọ́run lórí Israẹli!’ Sì jẹ́ kí a fi ìdílé Dafidi ìránṣẹ́ rẹ múlẹ̀ níwájú rẹ.
27 Nau nei hoki, e Ihowa o nga mano, e te Atua o Iharaira, i whakapuaki mai ki tau pononga, i mea, Ka hanga e ahau he whare mou: koia te ngakau o tau pononga i anga ai ki te inoi i tenei inoi ki a koe.
“Nítorí pé ìwọ, Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run Israẹli ti sọ létí ìránṣẹ́ rẹ, pé, ‘Èmí ó kọ́ ilé kan fún ọ.’ Nítorí náà ni ìránṣẹ́ rẹ sì ṣe ní i lọ́kàn rẹ̀ láti gbàdúrà yìí sí ọ.
28 Na, ko koe hoki, e te Ariki, e Ihowa, taua Atua nei, he pono hoki au kupu, a kua korerotia e koe tenei mea pai ki tau pononga.
Ǹjẹ́, Olúwa Olódùmarè, ìwọ ni Ọlọ́run náà, àwọn ọ̀rọ̀ rẹ sì jásí òtítọ́, ìwọ sì jẹ́ ẹ̀jẹ́ nǹkan rere yìí fún ìránṣẹ́ rẹ.
29 Na reira kia pai koe ki te manaaki i te whare o tau pononga, kia pumau tonu ai ki tou aroaro: nau hoki e Ihowa, e te Atua, te kupu: a hei tau manaaki te manaaki mo te whare o tau pononga a ake ake.
Ǹjẹ́, jẹ́ kí ó wù ọ́ láti bùkún ìdílé ìránṣẹ́ rẹ, kí ó wà títí láé níwájú rẹ, nítorí ìwọ, Olúwa Olódùmarè, ni ó ti sọ ọ́: sì jẹ́ kí ìbùkún wà ní ìdílé ìránṣẹ́ rẹ títí láé, nípasẹ̀ ìbùkún rẹ.”

< 2 Hamuera 7 >