< 2 Hamuera 24 >

1 Na ka mura ano te riri o Ihowa ki a Iharaira, a ka whakatutehu ia i a Rawiri ki te he mo ratou, ki te mea, Tikina, taua a Iharaira raua ko Hura.
Ìbínú Olúwa sì ru sí Israẹli, ó sì ti Dafidi sí wọn, pé, “Lọ ka iye Israẹli àti Juda!”
2 Na ko te kianga a te kingi ki a Ioapa ki te rangatira ope, i reira ia i a ia, Tena, haereerea nga iwi katoa o Iharaira mai o Rana a tae noa ki Peerehepa, ka tatau i te iwi, kia mohio ai ahau ki te toputanga o te iwi.
Ọba sì wí fún Joabu olórí ogun, tí ń bẹ lọ́dọ̀ rẹ̀ pé, “Lọ ní ìsinsin yìí sí gbogbo ẹ̀yà Israẹli láti Dani títí dé Beerṣeba, kí ẹ sì ka iye àwọn ènìyàn, kí èmi lè mọ iye àwọn ènìyàn náà!”
3 Ano ra ko Ioapa ki te kingi, Ma Ihowa, ma tou Atua e mea te iwi kia tatakirau noa atu i to ratou tokomaha i a ratou nei, a kia kite hoki nga kanohi o toku ariki, o te kingi: otiia he aha toku ariki, te kingi i ahuareka ai ki tenei mea?
Joabu sì wí fún ọba pé, “Kí Olúwa Ọlọ́run rẹ fi kún iye àwọn ènìyàn náà, iyekíye tí ó wù kí wọn jẹ́, ní ọ̀rọ̀ọ̀rún, ojú olúwa mi ọba yóò sì rí i, ṣùgbọ́n èétiṣe tí olúwa mi ọba fi fẹ́ nǹkan yìí?”
4 He ahakoa ra, u tonu te kupu a te kingi ki a Ioapa ratou ko nga rangatira ope. Na haere atu ana a Ioapa ratou ko nga rangatira ope i te aroaro o te kingi ki te tatau i te iwi, i a Iharaira.
Ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ ọba borí ti Joabu, àti ti àwọn olórí ogun. Joabu àti àwọn olórí ogun sì jáde lọ kúrò níwájú ọba, láti lọ ka àwọn ènìyàn Israẹli.
5 Na ka whiti ratou i Horano, ka noho ki Aroere, ki te taha ki matau o te pa i waenganui o te awaawa o Kara, a tae noa ki Iatere:
Wọ́n sì kọjá odò Jordani, wọ́n sì pàgọ́ ní Aroeri, ní ìhà apá ọ̀tún ìlú tí ó wà láàrín àfonífojì Gadi, àti sí ìhà Jaseri.
6 Katahi ka tae ratou ki Kireara, ki te whenua o Tahatimihorohi, a ka tae ki Ranaiaana a awhio haere ana ki Hairona;
Wọ́n sì wá sí Gileadi, àti sí ilé Tatimi Hodṣi; wọ́n sì wá sí Dani Jaani àti yíkákiri sí Sidoni.
7 A ka tae ki te pa kaha ki Taira, ki nga pa katoa o nga Hiwi, o nga Kanaani: a puta ana ratou ki te tonga o Hura, ki Peerehepa.
Wọ́n sì wá sí ìlú olódi Tire, àti sí gbogbo ìlú àwọn Hifi, àti ti àwọn ará Kenaani, wọ́n sì jáde lọ síhà gúúsù ti Juda, àní sí Beerṣeba.
8 Na, ka oti te whenua katoa te haereere e ratou, ka tae ratou ki Hiruharama i te paunga o nga marama e iwa, o nga ra e rua tekau.
Wọ́n sì la gbogbo ilẹ̀ náà já, wọ́n sì wá sí Jerusalẹmu ní òpin oṣù kẹsànán àti ogúnjọ́.
9 Na ka homai e Ioapa te toputanga o te iwi i taua ki te kingi: a e waru rau mano nga marohirohi i roto i a Iharaira, he hunga mau hoari; a e rima rau mano nga tangata o Hura.
Joabu sì fi iye tí àwọn ènìyàn náà jásí lé ọba lọ́wọ́. Ó sì jẹ́ ogójì ọ̀kẹ́ ọkùnrin alágbára ní Israẹli, àwọn onídà, àwọn ọkùnrin Juda sì jẹ́ ọ̀kẹ́ mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n ènìyàn.
10 Na ka patu te ngakau o Rawiri i a ia i muri i tana tauanga i te iwi. A ka mea a Rawiri ki a Ihowa, Nui atu toku hara i taku i mea nei: na, tena, kia whakarerea noatia iho, e Ihowa, te he o tau pononga; nui atu hoki te kuware o taku i mea ai.
Àyà Dafidi sì gbọgbẹ́ lẹ́yìn ìgbà tí ó ka àwọn ènìyàn náà tán. Dafidi sì wí fún Olúwa pé, “Èmi ṣẹ̀ gidigidi ní èyí tí èmi ṣe, ṣùgbọ́n, èmi bẹ̀ ọ, Olúwa, fi ẹ̀ṣẹ̀ ìránṣẹ́ rẹ jì ní, nítorí pé èmi hùwà aṣiwèrè gidigidi!”
11 Na, i te marangatanga ake o Rawiri i te ata, ka puta te kupu a Ihowa ki a Kara poropiti, ki ta Rawiri matakite, i mea ia,
Dafidi sì dìde ní òwúrọ̀, ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Gadi wòlíì wá, aríran Dafidi wí pé,
12 Haere, mea atu ki a Rawiri, ko te kupu tenei a Ihowa, E toru nga mea ka whakaaria e ahau ki a koe; whiriwhiria e koe tetahi o aua mea, a ka meatia e ahau ki a koe.
“Lọ kí o sì wí fún Dafidi pé, ‘Báyìí ni Olúwa wí, èmi fi nǹkan mẹ́ta lọ̀ ọ́; yan ọ̀kan nínú wọn, kí èmi ó sì ṣe é sí ọ.’”
13 Heoi ka tae a Kara ki a Rawiri, a ka korero ki a ia, ka mea, Kia tae atu ranei ki a koe etahi tau matekai e whitu ki tou whenua? kia toru ranei nga marama e rere ai koe i te aroaro o ou hoariri, me ta ratou whai ano i a koe? kia toru ranei nga r a o te mate uruta ki tou whenua? Na whakaaroa e koe kia kitea ai taku kupu e whakahoki ai ki toku kaitono mai.
Gadi sì tọ Dafidi wá, ó sì bi í léèrè pé, “Kí ìyàn ọdún méje ó tọ̀ ọ́ wá ní ilẹ̀ rẹ bí? Tàbí kí ìwọ máa sá ní oṣù mẹ́ta níwájú àwọn ọ̀tá rẹ, nígbà tí wọn ó máa lé ọ? Tàbí kí ààrùn ìparun ọjọ́ mẹ́ta ó wá sí ilẹ̀ rẹ? Rò ó nísinsin yìí, kí o sì mọ èsì tí èmi ó mú padà tọ ẹni tí ó rán mi.”
14 Ano ra ko Rawiri ki a Kara, he noa iho oku whakaaro: na kia taka tatou aianei ki roto ki te ringa o Ihowa, he nui hoki ana mahi tohu; a kaua ahau e taka ki te ringa o te tangata.
Dafidi sì wí fún Gadi pé, “Ìyọnu ńlá bá mi. Jẹ́ kí a fi ara wa lé Olúwa ní ọwọ́; nítorí pé àánú rẹ̀ pọ̀; kí ó má sì ṣe fi mí lé ènìyàn ní ọwọ́.”
15 Heoi whakapangia ana e Ihowa he mate uruta ki a Iharaira, o te ata iho ano a taea noatia te wa i whakaritea: a mate ake o te iwi, o Rana a tae noa ki Peerehepa, e whitu tekau mano tangata.
Olúwa sì rán ààrùn ìparun sí Israẹli láti òwúrọ̀ títí dé àkókò tí a dá, ẹgbẹ̀rún ní ọ̀nà àádọ́rin ènìyàn sì kú nínú àwọn ènìyàn náà láti Dani títí fi dé Beerṣeba.
16 A, no te toronga atu o te ringa o te anahera ki Hiruharama whakangaro ai, ka puta ke to Ihowa whakaaro mo te kino, a ka mea ia ki te anahera e whakangaro ana i te iwi, Kua nui tenei: kati tou ringa. A, i te patunga witi a Arauna Iepuhi, te anahe ra a Ihowa.
Nígbà tí angẹli náà sì nawọ́ rẹ̀ sí Jerusalẹmu láti pa á run, Olúwa sì káàánú nítorí ibi náà, ó sì sọ fún angẹli tí ń pa àwọn ènìyàn náà run pé, “Ó tó, dá ọwọ́ rẹ dúró wàyí!” Angẹli Olúwa náà sì wà níbi ìpakà Arauna ará Jebusi.
17 I korero hoki a Rawiri ki a Ihowa i tona kitenga i te anahera i patua ai te iwi, i mea, Ina, kua hara ahau, kua mahi i te mahi he: ko enei hipi ia, i aha ratou? Tena, kia pa tou ringa ki ahau, ki te whare ano o toku papa.
Dafidi sì wí fún Olúwa nígbà tí ó rí angẹli tí ń kọlu àwọn ènìyàn pé, “Wò ó, èmi ti ṣẹ̀, èmi sì ti hùwà búburú ṣùgbọ́n àwọn àgùntàn wọ̀nyí, kín ni wọ́n ha ṣe? Jẹ́ kí ọwọ́ rẹ, èmi bẹ̀ ọ́, kí ó wà lára mi àti ìdílé baba mi.”
18 Na ka haere a Kara ki a Rawiri i taua ra, a ka mea ki a ia, Haere ki runga, whakaarahia he aata ki a Ihowa ki te patunga witi a Arauna Iepuhi.
Gadi sì tọ Dafidi wá ní ọjọ́ náà, ó sì wí fún un pé, “Gòkè, tẹ́ pẹpẹ kan fún Olúwa lórí ilẹ̀ ìpakà Arauna ará Jebusi.”
19 Na whakatika ana a Rawiri, pera ana me te kupu a Kara, me ta Ihowa i whakahau ai.
Gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Gadi, Dafidi sì gòkè lọ bí Olúwa ti pa á ní àṣẹ.
20 A ka titiro atu a Arauna, ka kite i te kingi ratou ko ana tangata e haere mai ana ki a ia: na ka puta atu a Arauna, piko ana ki te kingi, ahu ana tona mata ki te whenua.
Arauna sì wò, ó sì rí ọba àti àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ ń bọ̀ wá lọ́dọ̀ rẹ̀, Arauna sì jáde, ó sì wólẹ̀ níwájú ọba ó sì dojú rẹ̀ bolẹ̀.
21 Na ka mea a Arauna, He aha toku ariki, te kingi, i haere mai ai ki tana pononga? Na ka mea a Rawiri, Ki te hoki i tau patunga witi, kia hanga ai he aata ki a Ihowa, kia mutu ai te whiunga o te iwi.
Arauna sì wí pé, “Nítorí kín ni olúwa mi ọba ṣe tọ ìránṣẹ́ rẹ̀ wá?” Dafidi sì dáhùn pé, “Láti ra ibi ìpakà rẹ lọ́wọ́ rẹ, láti tẹ́ pẹpẹ kan fún Olúwa, kí ààrùn ìparun lè dá lára àwọn ènìyàn náà.”
22 Na ka mea a Arauna ki a Rawiri, Me tango e toku ariki, e te kingi, me whakaeke te mea e pai ana ki tana titiro: nana, nga kau hei tahunga tinana, me nga patu witi, me nga mea o nga kau hei wahie!
Arauna sì wí fún Dafidi pé, “Jẹ́ kí olúwa mi ọba ó mú èyí tí ó dára lójú rẹ̀, kí o sì fi í rú ẹbọ, wò ó, màlúù nìyìí láti fi ṣe ẹbọ sísun, àti ohun èlò ìpakà, àti ohun èlò mìíràn ti màlúù fún igi.
23 Ko enei katoa, e te kingi, e hoatu ana e Arauna ki te kingi. I mea ano a Arauna ki te kingi, Kia manako a Ihowa, tou Atua ki a koe
Gbogbo nǹkan wọ̀nyí ni Arauna fi fún ọba, bí ọba.” Arauna sì wí fún ọba pé, “Kí Olúwa Ọlọ́run rẹ ó gba ọrẹ rẹ.”
24 Na ka mea te kingi ki a Arauna, Kahore, engari me ata hoki e ahau tou wahi ki te utu, e kore hoki e whakaherea e ahau he tahunga tinana ki a Ihowa, ki toku Atua, kahore i utua e ahau. Heoi hokona ana e Rawiri taua patunga witi me nga kau ki te h iriwa, e rima tekau hekere.
Ọba sì wí fún Arauna pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́; ṣùgbọ́n èmi ó rà á ní iye kan lọ́wọ́ rẹ, bí ó ti wù kí ó ṣe; bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò fi èyí tí èmi kò náwó fún, rú ẹbọ sísun sí Olúwa Ọlọ́run mi.” Dafidi sì ra ibi ìpakà náà, àti àwọn màlúù náà ní àádọ́ta ṣékélì fàdákà.
25 A hanga ana e Rawiri he aata ki reira ma Ihowa, whakaekea ana e ia etahi tahunga tinana me etahi whakahere mo te pai. Heoi ka marie a Ihowa ki te whenua, a ka mutu te mate uruta ki a Iharaira.
Dafidi sì tẹ́ pẹpẹ kan níbẹ̀ sí Olúwa, ó sì rú ẹbọ sísun àti ti ìlàjà. Olúwa sì gbọ́ ẹ̀bẹ̀ fún ilẹ̀ náà, ààrùn náà sì dá kúrò ní Israẹli.

< 2 Hamuera 24 >