< 2 Kingi 2 >

1 Na, i te meatanga a Ihowa kia tangohia atu a Iraia ki te rangi i roto i te tukauati, ka haere atu a Iraira raua ko Eriha i Kirikara.
Nígbà tí Olúwa ń fẹ́ gbé Elijah lọ sí òkè ọ̀run nínú àjà, Elijah àti Eliṣa wà ní ọ̀nà láti Gilgali.
2 Na ka mea atu a Iraia ki a Eriha, Hei konei koe noho ai, kua unga hoki ahau e Ihowa ki Peteere. Ano ra ko Eriha, E ora ana a Ihowa, e ora ana hoki tou wairua, e kore ahau e whakarere i a koe. Heoi haere tahi ana raua ki raro, ki Peteere.
Elijah wí fún Eliṣa pé, “Dúró níbí; Olúwa rán mi lọ sí Beteli.” Ṣùgbọ́n Eliṣa wí pé, “Gẹ́gẹ́ bí ó ti dájú pé Olúwa wà láyé àti gẹ́gẹ́ bí ó ti yẹ, èmi kò ní fi ọ́ sílẹ̀.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sọ̀kalẹ̀ lọ sí Beteli.
3 Na ka puta mai nga tama a nga poropiti i Peteere ki a Eriha, a ka mea ki a ia, E mohio ana ranei koe ko aianei tangohia ai e Ihowa tou ariki i runga i tou upoko? Ano ra ko ia, E mohio ana ano ahau; whakarongoa.
Àwọn ọmọ wòlíì ní Beteli jáde wá sí ọ̀dọ̀ Eliṣa wọ́n sì béèrè pé, “Ṣé ìwọ mọ̀ pé Olúwa yóò gba ọ̀gá rẹ kúrò lọ́dọ̀ rẹ lónìí?” “Bẹ́ẹ̀ ni, èmi mọ̀,” Eliṣa dáhùn, “Ṣùgbọ́n ẹ má ṣe sọ̀rọ̀ nípa rẹ̀.”
4 Na ka mea a Iraia ki a ia, E Eriha, heoi konei koe noho ai; kua unga hoki ahau e Ihowa ki Heriko. Ano ra ko tera, E ora ana a Ihowa, e ora ana hoki tou wairua, e kore ahau e whakarere i a koe. Heoi haere ana raua ki Heriko.
Nígbà náà Elijah sì wí fún un pé, “Dúró níbí, Eliṣa: Olúwa ti rán mi lọ sí Jeriko.” Ó sì dá a lóhùn pé, “Bí ó ti dájú pé Olúwa yè àti tí ìwọ náà yè, èmi kò ní fi ọ́ sílẹ̀.” Wọ́n sì jọ lọ sí Jeriko.
5 Na ka whakatata mai nga tama a nga poropiti i Heriko ki a Eriha, a ka mea ki a ia, E mohio ana ranei koe ko aianei tangohia ai e Ihowa tou ariki i runga i tou upoko? Ano ra ko ia, E mohio ana ano ahau; whakarongoa.
Àwọn ọmọ wòlíì tí ó wà ní Jeriko sì gòkè tọ Eliṣa wá wọ́n sì béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ pé, “Ṣé ìwọ mọ̀ wí pé Olúwa yóò gba ọ̀gá rẹ kúrò lọ́dọ̀ rẹ lónìí?” “Bẹ́ẹ̀ ni, èmi mọ̀,” Ó dá wọn lóhùn, “Ṣùgbọ́n ẹ má ṣe sọ nípa rẹ̀.”
6 Na ka mea a Iraia ki a ia, Hei konei koe noho ai; kua unga hoki ahau e Ihowa ki Horano. Ano ra ko tera, E ora ana a Ihowa, e ora ana ano hoki tou wairua, e kore ahau e whakarere i a koe. Na haere ana raua tokorua.
Nígbà náà Elijah wí fún un pé, “Dúró níbí; Olúwa rán mi lọ sí Jordani.” Ó sì dá a lóhùn pé, “Gẹ́gẹ́ bí ó ti jẹ́ wí pé, Olúwa yè àti gẹ́gẹ́ bí o ti yè, èmi kò ní fi ọ́ sílẹ̀.” Bẹ́ẹ̀ ni àwọn méjèèjì sì jọ ń lọ.
7 Na ka haere etahi tangata e rima tekau, he tama na nga poropiti, a tu atu ana i tawhiti; me te tu ano raua tokorua i te taha o Horano.
Àádọ́ta àwọn ọkùnrin ọmọ wòlíì sì lọ láti lọ dúró ní ọ̀nà jíjìn, wọ́n sì kọ ojú da ibi tí Elijah àti Eliṣa ti dúró ní Jordani.
8 Na ka mau a Iraia ki tona koroka, whakakopaia ana e ia, patua ana ki nga wai, a ka wehea ki tetahi taha, ki tetahi taha, a whiti ana raua i te wahi maroke.
Elijah sì mú agbádá ó sì ká a sókè ó sì lu omi náà pẹ̀lú rẹ̀. Omi náà sì pín sí ọ̀tún àti sí òsì, àwọn méjèèjì sì rékọjá lórí ilẹ̀ gbígbẹ.
9 A, no to raua whitinga, ka mea a Iraira ki a Eriha, Tonoa mai, ko te aha e meatia e ahau mau i ahau kiano kia wehea noatia i a koe. Ano ra ko Eriha, Kia rereruatia mai ki ahau te wahi wairua i a koe na.
Nígbà tí wọ́n rékọjá, Elijah sì wí fún Eliṣa pé, “Sọ fún mi, kí ni èmi lè ṣe fún ọ kí ó tó di wí pé wọ́n gbà mí kúrò lọ́dọ̀ rẹ?” “Jẹ́ kí èmi kí ó jogún ìlọ́po méjì ẹ̀mí rẹ.” Ó dá a lóhùn.
10 Na ka mea tera, He mea pakeke tau i tono mai na: he ahakoa ra, ki te kite koe i ahau e tangohia atu ana i a koe, ka rite ki tau na; ki te kahore, ka kore e pena.
“Ìwọ ti béèrè ohun tí ó ṣòro,” Elijah wí pé, “Síbẹ̀ tí ìwọ bá rí mi nígbà tí a bá gbà mí kúrò lọ́wọ́ rẹ, yóò jẹ́ tìrẹ bí bẹ́ẹ̀ kọ́ kò ní rí bẹ́ẹ̀.”
11 Na, i a raua e haere ana, me te korero haere, ka puta mai tetahi hariata ahi me nga hoiho ahi, a wehea ana raua tokorua; a kake ana a Iraia i roto i te tukauati ki te rangi.
Gẹ́gẹ́ bí wọ́n ti ń rìn lọ tí wọ́n sì ń sọ̀rọ̀ pọ̀, lọ́gán kẹ̀kẹ́ iná àti ẹṣin iná yọ sí wọn ó sì ya àwọn méjèèjì nípa, Elijah sì gòkè lọ sí ọ̀run pẹ̀lú àjà.
12 A ka kite a Eriha, ka karanga ia, E toku papa, e toku papa, e nga hariata o Iharaira, e ona kaieke hoiho! A kihai ia i kite i a ia i muri. Na ka mau ia ki ona kakahu ake, a haea iho kia rua nga wahi.
Eliṣa rí èyí ó sì kígbe sókè, “Baba mi! Baba mi! Kẹ̀kẹ́ àti ẹlẹ́ṣin Israẹli!” Eliṣa kò sì rí i mọ́. Ó sì mú aṣọ ara rẹ̀ ó sì fà wọ́n ya sọ́tọ̀.
13 I tangohia ake hoki e ia te koroka o Iraia i marere i runga i a ia, e hoki ana, tu ana i te pareparenga o Horano.
Ó sì mú agbádá tí ó ti jábọ́ láti ọ̀dọ̀ Elijah ó sì padà lọ, ó sì dúró lórí bèbè Jordani.
14 Na ka mau ia ki te koroka o Iraia i marere nei i runga i a ia, a patua iho ki nga wai, me te ki ano, Kei hea ra a Ihowa, te Atua o Iraia? Na, ka patua e ia nga wai, wehe ana ki tetahi taha, ki tetahi taha: a whiti ana a Eriha.
Ó sì mú agbádá náà tí ó jábọ́ láti ọwọ́ rẹ̀, ó sì lu omi pẹ̀lú rẹ̀. “Níbo ni Olúwa Ọlọ́run Elijah wà?” Ó béèrè. Nígbà tí ó lu omi náà, ó sì pín sí apá ọ̀tún àti sí òsì, Eliṣa sì rékọjá.
15 A, no te kitenga o nga tama a nga poropiti, o era o Heriko i te ritenga mai ki a ia, ka mea ratou, Kua tau te wairua o Iraia ki runga ki a Eriha. Na haere ana mai ratou ki te whakatau i a ia, piko ana ki tona aroaro ki te whenua.
Àwọn ọmọ wòlíì láti Jeriko, tí wọ́n ń wò, wí pé, “Ẹ̀mí Elijah sinmi lé Eliṣa.” Wọ́n sì lọ láti lọ bá a, wọ́n sì dojúbolẹ̀ níwájú rẹ̀.
16 Na ka mea ratou ki a ia, Nana, tenei etahi tangata e rima tekau kei au pononga, he marohirohi; tukua ratou kia haere ki te rapu i tou ariki; kei tupono kua kahakina atu ia e te wairua o Ihowa, kua maka ki runga ki tetahi maunga, ki roto ranei ki tetahi awaawa. Na ka mea ia, Kaua e unga.
“Wò ó,” wọ́n wí pé, “Àwa ìránṣẹ́ ni àádọ́ta ọkùnrin alágbára. Jẹ́ kí wọ́n lọ láti lọ wá ọ̀gá rẹ wá. Bóyá ẹ̀mí Olúwa ti gbé e sókè, ó sì gbé e kalẹ̀ lórí òkè ńlá tàbí lórí ilẹ̀.” “Rárá,” Eliṣa dá a lóhùn pé, “Má ṣe rán wọn.”
17 A, i ta ratou tohenga a whakama noa ia, ka ki atu ia, Unga. Na unga ana e ratou e rima tekau nga tangata: a e toru nga ra i rapu ai ratou, heoi kihai i kitea.
Ṣùgbọ́n wọ́n rọ̀ ọ́ títí ojú fi tì í láti gbà. Ó wí pé, “Rán wọn.” Wọ́n sì rán àádọ́ta ènìyàn tí ó wá a fún ọjọ́ mẹ́ta ṣùgbọ́n wọn kò rí i.
18 Na hoki ana ratou ki a ia, i Heriko hoki ia e noho ana; a ka mea ia ki a ratou, Kihai ianei ahau i ki atu ki a koutou, Kaua e haere?
Nígbà tí wọ́n padà dé ọ̀dọ̀ Eliṣa, tí ó dúró ní Jeriko, ó wí fún wọn pé, “Ṣé èmi kò sọ fún un yín kí ẹ má lọ?”
19 Na ka mea nga tangata o te pa ki a Eriha, Nana, he pai te turanga o tenei pa, e kite nei hoki toku ariki; engari ko te wai he kino, a ko te whenua he whakatahe.
Àwọn ọkùnrin ìlú wí fún Eliṣa, pé, “Wò ó, olúwa wa, ìtẹ̀dó ìlú yìí dára, gẹ́gẹ́ bí ẹ ti rí i, ṣùgbọ́n omi náà burú, ilẹ̀ náà sì sá.”
20 Na ka mea ia, Maua mai he oko hou ki ahau, ka mea he tote ki roto. Na ka kawea mai e ratou ki a ia
Ó sì wí pé, “Mú àwokòtò tuntun fún mi wá, kí o sì mú iyọ̀ sí inú rẹ̀.” Wọ́n sì gbé e wá fún un.
21 Na haere ana ia ki te matapuna o te wai, a maka ana te tote ki roto, me te ki ano, Ko te kupu tenei a Ihowa, Kua ora tenei wai i ahau; heoi ano o konei mate, o konei whakatahe.
Nígbà náà ó sì jáde lọ sí ibi orísun omi, ó sì da iyọ̀ sí inú rẹ̀, ó wí pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa wí: ‘Èmi ti wo omi yìí sàn. Kò ní mú ikú wá mọ́ tàbí mú ilẹ̀ náà sá.’”
22 Na ora tonu ake taua wai a mohoa noa nei, pera tonu me ta Eriha kupu i korero ai.
Omi náà sì ti dára ni mímu títí di òní, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ tí Eliṣa ti sọ.
23 Na ka haere atu ia i reira ki Peteere; a, i a ia e haere ana i te ara, ka puta mai etahi tamariki ririki i te pa, ka taunu ki a ia, ka mea, Pakira, haere ki runga; pakira, haere ki runga.
Láti ibẹ̀ Eliṣa lọ sókè ní Beteli gẹ́gẹ́ bí ó ti ń rìn lọ lójú ọ̀nà, àwọn ọ̀dọ́ kan jáde wá láti ìlú náà wọ́n sì fi ṣe ẹlẹ́yà. “Máa lọ sókè ìwọ apárí!” Wọ́n wí pé. “Máa lọ sókè ìwọ apárí!”
24 Na ka tahuri ake ia, ka titiro ki a ratou, a kanga iho ratou i runga i te ingoa o Ihowa. Na ko te putanga mai o nga pea uha e rua i te ngahere, a haehaea ana etahi o ratou, e wha tekau ma rua nga tamariki.
Ó sì yípadà, ó sì wò wọ́n ó sì fi wọ́n bú ní orúkọ Olúwa. Nígbà náà beari méjì sì jáde wá láti inú igbó ó sì lu méjìlélógójì lára àwọn ọ̀dọ́ náà.
25 Na haere atu ana ia i reira ki Maunga Karamere, a hoki ana i reira ki Hamaria.
Ó sì lọ sí orí òkè Karmeli láti ibẹ̀ ó sì padà sí Samaria.

< 2 Kingi 2 >