< 2 Kingi 18 >

1 Na, no te toru o nga tau o Hohea tama a Eraha kingi o Iharaira, i kingi ai a Hetekia tama a Ahata kingi o Hura.
Ní ọdún kẹta Hosea ọmọ Ela ọba Israẹli, Hesekiah ọmọ Ahasi ọba Juda bẹ̀rẹ̀ ìjọba.
2 E rua tekau ma rima ona tau i tona kingitanga, a e rua tekau ma iwa nga tau i kingi ai ia ki Hiruharama; a ko te ingoa o tona whaea ko Api, he tamahine na Hakaraia.
Ó jẹ́ ẹni ọdún mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n nígbà tí ó ti di ọba, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mọ́kàndínlọ́gbọ̀n. Orúkọ ìyá rẹ̀ sì ni Abijah ọmọbìnrin Sekariah.
3 Na he tika tana mahi ki te titiro a Ihowa, i rite ki nga mea katoa i mea ai a Rawiri, tona tupuna.
Ó sì ṣe ohun tí ó dára níwájú Olúwa, gẹ́gẹ́ bí i baba rẹ̀ Dafidi ti ṣe.
4 I whakakahoretia e ia nga wahi tiketike, i tukitukia hoki nga whakapakoko, tuaina ana e ia te Ahera: a mongamonga ana i a ia te nakahi parahi, i hanga nei e Mohi; tahu tonu ai hoki nga tama a Iharaira i te whakakakara ki taua mea a taea noatia ta ua ra; a tapa ana e ia, ko Nehuhatana.
Ó mú ibi gíga náà kúrò, ó sì fọ́ àwọn ère òkúta, ó sì gé àwọn ère Aṣerah lulẹ̀, ó sì fọ́ ejò idẹ tí Mose ti ṣe náà túútúú, títí di ọjọ́ tí àwọn ọmọ Israẹli ń sun tùràrí sí. (Wọ́n sì pè é ní Nehuṣitani.)
5 I whakawhirinaki hoki ia ki a Ihowa, ki te Atua o Iharaira; na kahore he rite mona o nga kingi katoa o Hura i muri i a ia, o era ranei i mua atu i a ia.
Hesekiah sì gbẹ́kẹ̀lé Olúwa Ọlọ́run Israẹli. Kò sì ṣí ẹnìkan tí ó dàbí tirẹ̀ lára gbogbo àwọn ọba Juda, bóyá kí ó tó jẹ tàbí lẹ́yìn rẹ̀.
6 I piri tonu hoki ia ki a Ihowa, kihai i mahue te whai i a ia, engari i puritia e ia ana whakahau i whakahau ai a Ihowa ki a Mohi.
Ó súnmọ́ Olúwa, kò sì dẹ́kun láti tì í lẹ́yìn: ó sì pa òfin Olúwa mọ́ tí ó ti fi fún Mose.
7 Na i a ia a Ihowa, a oti pai ana tana i nga wahi katoa i haere ai ia. Na ka whakakeke ia ki te kingi o Ahiria, a kihai i mahi ki a ia.
Olúwa sì wà pẹ̀lú rẹ̀; ó sì ń ṣe rere nínú gbogbo ohun tí ó dáwọ́lé. Ó ṣe ọ̀tẹ̀ sí ọba Asiria kò sì sìn ín.
8 I patua e ia nga Pirihitini tae noa ki Kaha, ki ona rohe, i te taumaihi o nga kaitutei ki te pa taiepa.
Láti ilé ìṣọ́ títí dé ìlú olódi, ó sì pa àwọn ará Filistini run, àti títí dé Gasa àti agbègbè rẹ̀.
9 Na i te wha o nga tau o Kingi Hetekia, ara i te whitu o nga tau o Honea tama a Eraha kingi o Iharaira, ka whakaekea Hamaria e Haramanehere kingi o Ahiria, whakapaea ana e ia.
Ní ọdún kẹrin ọba Hesekiah, nígbà tí ó jẹ́ ọdún keje Hosea ọmọ Ela ọba Israẹli. Ṣalamaneseri ọba Asiria yàn lára Samaria ó sì tẹ̀dó tì í.
10 A, i te mutunga o te toru o nga tau, ka horo a reira i a ratou; ara no te ono o nga tau o Hetekia, koia ra te iwa o nga tau o Hohea kingi o Iharaira, ka horo Hamaria.
Lẹ́yìn ọdún mẹ́ta Asiria gbé e. Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n kó Samaria ní ọdún kẹfà Hesekiah tí ó sì jẹ́ ọdún kẹsànán Hosea ọba Israẹli.
11 Na ka whakahekea e te kingi o Ahiria a Iharaira ki Ahiria, whakanohoia ana e ia ki Haraha, ki Haporo, ki te taha o te awa o Kotana ki nga pa ano hoki o nga Meri:
Ọba Asiria lé Israẹli kúrò ní Asiria, wọ́n sì ṣe àtìpó wọn ní Hala, ní Gosani létí odò Habori àti ní ìlú àwọn ará Media.
12 Mo ratou kihai i rongo ki te reo o Ihowa, o to ratou Atua, engari takahia ana e ratou tana kawenata me nga mea katoa i whakahaua mai e Mohi, e ta Ihowa pononga; kihai i whakarangona, kihai i mahia.
Èyí ṣẹlẹ̀ nítorí wọn kò pa àṣẹ Olúwa Ọlọ́run wọn mọ́. Ṣùgbọ́n wọ́n ti dà májẹ̀mú rẹ̀ gbogbo èyí tí Mose ìránṣẹ́ Olúwa ti pàṣẹ. Wọn kò fi etí wọn sílẹ̀ sí òfin wọn kò sì gbé wọn jáde.
13 Na no te tekau ma wha o nga tau o Kingi Hetekia ka whakaekea nga pa taiepa katoa o Hura e Henakeripi kingi o Ahiria, a horo ana i a ia.
Ní ọdún kẹrìnlá tí Hesekiah jẹ ọba, Sennakeribu ọba Asiria kọlu gbogbo ìlú olódi ti Juda ó sì pa wọ́n run.
14 Na ka unga tangata a Hetekia kingi o Hura ki te kingi o Ahiria ki Rakihi hei mea, Kua hara ahau; hoki atu i ahau: ko tau e whakapikau mai ai ki ahau ka pikaua e ahau. Na whakaritea ana e te kingi o Ahiria ki a Hetekia kingi o Hura kia toru rau t aranata hiriwa, kia toru tekau hoki taranata koura.
Bẹ́ẹ̀ ni Hesekiah ọba Juda sì ránṣẹ́ yìí sí ọba Asiria ní Lakiṣi, wí pé, “Mo ti ṣẹ̀, padà lẹ́yìn mi: èmi yóò sì san ohunkóhun tí ìwọ bá béèrè lọ́wọ́ mi.” Ọba Asiria sì bu fún Hesekiah ọba Juda ọ̀ọ́dúnrún tálẹ́ǹtì fàdákà àti ọgbọ̀n tálẹ́ǹtì wúrà.
15 Na hoatu ana e Hetekia ki a ia te hiriwa katoa i kitea ki te whare o Ihowa, ki nga taonga ano o te whare o te kingi.
Hesekiah fún un ní gbogbo fàdákà tí a rí nínú ilé Olúwa àti nínú ìṣúra ilé ọba.
16 No taua wa ano ka tapahia e Hetekia te koura o nga tatau o te temepara o Ihowa, o nga pou hoki i whakakikoruatia nei e Hetekia kingi o Hura, a hoatu ana ki te kingi o Ahiria.
Ní àkókò yìí Hesekiah ọba Juda ké wúrà tí ó wà ní ẹnu ìlẹ̀kùn ilé Olúwa, kúrò àti ti òpó tí Hesekiah ọba Juda ti gbéró ó sì fi fún ọba Asiria.
17 Na ka unga e te kingi o Ahiria a Taratana, a Rapaharihi, a Rapahake i Rakihi ki a Kingi Hetekia ki Hiruharama, he nui te ope, Na haere ana ratou, ka tae ki Hiruharama. A, i to ratou taenga atu, ka haere ratou, ka tu ki te awakeri o te puna wai o runga, o tera i te huarahi o te mara a te kaihoroi kakahu.
Ọba Asiria rán alákòóso gíga jùlọ, ìjòyè pàtàkì àti àwọn adarí pápá pẹ̀lú àwọn ọmọ-ogun tí ó pọ̀, láti Lakiṣi sí ọba Hesekiah ní Jerusalẹmu. Wọ́n wá sí òkè Jerusalẹmu wọ́n sì dúró ní etí ìdarí omi àbàtà òkè, ní ojú ọ̀nà tó lọ sí òpópó pápá alágbàfọ̀.
18 Na, ka karanga ratou ki te kingi, ka puta atu ki a ratou a Eriakimi tama a Hirikia, te rangatira o te whare, a Hepena kaituhituhi, a Ioaha tama a Ahapa te kaiwhakamahara.
Wọ́n sì pe ọba; àti Eliakimu ọmọ Hilkiah ẹni tí í ṣe ilé olùtọ́jú, Ṣebna akọ̀wé, àti Joah ọmọkùnrin Asafu tí ó jẹ́ akọ̀wé ìrántí jáde pẹ̀lú wọn.
19 Na ka mea a Rapahake ki a ratou, Korero atu ainei ki a Hetekia, Ko te kupu tenei a te kingi nui, a te kingi o Ahiria, He aha tenei whakawhirinaki, e whakawhirinaki na koe?
Olùdarí pápá wí fún wọn pé, “Sọ fún Hesekiah pé, “‘Èyí ni ohun tí ọba ńlá, ọba Asiria sọ: Kí ni ìgbẹ́kẹ̀lé yìí tí ìwọ gbẹ́kẹ̀lé?
20 E mea na koe, otiia he mea ngutu kau, Tenei te ngarahu tika, te kaha mo te whawhai. Na e whakawhirinaki ana koe ki a wai, i whakakeke ai koe ki ahau?
Ìwọ wí pé ìwọ ni ìmọ̀ àti agbára láti jagun, ṣùgbọ́n ìwọ sọ̀rọ̀ òfìfo lásán. Ǹjẹ́ ta ni ìwọ gbẹ́kẹ̀ rẹ lé, tí ìwọ fi ń ṣe ọ̀tẹ̀ sí mi?
21 Nana, e whakawhirinaki ana koe ki tena kakaho pepe hei tokotoko, ki a ngoto ki roto ki tona ringa, na, kua tu. Ka pera ano a Parao kingi o Ihipa ki te hunga katoa e okioki ana ki a ia.
Wò ó, nísinsin yìí, ìwọ gbẹ́kẹ̀ rẹ lé Ejibiti, ẹ̀rún ọ̀pá pẹlẹbẹ ìyè fífọ́ yìí, èyí tí yóò wọ inú ọwọ́ ẹni tí ó sì bá fi ara tì í. Bẹ́ẹ̀ ni Farao ọba Ejibiti ṣe rí fún gbogbo àwọn tí ó gbẹ́kẹ̀ wọn lé e.
22 Otiia ki te mea mai koutou ki ahau, Ko Ihowa, ko to matou Atua ta matou e whakawhirinaki nei: he teka ianei ko ia tena, nana nei nga wahi tiketike, me nga aata i whakakahoretia atu nei e Hetekia, a kua mea ia ki a Hura raua ko Hiruharama, Hei mu a i tenei aata i Hiruharama koutou koropiko ai?
Tí ìwọ bá sì sọ fún mi pé, “Àwa gbẹ́kẹ̀ wa lé Olúwa Ọlọ́run.” Òun ha kọ́ ní ẹnìkan náà tí ibi gíga àti àwọn pẹpẹ tí Hesekiah mú kúrò, tí ó wí fún Juda àti Jerusalẹmu pé, “O gbọdọ̀ sìn níwájú pẹpẹ yìí ní Jerusalẹmu”?
23 Na homai aianei he utu pupuri ki toku ariki, ki te kingi o Ahiria, a ka hoatu e ahau ki a koe etahi hoiho, kia rua mano, ki te taea e koe te whakanoho kaieke ki runga.
“‘Wá nísinsin yìí, ṣe àdéhùn pẹ̀lú ọ̀gá mi, ọba Asiria èmi yóò sì fún ọ ní ẹgbẹ̀rún méjì ẹṣin tí ìwọ bá lè kó àwọn tí yóò gùn ún sí orí rẹ!
24 A me pehea e taea ai e koe te pare atu te kanohi o tetahi rangatira kotahi o nga iti rawa o nga pononga a toku ariki, a ka whakawhirinaki koe ki Ihipa hei hariata, hei kaieke hoiho mau?
Báwo ni ìwọ yóò ha ti ṣe le yí ojú balógun kan tí ó kéré jùlọ padà nínú àwọn ìránṣẹ́ olúwa mi, tí ìwọ sì gbẹ́kẹ̀ rẹ lé Ejibiti fún àwọn kẹ̀kẹ́ àti ẹlẹ́ṣin?
25 I haere kau mai ranei ahau, kahore a Ihowa, ki te huna i tenei wahi? I mea a Ihowa ki ahau, Haere ki te whenua ra huna ai.
Síwájú sí i, èmi ti wá láti mú àti láti parun ibí yìí láìsí ọ̀rọ̀ láti ọ̀dọ̀ Olúwa? Olúwa fún rara rẹ̀ sọ fún mi pé kí n yára láti yan lórí ìlú yìí, kí n sì pa á run.’”
26 Katahi ka mea a Eriakimi tama a Hirikia ratou ko Hepena, ko Ioaha, ki a Rapahake, Korero koa ki au pononga i te reo Hiriani; e matau ana hoki matou ki tena reo; kaua e korero mai ki a matou i te reo Hurai i te mea e whakarongo ana te iwi i runga i te taiepa.
Nígbà náà Eliakimu ọmọ Hilkiah, àti Ṣebna àti Joah sọ fún olùdarí pápá pé, “Jọ̀wọ́ sọ̀rọ̀ fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ ní èdè Aramaiki, nítorí ti ó tí yé wa, má ṣe sọ̀rọ̀ fún wa pẹ̀lú èdè Heberu ní etí ìgbọ́ àwọn ènìyàn tí ń bẹ lórí odi.”
27 Ano ra ko Rapahake ki a ratou, I unga mai ranei ahau e toku ariki ki tou ariki, a ki a koe, hei korero i enei kupu? He teka ianei i unga mai ahau e ia ki nga tangata e noho ana i runga i te taiepa, kia kainga e ratou to ratou paru, kia inumia to ratou mimi, ara e koutou tahi?
Ṣùgbọ́n aláṣẹ dáhùn pé, “Ṣé fún ọ̀gá rẹ àti ìwọ nìkan ní ọ̀gá mi rán mi sí láti sọ àwọn nǹkan wọ̀nyí kì í sì í ṣe fún àwọn ọkùnrin tí ó jókòó lórí odi ni gẹ́gẹ́ bí ìwọ, ni yóò ní láti jẹ ìgbẹ́ ará wọn kí wọ́n sì mu ìtọ̀ ará wọn?”
28 Katahi a Rapahake ka tu, a he nui tona reo ki te karanga i te reo Hurai; i korero ia, i mea, Whakarongo ki te kupu a te kingi nui, a te kingi o Ahiria.
Nígbà náà, aláṣẹ dìde, ó sì pè jáde ní èdè Heberu pé, “Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ ọba ńlá, ọba Asiria!
29 Ko te kupu tenei a te kingi Kei tinihangatia koutou e Hetekia; e kore hoki koutou e taea te whakaora e ia i tona ringa:
Èyí ni ohun tí ọba sọ, má ṣe jẹ́ kí Hesekiah tàn ọ́ jẹ kò le gbà ọ́ kúrò ní ọwọ́ mi.
30 Kei meinga hoki koutou e Hetekia kia whakawhirinaki ki a Ihowa, i a ia e ki na, He pono, tera tatou e whakaorangia e Ihowa, e kore hoki tenei pa e tukua ki te ringa o te kingi o Ahiria.
Ẹ má ṣe jẹ́ kí Hesekiah mú yín gbẹ́kẹ̀lé Olúwa nípa sísọ pé, ‘Olúwa yóò gbà wá nítòótọ́; ìlú yìí ni wọn kò ní fi lé ọba ìlú Asiria lọ́wọ́.’
31 Kaua e rongo ki a Hetekia; ko te kupu tenei a te kingi o Ahiria, Houhia ta koutou rongo ki ahau, ka haere mai ki waho ki ahau; ka kai ai koutou i nga hua o tana waina, o tana waina, o tana piki, o tana piki, ka inu ano i te wai o tana puna, o ta na puna:
“Má ṣe tẹ́tí sí Hesekiah. Èyí ni ohun tí ọba Asiria wí pé, ‘Fi ẹ̀bùn wá ojúrere mi, kí o sì jáde tọ̀ mí wá.’ Nígbà náà olúkúlùkù yín yóò jẹun láti inú àjàrà rẹ̀ àti igi ọ̀pọ̀tọ́, yóò sì mu omi láti inú àmù rẹ̀,
32 Kia tae atu ra ano ahau ki te tiki atu i a koutou ki te whenua penei i to koutou nei whenua, ki te whenua witi, waina, ki te whenua taro, mara waina, ki te whenua hinu oriwa, honi hoki, kia ora ai koutou, kei mate; kaua hoki e whakarongo ki a He tekia, i a ia e tohe na ki a koutou, e mea na, Ma Ihowa tatou e whakaora.
títí tí èmi yóò fi wá mú ọ lọ sí ilé gẹ́gẹ́ bí i tìrẹ, ilẹ̀ ọkà àti ọtí wáìnì, ilẹ̀ oúnjẹ àti ọgbà àjàrà, ilẹ̀ òróró olifi àti ti ilẹ̀ oyin; yàn ìyè má sì ṣe yàn ikú! “Kí ẹ má ṣe gbọ́ tí Hesekiah, nítorí ó ń tàn yín tí ó ba tí wí pé, ‘Olúwa yóò gbà wá?’
33 I ora ranei i tetahi o nga atua o nga tauiwi tona whenua i te ringa o te kingi o Ahiria?
Ṣé òrìṣà àwọn orílẹ̀-èdè kankan ti gba ilé rẹ lọ́wọ́ àwọn ọba Asiria?
34 Kei hea nga atua o Hamata, o Arapara? kei hea nga atua o Heparawaima, o Hena, o Iwa? i whakaorangia ranei e ratou a Hamaria i toku ringa?
Níbo ni àwọn òrìṣà Hamati àti Arpadi gbé wà? Níbo ni àwọn òrìṣà Sefarfaimi, Hena àti Iffa gbé wà? Wọ́n ha gba Samaria kúrò lọ́wọ́ mi bí?
35 Ko wai o nga atua katoa o nga whenua, kua whakaorangia e ratou to ratou whenua i toku ringa, e whakaorangia ai e Ihowa a Hiruharama i toku ringa?
Ta ni nínú gbogbo àwọn òrìṣà ilẹ̀ yìí tí ó ti gbìyànjú láti gba ilẹ̀ rẹ̀ kúrò lọ́wọ́ mi? Báwo ni Olúwa yóò ṣe gba Jerusalẹmu kúrò lọ́wọ́ mi?”
36 Otiia whakarongo kau ana tera te iwi, kihai i whakahoki kupu ki a ia; ko ta te kingi hoki tena i ako ai, i ki ai, Kaua e whakahoki kupu atu ki a ia.
Ṣùgbọ́n gbogbo àwọn ènìyàn náà dákẹ́ síbẹ̀ wọn kò sì sọ ohunkóhun, láti fi fèsì, nítorí ọba ti paláṣẹ, “Ẹ má ṣe dá a lóhùn.”
37 Katahi ka haere a Eriakimi tama a Hirikia, te rangatira o te whare, a Hepena te kaituhituhi, a Ioaha tama a Ahapa te kaiwhakamahara ki a Hetekia, he mea haehae o ratou kakahu, a korerotia ana e ratou ki a ia nga kupu a Rapahake.
Nígbà náà Eliakimu ọmọ Hilkiah olùtọ́jú ààfin, Ṣebna akọ̀wé àti Joah ọmọ Asafu akọ̀wé ránṣẹ́ lọ sí ọ̀dọ̀ Hesekiah, pẹ̀lú aṣọ wọn yíya, ó sì wí fún un ohun tí olùdarí pápá ti sọ.

< 2 Kingi 18 >