< 2 Whakapapa 12 >
1 Nawai a, no te unga o te kingitanga o Rehopoama, a ka whai kaha ia, whakarerea ake e ia te ture a Ihowa, e ratou ko Iharaira katoa.
Lẹ́yìn ìgbà tí a fi ìjọba Rehoboamu múlẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọba, tí ó sì ti di alágbára, òun àti gbogbo Israẹli, pẹ̀lú rẹ̀ ni wọ́n pa òfin Olúwa tì.
2 Na i te rima o nga tau o Kingi Rehopoama ka haere mai a Hihaka kingi o Ihipa ki Hiruharama, kua whakakeke nei hoki ratou ki a Ihowa,
Nítorí tí wọn kò ṣọ òtítọ́ sí Olúwa. Ṣiṣaki ọba Ejibiti dojúkọ Jerusalẹmu ní ọdún karùn-ún ti ọba Rehoboamu.
3 Me nga hariata tekau ma rua rau, me nga hoia eke hoiho e ono tekau mano: kahore hoki he tauanga o te hunga i haere tahi mai i a ia i Ihipa; ko nga Rupimi, ko nga Hukiimi, ko nga Etiopiana.
Pẹ̀lú ẹgbàá mẹ́fà kẹ̀kẹ́ àti ọ̀kẹ́ mẹ́ta àwọn ọkùnrin ẹlẹ́ṣin àti àìníye ọ̀wọ́ ogun ti Libia, Sukki àti Kuṣi, tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ láti Ejibiti.
4 Na kua riro i a ia nga pa taiepa o Hura, a ka tae ki Hiruharama.
Ó fi agbára mú àwọn ìlú ààbò ti Juda, pẹ̀lú wá sí Jerusalẹmu bí ó ti jìnnà tó.
5 Katahi a Hemaia poropiti ka haere mai ki a Rehopoama, ki nga rangatira o Hura i huihui nei ki Hiruharama i te wehi i a Hihaka, a ka mea ki a ratou, Ko te kupu tenei a Ihowa, Kua whakarerea ahau e koutou, no reira kua waiho atu koutou e ahau ki te ringa o Hihaka.
Nígbà náà, wòlíì Ṣemaiah wá sí ọ̀dọ̀ Rehoboamu àti sí ọ̀dọ̀ àwọn olórí Juda tí wọ́n ti péjọ ní Jerusalẹmu nítorí ìbẹ̀rù Ṣiṣaki, ó sì wí fún wọn pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa wí: ìwọ ti pa mí tì; nítorí náà èmi náà ti pa yín tì sí ọ̀dọ̀ Ṣiṣaki.”
6 Katahi ka whakaiti nga rangatira o Iharaira me te kingi i a ratou, ka mea, He tika a Ihowa.
Àwọn olórí Israẹli àti ọba rẹ̀ ará wọn sílẹ̀, wọ́n sì wí pé, “Olódodo ni Olúwa.”
7 A, no te kitenga o Ihowa kua whakaiti ratou i a ratou, ka puta te kupu a Ihowa ki a Hemaia; i mea ia, Kua whakaiti ratou i a ratou; e kore ratou e huna e ahau; engari ka hoatu e ahau ki a ratou he oranga, he mea iti nei; e kore hoki toku riri e t ahoroa ki runga ki Hiruharama e te ringa o Hihaka.
Nígbà tí Olúwa rí i pé, wọ́n ti rẹ̀ ara wọn sílẹ̀ ọ̀rọ̀ Olúwa yí tọ Ṣemaiah lọ pé, “Níwọ́n ìgbà tí wọ́n ti rẹ ara wọn sílẹ̀, Èmi kì yóò pa wọ́n ṣùgbọ́n, yóò fún wọn ní ìtúsílẹ̀ tó bá yá. Ìbínú mi kì yóò dà sórí Jerusalẹmu ní ipasẹ̀ Ṣiṣaki.
8 Otiia ka meinga ratou hei pononga mana; kia mohio ai ratou ki taku mahi, ki te mahi ano a nga kingitanga o nga whenua.
Bí ó ti wù kí ó rí, wọn yóò sìn ní abẹ́ rẹ̀, kí wọn kí ó lè mọ̀ ìyàtọ̀ láàrín sí sìn mí àti sí sin àwọn ọba ilẹ̀ mìíràn.”
9 Heoi haere ana mai a Hihaka kingi o Ihipa ki Hiruharama, tangohia ana e ia nga taonga o te whare o Ihowa, me nga taonga o te whare o te kingi: riro katoa ana i a ia: tangohia ana ano e ia nga pukupuku koura i hanga nei e Horomona.
Nígbà tí Ṣiṣaki ọba Ejibiti dojúkọ Jerusalẹmu, ó gbé àwọn ìṣúra ilé Olúwa, àti àwọn ìṣúra ààfin ọba. Ó gbé gbogbo rẹ̀, pẹ̀lú àwọn àpáta wúrà tí Solomoni dá.
10 Na ka hanga e Kingi Rehopoama etahi pukupuku parahi hei whakakapi mo era, a tukua ana e ia ki te ringa o te rangatira o nga kaitiaki, i tiaki nei i te tatau o te whare o te kingi.
Bẹ́ẹ̀ ni, ọba Rehoboamu dá àwọn àpáta idẹ láti fi dípò wọn, ó sì fi èyí lé àwọn alákòóso àti olùṣọ́ tí ó wà ní ẹnu iṣẹ́ ní àbáwọlé ẹnu-ọ̀nà ààfin ọba lọ́wọ́.
11 Na i te wa i haere ai te kingi ki te whare o Ihowa, ka haere nga kaitiaki ki te tiki, a whakahokia ana e ratou ki te whare o nga kaitiaki.
Ìgbàkígbà tí ọba bá lọ sí ilé Olúwa, àwọn olùṣọ́ n lọ pẹ̀lú rẹ̀, wọ́n ń gbé àwọn àpáta náà àti lẹ́yìn, wọ́n dá wọn padà sí yàrá ìṣọ́.
12 Na i a ia ka whakaiti i a ia, ka tahuri atu te riri o Ihowa i a ia, kia kaua ia e whakangaromia rawatia e ia: he pai hoki nga mea i kitea ki a Hura.
Nítorí ti Rehoboamu rẹ ara rẹ̀ sílẹ̀, ìbínú Olúwa yí padà kúrò lórí rẹ̀, a kò sì pa á run pátápátá. Nítòótọ́, ìre díẹ̀ wà ní Juda.
13 Heoi kua u a Kingi Rehopoama ki Hiruharama hei kingi: e wha tekau ma tahi hoki nga tau o Rehopoama i a ia ka meinga hei kingi, a kotahi tekau ma whitu nga tau i kingi ai ia ki Hiruharama, ki te pa i whiriwhiria e Ihowa i roto i nga iwi katoa o I haraira hei waihotanga iho mo tona ingoa. A ko te ingoa o tona whaea ko Naama, he Amoni.
Ọba Rehoboamu fi ara rẹ̀ lélẹ̀ gidigidi ní Jerusalẹmu, ó sì tẹ̀síwájú gẹ́gẹ́ bí ọba. Ó jẹ́ ẹni ọdún mọ́kànlélógójì nígbà tí ó di ọba. Ó sì jẹ ọba fún ọdún mẹ́tàdínlọ́gbọ̀n ní Jerusalẹmu, ìlú ńlá tí Olúwa ti yàn jáde kúrò nínú gbogbo àwọn ẹ̀yà Israẹli ní èyí tí ó fẹ́ fi orúkọ rẹ̀ síbẹ̀. Orúkọ ìyá rẹ̀ ni Naama, ará Ammoni.
14 He kino tana mahi; kihai hoki i whakatikaia e ia tona ngakau ki te rapu i a Ihowa.
O sì ṣe búburú, nítorí tí kò múra nínú ọkàn rẹ̀ láti wá Olúwa.
15 Na, ko nga meatanga a Rehopoama, o mua, o muri, kahore ianei i tuhituhia ki te pukapuka a Hemaia poropiti, ki ta Iro matakite ano, kei reira nei nga korero whakapapa? Na he whawhai ta Rehopoama raua ko Ieropoama ki a raua i nga ra katoa.
Fún tí iṣẹ́ ìjọba Rehoboamu láti ìbẹ̀rẹ̀ dé ìparí, ṣé a kò kọ wọ́n sínú ìwé ìrántí ti Ṣemaiah wòlíì àti ti Iddo, aríran tí ó ní ṣe pẹ̀lú ìtàn ìdílé láti ọ̀dọ̀ àwọn baba ńlá? Ìtẹ̀síwájú ogun jíjà sì wà láàrín Rehoboamu àti Jeroboamu.
16 Na kua moe a Rehopoama ki ona matua, a tanumia iho ki te pa o Rawiri; a ko Apia, ko tana tama, te kingi i muri i a ia.
Rehoboamu sun pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀ a sin ín sínú ìlú ńlá ti Dafidi. Abijah ọmọ rẹ̀ sì rọ́pò rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọba.