< 1 Hamuera 19 >

1 Na ka korero a Haora ki a Honatana, ki tana tama, ratou ko ana tangata katoa, kia whakamatea a Rawiri.
Saulu sọ fún Jonatani ọmọ rẹ̀ àti gbogbo àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pé kí wọ́n pa Dafidi. Ṣùgbọ́n Jonatani fẹ́ràn Dafidi púpọ̀
2 Otiia nui atu te whakaahuareka o Honatana, tama a Haora, ki a Rawiri. Na ka korero a Honatana ki a Rawiri, ka mea, E whai ana toku papa, a Haora kia whakamatea koe: na kia tupato ki a koe i te ata, me noho ki te wahi ngaro, ka huna ai i a koe;
Jonatani sì kìlọ̀ fún Dafidi pé, “Baba mi Saulu wá ọ̀nà láti pa ọ́, kíyèsi ara rẹ di òwúrọ̀ ọ̀la; lọ sí ibi ìkọ̀kọ̀, kí o sì sá pamọ́ sí ibẹ̀.
3 A ka puta atu ahau, ka tu ki te taha o toku papa i te mara kei reira nei koe, na ka korerotia koe e ahau ki toku papa, a ko taku e kite ai ka korerotia e ahau ki a koe.
Èmi yóò jáde lọ láti dúró ní ọ̀dọ̀ baba mi ní orí pápá níbi tí ó wà. Èmi yóò sọ̀rọ̀ fún un nípa à rẹ, èmi yóò sì sọ ohun tí òun bá wí fún ọ.”
4 Na ka korerotia paitia a Rawiri e Honatana ki tona papa, ki a Haora; i mea ia ki a ia, Kei hara te kingi ki tana pononga, ki a Rawiri; kahore hoki ona hara ki a koe, he nui rawa hoki te pai o ana mahi ki a koe.
Jonatani sọ̀rọ̀ rere nípa Dafidi fún Saulu baba rẹ̀, ó sì wí fún un pé, “Má ṣe jẹ́ kí ọba kí ó ṣe ohun tí kò dára fún Dafidi ìránṣẹ́ rẹ̀; nítorí tí kò ṣẹ̀ ọ́, ohun tí ó sì ṣe pé ọ púpọ̀.
5 I whakamomori atu na hoki ia ki te mate, a patua iho te Pirihitini, na he nui te whakaoranga i whakaora ai a Ihowa i a Iharaira katoa: i kite koe, i koa hoki, a he aha ra koe ka hara ai ki nga toto harakore, ka whakamate noa iho ai i a Rawiri?
Ó fi ẹ̀mí rẹ̀ wéwu nígbà tí ó pa Filistini. Olúwa ṣẹ́ ogun ńlá fún gbogbo Israẹli, ìwọ rí i inú rẹ dùn. Ǹjẹ́ nítorí kí ni ìwọ yóò ṣe dẹ́ṣẹ̀ sí Dafidi aláìṣẹ̀, tí ìwọ yóò fi pa á láìnídìí?”
6 Na ka whakarongo a Haora ki te reo o Honatana; a ka oati a Haora, E ora ana a Ihowa, e kore ia e whakamatea.
Saulu fetísí Jonatani, ó sì búra báyìí, “Níwọ́n ìgbà tí Olúwa bá ti ń bẹ láààyè, a kì yóò pa Dafidi.”
7 Na ka karangatia a Rawiri e Honatana, a whakaaturia ana e Honatana enei mea katoa ki a ia. Na kawea ana a Rawiri e Honatana ki a Haora; a noho ana ia ki tona aroaro, pera i mua.
Nítorí náà Jonatani pe Dafidi, ó sì sọ gbogbo àjọsọ wọn fún un. Ó sì mú un wá fún Saulu, Dafidi sì wà lọ́dọ̀ Saulu gẹ́gẹ́ bí i ti tẹ́lẹ̀.
8 Na he whawhai ano tera: a haere ana a Rawiri ki te whawhai ki nga Pirihitini, a patua iho ratou e ia, he nui te parekura, a whati ana ratou i tona aroaro.
Lẹ́ẹ̀kan an sí i ogun tún wá, Dafidi sì jáde lọ, ó sì bá àwọn ara Filistini jà. Ó sì pa wọn pẹ̀lú agbára, wọ́n sì sálọ níwájú u rẹ̀.
9 Na kua puta he wairua kino i a Ihowa ki a Haora, i a ia e noho ana i tona whare, me tana tao i tona ringa; a ko Rawiri i whakatangi i te hapa ki tona ringa.
Ṣùgbọ́n ẹ̀mí búburú láti ọ̀dọ̀ Olúwa wá sí orí Saulu bí ó ti jókòó ní ilé e rẹ̀ pẹ̀lú ọ̀kọ̀ rẹ̀ ní ọwọ́ rẹ̀. Bí Dafidi sì ti fọn ohun èlò orin olókùn,
10 Na ka whai a Haora kia werohia a Rawiri ki te tao, kia titi pu ki te pakitara; otiia i whakahipa ia i te aroaro o Haora, a akina kautia ana e tera te tao ki te pakitara; ko Rawiri ia i rere, i mawhiti i taua po.
Saulu sì wá ọ̀nà láti gún un mọ́ ògiri pẹ̀lú ọ̀kọ̀ rẹ̀, ṣùgbọ́n Dafidi yẹ̀ ẹ́ sílẹ̀ gẹ́gẹ́ bí Saulu ti ju ọ̀kọ̀ náà mọ́ ara ògiri. Ní alẹ́ ọjọ́ náà Dafidi sì fi ara pamọ́ dáradára.
11 Na ka tono karere a Haora ki te whare o Rawiri, ki te whanga ki a ia, kia whakamatea ia i te ata. Na ka korerotia ki a Rawiri, ki te whanga ki a ia, kia whakamatea ia i te ata. Na ka korerotia ki a Rawiri e Mikara, e tana wahine; i mea, Ki te ka hore koe e whakaora i a koe i tenei po, apopo koe whakamatea ai.
Saulu rán ènìyàn sí ilé Dafidi láti ṣọ́ ọ kí wọ́n sì pa á ní òwúrọ̀. Ṣùgbọ́n Mikali, ìyàwó Dafidi kìlọ̀ fún un pé, “Tí o kò bá sá fún ẹ̀mí rẹ ní alẹ́ yìí, ní ọ̀la ni a yóò pa ọ́.”
12 Heoi ka tukua iho a Rawiri e Mikara na te matapihi: a ka haere ia, ka rere, ka ora.
Nígbà náà Mikali sì gbé Dafidi sọ̀kalẹ̀ ó sì fi aṣọ bò ó.
13 Na ka mau a Mikara ki tetahi whakapakoko, a whakatakotoria ana e ia ki te moenga, i whakatakotoria iho ano e ia tetahi urunga huruhuru koati ki to tera urunga, hipokina iho ki te kakahu.
Mikali gbé ère ó sì tẹ́ e lórí ibùsùn, ó sì fi irun ewúrẹ́ sí ibi orí rẹ̀.
14 A, no te tononga a Haora i nga tangata ki te tiki i a Rawiri, ka mea tera, E mate ana ia.
Nígbà ti Saulu rán ènìyàn láti lọ fi agbára mú Dafidi, Mikali wí pé, “Ó rẹ̀ ẹ́.”
15 Na ka tono ano a Haora i nga karere kia kite i a Rawiri, ka mea, Kawea mai ki ahau i runga i te moenga, kia whakamatea ia e ahau.
Nígbà náà ni Saulu rán ọkùnrin náà padà láti lọ wo Dafidi ó sì sọ fún wọn pé, “Mú wa fún mi láti orí ibùsùn rẹ̀ kí èmi kí ó le pa á.”
16 A, i te taenga atu o nga karere, na ko te whakapakoko i te moenga, me te urunga huruhuru koati i te wahi ki tona pane.
Ṣùgbọ́n nígbà tí ọkùnrin náà wọlé, ère ni ó bá lórí ibùsùn àti irun ewúrẹ́ ní orí ère náà.
17 Na ka mea a Haora ki a Mikara, Na te aha koe i tinihanga nei ki ahau, i tuku nei i toku hoariri kia haere, a mawhiti atu ana ia? Ano ra ko Mikara ki a Haora, Nana ra i ki mai ki ahau, Tukua ahau kia haere; kia whakamate ahau i a koe hei aha?
Saulu wí fún Mikali pé, “Èéṣe tí ìwọ fi tàn mí báyìí tí o sì jẹ́ kí ọ̀tá mi sálọ tí ó sì bọ́?” Mikali sọ fún un pé, “Ó wí fún mi, ‘Jẹ́ kí èmi ó lọ. Èéṣe tí èmi yóò fi pa ọ́?’”
18 Heoi ka rere a Tawiri, a mawhiti atu ana; tae tonu atu ki a Hamuera, ki Rama, a korerotia ana ki a ia nga mea katoa i mea ai a Haora ki a ia. Na ka haere raua ko Hamuera, a noho ana raua ki Naioto.
Nígbà tí Dafidi ti sálọ tí ó sì ti bọ́, ó sì lọ sọ́dọ̀ Samuẹli ní Rama ó sì sọ gbogbo ohun tí Saulu ti ṣe fún un. Òun àti Samuẹli lọ sí Naioti láti dúró níbẹ̀.
19 A i korerotia te korero ki a Haora, Ko Rawiri tera kei Naiota o Rama e noho ana.
Ọ̀rọ̀ sì tọ Saulu wá pé, “Dafidi wà ní Naioti ní Rama,”
20 Na ka tono tangata a Haora ki te hopu i a Rawiri: na, i to ratou kitenga i te ropu poropiti e poropiti ana, me Hamuera e tu ana hei tumuaki mo ratou, ka tau iho te wairua o te Atua ki nga tangata a Haora, a poropiti ana hoki ratou.
Saulu sì rán àwọn ènìyàn láti fi agbára mú Dafidi wá ṣùgbọ́n nígbà tí wọ́n rí ọ̀pọ̀ àwọn wòlíì tí ń sọtẹ́lẹ̀, pẹ̀lú Samuẹli dúró níbẹ̀ gẹ́gẹ́ bí olórí, Ẹ̀mí Ọlọ́run sì wá sórí àwọn arákùnrin Saulu àwọn náà sì ń sọtẹ́lẹ̀.
21 A, no ka korerotia ki a Haora, ka tono ia i etahi atu tangata, a ka poropiti ano ratou. Na ko te toru o nga tononga tangata ano a Haora, a poropiti ana ano hoki ratou.
Wọ́n sì sọ fún Saulu nípa rẹ̀, ó sì rán ọ̀pọ̀ àwọn ènìyàn mìíràn lọ àwọn náà sì ń sọtẹ́lẹ̀. Saulu tún rán oníṣẹ́ lọ ní ìgbà kẹta, àwọn náà bẹ̀rẹ̀ sí ní sọtẹ́lẹ̀.
22 Katahi ka haere ko ia hoki ki Rama, a ka tae ki te puna nui i Heku; a ka ui ia, ka mea, Kei hea a Hamuera raua ko Rawiri? ka mea ko tetahi, Nana, kei Naioto o Rama.
Nígbẹ̀yìn, òun fúnra rẹ̀ sì lọ sí Rama ó sì dé ibi àmù ńlá kan ní Seku. Ó sì béèrè, “Níbo ni Samuẹli àti Dafidi wà?” Wọ́n wí pé, “Wọ́n wà ní ìrékọjá ní Naioti ní Rama.”
23 Na ka haere ia ki reira, ki Naioto o Rama; a ka tau iho te wairua o te Atua ki a ia ano hoki; na ka haere ia, me te poropiti haere, a tae noa ki Naioto o Rama.
Saulu sì lọ sí Naioti ni Rama. Ṣùgbọ́n, Ẹ̀mí Ọlọ́run bà lé e lórí ó sì ń lọ lọ́nà, ó sì ń sọtẹ́lẹ̀ títí tí ó fi dé Naioti.
24 A i huia hoki e ia ona kakahu, a poropiti ana ano ia i te aroaro o Hamuera; a takoto tahanga ana ia i taua ra katoa, me taua po katoa. Na reira ta ratou kupu, Kei roto ano koia a Haora i nga poropiti?
Ó sì bọ́ aṣọ rẹ̀, òun pẹ̀lú sì ń sọtẹ́lẹ̀ níwájú Samuẹli. Ó sì dùbúlẹ̀ bẹ́ẹ̀ ní gbogbo ọjọ́ náà àti ní òru. Ìdí nìyìí tí àwọn ènìyàn fi wí pé, “Ṣé Saulu náà wà lára àwọn wòlíì ni?”

< 1 Hamuera 19 >