< 1 Hamuera 18 >

1 A ka mutu tana korero ki a Haora, na piri tonu te wairua o Honatana ki te wairua o Rawiri, a aroha ana a Honatana ki a ia me te mea ko tona wairua ake.
Lẹ́yìn ìgbà tí Dafidi ti parí ọ̀rọ̀ tí ó ń bá Saulu sọ, ọkàn Jonatani di ọ̀kan pẹ̀lú ti Dafidi, ó sì fẹ́ràn rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ara rẹ̀.
2 Na ka mau a Haora ki a ia i taua ra, kihai hoki ia i tukua kia hoki ki te whare o tona papa.
Láti ọjọ́ náà Saulu pa Dafidi mọ́ sí ọ̀dọ̀ rẹ̀ kò sì jẹ́ kí ó padà sí ilé baba rẹ̀ mọ́.
3 I whakarite kawenata ano a Honatana raua ko Rawiri; i arohaina hoki ia e ia, me te mea ko tona wairua ake.
Jonatani bá Dafidi dá májẹ̀mú nítorí tí ó fẹ́ràn rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ara rẹ̀.
4 I huia ano e Honatana tona koroka i runga i a ia, a hoatu ana ki a Rawiri, me ona kakahu, tae noa ki tana hoari, me tana kopere, me tona whitiki.
Jonatani sì bọ́ aṣọ ìgúnwà, ó sì fi fun Dafidi pẹ̀lú aṣọ àwọ̀tẹ́lẹ̀ rẹ̀ àti pẹ̀lú idà rẹ̀, ọrun rẹ̀ àti àmùrè rẹ̀.
5 Na ka haere a Rawiri ki nga wahi katoa i tonoa ai ia e Haora, ka mahi tupato; a ka meinga ia e Haora hei rangatira mo nga tangata whawhai, a pai tonu ia ki te titiro a te iwi katoa, ki te titiro ano hoki a nga tangata a Haora.
Ohunkóhun tí Saulu bá rán an láti ṣe, Dafidi máa ṣe ní àṣeyọrí, Saulu náà sì fun un ní ipò tí ó ga jù láàrín àwọn ológun. Eléyìí sì tẹ́ gbogbo ènìyàn lọ́rùn, àti pẹ̀lú ó sì tẹ́ àwọn ìjòyè Saulu lọ́rùn pẹ̀lú.
6 Na i to ratou haerenga mai, i te hokinga mai o Rawiri i te patu i te Pirihitini, ka puta nga wahine i nga pa katoa o Iharaira, me te waiata, me te kanikani, me nga timipera, me te koa, me nga mea whakatangi, ki te whakatau i a Kingi Haora.
Nígbà tí àwọn ènìyàn padà sí ilé lẹ́yìn ìgbà tí Dafidi ti pa Filistini, gbogbo àwọn obìnrin tú jáde láti inú ìlú Israẹli wá láti pàdé ọba Saulu pẹ̀lú orin àti ijó, pẹ̀lú orin ayọ̀ àti tambori àti ohun èlò orin olókùn.
7 Na ka waiata whakatene nga wahine i a ratou e takaro ana, ka mea, Na Haora ana mano, na Rawiri ana tekau mano i patu.
Bí wọ́n ṣe ń jó, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n ń kọrin pé, “Saulu pa ẹgbẹ̀rún tirẹ̀ Dafidi sì pa ẹgbẹẹgbàárún ní tirẹ̀.”
8 Na nui rawa te riri o Haora; he mea kino hoki taua kupu ki tona whakaaro. Na ka mea ia, Tekau a ratou mano i hoatu ai ki a Rawiri, he mano kau nei a ratou i homai nei ki ahau: ko te aha ake mana ki te kahore te kingitanga?
Saulu sì bínú gidigidi, ọ̀rọ̀ náà sì korò létí rẹ̀ pé, “Wọ́n ti gbé ògo fún Dafidi pẹ̀lú ẹgbẹẹgbàárún,” ó sì wí pé, “ṣùgbọ́n èmi pẹ̀lú ẹgbẹ̀rún kan. Kí ni ó kù kí ó gbà bí kò ṣe ìjọba?”
9 Na whakatau ana te kanohi o Haora ki a Rawiri no taua ra tonu iho.
Láti ìgbà náà lọ ni Saulu ti bẹ̀rẹ̀ sí ní fi ojú ìlara wo Dafidi.
10 Na i te aonga ake ka puta kaha mai he wairua kino i te Atua ki a Haora, a ka poropiti ia i waenganui o te whare; a ka whakatangi te ringa o Rawiri i te hapa, ko tana hanga i tena ra, i tena ra: he tao ano i te ringa o Haora:
Ní ọjọ́ kejì ẹ̀mí búburú láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run wá pẹ̀lú agbára sórí Saulu, ó sì sọ àsọtẹ́lẹ̀ ní ilé rẹ̀ nígbà tí Dafidi sì ń fọn ohun èlò orin olókùn, gẹ́gẹ́ bí ó ti máa ń ṣe láti ẹ̀yìn wá, Saulu sì ní ọ̀kọ̀ kan ní ọwọ́ rẹ̀.
11 Ko te tino werohanga a Haora i te tao; i mea hoki ia, Me patu a Rawiri e ahau, kia titi rawa ki te pakitara. Na karohia ana e Rawiri: e rua nga mawhititanga i tona aroaro.
Ó sì gbé e sókè, ó sì wí fún ara rẹ̀ pé, “Èmi yóò gún Dafidi pọ̀ mọ́ ògiri.” Ṣùgbọ́n, Dafidi yẹ̀ fún un lẹ́ẹ̀méjì.
12 Na ka wehi a Haora i a Rawiri, no te mea i a ia a Ihowa, a kua mawehe i a Haora.
Saulu sì ń bẹ̀rù Dafidi nítorí pé Olúwa wà pẹ̀lú Dafidi, ṣùgbọ́n ó ti fi Saulu sílẹ̀.
13 Koia i wehea atu ai ia e Haora i a ia, a meinga ana ia e ia ko tana rangatira mano: na ka haere atu ia, ka haere mai i te aroaro o te iwi.
Ó sì lé Dafidi jáde ní ọ̀dọ̀ rẹ̀, ó sì fi jẹ olórí ogun ẹgbẹ̀rún kan, Dafidi ń kó wọn lọ, ó ń kó wọn bọ̀ nínú ìgbòkègbodò ogun.
14 Na tupato tonu te whakahaere a Rawiri i ona ara katoa: i a ia ano a Ihowa.
Dafidi sì ṣe ọlọ́gbọ́n ní gbogbo ìṣe rẹ̀, nítorí tí Olúwa wà pẹ̀lú rẹ̀.
15 A, i te kitenga o Haora he tangata tupato rawa ia, ka wehi ia i a ia.
Nígbà tí Saulu rí bi àṣeyọrí rẹ̀ ti tó, ó sì bẹ̀rù rẹ̀.
16 A i aroha a Iharaira katoa ratou ko Hura ki a Rawiri, no te mea i haere atu ia, i haere mai i to ratou aroaro.
Ṣùgbọ́n gbogbo Israẹli àti Juda ni wọ́n fẹ́ràn Dafidi, nítorí ó darí wọn lọ ní ìgbòkègbodò ogun wọn.
17 Na ka mea a Haora ki a Rawiri, Nana, taku tamahine matamua, a Merapa, me hoatu e ahau hei wahine mau, otiia ko koe hei toa maku, hei whawhai i nga whawhai a Ihowa. I mea hoki a Haora, Kaua toku ringa e pa ki a ia; engari kia pa te ringa o nga Pi rihitini ki a ia.
Saulu wí fún Dafidi pé, “Èyí ni àgbà nínú àwọn ọmọbìnrin mi Merabu. Èmi yóò fi òun fún ọ ní aya. Kí ìwọ sìn mí bí akọni, kí o sì máa ja ogun Olúwa.” Nítorí tí Saulu wí fún ara rẹ̀ pé, “Èmi kì yóò gbé ọwọ́ mi sókè sí i. Jẹ́ kí àwọn Filistini ṣe èyí.”
18 Na ka mea a Rawiri ki a Haora, Ko wai ahau, he oranga aha hoki toku, he hapu aha to toku papa i roto i a Iharaira, e meinga ai ahau hei hunaonga me te kingi?
Ṣùgbọ́n Dafidi wí fún Saulu pé, “Ta ni mí, kí sì ni ìdílé mi tàbí ìdílé baba mi ní Israẹli, tí èmi yóò di àna ọba?”
19 I te wa ia e homai ai a Merapa, te tamahine a Haora ma Rawiri, na ka hoatu ia hei wahine ma Atariere o Mehora.
Nígbà tí àkókò tó fún Merabu, ọmọbìnrin Saulu, láti fi fún Dafidi, ni a sì fi fún Adrieli ará Mehola ní aya.
20 Na i aroha a Mikara, te tamahine a Haora ki a Rawiri, a ka korerotia ki a Haora, a he mea ahuareka tena ki tona whakaaro.
Nísinsin yìí ọmọbìnrin Saulu Mikali sì fẹ́ràn Dafidi, nígbà tí wọ́n sọ fún Saulu nípa rẹ̀, ó sì dùn mọ́ ọn.
21 Na ka mea a Haora, Me hoatu ia e ahau ki a ia a hei rore ia mona e pa ai te ringa o nga Pirihitini ki a ia. Koia a Haora i mea ai ki a Rawiri, Ko aianei te rua o ou meatanga hei hunaonga maku.
Ó sọ nínú ara rẹ̀ pé, “Èmi yóò fi fún un kí òun ba à le jẹ́ ìkẹ́kùn fún un, kí ọwọ́ àwọn ará Filistini lè wà lára rẹ̀.” Nígbà náà ni Saulu wí fún Dafidi pé, “Nísinsin yìí ìwọ ní àǹfààní eléyìí láti jẹ́ àna án mi.”
22 Na ka whakahau a Haora ki ana tangata, Korero puku ki a Rawiri, mea atu, Nana, e whakaahuareka ana te kingi ki a koe, e aroha ana hoki ana tangata katoa ki a koe: na reira ko koe hei hunaonga ma te kingi.
Saulu pàṣẹ fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, “Ẹ sọ fún Dafidi ní ìkọ̀kọ̀, kí ẹ sì wí pé, ‘Wò ó, inú ọba dùn sí ọ, gbogbo àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ ni ó fẹ́ràn rẹ, nísinsin yìí jẹ́ àna ọba.’”
23 Na korerotia ana aua kupu e nga tangata a Haora ki nga taringa o Rawiri. A ka mea a Rawiri, He mea noa iho koia ki a koutou kia meinga ahau hei hunaonga ma te kingi, he rawakore nei hoki ahau, he ware?
Wọ́n tún ọ̀rọ̀ náà sọ fún Dafidi. Ṣùgbọ́n Dafidi wí pé, “Ṣé ẹ rò pé ohun kékeré ni láti jẹ́ àna ọba? Mo jẹ́ tálákà ènìyàn àti onímọ̀ kékeré.”
24 Na ka korero nga tangata a Haora ki a ia, ka mea, ko nga kupu enei i puaki mai i a Rawiri.
Nígbà tí àwọn ìránṣẹ́ Saulu sọ fún un ohun tí Dafidi sọ,
25 Na ka mea a Haora, Kia penei ta koutou ki ki a Rawiri, Kahore o te kingi hiahia ki te kaipakuha; engari ki nga kiri matamata kotahi rau o nga Pirihitini: kia whai utu ai i nga hoariri o te kingi. I whakaaro hoki a Haora kia hinga a Rawiri i te r inga o nga Pirihitini.
Saulu dáhùn pé, “Sọ fún Dafidi pé, ‘Ọba kò fẹ́ owó orí láti ọ̀dọ̀ àna rẹ̀ ju awọ iwájú orí ọgọ́rùn-ún Filistini lọ láti fi gba ẹ̀san lórí àwọn ọ̀tá rẹ̀.’” Èrò Saulu ni wí pé kí Dafidi ṣubú sí ọwọ́ àwọn ará Filistini.
26 A, no ka korerotia e ana tangata enei kupu ki a Rawiri, ahuareka tonu ki a Rawiri kia meinga ia hei hunaonga ma te kingi. A kahore ano nga ra kia rite.
Nígbà tí àwọn ìránṣẹ́ sọ àwọn nǹkan yìí fún Dafidi, inú rẹ̀ dùn láti di àna ọba kí àkókò tí ó dá tó kọjá,
27 Na ka whakatika a Rawiri, a haere ana ratou ko ana tangata, na patua iho e ia o nga Pirihitini e rua rau nga tangata; a kawea ana e Rawiri o ratou kiri matamata; na hoatu ana e ratou ki te kingi te mea e rite ana, kia meinga ai ia hei hunaonga m a te kingi. Na ka homai e Haora a Mikara, tana tamahine hei wahine mana.
Dafidi àti àwọn arákùnrin rẹ̀ jáde lọ wọ́n sì pa igba lára àwọn Filistini. Ó kó awọ iwájú orí wọn wá, ó sì pé iye tí ọba fẹ́ kí ó ba à lè jẹ́ àna ọba. Saulu sì fi ọmọ obìnrin Mikali fún un ní aya.
28 A i kite a Haora, i mohio, kei a Rawiri a Ihowa; a i arohaina ia e Mikara tamahine a Haora.
Nígbà tí Saulu sì wá mọ̀ pé Olúwa wà pẹ̀lú Dafidi tí ọmọbìnrin rẹ̀ Mikali sì fẹ́ràn Dafidi,
29 Na ka nui rawa atu te wehi o Haora i a Rawiri; a he ito a Rawiri ki a Haora i nga ra katoa.
Saulu sì tún wá bẹ̀rù Dafidi síwájú àti síwájú, Saulu sì wá di ọ̀tá Dafidi fún gbogbo ọjọ́ rẹ̀ tókù.
30 Katahi ka whakaputa nga rangatira o nga Pirihitini, a i nga wa katoa i whakaputa ai ratou, nui atu te tika o te ngarahu a Rawiri i ta nga tangata katoa a Haora; koia i tino matea nuitia ai tona ingoa.
Àwọn ọmọ-aládé Filistini tún tẹ̀síwájú láti lọ sí ogun, ó sì ṣe lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n lọ, Dafidi ṣe àṣeyọrí ju gbogbo àwọn ìránṣẹ́ Saulu lọ, orúkọ rẹ̀ sì gbilẹ̀.

< 1 Hamuera 18 >