< 1 Hamuera 12 >

1 Na ka mea a Hamuera ki a Iharaira katoa, Nana, kua rongo nei ahau ki to koutou reo, ki nga mea katoa i kiia mai ki ahau, kua whakakingi hoki i tetahi kingi mo koutou.
Samuẹli sì wí fún gbogbo Israẹli pé, “Èmi tí gbọ́ gbogbo ohun tí ẹ sọ fún mi, èmi sì ti yan ọba fún un yín.
2 Ina, te kingi na, e haereere na i to koutou aroaro: ko ahau hoki, kua koroheketia ahau, kua hina; a ko aku tama kei a koutou ena: no toku tamarikitanga hoki toku haereere i to koutou aroaro a tae noa mai ki tenei ra.
Nísinsin yìí ẹ ti ní ọba bí olórí yín. Bí ó ṣe tèmi, èmi ti di arúgbó, mo sì ti hewú, àwọn ọmọ mi sì ń bẹ níhìn-ín yìí pẹ̀lú yín. Èmi ti ń ṣe olórí yín láti ìgbà èwe mi wá títí di òní yìí.
3 Tenei ahau: whakaaturia mai toku he i te aroaro o Ihowa, i te aroaro ano hoki o tana tangata i whakawahi ai: i tango ranei ahau i te kau a tetahi? i tango ranei ahau i te kaihe a tetahi? i riro mai ranei i ahau nga taonga o tetahi? i tukinotia ra nei e ahau tetahi? i tango ranei ahau i te utu whakapati a tetahi hei mea kia huna oku kanohi? a ka whakahokia e ahau ki a koutou.
Èmi dúró níhìn-ín yìí, ẹ jẹ́rìí sí mi níwájú Olúwa àti níwájú ẹni àmì òróró rẹ̀. Màlúù ta ni mo gbà rí? Kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ta ni mo gbà rí? Ta ni mo rẹ́ jẹ rí? Ọwọ́ ta ni mo ti gba owó àbẹ̀tẹ́lẹ̀ kan rí láti fi bo ara mi lójú? Bí mo bá ti ṣe nǹkan kan nínú ohun wọ̀nyí, èmi yóò sì san án padà fún yín.”
4 Ano ra ko ratou, Kihai tetahi mea a matou i riro he i a koe, kihai hoki koe i tukino i a matou, kihai ano hoki i tangohia e koe tetahi mea a te tangata.
Wọ́n sì dáhùn wí pé, “Ìwọ kò rẹ́ wa jẹ tàbí pọ́n wa lójú rí, ìwọ kò sì gba ohunkóhun lọ́wọ́ ẹnìkankan.”
5 Na ka mea ia ki a ratou, Ko Ihowa hei kaiwhakaatu mo ta koutou; hei kaiwhakaatu ano hoki inaianei tana tangata i whakawahi ai, kihai i mau i a koutou tetahi mea a toku ringa. A ka mea ratou, Hei kaiwhakaatu ano ia.
Samuẹli sì wí fún wọn pé, “Olúwa ni ẹlẹ́rìí sí i yín, àti ẹni àmì òróró rẹ̀ ni ẹlẹ́rìí lónìí pé, ẹ̀yin kò rí ohunkóhun lọ́wọ́ mi.” Wọ́n sì sọ wí pé, “Òun ni ẹlẹ́rìí.”
6 Na ka mea a Hamuera ki te iwi, Na Ihowa i whakatu a Mohi raua ko Arona, nana hoki o koutou matua i kawe mai i te whenua o Ihipa.
Nígbà náà ni Samuẹli wí fún àwọn ènìyàn náà pé, “Olúwa ni ó yan Mose àti Aaroni àti ti ó mú àwọn baba ńlá yín gòkè wá láti Ejibiti.
7 Na, tu tonu koutou, a ka whakahaerea e ahau ki a koutou ki te aroaro o Ihowa nga mahi tika katoa a Ihowa i mahia e ia ki a koutou, ki o koutou matua hoki.
Nísinsin yìí, ẹ dúró níbi, nítorí èmi ń lọ láti bá a yín sọ̀rọ̀ níwájú Olúwa ní ti gbogbo ìṣe òdodo rẹ̀ tí ó ti ṣe fún un yín àti fún àwọn baba yín.
8 I te haerenga atu o Hakopa ki Ihipa, a ka tangi o koutou matua ki a Ihowa, na ka tonoa e Ihowa a Mohi raua ko Arona hei whakaputa mai i o koutou matua i Ihipa, hei whakanoho hoki i a ratou ki tenei wahi.
“Lẹ́yìn ìgbà tí Jakọbu wọ Ejibiti, wọ́n ké pe Olúwa fún ìrànlọ́wọ́, Olúwa sì rán Mose àti Aaroni, tí wọ́n mú àwọn baba ńlá yín jáde láti Ejibiti láti mú wọn jókòó níbí yìí.
9 A ka wareware ratou ki a Ihowa, ki to ratou Atua, na hokona ana ratou e ia ki te ringa o Hihera, rangatira o te ope a Hatoro, ki te ringa hoki o nga Pirihitini, ki te ringa hoki o te kingi o Moapa, a whawhai ana ratou ki a ratou.
“Ṣùgbọ́n wọ́n gbàgbé Olúwa Ọlọ́run wọn; bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì tà wọ́n sí ọwọ́ àwọn Sisera, olórí ogun Hasori, àti sí ọwọ́ àwọn Filistini àti sí ọwọ́ ọba Moabu, tí ó bá wọn jà.
10 A ka tangi atu ratou ki a Ihowa, ka mea, Kua hara matou, i a matou i whakarere nei i a Ihowa, i mahi ki nga Paara, ki a Ahataroto; otiia whakaorangia matou i te ringa o o matou hoariri, a ka mahi matou ki a koe.
Wọ́n kégbe pe Olúwa, wọ́n sì wí pé, ‘Àwa ti ṣẹ̀; a ti kọ Olúwa sílẹ̀, a sì ti sin Baali, àti Aṣtoreti. Ṣùgbọ́n nísinsin yìí gbà wá lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá wa, àwa yóò sì sìn ọ́.’
11 Na ka unga mai e Ihowa a Ierupaara, a Perana, a Iepeta, a Hamuera, a whakaorangia ana koutou i roto i nga ringa o o koutou hoariri i tetahi taha, i tetahi taha, a noho wehikore noa iho ana koutou.
Nígbà náà ni Olúwa rán Jerubbaali, Bedani, Jefta àti Samuẹli, ó sì gbà yín lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá a yín gbogbo, bẹ́ẹ̀ ni ẹ̀yin ń gbé ní àlàáfíà.
12 A, no to koutou kitenga e haere mai ana a Nahaha kingi o nga tama a Amona ki a koutou, ka mea koutou ki ahau, Kahore, engari me whai kingi ano matou; i te mea ko Ihowa, ko to koutou Atua to koutou kingi.
“Ṣùgbọ́n nígbà tí ẹ̀yin sì rí i pé Nahaṣi ọba àwọn Ammoni dìde sí i yín, ẹ sọ fún mi pé, ‘Rárá, àwa ń fẹ́ ọba tí yóò jẹ́ lórí wa,’ bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé Olúwa Ọlọ́run yín jẹ́ ọba yín.
13 Ina ra te kingi i whiriwhiria nei e koutou, i tonoa nei e koutou! Nana, kua hoatu e Ihowa he kingi mo koutou.
Nísinsin yìí èyí ni ọba tí ẹ̀yin ti yàn, tí ẹ̀yin béèrè fún; wò ó, Olúwa ti fi ọba jẹ lórí yín.
14 Ki te wehi koutou i a Ihowa, ki te mahi ki a ia, ki te whakarongo ki tona reo, ki te kore hoki e tutu ki te kupu a Ihowa, katahi koutou ko te kingi e kingi ana i a koutou ka whai tonu i a Ihowa, i to koutou Atua.
Bí ẹ̀yin bá bẹ̀rù Olúwa àti bí ẹ̀yin bá ń sìn ín, tí ẹ sì gbọ́ tirẹ̀, tí ẹ̀yin kò sì ṣọ̀tẹ̀ sí àṣẹ rẹ̀, àti tí ẹ̀yin àti ọba tí ó jẹ lórí yín bá ń tẹ̀lé Olúwa Ọlọ́run yín: ó dára
15 Engari ki te kore koutou e rongo ki te reo o Ihowa, a ka tutu ano ki te kupu a Ihowa, katahi ka anga mai ki a koutou te ringa o Ihowa, ka rite ki tana ki o koutou matua.
ṣùgbọ́n bí ẹ̀yin kò bá gbọ́ tí Olúwa, tí ẹ sì ṣọ̀tẹ̀ sí àṣẹ rẹ̀, ọwọ́ rẹ̀ yóò wà lára yín sí ibi, bí ó ti wà lára baba yín.
16 Tena, tu tonu koutou, kia kite koutou i tenei mea nui ka meatia nei e Ihowa ki to koutou aroaro.
“Nítorí náà, ẹ dúró jẹ́ẹ́ kí ẹ sì wo ohun ńlá yìí tí Olúwa fẹ́ ṣe ní ojú u yín!
17 Ehara ianei tenei i te kotinga witi inaianei? Ka karanga ahau ki a Ihowa, a ka homai he whatitiri, he ua, kia mohio ai koutou, kia kite ai, he nui to koutou he i meatia nei e koutou i te aroaro o Ihowa i a koutou i tono kingi nei mo koutou.
Òní kì í ha á ṣe ọjọ́ ìkórè ọkà alikama bí? Èmi yóò ké pe Olúwa kí ó rán àrá àti òjò. Ẹ̀yin yóò sì mọ irú ohun búburú tí ẹ ti ṣe níwájú Olúwa nígbà tí ẹ̀ ń béèrè fún ọba.”
18 Na ka karanga a Hamuera ki a Ihowa, a homai ana e Ihowa he whatitiri, he ua, i taua rangi ano. Na nui noa atu te wehi o te iwi katoa ki a Ihowa, ki a Hamuera.
Nígbà náà ni Samuẹli ké pe Olúwa, Olúwa sì rán àrá àti òjò ní ọjọ́ náà. Bẹ́ẹ̀ ni gbogbo ènìyàn sì bẹ̀rù Olúwa àti Samuẹli púpọ̀.
19 Na ka mea te iwi katoa ki a Hamuera, Inoi atu mo au pononga ki a Ihowa, ki tou Atua, kei mate matou; kua tapiritia hoki o matou hara katoa ki tenei kino, ki ta matou tono i te kingi mo matou.
Gbogbo àwọn ènìyàn sì wí fún Samuẹli pé, “Gbàdúrà sí Olúwa Ọlọ́run rẹ fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ kí a má ba à kú, nítorí tí àwa ti fi búburú yìí kún ẹ̀ṣẹ̀ wa ní bíbéèrè fún ọba.”
20 Ano ra ko Hamuera ki te iwi, Kaua e wehi: kua oti tenei kino katoa te mea e koutou, kaua ia e peka atu i te whai a Ihowa; engari me whakapau o koutou ngakau ki te mahi ki a Ihowa.
Samuẹli sì dá wọn lóhùn pé, “Ẹ má bẹ̀rù, ẹ ti ṣe gbogbo búburú yìí; síbẹ̀ ẹ má ṣe yípadà kúrò lọ́dọ̀ Olúwa, ṣùgbọ́n ẹ fi gbogbo àyà yín sin Olúwa.
21 Kaua ano hoki e peka atu: ko reira hoki koutou whai ai i nga mea tekateka noa, e kore e mana, e kore ano hoki e whakaora; he mea tekateka noa hoki.
Ẹ má ṣe yípadà sọ́dọ̀ àwọn òrìṣà. Wọn kò le ṣe ohun rere kan fún un yín, tàbí kí wọ́n gbà yín là, nítorí asán ni wọ́n.
22 E kore hoki a Ihowa e whakarere i tana iwi, ka mahara ia ki tona ingoa nui; kua pai nei hoki a Ihowa ki te mea i a koutou hei iwi mana.
Nítorí orúkọ ńlá rẹ̀ Olúwa kì yóò kọ àwọn ènìyàn rẹ̀ sílẹ̀, nítorí tí inú Olúwa dùn láti fi yín ṣe ènìyàn rẹ̀.
23 Ko ahau hoki! E! kia hara ahau ki a Ihowa! kia mutu taku inoi mo koutou! Tena ko tenei, me whakaako koutou e ahau ki te ara pai, ki te ara tika.
Bí ó ṣe ti èmi ni, kí á má rí i pé èmi dẹ́ṣẹ̀ sí Olúwa nípa dídẹ́kun àti gbàdúrà fún un yín. Èmi yóò sì kọ́ ọ yín ní ọ̀nà rere àti ọ̀nà òtítọ́.
24 Engari kia wehi i a Ihowa; whakapaua hoki o koutou ngakau ki te mahi ki a ia i runga i te pono; whakaaroa hoki nga mea nunui i mea ai ia ki a koutou.
Ṣùgbọ́n ẹ rí i dájú pé, ẹ bẹ̀rù Olúwa, kí ẹ sì sìn ín nínú òtítọ́ pẹ̀lú gbogbo ọkàn an yín, ẹ kíyèsi ohun ńlá tí ó ti ṣe fún un yín.
25 Na, ki te mahi tonu koutou i te he, ka ngaro ngatahi koutou ko to koutou kingi.
Síbẹ̀ bí ẹ̀yin bá ń ṣe búburú, ẹ̀yin àti ọba yín ni a ó gbá kúrò.”

< 1 Hamuera 12 >