< 1 Hamuera 1 >

1 Na tera tetahi tangata no Ramataima Topimi, no te whenua pukepuke o Eparaima, ko Erekana tona ingoa, he Eparati, he tama na Iorohama, tama a Erihu, tama a Tohu, tama a Tupu:
Ọkùnrin kan wà, láti Ramataimu-Sofimu, láti ìlú olókè Efraimu, ẹni tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Elkana, ọmọ Jerohamu, ọmọ Elihu, ọmọ Tohu, ọmọ Sufu, ará Efrata.
2 A tokorua ana wahine; ko Hana te ingoa o tetahi, ko Penina te ingoa o tetahi: na he tamariki a Penina, kahore ia he tamariki a Hana.
Ó sì ní ìyàwó méjì, orúkọ wọn ni Hana àti Penina: Penina ní ọmọ, ṣùgbọ́n Hana kò ní.
3 A haere atu ai tenei tangata i ia tau, i ia tau, i tona pa ki te koropiko, ki te patu whakahere ki a Ihowa o nga mano, ki Hiro. A i reira nga tama tokorua a Eri, a Hoponi raua ko Pinehaha, nga tohunga a Ihowa.
Ní ọdọọdún, ọkùnrin yìí máa ń gòkè láti ìlú rẹ̀ láti lọ sìn àti láti ṣe ìrúbọ sí Olúwa àwọn ọmọ-ogun jùlọ ní Ṣilo, níbi tí àwọn ọmọkùnrin Eli méjèèjì, Hofini àti Finehasi ti jẹ́ àlùfáà Olúwa.
4 A, ka tae ki te ra i patu whakahere ai a Erekana, na, hoatu ana e ia etahi mea ki a Penina, ki tana wahine, ki ana tama katoa ano, ratou ko ana tamahine:
Nígbàkígbà tí ó bá kan Elkana láti ṣe ìrúbọ, òun yóò bù lára ẹran fún aya rẹ̀ Penina àti fún gbogbo àwọn ọmọ ọkùnrin àti obìnrin.
5 Ki tana wahine ia, ki a Hana, e rua nga wahi i hoatu e ia; i aroha hoki ia ki a Hana; otiia kua oti tona kopu te tutaki e Ihowa.
Ṣùgbọ́n ó máa ń pín ìlọ́po fun Hana nítorí pé ó fẹ́ràn rẹ̀ àti pé Olúwa ti sé e nínú.
6 A nui atu te whakatoia a tona hoa tauwhainga ki a ia, a mamae noa ia, no te mea kua tutakina tona kopu e Ihowa.
Nítorí pé Olúwa ti sé e nínú, orogún rẹ̀ bẹ̀rẹ̀ sí ní fín níràn láti lè mú kí ó bínú.
7 Pena tonu ta te tane mahi, i ia tau, i ia tau, i nga haerenga o tenei ki runga, ki te whare o Ihowa, a pena tonu ta tera whakatoi i tenei; a tangi noa ia, kihai hoki i kai.
Eléyìí sì máa ń ṣẹlẹ̀ ní ọdọọdún. Nígbàkígbà tí Hana bá gòkè lọ sí ilé Olúwa, orogún rẹ̀ a máa fín níràn títí tí yóò fi máa sọkún tí kò sì ní lè jẹun.
8 Na ka mea tana tahu, e Erekana ki a ia, E Hana, he aha koe i tangi ai? he aha hoki koe te kai ia? he aha ano i pouri ai tou ngakau? ki tau e kore ianei e nui atu toku pai i to nga tama kotahi tekau?
Elkana ọkọ rẹ̀ yóò sọ fún un pé, “Hana èéṣe tí ìwọ fi ń sọkún? Èéṣe tí ìwọ kò fi jẹun? Èéṣe tí ìwọ fi ń ba ọkàn jẹ́? Èmi kò ha ju ọmọ mẹ́wàá lọ fún ọ bí?”
9 Heoi ka whakatika a Hana i muri i a ratou i kai ai i Hiro, i inu ai hoki. Na ko Eri, ko te tohunga, i runga i tona nohoanga noho ai, i te pou o te kuwaha o te temepara o Ihowa.
Lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n ti jẹ, tí wọ́n tún mu tán ní Ṣilo, Hana dìde wá síwájú Olúwa. Nígbà náà, Eli àlùfáà wà lórí àga ní ẹ̀gbẹ́ ẹnu-ọ̀nà ilé Olúwa ní ibi tí ó máa ń jókòó.
10 A i tino pouri te ngakau o tera, ka inoi ki a Ihowa, a nui atu tana tangi.
Pẹ̀lú ẹ̀dùn ọkàn Hana sọkún gidigidi, ó sì gbàdúrà sí Olúwa.
11 Na ka puaki tana ki taurangi, i mea ia, E Ihowa o nga mano, ki te ata titiro mai koe ki te pouri o tau pononga wahine, a ka mahara ki ahau, a e kore e wareware ki tau pononga, engari ka homai i tetahi tama ki tau pononga, na, ka hoatu ia e ahau ki a Ihowa i nga ra katoa e ora ai ia; e kore ano he heu e heua ki tona matenga.
Ó sì jẹ́ ẹ̀jẹ́ wí pé, “Olúwa àwọn ọmọ-ogun, jùlọ tí ìwọ bá le bojú wo ìránṣẹ́bìnrin rẹ kí ìwọ sì rántí rẹ̀, tí ìwọ kò sì gbàgbé ìránṣẹ́ rẹ ṣùgbọ́n tí ìwọ yóò fún un ní ọmọkùnrin, nígbà náà èmi yóò sì fi fún Olúwa ní gbogbo ọjọ́ ayé rẹ̀ a kì yóò sì fi abẹ kàn án ní orí.”
12 Na, i te mea e inoi tonu ana ia i te aroaro o Ihowa, ka titiro a Eri ki tona waha.
Bí ó sì ṣe ń gbàdúrà sí Olúwa, Eli sì kíyèsi ẹnu rẹ̀.
13 Na ko Hana, e korero ana ia i roto i tona ngakau; ko ona ngutu kau e komeme ana, kihai ia tona reo i rangona: na reira i mea ai a Eri e haurangi ana ia.
Hana ń gbàdúrà láti inú ọkàn rẹ̀, ṣùgbọ́n ètè rẹ̀ ni ó ń mì, a kò gbọ́ ohùn rẹ̀. Eli rò wí pé ó ti mu ọtí yó.
14 Na ka mea a Eri ki a ia, Ka tae te roa o tou haurangi! Whakarerea atu tau waina.
Eli sì wí fún un pé, “Yóò ti pẹ́ fún ọ tó tí ìwọ yóò máa yó? Mú ọtí wáìnì rẹ̀ kúrò.”
15 Na ka utua e Hana, ka mea, Kahore, e toku ariki; he wahine ngakau pouri ahau: kahore ahau i inu i te waina, i te wai whakahaurangi ranei; engari e ringihia ana e ahau toku ngakau ki te aroaro o Ihowa.
Hana dá a lóhùn pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́, Olúwa mi, èmi ni obìnrin oníròbìnújẹ́. Èmi kò mu ọtí wáìnì tàbí ọtí líle; èmi ń tú ọkàn mi jáde sí Olúwa ni.
16 Kaua tau pononga e kiia he tamahine na Periara: na te nui hoki o toku mamae, o toku pouri, enei korero aku.
Má ṣe mú ìránṣẹ́ rẹ gẹ́gẹ́ bí obìnrin búburú. Èmi ti ń gbàdúrà níhìn-ín nínú ìrora ọkàn àti ìbànújẹ́ mi.”
17 Katahi ka utua e Eri, ka mea ia, Haere marie: a ma te Atua o Iharaira e homai tau mea i inoi ai koe ki a ia.
Eli dáhùn pé, “Máa lọ ní àlàáfíà, kí Ọlọ́run Israẹli fi ohun tí ìwọ ti béèrè ní ọwọ́ rẹ̀ fún ọ.”
18 Na ka mea tera, Kia manakohia tau pononga e koe. Katahi taua wahine ka haere, ka kai, a mutu ake te pouri o tona mata.
Ó wí pé, “Kí ìránṣẹ́bìnrin rẹ rí oore-ọ̀fẹ́ lójú rẹ.” Bẹ́ẹ̀ ni obìnrin náà bá tirẹ̀ lọ, ó sì jẹun, kò sì fa ojú ro mọ́.
19 Na ka maranga wawe ratou i te ata, a ka koropiko ki te aroaro o Ihowa, a hoki ana, haere ana ki to ratou whare i Rama. Na ka mohio a Erekana ki a Hana, ki tana wahine; i mahara ano a Ihowa ki a ia.
Wọ́n sì dìde ni kùtùkùtù òwúrọ̀, wọn wólẹ̀ sìn níwájú Olúwa, wọn padà wa sí ilé wọn ni Rama: Elkana si mọ Hana aya rẹ̀: Olúwa sì rántí rẹ̀.
20 Na, ka taka nga ra, ka hapu a Hana, a ka whanau he tama; a huaina iho e ia tona ingoa ko Hamuera, i mea hoki, No te mea i inoia ia e ahau i a Ihowa.
Ó sì ṣe, nígbà tí ọjọ́ rẹ̀ pé, lẹ́yìn ìgbà tí Hana lóyún, ó sì bí ọmọkùnrin kan, ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Samuẹli, pé, “Nítorí tí mo béèrè rẹ̀ lọ́wọ́ Olúwa.”
21 Na ka haere taua tangata a Erekana me tona whare katoa ki runga, ki te patu i te whakahere o te tau ki a Ihowa, me tana ki taurangi hoki.
Ọkùnrin náà Elkana, àti gbogbo àwọn ará ilé rẹ̀, gòkè lọ láti rú ẹbọ ọdún sí Olúwa, àti láti sán ẹ̀jẹ́ rẹ̀.
22 Ko Hana ia kihai i haere; i mea hoki ki tana tahu, Kia whakamutua ra ano te kai u a te tamaiti, ko reira ahau kawe atu ai i a ia, kia puta ai ia ki te aroaro o Ihowa, mo tona noho tonu atu ki reira.
Ṣùgbọ́n Hana kò gòkè lọ; nítorí tí ó sọ fún ọkọ rẹ̀ pé, “Ó di ìgbà tí mo bá gba ọmú lẹ́nu ọmọ náà, nígbà náà ni èmi yóò mú un lọ, kí òun lè fi ara hàn níwájú Olúwa, kí ó sí máa gbé ibẹ̀ títí láé.”
23 Na ka mea a Erekana tana tahu ki a ia, Meatia ta tou whakaaro e whakapai ai; e noho, kia whakamutua ra ano tana kai u; otiia kia mau te kupu a Ihowa. Heoi, noho ana taua wahine, whakangotea ana tana tama, a mutu noa tana kai u.
Elkana ọkọ rẹ̀ sì wí fún un pé, “Ṣe èyí tí ó tọ́ lójú rẹ. Dúró títí ìwọ yóò fi gba ọmú lẹ́nu rẹ̀; ṣùgbọ́n kí Olúwa sá à mú ọ̀rọ̀ rẹ̀ ṣẹ.” Bẹ́ẹ̀ ni obìnrin náà sì jókòó, ó sì fi ọmú fún ọmọ rẹ̀ títí ó fi gbà á lẹ́nu rẹ̀.
24 Na, i te mutunga o tana kai u, ka mauria ia e ia, me etahi puru e toru, kotahi hoki te epa paraoa, me te pounamu waina, kawea ana ia e ia ki te whare o Ihowa, ki Hiro: he tamariki rawa hoki taua tamaiti.
Nígbà tí ó sì gba ọmú lẹ́nu rẹ̀, ó sì mú un gòkè lọ pẹ̀lú ara rẹ̀. Pẹ̀lú ẹgbọrọ màlúù mẹ́ta, àti ìyẹ̀fun efa kan, àti ìgò ọtí wáìnì kan, ó sì mú un wá sí ilé Olúwa ní Ṣilo: ọmọ náà sì wà ní ọmọdé.
25 Na patua ana e ratou te puru, a kawea ana te tamaiti ki a Eri.
Wọ́n pa ẹgbọrọ màlúù, wọ́n sì mú ọmọ náà tọ Eli wá.
26 A ka mea ia, E toku ariki, kia ora tou wairua; e toku ariki, ko ahau te wahine i tu i tou taha i konei nei, i inoi ra ki a Ihowa.
Hana sì wí pé, “Olúwa mi, bí ọkàn rẹ ti wà láààyè, Olúwa mi, èmi ni obìnrin náà tí ó dúró lẹ́bàá ọ̀dọ̀ rẹ níhìn-ín tí ń tọrọ lọ́dọ̀ Olúwa.
27 Ko tenei tamaiti taku i inoi ai; a homai ana e Ihowa ki ahau taku mea i inoi ai ahau ki a ia:
Ọmọ yìí ni mo ń tọrọ; Olúwa sì fi ìdáhùn ìbéèrè tí mo béèrè lọ́dọ̀ rẹ̀ fún mi.
28 Na reira kua tukua atu nei ia e ahau ki a Ihowa; he mea tuku ia ki a Ihowa i nga ra katoa e ora ai ia. A koropiko ana te tamaiti ki a Ihowa ki reira.
Nítorí náà pẹ̀lú, èmi fi í fún Olúwa; ní gbogbo ọjọ́ ayé rẹ̀: nítorí tí mo ti béèrè rẹ̀ fún Olúwa.” Wọn si wólẹ̀ sin Olúwa níbẹ̀.

< 1 Hamuera 1 >