< 1 Kingi 18 >
1 A, ka maha nga ra, ka puta mai te kupu a Ihowa ki a Iraia i te toru o nga tau; i mea ia, Haere whakakitea atu koe ki a Ahapa; a maku e hoatu he ua ki te whenua.
Ó sì ṣe, lẹ́yìn ọjọ́ púpọ̀, ní ọdún kẹta, ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Elijah wá pé, “Lọ, kí o sì fi ara rẹ̀ hàn fún Ahabu, èmi yóò sì rọ òjò sórí ilẹ̀.”
2 Na haere ana a Iraia ki te whakakite i a ia ki a Ahapa. Nui atu hoki te matekai o Hamaria.
Bẹ́ẹ̀ ni Elijah lọ fi ara rẹ̀ han Ahabu. Ìyàn ńlá sì mú ní Samaria,
3 Na ka karanga a Ahapa ki a Oparia, kaitohutohu o tona whare. Na he nui te wehi o Oparia ki a Ihowa;
Ahabu sì ti pe Obadiah, ẹni tí ń ṣe olórí ilé rẹ̀. Obadiah sì bẹ̀rù Olúwa gidigidi.
4 A i ta Ietepere hautopenga atu i nga poropiti a Ihowa, na ka mau a Oparia ki nga poropiti kotahi rau, a huna ana e ia, takirima tekau nga tangata ki te ana kotahi, a whangainga ana ratou e ia ki te taro, ki te wai.
Nígbà tí Jesebeli sì ń pa àwọn wòlíì Olúwa kúrò, Obadiah sì mú ọgọ́rùn-ún wòlíì, ó sì fi wọ́n pamọ́ sínú ihò òkúta, àádọ́ta ní ihò kọ̀ọ̀kan, ó sì fi àkàrà pẹ̀lú omi bọ́ wọn.
5 Na ka mea a Ahapa ki a Oparia, Haere puta noa i te whenua ki nga puna wai katoa; ki nga awa katoa; tera pea ka kitea e tatou tetahi tarutaru e ora ai nga hoiho me nga muera; kei poto katoa a tatou kararehe.
Ahabu sì ti wí fún Obadiah pé, “Lọ sí gbogbo ilẹ̀ sí orísun omi gbogbo àti sí ilẹ̀ gbogbo. Bóyá àwa lè rí koríko láti gba àwọn ẹṣin àti àwọn ìbáaka là, kí a má bá à ṣòfò àwọn ẹranko pátápátá.”
6 Heoi ka wehea e raua te whenua hei haerenga mo raua: haere ana a Ahapa, tona kotahi i tetahi ara, haere ana a Oparia, tona kotahi i tetahi ara.
Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì pín ilẹ̀ tí wọ́n fẹ́ dé láàrín ara wọn, Ahabu gba ọ̀nà kan lọ, Obadiah sì gba ọ̀nà mìíràn lọ.
7 A, i a Oparia i te ara, na ko Iraia kua tutaki ki a ia; a ka mohio ia ki tera, ka tapapa, ka mea, Ko koe ranei tena, e toku Ariki, e Iraia?
Bí Obadiah sì ti ń rìn lọ, Elijah sì pàdé rẹ̀. Obadiah sì mọ̀ ọ́n, ó dojúbolẹ̀, ó sì wí pé, “Ǹjẹ́ ìwọ ni nítòótọ́, Elijah, olúwa mi?”
8 Ano ra ko ia ki a ia, Ko ahau ra; haere, korero atu ki tou ariki, Ko Iraia tenei.
Elijah sì dá a lóhùn pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, lọ kí o sọ fún olúwa rẹ pé, ‘Elijah ń bẹ níhìn-ín.’”
9 Na ka mea tera, He aha ra toku hara i hoatu ai tau pononga ki te ringa o Ahapa kia whakamatea?
Obadiah sì béèrè pé, “Ẹ̀ṣẹ̀ kí ni mo ha dá tí ìwọ fi ń fi ìránṣẹ́ rẹ lé Ahabu lọ́wọ́ láti pa?
10 E ora ana a Ihowa, tou Atua, kahore he iwi, ke kingitanga, i kore nei toku ariki e tono tangata ki reira ki te rapu i a koe: a, i ta ratou meatanga mai, Kahore nei; whakaoatitia iho e ia taua kingitanga, taua iwi ranei, me kahore ratou i kite i a koe.
Mo mọ̀ dájú pé bí Olúwa Ọlọ́run rẹ ti ń bẹ, kò sí orílẹ̀-èdè tàbí ìjọba kan tí olúwa mi kò ti rán ènìyàn lọ láti wò ọ́. Àti nígbà tí orílẹ̀-èdè tàbí ìjọba kan bá wí pé o kò sí, òun a sì mú kí wọ́n búra wí pé wọn kò rí ọ.
11 Na kua mea na koe inaianei, Haere, korero atu ki tou ariki, Ko Iraia tenei.
Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, ìwọ wí fún mi pé kí n lọ sọ́dọ̀ olúwa mi, kí n sì wí pé, ‘Elijah ń bẹ níhìn-ín.’
12 Na akuanei, kei toku mawehenga atu i a koe, ka kahakina atu koe e te wairua o Ihowa ki te wahi e kore ai ahau e mohio; a, i toku taenga atu ki te whakaatu ki a Ahapa, a ka kore ia e kite i a koe, katahi ahau ka patua e ia: heoi e wehi ana tau po nonga i a Ihowa, no toku tamarikitanga ake.
Èmi kò sì mọ ibi tí ẹ̀mí Olúwa yóò gbé ọ lọ nígbà tí mo bá fi ọ́ sílẹ̀. Bí mo bá lọ, tí mo sì sọ fún Ahabu, tí kò sì rí ọ, òun a sì pa mí. Síbẹ̀ èmi ìránṣẹ́ rẹ bẹ̀rù Olúwa láti ìgbà èwe mi wá.
13 Kahore ianei i korerotia ki toku ariki taku i mea ai i ta Ietepere patunga i nga poropiti a Ihowa, taku hunanga i nga poropiti kotahi rau a Ihowa, takirima tekau nga tangata ki roto i te ana kotahi, a whangainga ana e ahau ki te taro, ki te wai?
Ṣé Olúwa mi kò ha ti gbọ́ ohun tí mo ṣe nígbà tí Jesebeli ń pa àwọn wòlíì Olúwa? Mo fi ọgọ́rùn-ún wòlíì Olúwa pamọ́ sínú ihò òkúta méjì, àràádọ́ta ní ọ̀kọ̀ọ̀kan, mo sì fi omi àti oúnjẹ bọ́ wọn.
14 A ka mea mai na koe inaianei, Haere, korero atu ki tou ariki, Ko Iraia tenei: ka patua hoki ahau e ia.
Ìwọ sì sọ fún mi nísinsin yìí pé, kí n tọ olúwa mi lọ pé, ‘Elijah ń bẹ níhìn-ín.’ Òun a sì pa mí!”
15 Ano ra ko Iraia ki a ia, E ora ana a Ihowa o nga mano e tu nei ahau i tona aroaro, ko a tenei ra pu ahau puta ai ki a ia.
Elijah sì wí pé, “Bí Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti wà, ẹni tí èmi ń sìn, nítòótọ́ èmi yóò fi ara mi hàn fún Ahabu lónìí.”
16 Heoi haere ana a Oparia ki te whakatau i a Ahapa, a korerotia ana ki a ia. Na haere ana a Ahapa ki te whakatau i a Iraia.
Bẹ́ẹ̀ ni Obadiah sì lọ láti pàdé Ahabu, ó sì sọ fún un, Ahabu sì lọ láti pàdé Elijah.
17 A, no te kitenga o Ahapa i a Iraia, na ka mea a Ahapa ki a ia, Ko koe tenei, e te kaiwhakararuraru o Iharaira?
Nígbà tí Ahabu sì rí Elijah, ó sì wí fún un pé, “Ṣé ìwọ nìyìí, ìwọ tí ń yọ Israẹli lẹ́nu?”
18 Ano ra ko ia, Kahore i whakararurarutia e ahau a Iharaira; engari koe me te whare o tou papa i ta koutou whakarerenga nei i nga whakahau a Ihowa, i a koe ka whai nei i nga Paara.
Elijah sì dá a lóhùn pé, “Èmi kò yọ Israẹli lẹ́nu, bí kò ṣe ìwọ àti ilé baba rẹ. Ẹ ti kọ òfin Olúwa sílẹ̀, ẹ sì ń tọ Baali lẹ́yìn.
19 Na tikina aianei, huihuia mai a Iharaira katoa ki ahau ki Maunga Karamere, me nga poropiti e wha rau e rima tekau a Paara, me nga poropiti e wha rau o te Ahera, e kai na ki te tepu a Ietepere.
Nísinsin yìí kó gbogbo Israẹli jọ láti pàdé mi lórí òkè Karmeli. Àti kí o sì mú àádọ́ta lé ní irinwó àwọn wòlíì Baali àti irinwó àwọn wòlíì òrìṣà Aṣerah tí wọ́n ń jẹun ní tábìlì Jesebeli.”
20 Heoi tono tangata ana a Ahapa puta noa i nga tama katoa a Iharaira, a whakaminea ana aua poropiti ki Maunga Karamere.
Bẹ́ẹ̀ ni Ahabu ránṣẹ́ sí gbogbo àwọn ọmọ Israẹli, ó sì kó àwọn wòlíì jọ sí orí òkè Karmeli.
21 Na ka whakatata a Iraia ki te iwi katoa, ka mea, Kia pehea te roa o to koutou tuhurihuri ki nga tikanga e rua? ki te mea ko Ihowa te Atua, me whai ki a ia; ki te mea ia ko Paara, me whai ki a ia. Na kahore he kupu i whakahokia e te iwi ki a ia.
Elijah sì lọ síwájú gbogbo àwọn ènìyàn, ó sì wí pé, “Yóò ti pẹ́ tó tí ẹ̀yin yóò máa ṣiyèméjì? Bí Olúwa bá ni Ọlọ́run, ẹ máa tọ̀ ọ́ lẹ́yìn, ṣùgbọ́n bí Baali bá ni Ọlọ́run, ẹ máa tọ̀ ọ́ lẹ́yìn.” Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn náà kò sì wí ohun kan.
22 Katahi ka mea a Iraia ki te iwi, Ko ahau anake kua mahue nei o nga poropiti a Ihowa; e wha rau ia e rima tekau tangata nga poropiti a Paara.
Nígbà náà ni Elijah wí fún wọn pé, “Èmi nìkan ṣoṣo ni ó kù ní wòlíì Olúwa, ṣùgbọ́n, àádọ́ta lé ní irinwó ni wòlíì Baali.
23 Na me homai e ratou etahi puru ma matou, kia rua, ma ratou e whiriwhiri tetahi puru ma ratou, ka tapatapahi ai, ka whakaeke ai ki runga ki nga wahie, kaua hoki he ahi e meatia atu: maku hoki e taka tetahi puru, e whakatakoto ki runga ki nga wahi e; e kore hoki e meatia atu he ahi.
Ẹ fún wa ní ẹgbọrọ akọ màlúù méjì. Jẹ́ kí wọn kí ó sì yan ẹgbọrọ akọ màlúù kan fún ara wọn, kí wọn kí ó sì gé e sí wẹ́wẹ́, kí wọn kí ó sì tò ó sí orí igi, kí wọn kí ó má ṣe fi iná sí i. Èmi yóò sì tún ẹgbọrọ akọ màlúù kejì ṣe, èmi yóò sì tò ó sórí igi, èmi kì yóò sì fi iná sí i.
24 A ma koutou e karanga ki te ingoa o to koutou atua; maku hoki e karanga ki te ingoa o Ihowa. Na, ko te Atua e utua ai te karanga ki te ahi, ko ia hei Atua. Na ka whakahoki te iwi katoa, ka mea, Ka pai tena kupu.
Nígbà náà ẹ ó sì ké pe orúkọ àwọn Ọlọ́run yín, èmi yóò sì ké pe orúkọ Olúwa. Ọlọ́run náà tí ó fi iná dáhùn, òun ni Ọlọ́run.” Nígbà náà ni gbogbo àwọn ènìyàn náà sì wí pé, “Ohun tí ìwọ sọ dára.”
25 Na ka mea a Iraia ki nga poropiti a Paara, Whiriwhiria tetahi puru ma koutou, taka; ko ta koutou ki mua, he tokomaha hoki koutou; ka karanga ai ki te ingoa o to koutou atua; kaua hoki he ahi e meatia atu.
Elijah sì wí fún àwọn wòlíì Baali wí pé, “Ẹ yan ẹgbọrọ akọ màlúù kan fún ara yín, kí ẹ sì tètè kọ́ ṣe é, nítorí ẹ̀yin pọ̀. Ẹ ké pe orúkọ àwọn ọlọ́run yín, ṣùgbọ́n ẹ má ṣe fi iná sí i.”
26 Na ka tango ratou i te puru i hoatu ki a ratou, a mahia ana e ratou. Na ka karanga ki te ingoa o Paara o te ata iho ano a taea noatia te poutumarotanga; i mea ai, E Paara, utua mai ta matou karanga. Otiia kahore he kupu, kihai hoki i utua e teta hi. A tupekepeke ana ratou i te aata i hanga nei.
Nígbà náà ni wọ́n sì mú ẹgbọrọ akọ màlúù náà, tí a ti fi fún wọn, wọ́n sì ṣe é. Nígbà náà ni wọ́n sì ké pe orúkọ Baali láti òwúrọ̀ títí di ọ̀sán gangan wí pé, “Baali! Dá wa lóhùn!” Wọ́n sì ń kégbe. Ṣùgbọ́n kò sí ìdáhùn; kò sí ẹnìkan tí ó sì dáhùn. Wọ́n sì jó yí pẹpẹ náà ká, èyí tí wọ́n tẹ́.
27 A, i te poutumarotanga, ka tawai a Iraia ki a ratou, ka mea, Karanga, kia nui te reo; he atua hoki ia: kei te purakau pea ia, kei tahaki ranei, kei te ara ranei, tena ranei kei te moe, a me whakaara.
Ní ọ̀sán gangan, Elijah bẹ̀rẹ̀ sí ń fi wọ́n ṣe ẹlẹ́yà ó sì wí pé, “Ẹ kígbe lóhùn rara Ọlọ́run sá à ni òun! Bóyá ó ń ṣe àṣàrò, tàbí kò ráyè, tàbí ó re àjò. Bóyá ó sùn, ó yẹ kí a jí i.”
28 Na nui atu to ratou reo ki te karanga, ka haehae i a ratou ki te maripi, ki te oka, ko ta ratou tikanga hoki ia, a tarere noa nga toto ki runga ki a ratou.
Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì kígbe lóhùn rara, wọ́n sì fi ọ̀bẹ àti ọ̀kọ̀ ya ara wọn gẹ́gẹ́ bí ìṣe wọn, títí tí ẹ̀jẹ̀ fi tú jáde ní ara wọn.
29 Heoi kua tawharara te ra, na ka poropiti ratou a tae noa ki te whakaekenga o to te ahiahi whakahere; otiia kahore he reo, kihai i utua te karanga, kahore tetahi hei whakarongo.
Nígbà tí ọjọ́ yẹ àtàrí, wọ́n sì ń fi òmùgọ̀ sọtẹ́lẹ̀ títí di àkókò ìrúbọ àṣálẹ́, ṣùgbọ́n kò sí ohùn, kò sì ṣí ìdáhùn, kò sì ṣí ẹni tí ó kà á sí.
30 Na ka mea a Iraia ki te iwi katoa, Neke mai ki ahau. Na neke ana te iwi katoa ki a ia, Na ka whakatikaia e ia te aata a Ihowa i turakina.
Nígbà náà ni Elijah wí fún gbogbo àwọn ènìyàn náà pé, “Ẹ súnmọ́ mi.” Wọ́n sì súnmọ́ ọn, ó sì tún pẹpẹ Olúwa tí ó ti wó lulẹ̀ ṣe.
31 I mau hoki a Iraia ki nga kohatu kotahi tekau ma rua; rite tonu te maha ki nga iwi o nga tama a Hakopa, ki a ia nei te kupu a Ihowa, i ki nei, Ko Iharaira hei ingoa mou.
Elijah sì mú òkúta méjìlá, ọ̀kọ̀ọ̀kan fún ẹ̀yà ọmọ Jakọbu kan, ẹni tí ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ wá wí pé, “Israẹli ni orúkọ rẹ̀ yóò máa jẹ́.”
32 Na hanga ana e ia aua kohatu hei aata mo te ingoa o Ihowa; a keria ana he awa ki te taha o te aata a taka noa, kia rua nga mehua purapura ka ki.
Ó sì tẹ́ pẹpẹ pẹ̀lú àwọn òkúta wọ̀nyí ní orúkọ Olúwa, ó sì wa yàrá yí pẹpẹ náà ká, tí ó lè gba ìwọ̀n òsùwọ̀n irúgbìn méjì.
33 Na whakapaia ana e ia nga wahie, a tapatapahia ana te puru, whakatakotoria ana ki runga ki nga wahie. A ka mea ia, Whakakiia etahi oko, kia wha, ki te wai, ka riringi ki runga ki te tahunga tinana, ki nga wahie.
Ó sì to igi náà dáradára, ó sì ké ẹgbọrọ akọ màlúù náà wẹ́wẹ́, ó sì tò ó sórí igi. Nígbà náà ni ó sì wí fún wọn wí pé, “Ẹ fi omi kún ìkòkò mẹ́rin, kí ẹ sì tu sórí ẹbọ sísun àti sórí igi náà.”
34 I mea ano ia, Tena ano. Na ka meatia ano e ratou. I mea hoki ia, Tuatorutia. Na ka tuatorutia e ratou.
Ó sì wí pe, “Ẹ ṣe é ní ìgbà kejì.” Wọ́n sì ṣe é ní ìgbà kejì. Ó sì tún wí pé, “Ṣe é ní ìgbà kẹta.”
35 Na ka rere te wai i nga taha o te aata tawhio noa: whakakiia ana hoki e ia te waikeri ki te wai.
Omi náà sì sàn yí pẹpẹ náà ká, ó sì fi omi kún yàrá náà pẹ̀lú.
36 Na i te whakaekenga o to te ahiahi whakahere, ka whakatata a Iraia poropiti, a ka mea, E Ihowa, e te Atua o Aperahama, o Ihaka, o Iharaira, kia mohiotia i tenei ra ko koe te Atua i roto i a Iharaira, ko ahau tau pononga, a nau te kupu i mea ai a hau i enei mea katoa.
Ó sì ṣe, ní ìrúbọ àṣálẹ́, wòlíì Elijah sì súnmọ́ tòsí, ó sì gbàdúrà wí pé, “Olúwa, Ọlọ́run Abrahamu, Isaaki àti Israẹli, jẹ́ kí ó di mí mọ̀ lónìí pé ìwọ ni Ọlọ́run ní Israẹli àti pé èmi ni ìránṣẹ́ rẹ, àti pé mo ṣe gbogbo nǹkan wọ̀nyí nípa àṣẹ rẹ.
37 Whakarongo mai ki ahau, e Ihowa, whakarongo mai ki ahau, kia mohio ai tenei iwi ko te Atua koe, e Ihowa, nau ano i whakahoki o ratou ngakau ki muri nei.
Gbọ́ ti èmi, Olúwa, gbọ́ ti èmi, kí àwọn ènìyàn wọ̀nyí lè mọ̀ pé ìwọ Olúwa ni Ọlọ́run àti pé ìwọ tún yí ọkàn wọn padà.”
38 Na ko te tino takanga iho o te ahi a Ihowa, pau ake te tahunga tinana, me nga wahie, me nga kohatu, me te puehu, mitikia ake ana ano hoki te wai i roto i te waikeri.
Nígbà náà ni iná Olúwa bọ́ sílẹ̀, ó sì sun ẹbọ sísun náà àti igi, àti àwọn òkúta, àti erùpẹ̀, ó sì tún lá omi tí ń bẹ nínú yàrá náà.
39 A, no te kitenga o te iwi katoa, tapapa ana, me te ki ake ano, Ko Ihowa, ko ia te Atua: ko Ihowa, ko ia te Atua.
Nígbà tí gbogbo àwọn ènìyàn sì rí èyí, wọ́n da ojú wọn bolẹ̀, wọ́n sì kígbe pé, “Olúwa, òun ni Ọlọ́run! Olúwa, òun ni Ọlọ́run!”
40 Katahi ka mea a Iraia ki a ratou, Hopukia nga poropiti a Paara: kei mawhiti tetahi o ratou. Na hopukia ana e ratou, a kawea ana e Iraia ki raro, ki te awa, ki Kihona, patua iho ki reira.
Nígbà náà ni Elijah sì pàṣẹ fún wọn pé, “Ẹ mú àwọn wòlíì Baali. Ẹ má ṣe jẹ́ kí ọ̀kan nínú wọn kí ó sálọ!” Wọ́n sì mú wọn, Elijah sì mú wọn sọ̀kalẹ̀ sí àfonífojì Kiṣoni, ó sì pa wọ́n níbẹ̀.
41 Na ka mea a Iraia ki a Ahapa, Haere ki runga, ki te kai, ki te inu; he haruru ua hoki te rara mai nei.
Elijah sì wí fún Ahabu pé, “Lọ, jẹ, kí o sì mu, nítorí ìró ọ̀pọ̀lọpọ̀ òjò ń bọ̀.”
42 Heoi haere ana a Ahapa ki te kai, ki te inu. Ko Iraia ia i piki ki te tihi o Karamere; a tapapa ana ia ki te whenua, ko tona mata i roto i ona turi.
Bẹ́ẹ̀ ni Ahabu gòkè lọ láti jẹ àti láti mu. Ṣùgbọ́n Elijah gun orí òkè Karmeli lọ ó sì tẹríba, ó sì fi ojú rẹ̀ sí agbede-méjì eékún rẹ̀.
43 Na ka mea ia ki tana tangata, Tena, piki atu inaianei, tirohia te ritenga atu o te moana. Na piki ana ia, titiro ana, a ka mea, Kahore kau he mea. Na ka mea ano tera, Hoki atu ano, kia whitu nga hokinga.
Ó sì wí fún ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ pé, “Lọ, kí o sì wo ìhà Òkun, òun sì gòkè lọ, ó sì wò.” Ó sì wí pé, “Kò sí nǹkan níbẹ̀.” Ó sì wí pé, “Tún lọ nígbà méje.”
44 A i te whitu ka mea ia, Nana, he kapua nohinohi tera te haere ake ra i roto i te moana; kei te kapu o te ringa tangata te rite. Na ka mea tera, Haere, mea atu ki a Ahapa, Whakanohoia tou hariata, ka haere ki raro; kei araia koe e te ua.
Nígbà keje, ìránṣẹ́ náà sì wí pé, “Àwọsánmọ̀ kékeré kan dìde láti inú Òkun, gẹ́gẹ́ bí ọwọ́ ènìyàn.” Elijah sì wí pé, “Lọ, kí o sọ fún Ahabu pé, ‘Di kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ, kí o sì sọ̀kalẹ̀ lọ, kí òjò ó má ba à dá ọ dúró.’”
45 Na mea rawa ake kua pouri pu te rangi i te kapua, i te hau, nui atu hoki te ua. Na rere ana tera a Ahapa i runga i te hariata, a haere ana ki Ietereere.
Ó sì ṣe, nígbà díẹ̀ sí i, ọ̀run sì ṣú fún àwọsánmọ̀, ìjì sì dìde, òjò púpọ̀ sì rọ̀, Ahabu sì gun kẹ̀kẹ́ lọ sí Jesreeli.
46 A i runga i a Iraia te ringa o Ihowa; na whitikiria ana e ia tona hope, a rere ana i mua i a Ahapa a tae noa ki Ietereere.
Agbára Olúwa sì ń bẹ lára Elijah; ó sì di àmùrè ẹ̀gbẹ́ rẹ, ó sì sáré níwájú Ahabu títí dé Jesreeli.