< 1 Whakapapa 16 >
1 Heoi kawea ana e ratou te aaka a te Atua, whakaturia ana ki waenganui o te teneti i whakaarahia e Rawiri mona; a tapaea ana e ratou he tahunga tinana, he whakahere mo te pai ki te aroaro o te Atua.
Wọ́n gbé àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run, wá sínú àgọ́ ti Dafidi ti pèsè fún un, wọ́n sì gbé ẹbọ sísun àti ọrẹ ìdàpọ̀ kalẹ̀ níwájú Ọlọ́run.
2 A, ka mutu ta Rawiri whakaeke i nga tahunga tinana, i nga whakahere mo te pai, ka manaakitia e ia te iwi i runga i te ingoa o Ihowa.
Lẹ́yìn tí Dafidi parí ẹbọ sísun àti ọrẹ ìdàpọ̀, ó bùkún àwọn ènìyàn ní orúkọ Olúwa.
3 I tuwhaina ano e ia ma nga tangata katoa o Iharaira, ma te tane, ma te wahine, kotahi rohi taro ma tenei, ma tenei, tetahi wahi kikokiko, me tetahi keke karepe whakamaroke.
Nígbà náà ó fún olúkúlùkù ọkùnrin àti obìnrin ọmọ Israẹli ní ìṣù àkàrà kan, àkàrà dídùn ti àkókò kan àti àkàrà dídùn ti èso àjàrà kan.
4 I whakaritea ano e ia etahi o nga Riwaiti hei minita ki mua i te aaka a Ihowa, hei whakamahara, hei whakawhetai, hei whakamoemiti ki a Ihowa, ki te Atua o Iharaira:
Ó yan díẹ̀ lára àwọn ará Lefi láti máa jọ́sìn níwájú àpótí ẹ̀rí Olúwa, àti láti ṣe ìrántí àti dúpẹ́ àti láti yin Olúwa, Ọlọ́run Israẹli.
5 Ko Ahapa hei tuatahi; i muri i a ia ko Hakaraia, ko Teiere, ko Hemiramoto, ko Penaia, ko Opereeroma, ko Teiere hoki ki nga hatere, ki nga hapa, ko Ahapa hei whakatangi i nga himipora:
Asafu ni olóyè, àtẹ̀lé rẹ ni Sekariah, Jehieli, Ṣemiramotu, Asieli, Mattitiah, Eliabu, Benaiah, Obedi-Edomu àti Jeieli, àwọn ni yóò lu ohun èlò orin olókùn àti dùùrù haapu. Asafu ni yóò lu símbálì kíkan.
6 Ko Penaia hoki raua ko Tahatiere, ko nga tohunga, kia tuturu tonu ta raua mau tetere ki mua i te aaka o te kawenata a te Atua.
Àti Benaiah àti Jahasieli àwọn àlùfáà ni yóò fọn ìpè nígbà gbogbo níwájú àpótí ẹ̀rí májẹ̀mú ti Ọlọ́run.
7 I reira ano i taua ra ka whakaritea tuatahitia e Rawiri he whakamoemiti mo Ihowa, na te ringa o Ahapa ratou ko ona teina.
Ní ọjọ́ náà Dafidi kọ́kọ́ fi lé Asafu àti àwọn ẹlẹgbẹ́ rẹ̀ lọ́wọ́ orin Dafidi ti ọpẹ́ sí Olúwa.
8 Whakawhetai atu ki a Ihowa, karanga ki tona ingoa; whakapuakina ana mahi ki waenganui o nga iwi.
Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa, ẹ pe orúkọ rẹ̀, ẹ fi iṣẹ́ rẹ̀ hàn nínú àwọn ènìyàn fún ohun tí ó ṣe
9 Waiata ki a ia, himene ki a ia; korerotia ana mahi whakamiharo katoa.
Ẹ kọrin sí i, ẹ kọrin ìyìn, sí i, ẹ sọ ti gbogbo iṣẹ́ ìyanu rẹ̀.
10 Kia whakamanamana koutou ki tona ingoa tapu: kia hari nga ngakau o te hunga e rapu ana i a Ihowa.
Ìyìn nínú orúkọ rẹ̀ mímọ́; jẹ kí ọkàn àwọn tí ó yin Olúwa kí ó yọ̀.
11 Rapua a Ihowa, me tona kaha; rapua tonutia tona mata.
Ẹ wá Olúwa àti agbára rẹ̀; e wá ojú rẹ̀ nígbà gbogbo.
12 Maharatia ana mahi whakamiharo i mahi ai ia; ana merekara, me nga whakaritenga a tona mangai;
Rántí àwọn ìyanu tí Ó ti ṣe, iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ àti ìdájọ́ tí Ó ti sọ.
13 E nga uri o Iharaira, o tana pononga, e nga tama a Hakopa, e ana i whiriwhiri ai.
A! ẹ̀yin ìran ọmọ Israẹli ìránṣẹ́ rẹ̀, àwọn ọmọ Jakọbu, ẹ̀yin tí ó ti yàn.
14 Ko Ihowa ia, ko to tatou Atua: kei te whenua katoa ana whakaritenga.
Òun ni Olúwa Ọlọ́run wa; ìdájọ́ rẹ̀ wà ní gbogbo ayé.
15 Maharatia tonutia tana kawenata, te kupu i kiia iho e ia ki te mano o nga whakatupuranga;
Ó rántí májẹ̀mú rẹ̀ láéláé, ọ̀rọ̀ tí ó pàṣẹ, fún ẹgbẹẹgbẹ̀rún ìran,
16 Te kawenata i whakarite ai ia ki a Aperahama, tana oati hoki ki a Ihaka;
májẹ̀mú tí ó dá pẹ̀lú Abrahamu, ìbúra tí ó ṣe pẹ̀lú fún Isaaki.
17 A whakapumautia iho hei tikanga ki a Hakopa, hei kawenata mau tonu ki a Iharaira:
Ó ṣe ìdánilójú u rẹ̀ fún Jakọbu, gẹ́gẹ́ bí àṣẹ sí Israẹli, gẹ́gẹ́ bi májẹ̀mú ayérayé:
18 I a ia i mea ra, Ka hoatu e ahau ki a koe te whenua o Kanaana hei wahi pumau mo koutou:
“Sí ọ, ni èmi yóò fún ní ilẹ̀ Kenaani. Gẹ́gẹ́ bí ààyè tí ìwọ yóò jogún.”
19 I te mea e torutoru ana ano koutou; ae, e tokoiti rawa ana, he manene hoki ki reira;
Nígbà tí wọn kéré ní iye, wọ́n kéré gidigidi, wọ́n sì jẹ́ àlejò níbẹ̀,
20 I a ratou e haereere ana i tenei iwi ki tera atu iwi, i tetahi rangatiratanga ki tetahi iwi ke.
wọ́n rìn kiri láti orílẹ̀-èdè sí orílẹ̀-èdè láti ìjọba kan sí èkejì.
21 Kihai ratou i tukua e ia kia tukinotia e te tangata; ae ra, i riria e ia nga kingi, he whakaaro ki a ratou;
Kò gba ọkùnrin kankan láyè láti pọ́n wọn lójú; nítorí tiwọn, ó bá àwọn ọba wí.
22 I mea ia, Kei pa ki aku i whakawahi ai, kei kino hoki ki aku poropiti.
“Má ṣe fọwọ́ kan àwọn ẹni àmì òróró mi; má ṣe pa àwọn wòlíì mi lára.”
23 Waiata, e te whenua katoa ki a Ihowa; kauwhautia tana mahi whakaora i tena rangi, i tena rangi.
Kọrin sí Olúwa gbogbo ayé; ẹ máa fi ìgbàlà rẹ̀ hàn láti ọjọ́ dé ọjọ́.
24 Whakapuakina tona kororia i waenganui i nga tauiwi, ana mahi whakamiharo i waenganui i nga iwi katoa.
Kéde ògo à rẹ̀ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, ohun ìyàlẹ́nu tí ó ṣe láàrín gbogbo ènìyàn.
25 He nui hoki a Ihowa, kia nui te whakamoemiti ki a ia; kia wehingia nuitia atu hoki ia i nga atua katoa.
Nítorí títóbi ni Olúwa òun sì ni ìyìn yẹ jùlọ; òun ni kí a bẹ̀rù ju gbogbo àwọn Ọlọ́run lọ.
26 He whakapakoko hoki nga atua katoa o nga iwi: na Ihowa ia i hanga nga rangi.
Nítorí gbogbo àwọn ọlọ́run orílẹ̀-èdè jẹ́ àwọn òrìṣà, ṣùgbọ́n Olúwa dá àwọn ọ̀run.
27 He honore, he kingitanga kei tona aroaro; kei tona wahi te kaha me te koa.
Dídán àti ọláńlá ni ó wà níwájú rẹ̀; agbára àti ayọ̀ ni ó wà ní ibi ibùgbé rẹ̀.
28 Tukua ki a Ihowa, e nga hapu o nga iwi, tukua ki a Ihowa te kororia me te kaha.
Fi fún Olúwa, ẹ̀yin ìdílé àwọn orílẹ̀-èdè, ẹ fi ògo àti ipá fún Olúwa.
29 Tukua atu ki a Ihowa te kororia e tika ana mo tona ingoa: maua mai he whakahere, haere mai ki tona aroaro: koropiko ki a Ihowa i roto i te ataahua o te tapu.
Fún Olúwa ní ìyìn nítorí orúkọ rẹ̀; gbé ọrẹ kí ẹ sì wá síwájú rẹ̀. Sìn Olúwa nínú inú dídùn ìwà mímọ́ rẹ̀.
30 Kia wehi ra ki tona aroaro, e te whenua katoa: e u ano te ano, te taea te whakanekeneke.
Wárìrì níwájú rẹ̀, gbogbo ayé! Ayé sì fi ìdí múlẹ̀; a kò sì le è ṣí i.
31 Kia hari nga rangi, kia koa te whenua; kia mea ratou i roto i nga iwi, Ko Ihowa te kingi.
Jẹ́ kí àwọn ọ̀run kí ó yọ̀, jẹ́ kí ayé kí ó ṣe inú dídùn; lẹ́ kí wọn kí ó sọ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, pé “Olúwa jẹ ọba!”
32 Kia haruru te moana, me nga mea e hua ana i roto; kia koa te mara, me nga mea katoa i runga:
Jẹ́ kí ọ̀run kí ó tún dún padà, àti gbogbo ohun tí ó wà nínú rẹ̀; Jẹ́ kí àwọn pápá kí ó hó fún ayọ̀, àti gbogbo ohun tí ó wà nínú rẹ̀!
33 Ko reira nga rakau o te ngahere waiata ai i te hari i te aroaro o Ihowa, e haere mai ana hoki ia ki te whakarite i runga i te whenua.
Nígbà náà ni igi igbó yóò kọrin, wọn yóò kọrin fún ayọ̀ níwájú Olúwa, nítorí tí ó wá láti ṣèdájọ́ ayé.
34 Whakawhetai ki a Ihowa, he pai hoki ia, he pumau tonu hoki tana mahi tohu.
Fi ọpẹ́ fún Olúwa, nítorí tí ó dára; ìfẹ́ ẹ rẹ̀ dúró títí láé.
35 Mea atu hoki, Whakaorangia matou, e te Atua o to matou whakaoranga, kohikohia matou, whakaorangia matou i nga tauiwi, kia whakawhetai ai matou ki tou ingoa tapu, kia whakamanamana ai ki tou whakamoemititanga.
Ké lóhùn rara, “Gbà wá, Ọlọ́run olùgbàlà a wa; kó wa jọ kí o sì gbà wá kúrò lọ́wọ́ àwọn orílẹ̀-èdè, kí àwa kí ó lè fi ọpẹ́ fún orúkọ mímọ́ rẹ, kí àwa kí ó lè yọ̀ nínú ìyìn rẹ̀.”
36 Kia whakapaingia a Ihowa, te Atua o Iharaira ake nei, a ake nei. Na ka mea te iwi katoa, Amine; a whakamoemiti ano ratou ki a Ihowa.
Olùbùkún ni Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, láé àti láéláé. Lẹ́yìn náà gbogbo àwọn ènìyàn wí pé, “Àmín,” wọ́n “Yin Olúwa.”
37 Heoi ka waiho e ia i reira, i mua i te aaka o te kawenata a Ihowa, a Ahapa ratou ko ona teina, hei minita tonu ki mua i te aaka, i nga meatanga o tenei ra, o tenei ra:
Dafidi fi Asafu àti àwọn ẹlẹgbẹ́ rẹ̀ sílẹ̀ níwájú àpótí ẹ̀rí Olúwa láti jíṣẹ́ níbẹ̀ déédé, gẹ́gẹ́ bí ọjọ́ kọ̀ọ̀kan ṣe gbà.
38 A Opereeroma me o ratou teina, e ono tekau ma waru; a Opereeroma hoki tama a Ierutunu, raua ko Hoha hei kaitiaki tatau;
Ó fi Obedi-Edomu àti méjìdínláàádọ́rin ẹlẹgbẹ́ ẹ rẹ̀ láti ṣiṣẹ́ ìránṣẹ́ pẹ̀lú wọn. Obedi-Edomu mọ Jedutuni, àti Hosa pẹ̀lú jẹ́ olùtọ́jú ẹnu-ọ̀nà.
39 Ko Haroko tohunga me ona teina, me nga tohunga, ki mua o te tapenakara o Ihowa i te wahi tiketike i Kipeono,
Dafidi fi Sadoku àlùfáà àti àwọn àlùfáà ẹlẹgbẹ́ rẹ̀ níwájú Àgọ́ Olúwa ní ibi gíga ní Gibeoni.
40 Hei whakaeke tonu i nga tahunga tinana ma Ihowa ki runga ki te aata tahunga tinana i te ata, i te ahiahi, hei mea i nga mea katoa i tuhituhia ki te ture a Ihowa, i whakahaua e ia ki a Iharaira;
Láti gbé pẹpẹ ẹbọ sísun déédé, àárọ̀ àti ìrọ̀lẹ́ ní ìbámu pẹ̀lú gbogbo ohun tí a kọ sínú òfin Olúwa, tí ó ti fún Israẹli.
41 A, hei hoa mo ratou a Hemana raua ko Ierutunu, me era atu i whiriwhiria, i whakahuatia nei nga ingoa, hei whakawhetai ki a Ihowa, no te mea he pumau tonu tana mahi tohu;
Pẹ̀lú wọn ni Hemani àti Jedutuni àti ìyókù tí a mú àti yàn nípasẹ̀ orúkọ láti fi ọpẹ́ fún Olúwa, nítorí tí ìfẹ́ rẹ̀ dúró títí láéláé
42 Hei hoa hoki mo ratou a Hemana raua ko Ierutunu me nga tetere me nga himipora ma nga kaiwhakatangi kaha, me nga whakatangi mo nga waiata a te Atua: a ko nga tama a Ierutunu hei kaitiaki kuwaha.
Hemani àti Jedutuni ni wọ́n dúró fún fífọn ìpè àti Kimbali àti fún lílo ohun èlò yòókù fún orin Ọlọ́run. Àwọn ọmọ Jedutuni wà ní ipò dídúró ní ẹnu-ọ̀nà.
43 Na haere ana te iwi katoa ki tona whare, ki tona whare; a hoki ana a Rawiri ki te manaaki i tona whare.
Nígbà náà gbogbo àwọn ènìyàn kúrò, olúkúlùkù sí ilé rẹ̀: Dafidi yípadà láti súre fún ìdílé rẹ̀.