< Apokalypsy 11 >
1 Tinolotse bararata hoe kobay fanjehean-draho, vaho nisaontsieñe ty hoe: Miongaha, zeheo i kivohon’ Añaharey naho i kitreliy vaho o mpitalaho aoo,
A sì fi ìfèéfèé kan fún mi tí o dàbí ọ̀pá-ìwọ̀n: ẹnìkan sì wí pé, “Dìde, wọn tẹmpili Ọlọ́run, àti pẹpẹ, àti àwọn tí ń sìn nínú rẹ̀.
2 fe apoho ty kiririsa’ i anjombay, ko zehè’o fa natolotse amo kilakila ondatio. Ho lialiàñe efa-polo ro’ amby volañe i rova miavakey.
Sì fi àgbàlá tí ń bẹ lóde tẹmpili sílẹ̀, má sì ṣe wọ́n ọ́n; nítorí tí a fi fún àwọn aláìkọlà: ìlú mímọ́ náà ni wọn ó sì tẹ̀ mọ́lẹ̀ ní oṣù méjìlélógójì.
3 Le ho tolorako lily ty valolombeloko roe, hitoky arivo tsy roan-jato tsy enem-polo andro misikin-gony.
Èmi ó sì yọ̀ǹda fún àwọn ẹlẹ́rìí mi méjèèje, wọn ó sì sọtẹ́lẹ̀ fún ẹgbẹ̀fà ọjọ́ ó lé ọgọ́ta nínú aṣọ ọ̀fọ̀.”
4 Ie i hatae oliva roe naho i fitongoàn-jiro roe mijohañe añatrefa’ i Talè’ ty tane toy rey.
Wọ̀nyí ni igi olifi méjì náà, àti ọ̀pá fìtílà méjì náà tí ń dúró níwájú Olúwa ayé.
5 Naho eo ty te hijoy iareo, le miporoak’ afo ty falie’ iareo hamorototo o rafelahi’eo. Aa ndra iaia ty te hanjevoñe iareo le tsy mete tsy izay ty hampibanirañe aze.
Bí ẹnikẹ́ni bá sì fẹ́ pa wọn lára, iná ó ti ẹnu wọn jáde, a sì pa àwọn ọ̀tá wọn run, báyìí ni a ó sì pa ẹnikẹ́ni tí ó ba ń fẹ́ pa wọn lára run.
6 Aman-dily hampikiteke i likerañey iereo tsy hahavia’ ty orañe amo andro hitokia’ iareoo; vaho aman-dily amo ranoo hañova aze ho lio, naho ty hampipaoke an-tane atoy ze fonga angorosy ndra mbia ‘mbia satrie’ iareo.
Àwọn wọ̀nyí ni ó ni agbára láti sé ọ̀run, tí òjò kò fi lè rọ̀ ni ọjọ́ àsọtẹ́lẹ̀ wọn. Wọ́n sì ní agbára lórí omi láti sọ wọn di ẹ̀jẹ̀, àti láti fi onírúurú àjàkálẹ̀-ààrùn kọlu ayé, nígbàkígbà tí wọ́n bá fẹ́.
7 Ie heneke ty fitalilia’ iareo, le hialia’ i biby miakats’ an-tsikeokeokey le handrebake naho hañè-doza am’ iereo, (Abyssos )
Nígbà tí wọn bá sì ti parí ẹ̀rí wọn, ẹranko tí o ń tí inú ọ̀gbun gòkè wá yóò bá wọn jagun, yóò sì ṣẹ́gun wọn, yóò sì pa wọ́n. (Abyssos )
8 vaho hapok’ an-dala’ i rova jabajaba razañeñe ty hoe Sodoma naho Egipte amy nipehañe i Talè’ iareoy ty fañòva’ iareo.
Òkú wọn yóò sì wà ni ìgboro ìlú ńlá náà tí a ń pè ní Sodomu àti Ejibiti nípa ti ẹ̀mí, níbi tí a gbé kan Olúwa wọ́n mọ́ àgbélébùú.
9 Aa le handritse telo andro naho tampa’e ty ila’ ondaty naho rofoko naho fameleke vaho fifeheañe hisamba i fañòva’ iareo reio ie hifoneñe tsy handenteke iareo an-kibory.
Fún ọjọ́ mẹ́ta àti ààbọ̀ ni àwọn ènìyàn nínú ènìyàn gbogbo àti ẹ̀yà, àti èdè, àti orílẹ̀, wo òkú wọn, wọn kò si jẹ kì a gbé òkú wọn sínú ibojì.
10 Le hitohàfa’ ze fonga mpimoneñe an-tane atoy naho hifale vaho hifampitsaloke falalàñe amy te nisamporerahe’ i mpitoky roe rey o mpimoneñe an-tane atoio.
Àti àwọn tí o ń gbé orí ilẹ̀ ayé yóò sì yọ̀ lé wọn lórí, wọn yóò sì ṣe àríyá, wọn ó sì ta ara wọn lọ́rẹ; nítorí tí àwọn wòlíì méjèèjì yìí dá àwọn tí o ń bẹ lórí ilẹ̀ ayé lóró.
11 Ie ritse ty telo andro naho tampa’e, le nizilik’ am’ iereo ao ty Kofò-belon’ Añahare le nitroatse am-pandia, vaho nitsipike ty anifañe ze nahaisake iareo.
Àti lẹ́yìn ọjọ́ mẹ́ta àti ààbọ̀ náà, ẹ̀mí ìyè láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run wá wọ inú wọn, wọn sì dìde dúró ni ẹsẹ̀ wọn; ẹ̀rù ńlá sì ba àwọn tí o rí wọn.
12 Nahajanjiñe ty fiarañanañañe nipazake boak’ andindìñe ey i roroey nanao ty hoe am’ iereo: Miambonea mb’etoy. Aa le nionjomb’ andindìmb’eo mb’amy rahoñey iereo am-pisamba’ o rafelahi’eo.
Wọn sì gbọ́ ohùn ńlá kan láti ọ̀run wá ń wí fún wọn pé, “Ẹ gòkè wá ìhín!” Wọn sì gòkè lọ sí ọ̀run nínú ìkùùkuu àwọsánmọ̀; lójú àwọn ọ̀tá wọn.
13 Tamy oray avao ty fanginikinihañe jabajaba nampihotrake ty faha-folo’ i rovay. Ondaty fito-arivo ty nikoromak’ amy fanginikinihañey le nangebahebake o ila’eo, nañomey engeñe an’Andrianañaharen-dikerañey.
Ní wákàtí náà omìmì-ilẹ̀ ńlá kan sì mì, ìdámẹ́wàá ìlú náà sì wó, àti nínú omìmì-ilẹ̀ náà ẹ̀ẹ́dẹ́gbàárin ènìyàn ní a pa; ẹ̀rù sì ba àwọn ìyókù, wọn sì fi ògo fún Ọlọ́run ọ̀run.
14 Añe i hankàñe faha-roey; Inao, fa ho tondroke ty faha-telo.
Ègbé kejì kọjá; sì kíyèsi i, ègbé kẹta sì ń bọ̀ wá kánkán.
15 Nitioke i anjely faha-fitoy le hoe ty fipoñam-piarañanañañe maro andindìñe ey: Fa a’ i Talèn-tikañey, toe i Noriza’ey o fifehea’ ty voatse toio henane zao, ie ho fehe’e nainai’e donia. (aiōn )
Angẹli keje sì fọn ìpè; a sì gbọ́ ohùn ńlá láti ọ̀run, wí pé, “Ìjọba ayé di ti Olúwa wá, àti tí Kristi rẹ̀; òun yóò sì jẹ ọba láé àti láéláé!” (aiōn )
16 Aa le nibabok’ an-daharañ’ eo i androanavy roapolo-efats’amby mpiambesatse am-piambesam-pifehea’ iareo añatrefan’ Añahare rey, vaho nitalaho aman’ Andrianañahare,
Àwọn àgbà mẹ́rìnlélógún náà tí wọn jókòó níwájú Ọlọ́run lórí ìtẹ́ wọn, dojúbolẹ̀, wọn sì sin Ọlọ́run,
17 nisabo ti-hoe: Mañandriañe Azo zahay, ry Talè Andrianañahare, Tsitongerèñe, I eo, naho teo, amy te rinambe’o o haozara’o jabahinakeo vaho fa mifehe.
wí pé: “Àwa fi ọpẹ́ fún ọ, Olúwa Ọlọ́run, Olódùmarè, tí ń bẹ, tí ó sì ti wà, nítorí pé ìwọ ti gba agbára ńlá rẹ̀, ìwọ sì ti jẹ ọba.
18 Nidabadoa o kilakila ondatio; Fe tondroke ty haviñera’o, naho ty androm-pizakañe o nivilasio naho ty androm-panambezañe o mpitoro’o mitokio, naho o noro’oo vaho ze hene ondaty miasy ty tahina’o, ndra ty bey ndra ty kede— vaho ty handrotsake o mpandrotsa’ ty tane toio.
Inú bí àwọn orílẹ̀-èdè, bẹ́ẹ̀ ni ìbínú rẹ̀ ti dé, àti àkókò láti dá àwọn òkú lẹ́jọ́, àti láti fi èrè fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ wòlíì, àti àwọn ènìyàn mímọ́, àti àwọn tí o bẹ̀rù orúkọ rẹ̀, àti ẹni kékeré àti ẹni ńlá; àti láti run àwọn tí ń pa ayé run.”
19 Sinokak’ amy zao i kivohon’ Añahare andindìñey le tendrek’ amy kibohotsey i vatam-pañina’ey, naho eo ty fibilobiloan-kelatse am-piparapapiahañe naho fikorokodoiñan-kotroke naho ty fanginikinihan-tane vaho ty fañavandrañan-gadaboñe.
A sì ṣí tẹmpili Ọlọ́run sílẹ̀ ní ọ̀run, a sì ri àpótí májẹ̀mú nínú tẹmpili rẹ̀. Mọ̀nàmọ́ná sì kọ, a sì gbọ́ ohùn, àrá sì sán, ilẹ̀ sì mi, yìnyín ńlá sì bọ́.